< Amos 9 >

1 Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé: “Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn kí àwọn òpó kí ó lè mì fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa, ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé, ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
Am văzut pe Domnul stând în picioare pe altar; și el a spus: Lovește pragul de sus al ușii, ca ușorii să se clatine; și retează-le capul, la toți; iar eu voi ucide pe ultimul dintre ei cu sabia; cel care fuge dintre ei nu va fugi departe și cel care scapă dintre ei nu va fi eliberat.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú, láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀. (Sheol h7585)
Chiar dacă ar săpa până în iad, de acolo îi va lua mâna mea; chiar dacă s-ar cățăra până la cer, de acolo îi voi coborî; (Sheol h7585)
3 Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli, èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀. Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun, láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
Și chiar dacă s-ar ascunde pe vârful Carmelului, voi cerceta și îi voi lua de acolo; și chiar dacă ar fi ascunși dinaintea ochilor mei pe fundul mării, de acolo voi porunci șarpelui și el îi va mușca;
4 Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa. “Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí, kì í sì í ṣe fún rere.”
Și chiar dacă merg în captivitate în fața dușmanilor lor, de acolo voi porunci sabiei și îi va ucide; și îmi voi pune ochii asupra lor pentru rău și nu pentru bine.
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
Și Domnul DUMNEZEUL oștirilor este cel care atinge țara și ea se va topi și toți cei ce locuiesc în ea vor jeli; și se va ridica în întregime ca un potop și se va îneca precum prin potopul Egiptului.
6 Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé, Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé Olúwa ni orúkọ rẹ̀.
El este cel ce își zidește locurile de sus, unele peste altele, în cer și a întemeiat ceata sa peste pământ; cel ce cheamă apele mării și le toarnă pe fața pământului, DOMNUL este numele său.
7 “Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?” ni Olúwa wí. “Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori àti àwọn ará Aramu láti Kiri?
Nu îmi sunteți voi precum copiii etiopienilor, copii ai lui Israel? spune DOMNUL. Nu l-am adus eu pe Israel din țara Egiptului și pe filisteni din Caftor și pe sirieni din Chir?
8 “Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀. Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀. Síbẹ̀, Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,” ni Olúwa wí.
Iată, ochii DOMNULUI Dumnezeu sunt asupra împărăției păcătoase și o voi nimici de pe fața pământului: numai că nu voi nimici de tot casa lui Iacob, spune DOMNUL.
9 “Nítorí Èmi yóò pàṣẹ, Èmi yóò sì mi ilé Israẹli ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀ tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
Pentru că, iată, eu voi porunci și voi vântura casa lui Israel printre toate națiunile, precum grânele sunt vânturate într-o sită, totuși nici cel mai mic grăunte nu va cădea pe pământ.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi ni yóò ti ipa idà kú gbogbo àwọn ti ń wí pé, ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’
Toți păcătoșii poporului meu vor muri prin sabie, cei care spun: Răul nu ne va întrece nici nu ne va întâmpina.
11 “Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró, Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya, Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè, Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
În acea zi voi ridica tabernacolul căzut al lui David și îi voi închide spărturile; și îi voi ridica ruinele și îl voi zidi ca în zilele din vechime;
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,” ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
Ca ei să stăpânească rămășița Edomului și a tuturor păgânilor, cei chemați după numele meu, spune DOMNUL care face aceasta.
13 “Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí, “tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá. Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá. Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀, tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèké.
Iată, vin zilele, spune DOMNUL, că plugarul va întrece pe secerător și cel care calcă struguri pe cel care seamănă sămânță; și munții vor picura vin dulce și toate dealurile se vor topi.
14 Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀. “Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn. Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn.
Și voi întoarce pe captivii poporului meu Israel; și ei vor zidi cetățile risipite și le vor locui; și vor sădi vii și vor bea vinul lor; vor face de asemenea grădini și vor mânca rodul lor.
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀. A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,” ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.
Și îi voi sădi în țara lor și nu vor mai fi smulși din țara lor pe care le-am dat-o, spune DOMNUL Dumnezeul tău.

< Amos 9 >