< Amos 7 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
Astfel mi-a arătat Domnul DUMNEZEU; și, iată, el a format cosași la începutul creșterii otavei; și, iată, era otava după cositul împăratului.
2 Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Și s-a întâmplat, după ce au terminat de mâncat iarba țării, că atunci am spus: Doamne DUMNEZEULE, iartă, te implor, prin cine se va ridica Iacob? pentru că el este mic.
3 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
DOMNUL s-a pocăit pentru aceasta: Nu va fi, spune DOMNUL.
4 Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
Astfel mi-a arătat Domnul DUMNEZEU; și, iată, Domnul DUMNEZEU a chemat la luptă prin foc și a mistuit adâncul cel mare și a mâncat o parte.
5 Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Atunci am spus: Doamne DUMNEZEULE, încetează, te implor, prin cine se va ridica Iacob? pentru că el este mic.
6 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
DOMNUL s-a pocăit pentru aceasta. Aceasta de asemenea nu va fi, spune Domnul DUMNEZEU.
7 Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
Astfel el mi-a arătat; și, iată, Domnul stătea în picioare pe un zid făcut cu un fir cu plumb, cu un fir cu plumb în mâna sa.
8 Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
Și DOMNUL mi-a spus: Amos ce vezi? Și eu am spus: Un fir cu plumb. Atunci Domnul a spus: Iată, voi pune un fir cu plumb în mijlocul poporului meu Israel; nu voi mai trece pe lângă ei;
9 “Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
Și înălțimile lui Isaac vor fi pustiite și sanctuarele lui Israel vor fi risipite; și mă voi ridica cu sabia împotriva casei lui Ieroboam.
10 Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Atunci Amația, preotul din Betel, a trimis la Ieroboam, împăratul lui Israel, spunând: Amos a uneltit împotriva ta în mijlocul casei lui Israel; țara nu este în stare să sufere toate cuvintele lui.
11 Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
Pentru că astfel a spus Amos: Ieroboam va muri prin sabie și Israel va fi, negreșit, dus captiv din propria lui țară.
12 Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
De asemenea Amația i-a spus lui Amos: Tu văzătorule, du-te, fugi în țara lui Iuda și acolo mănâncă pâine și acolo profețește;
13 Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
Dar să nu mai profețești la Betel, pentru că este capela împăratului și este curtea împăratului.
14 Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
Atunci Amos a răspuns și i-a zis lui Amația: Eu nu eram profet, nici fiu de profet, ci eram păzitor de oi și culegător de roade de sicomor;
15 Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Și DOMNUL m-a luat precum urmam turma și DOMNUL mi-a spus: Du-te, profețește poporului meu Israel.
16 Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
De aceea acum, ascultă cuvântul DOMNULUI: Tu spui: Nu profeți împotriva lui Israel și nu picura cuvântul tău împotriva casei lui Isaac.
17 “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
De aceea astfel spune DOMNUL: Soția ta va fi o curvă în cetate și fiii tăi și fiicele tale vor cădea prin sabie și țara ta va fi împărțită cu frânghia; și tu vei muri într-o țară întinată; iar Israel va merge negreșit în captivitate din țara lui.

< Amos 7 >