< Amos 8 >
1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
Ovo mi pokaza Gospod: gle, kotarica ljetnoga voæa.
2 Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
I reèe: što vidiš, Amose? A ja rekoh: kotaricu ljetnoga voæa. A Gospod mi reèe: doðe kraj narodu mojemu Izrailju, neæu ga više prolaziti.
3 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
I pjesme æe crkvene biti ridanje u onaj dan, govori Gospod; biæe mnoštvo mrtvijeh tjelesa, koja æe se svuda pobacati muèeæi.
4 Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
Èujte ovo, koji proždirete uboge i satirete siromahe u zemlji,
5 Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
Govoreæi: kad æe proæi mladina da prodajemo žito? i subota da otvorimo pšenicu? umaljujuæi efu i poveæavajuæi sikal i varajuæi lažnijem mjerilima;
6 kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
Da kupujemo siromahe za novce i ubogoga za jedne opanke, i da prodajemo oèinke od pšenice.
7 Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
Zakle se Gospod slavom Jakovljevom: neæu nigda zaboraviti nijednoga djela njihova.
8 “Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
Neæe li se zemlja potresti od toga, i protužiti svaki koji živi na njoj? i neæe li se sva razliti kao rijeka? i neæe li se odnijeti i potopiti kao od rijeke Misirske?
9 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
I u onaj dan, govori Gospod Gospod, uèiniæu da sunce zaðe u podne, i pomraèiæu zemlju za bijela dana.
10 Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
I pretvoriæu praznike vaše u žalost i sve pjesme vaše u plaè, i metnuæu kostrijet oko svijeh bedara, i uèiniæu da svaka glava oæelavi i da bude žalost kao za jedincem, i kraj æe joj biti kao gorak dan.
11 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Gle, idu dani, govori Gospod Gospod, kad æu pustiti glad na zemlju, ne glad hljeba ni žeð vode, nego slušanja rijeèi Gospodnjih.
12 Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
I potucaæe se od mora do mora, i od sjevera do istoka trèaæe tražeæi rijeè Gospodnju, i neæe je naæi.
13 “Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
U to æe vrijeme obamirati lijepe djevojke i mladiæi od žeði,
14 Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”
Koji se kunu krivicom Samarijskom i govore: tako da je živ Bog tvoj, Dane, i tako da je živ put u Virsaveju. I pašæe, i neæe više ustati.