< Amos 7 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
Ko ta te Ariki, ko ta Ihowa tenei i whakaatu ai ki ahau; nana, i hanga e ia he mawhitiwhiti i te timatanga o te pihinga ake o to muri tupu; nana, ko to muri tupu ia i muri iho i a te kingi tapahanga.
2 Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Na ka poto te tarutaru o te whenua te kai, ka mea ahau, E te Ariki, e Ihowa, tena ra, murua te he: ma te aha oti a Hakopa ka ara ai? he iti nei hoki ia.
3 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
I puta ke to Ihowa whakaaro mo tenei; E kore e meatia, e ai ta Ihowa.
4 Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
Ko ta te Ariki, ko ta Ihowa tenei i whakakite ai ki ahau: na kua karangatia e te Ariki, e Ihowa, he whawhai, he mea ahi, a ka pau te rire nui, a ka mea kia kainga te whenua.
5 Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Na ka mea ahau, Kati ra, e te Ariki, e Ihowa, ma te aha oti a Hakopa ka ara ai? he iti nei hoki ia.
6 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
I puta ke to Ihowa whakaaro mo tenei, E kore ano tenei e meatia, e ai ta te Ariki, ta Ihowa.
7 Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
I whakakitea tenei e ia ki ahau: na, ko te Ariki e tu ana i runga i te taiepa, he mea paramu ki te aho, me te aho paramu i tona ringa.
8 Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
Na ka mea a Ihowa ki ahau, Ko te aha e kitea ana e koe, e Amoho? Ano ra ko ahau, He aho paramu. Katahi te Ariki ka ki mai, Nana, ka iri i ahau he aho paramu i waenganui i taku iwi, i a Iharaira: e kore e whakarerea noatia iho ta ratou e ahau a mu ri ake nei.
9 “Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
A ka ururuatia nga wahi tiketike o Ihaka, ka tuheatia nga wahi tapu o Iharaira; ka whakatika atu ano ahau, me te hoari ki te whare o Ieropoama.
10 Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Na ka unga tangata a Amatia tohunga o Peteere ki a Ieropoama kingi o Iharaira hei ki atu, Kua whakatakotoria e Amoho he he mou i roto i te whare o Iharaira; kahore e taea e tenei whenua te waha ana kupu katoa.
11 Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
Ko te kupu hoki tenei a Amoho, Ka mate a Ieropoama i te hoari, a ka whakaraua rawatia atu a Iharaira i to ratou oneone.
12 Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
I mea ano a Amatia ki a Amoho, E te matakite, haere, e rere ki te whenua o Hura, ki reira kai ai i te taro mau, ki reira poropiti ai.
13 Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
Engari kati tau poropiti ki Peteere: ko to te kingi wahi tapu hoki ia, he whare hoki no te kingitanga.
14 Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
Na ka whakahoki a Amoho, ka mea ki a Amatia, Ehara ahau i te poropiti, ehara ano i te tama na te poropiti; engari he kaitiaki kahui ahau, he kaikikini hikamora:
15 Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
I tikina ake hoki ahau e Ihowa i te mea e whai ana i nga hipi, i ki mai ano a Ihowa ki ahau, Haere, poropiti ki taku iwi, ki a Iharaira.
16 Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
Na whakarongo ki te kupu a Ihowa, E mea na koe, Kaua e poropiti ki a Iharaira, kei maturuturu iho ano tetahi kupu au hei whakahe mo te whare o Ihaka.
17 “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
No reira ko te kupu tenei a Ihowa, Tera tau wahine e kairau i roto i te pa, a ka hinga au tama me au tamahine i te hoari, ka wehewehea tou oneone, mea rawa ki te aho; ka mate koe i runga i te oneone poke, ka whakaraua rawatia atu hoki a Iharaira i tona oneone.

< Amos 7 >