< Amos 9 >

1 Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé: “Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn kí àwọn òpó kí ó lè mì fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa, ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé, ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
Видях Господа, че стоеше при олтара и рече: Удари капителите, за да се потресат праговете, И разтроши ги върху главата на всички тях; А останалите от тях ще погубя с меч; Който от тях бяга, няма да избегне, И който от тях се отърве, няма да се избави.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú, láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ, láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀. (Sheol h7585)
Ако изкопаят до Шеол, И от там ръката ми ще ги изтръгне; И ако се изкачат на небето, От там ще ги сваля; (Sheol h7585)
3 Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli, èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀. Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun, láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
Ако се скрият на връх Кармил, Ще ги издиря и ще ги взема от там; И ако се скрият от очите Ми в морските дълбочини, Там ще заповядам на змията, и ще ги ухапе;
4 Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa. “Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí, kì í sì í ṣe fún rere.”
Ако отидат в плен пред неприятелите си, Там ще заповядам на ножа, та ще ги убие; И ще насоча очите Си върху тях за зло, а не за добро.
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
Защото Господ Иеова на Силите е оня, Който се допира до земята, и тя се топи, Така щото всички, които живеят на нея ще жалеят; Защото тя цяла ще се издига като Нил, И ще спада пак като Египетската река:
6 Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé, Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé Olúwa ni orúkọ rẹ̀.
Той е, който гради сферите си на небето, И основава свода си на земята; Който повиква морските води, И излива ги по лицето на земята; Иеова е името му.
7 “Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?” ni Olúwa wí. “Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori àti àwọn ará Aramu láti Kiri?
Вие Израиляни, казва Господ, Не сте ли на Мене като Етиопяни? Не възведох ли както Израиля от Египетската земя, Така и Филистимците от Кафтор И Сирийците от Кир?
8 “Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀. Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀. Síbẹ̀, Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,” ni Olúwa wí.
Ето, очите на Господа Иеова са върху грешното царство, И ще го погубя от лицето на света; Само че няма да погубя съвсем Якововия дом, казва Господ.
9 “Nítorí Èmi yóò pàṣẹ, Èmi yóò sì mi ilé Israẹli ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀ tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
Защото, ето, аз ще заповядам, И ще пресея Израилевия дом между всичките народи Както се пресява житото в решетото; Обаче ни най-малко зърно няма да падне на земята.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi ni yóò ti ipa idà kú gbogbo àwọn ti ń wí pé, ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’
От мене ще измрат всичките грешници между людете ми, Които казват - Това зло няма да стигне до нас, Нито ще ни предвари.
11 “Ní ọjọ́ náà ní Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró, Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya, Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè, Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
В оня ден ще въздигна падналата Давидова скиния, И ще заградя проломите й; Ще въздигна развалините й, И ще я съградя пак както в древните дни,
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,” ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.
За да завладеят останалите от Едом И всичките народи, които се наричаха с името ми, Казва Господ, който прави това.
13 “Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí, “tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá. Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá. Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀, tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèké.
Ето, идат дни, казва Господ, Когато орачът ще стигне жетваря, И линотъпкачът сеятеля, От планините ще капе мъст, И всичките хълми ще се стопят.
14 Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀. “Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn. Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn.
И аз ще върна от плен людете си Израиля; Те ще съградят запустелите градове и ще ги населят, Ще насадят лозя и ще пият виното им, И ще направят градини и ще ядат плодът им,
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀. A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,” ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.
И те няма вече да се изтръъгат от земята, Която им дадох, казва Господ твоя Бог.

< Amos 9 >