< Amos 8 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
Ainsi le Seigneur Yahvé m'a montré: voici une corbeille de fruits d'été.
2 Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
Il dit: « Amos, que vois-tu? » J'ai dit: « Un panier de fruits d'été. » Alors Yahvé me dit, « La fin est venue sur mon peuple Israël. Je ne passerai plus devant eux.
3 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
Les chants du temple seront des gémissements en ce jour-là, dit le Seigneur Yahvé. « Les cadavres seront nombreux. En tout lieu, on les jettera en silence.
4 Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
Écoutez ceci, vous qui voulez engloutir les indigents, et faire échouer les pauvres du pays,
5 Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
en disant: « Quand la nouvelle lune sera-t-elle passée, pour que nous puissions vendre du blé? Et le sabbat, pour que nous puissions commercialiser le blé, rendant l'épha petit, et le shekel grand, et de traiter faussement avec des balances de tromperie;
6 kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
afin que nous puissions acheter les pauvres pour de l'argent, et les nécessiteux pour une paire de sandales, et vendre les balayures avec le blé? »
7 Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
Yahvé a juré par l'orgueil de Jacob, « Je n'oublierai certainement jamais aucune de leurs œuvres.
8 “Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
Le pays ne tremblera-t-il pas pour cela? et tous ceux qui l'habitent en deuil? Oui, il s'élèvera entièrement comme le fleuve; et il sera remué et coulera de nouveau, comme le fleuve d'Égypte.
9 “Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
Cela arrivera en ce jour-là, dit le Seigneur Yahvé, « que je ferai en sorte que le soleil se couche à midi, et j'obscurcirai la terre en plein jour.
10 Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
Je transformerai vos fêtes en deuil, et toutes vos chansons en lamentations; et je vous ferai porter le sac sur tout votre corps, et la calvitie sur toutes les têtes. Je le ferai comme le deuil d'un fils unique, et sa fin comme un jour amer.
11 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Voici, les jours viennent, dit le Seigneur Yahvé, « que j'enverrai une famine dans le pays, pas une famine de pain, ni la soif d'eau, mais d'entendre les paroles de Yahvé.
12 Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
Ils erreront d'une mer à l'autre, et du nord jusqu'à l'est; ils courront de long en large pour chercher la parole de Yahvé, et ne le trouveront pas.
13 “Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
En ce jour-là, les belles vierges et les jeunes hommes s'évanouiront de soif.
14 Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”
Ceuxqui jurent par le péché de Samarie, et dire: « Ton dieu, Dan, est vivant ». et, « Comme le chemin de Beersheba vit, ils tomberont, et ne se relèveront jamais. »

< Amos 8 >