< Amos 1 >
1 Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
Ũyũ nĩguo ũhoro wa Amosi, ũmwe wa arĩithi arĩa maarĩithagia Tekoa, wa ũndũ ũrĩa onire ũkoniĩ Isiraeli mĩaka ĩĩrĩ mbere ya gĩthingithia, hĩndĩ ĩrĩa Uzia aarĩ mũthamaki wa Juda nake Jeroboamu mũrũ wa Joashu aarĩ mũthamaki wa Isiraeli.
2 Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
Oigire atĩrĩ: “Jehova araramaga arĩ Zayuni, na akaruruma arĩ Jerusalemu; ũrĩithio wa arĩithi a mbũri nĩũkooma, nako gacũmbĩrĩ ga Karimeli kahoohe.”
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Nĩ ũndũ wa mehia matatũ ma Dameski, o na mana-rĩ, niĩ ndikahũndũra mangʼũrĩ makwa. Tondũ nĩahũũrire Gileadi na ibũi irĩ na magego ma kĩgera,
4 Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
nĩngaitĩrĩria nyũmba ya Hazaeli mwaki ũrĩa ũgaacina ciĩhitho iria nũmu cia Beni-Hadadi.
5 Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
Nĩngoinanga kĩhingo kĩa Dameski; nĩngananga mũthamaki ũrĩa ũtũũraga Gĩtuamba kĩa Aveni, na niine ũrĩa ũnyiitĩte njũgũma ya wathani kũu Bethi-Edeni. Andũ a Suriata nĩmagatahwo matwarwo Kiri,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Nĩ ũndũ wa mehia matatũ ma Gaza, o na mana-rĩ, niĩ ndikahũndũra mangʼũrĩ makwa. Tondũ nĩanyiitire kĩrĩndĩ gĩothe mĩgwate, agĩkĩendia kũu Edomu.
7 Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
Nĩngaitĩrĩria thingo cia Gaza mwaki ũrĩa ũgaacina ciĩhitho iria nũmu ciakuo.
8 Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Nĩngananga mũthamaki wa Ashidodi, na niine ũrĩa ũnyiitĩte njũgũma ya wathani kũu Ashikeloni. Guoko gwakwa nĩgũgokĩrĩra Ekironi, o nginya hĩndĩ ĩrĩa Mũfilisti wa mũthia agaakua,” ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
Ningĩ Jehova ekuuga atĩrĩ: “Nĩ ũndũ wa mehia matatũ ma Turo, o na mana-rĩ, niĩ ndikahũndũra mangʼũrĩ makwa. Tondũ nĩendirie kĩrĩndĩ gĩothe kĩa mĩgwate kũu Edomu, akĩaga gũtĩĩa kĩrĩkanĩro kĩa ũiguano kĩa ariũ a ithe.
10 Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
Nĩngaitĩrĩria thingo cia Turo mwaki ũrĩa ũgaacina ciĩhitho iria nũmu ciakuo.”
11 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Nĩ ũndũ wa mehia matatũ ma Edomu, o na mana-rĩ, niĩ ndikahũndũra mangʼũrĩ makwa. Tondũ nĩatengʼeririe mũrũ wa nyina na rũhiũ rwa njora, atarĩ na tha, tondũ marakara make mahiũ matiathiraga, na mangʼũrĩ make makĩrĩrĩmbũka matekũhoreka,
12 Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
nĩĩngaitĩrĩria Temani mwaki ũrĩa ũgaacina ciĩhitho iria nũmu cia Bozara.”
13 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Nĩ ũndũ wa mehia matatũ ma Amoni, o na mana-rĩ, niĩ ndikahũndũra mangʼũrĩ makwa. Tondũ nĩatarũrire nda cia andũ-a-nja a Gileadi arĩa maarĩ na nda, nĩgeetha aaramie mĩhaka ya gwake.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
Nĩngaitĩrĩria thingo cia Raba mwaki ũrĩa ũgaacina ciĩhitho iria nũmu ciakuo, gatagatĩ-inĩ ka mbugĩrĩrio ya mbaara mũthenya ũcio wa mbaara, ũhaana ta rũhuho rũnene mũthenya wa kĩhuhũkanio.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.
Mũthamaki wakuo nĩagatahwo, athaamio, we mwene, hamwe na anene ake,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.