< Amos 9 >

1 Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé: “Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn kí àwọn òpó kí ó lè mì fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa, ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé, ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
I KE aku la au ia Iehova e ku ana maluna o ke kuahu: a i mai la ia, E hahau i ke poo o ke kia, i haalulu ai na kumu kia; A e oki ia lakou ma ke poo, ia lakou a pau; A e pepehi aku au i ke koena o lakou me ka pahikaua: O ka mea o lakou e holo ana, aole ia e malu; A o ka mea e pakele ana, aole e pakele io.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú, láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀. (Sheol h7585)
Ina e eli iho lakou i ka po, e lawe ko'u lima ia lakou mailaila mai; Ina e pii lakou i ka lani, e lawe au ia lakou mailaila mai; (Sheol h7585)
3 Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli, èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀. Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun, láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
A ina e pee lakou maluna o ka piko o Karemela, e imi aku au, a e lawe ia lakou mailaila mai; A ina e pee lakou mai kuu maka aku ma ka mole o ke kai, Malaila e kena aku au i ka nahesa, a e nahu aku ia ia lakou.
4 Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa. “Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí, kì í sì í ṣe fún rere.”
A ina e hele pio aku lakou imua o ko lakou poe enemi, Malaila e kena aku au i ka pahikaua, a e luku aku ia ia lakou; A e kau aku kuu mau maka maluna o lakou no ka ino, aole no ka maikai.
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
A o Iehova, ka Haku o na kaua, oia ka mea e hoopa i ka aina, a e hehee iho no ia; A e auwe iho ka poe a pau e noho ana iloko ona: A e ea ae ia me he muliwai la a puni ona; A e halana ae e like me ka muliwai o Aigupita.
6 Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé, Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé Olúwa ni orúkọ rẹ̀.
Oia ka i hana i na papaluna iloko o ka lani, a i hookumu i kona poai maluna o ka honua; O ka mea i hoopii ae i na wai o ka moana, a ninini iho ia lakou maluna o ka ili o ka aina; O Iehova kona inoa:
7 “Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?” ni Olúwa wí. “Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori àti àwọn ará Aramu láti Kiri?
E na mamo a Iseraela, aole anei oukou i like ia'u me na mamo a Kusa? wahi a Iehova. Aole anei au i lawe mai i ka Iseraela mai ka aina o Aigupita mai? A i ko Pilisetia mai Kapetora mai, a me ko Suria mai Kira mai?
8 “Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀. Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀. Síbẹ̀, Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,” ni Olúwa wí.
Aia hoi, o na maka o Iehova ka Haku maluna o ke aupuni hewa; A e hokai aku au ia mai ka honua aku; Aka hoi, aole au e luku loa aku i ko ka hale o Iakoba, wahi a Iehova.
9 “Nítorí Èmi yóò pàṣẹ, Èmi yóò sì mi ilé Israẹli ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀ tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
No ka mea, aia hoi, e kauoha aku au, a e kanana iho ai i ko ka hale o Iseraela iwaena o na lahuikanaka a pau; E like me ka hua palaoa i kananaia iloko o ke kanana, Aole e haule kekahi hua ma ka honaa.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi ni yóò ti ipa idà kú gbogbo àwọn ti ń wí pé, ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’
E make ka poe hewa a pau o kuu poe kanaka i ka pahikaua, Ka poe e olelo ana, Aole e hiki mai ka hewa mahope, aole hoi mamua o kakou.
11 “Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró, Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya, Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè, Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
I kela la e kukulu au i ka halelewa o Davida i wawahiia, A e hoopaa i kona wahi hiolo; A e hooku hou au i kona mau mea i heleleiia, A hana aku ia e like me na la mamua;
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,” ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
I lilo no lakou ke koena o ka Edoma, a me na lahuikanaka a pau, Ka poe i kaheaia ka inoa o Iehova maluna o lakou, wahi a Iehova, nana keia i hana.
13 “Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí, “tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá. Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá. Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀, tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèké.
Aia hoi, e hiki mai na la, wahi a Iehova, E halawai ai ka mea e mahiai ana, me ka mea e oki ana, A o ka mea e hehi i na huawaina, me ka mea e lulu i ka hua; A e hookulukulu iho na mauna i ka waina hou, A e hehee iho na puu a pau.
14 Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀. “Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn. Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn.
A e hoihoi mai au i ka poe pio o kuu poe kanaka o ka Iseraela, A e kukulu lakou i na kulanakauhale neoneo, a noho lakou iloko; A e kanu lakou i na pawaina, a e inu lakou i ko lakou waina; A e hana lakou i na kihapai, a e ai hoi i ko lakou hua.
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀. A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,” ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.
A e kanu iho au ia lakou ma ko lakou aina iho, Aole e uhuki hou ia ae lakou mai ko lakou aina ae, Ka mea a'u i haawi aku ai ia lakou, wahi a Iehova kou Akua.

< Amos 9 >