< Amos 9 >
1 Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé: “Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn kí àwọn òpó kí ó lè mì fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa, ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé, ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
Rab'bi gördüm, Sunağın yanında duruyordu. “Sütun başlıklarına vur, Eşikler sarsılsın” dedi, “Başlıkları insanların başında parala. Sağ kalanları kılıçtan geçireceğim. Kaçan, kurtulan olmayacak,
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú, láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀. (Sheol )
Ölüler diyarını delip girseler, Elimi uzatıp onları çıkaracağım. Göklere çıksalar, Onları oradan indireceğim. (Sheol )
3 Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli, èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀. Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun, láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
Karmel Dağı'nın doruklarına gizlenseler, Artlarına düşüp onları yakalayacağım. Gözümün önünden uzağa, denizin dibine girseler, Orada yılana buyruk vereceğim, Onları sokacak.
4 Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa. “Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí, kì í sì í ṣe fún rere.”
Düşmanlarınca sürgün edilseler, Orada kılıca buyruk vereceğim, Onları biçecek. Gözümü üzerlerinden ayırmayacağım, Ama iyilik için değil, kötülük için.”
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
Rab, Her Şeye Egemen RAB Yere dokununca yer erir, Üzerinde yaşayan herkes yasa bürünür, Bütün yeryüzü Nil gibi kabarır, Mısır'ın ırmağı gibi yine alçalır.
6 Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé, Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé Olúwa ni orúkọ rẹ̀.
Yukarı odalarını gökyüzünde yapan, Kubbesini yeryüzünde kuran, Denizin sularını çağırıp yeryüzüne döken O'dur; O'nun adı RAB'dir.
7 “Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?” ni Olúwa wí. “Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori àti àwọn ará Aramu láti Kiri?
“Ey İsrailliler, Benim için Kûşlular'dan ne farkınız var?” Diyor RAB. “İsrailliler'i Mısır'dan, Filistliler'i Kaftor'dan, Aramlılar'ı Kîr'den çıkaran ben değil miyim?
8 “Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀. Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀. Síbẹ̀, Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,” ni Olúwa wí.
“İşte, Egemen RAB'bin gözleri Bu günahlı krallığın üzerindedir. Onu yeryüzünden söküp atacağım, Ancak Yakup soyunu büsbütün yok etmeyeceğim” Diyor RAB.
9 “Nítorí Èmi yóò pàṣẹ, Èmi yóò sì mi ilé Israẹli ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀ tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
“İşte buyruk vereceğim, Bütün uluslar arasından İsrail'i kalburla eler gibi eleyeceğim, Bir çakıl bile yere düşmeyecek.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi ni yóò ti ipa idà kú gbogbo àwọn ti ń wí pé, ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’
Halkımın arasındaki bütün günahlılar, ‘Kötülük bizi bulmaz, bize erişmez’ diyenler Kılıçtan geçirilecek.”
11 “Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró, Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya, Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè, Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
“O gün Davut'un yıkık çardağını yeniden kuracağım, Gediklerini kapayacak, Yıkık yerlerini onaracağım, Onu eskisi gibi yapacağım,
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,” ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
Öyle ki, Edomlular'ın sağ kalanlarını, Bana ait olan bütün ulusları sahiplensinler.” Bunu yapacak olan RAB böyle diyor.
13 “Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí, “tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá. Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá. Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀, tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèké.
“İşte, günler geliyor” diyor RAB, “Çift süren orakçıya, Üzüm basan ekin ekene erişecek, Dağlardan tatlı şarap damlayacak, Bütün tepelerden akacak.
14 Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀. “Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn. Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn.
Sürgün halkım İsrail'i geri getireceğim, Yıkık kentleri onarıp orada yaşayacaklar, Bağlar dikip şarabını içecekler, Bahçeler yapıp meyvesini yiyecekler.
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀. A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,” ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.
Onları topraklarına dikeceğim, Bir daha sökülmeyecekler Kendilerine verdiğim topraktan.” Tanrınız RAB böyle diyor.