< Amos 8 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
Tako mi je pokazal Gospod Bog in glej, košara poletnega sadja.
2 Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
Rekel je: »Amos, kaj vidiš?« Rekel sem: »Košaro poletnega sadja.« Potem mi je Gospod rekel: »Konec je prišel nad moje ljudstvo Izrael; ne bom ponovno šel mimo njih.
3 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
Tempeljske pesmi bodo vpitje na ta dan, « govori Gospod Bog. »Na vsakem kraju bo mnogo trupel; metali jih bodo v tišini.
4 Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
Poslušajte to, oh vi, ki pogoltnete pomoči potrebnega, celo da revnemu v deželi storite, da propade,
5 Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
rekoč: ›Kdaj bo minil mlaj, da bomo lahko prodajali žito? In šabat, da bomo lahko odpremili pšenico, naredili škaf majhen in šekel velik in s prevaro izkrivili tehtnice?
6 kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
Da lahko ubogega kupimo za srebro in pomoči potrebnega za par čevljev, da, in prodamo pleve od pšenice?‹«
7 Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
Gospod je prisegel pri Jakobovi odličnosti: »Zagotovo ne bom nikoli pozabil nobenega izmed njihovih del.
8 “Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
Mar ne bo zemlja zaradi tega trepetala in vsak človek žaloval, ki prebiva na njej? Vstala bo v celoti kakor poplava, vržena bo ven in potopljena, kakor z egiptovsko poplavo.
9 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
Na tisti dan se bo zgodilo, « govori Gospod Bog, »da bom soncu povzročil, da zaide opoldan in na jasen dan bom zatemnil zemljo.
10 Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
Vaše praznike bom obrnil v žalovanje in vse vaše pesmi v žalostinko in privedel bom vrečevino na vsa ledja in plešavost na vsako glavo in naredil jo bom kakor žalovanje za edinim sinom in njen konec kakor grenek dan.
11 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Glejte, pridejo dnevi, « govori Gospod Bog, »da bom v deželo poslal lakoto, ne lakote po kruhu niti žeje po vodi, temveč [lakoto] po poslušanju Gospodovih besed.
12 Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
Tavali bodo od morja do morja in od severa, celo do vzhoda, tekali bodo sem ter tja, da iščejo besedo od Gospoda, pa je ne bodo našli.
13 “Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
Na tisti dan bodo lepe device in mladeniči slabeli zaradi žeje.
14 Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”
Tisti, ki prisegajo pri grehu Samarije in pravijo: ›Tvoj bog, oh Dan, živi; ‹ in: ›Način Beeršébe živi; ‹ celo padli bodo in nikoli več ne bodo ponovno vstali.«

< Amos 8 >