< Amos 7 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
Oasr aruruma se nga liye sin LEUM GOD Fulat. In aruruma se inge nga liye El orala u in locust na lulap se tukunna pacl se kosreyukla mah nun kosro nutin tokosra, ac sruen mah uh mutawauk in srunak.
2 Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Ke aruruma sac nga liye ke locust uh mutawauk in kangla mah ac sra nukewa fin acn uh, na nga fahk, “LEUM GOD Fulat, nunak munas nu sin mwet in fwil natul Jacob! Elos ac moulla fuka? Elos arulana munas!”
3 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
Na LEUM GOD El ekulla nunak lal ac fahk, “Ma kom liye uh ac fah tia sikyak.”
4 Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
Nga sifil liye sie aruruma sin LEUM GOD Fulat. In aruruma sac, nga liye El akoo in kalyei mwet lal ke e. E sac furreak meoa lulap ye faclu, ac mutawauk in esukak acn uh.
5 Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Na nga fahk, “O LEUM GOD Fulat, tulokinya e u! Mwet lom uh ac moulla fuka? Elos arulana pu ac munas!”
6 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Na LEUM GOD El sifilpa ekulla nunak lal ac fahk, “Ma se inge ac fah tia pac sikyak.”
7 Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
Na nga sifil liye sie aruruma sin LEUM GOD. In aruruma se inge nga liye El tu sisken soko pot, ma mwet musa elos tuh orekmakin soko ah in aksuwos ke elos musai, ac LEUM GOD El sruok ah in aksuwos soko in paol.
8 Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
El siyuk sik, “Amos, mea kom liye?” Na nga fahk, “Ah in aksuwos soko.” Na El fahk, “Nga orekmakin ah soko inge in akkalemye lah mwet luk elos oana soko pot ma kihla. Nga ac fah tia sifil ekulla nunak luk lah nga ac kalyaelos.
9 “Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
Acn nukewa mwet in fwil natul Isaac alu we ac fah kunanula. Acn mutal lun Israel ac fah sruala. Nga ac wotela tokosrai lun sou lal Tokosra Jeroboam in wanginla.”
10 Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Na Amaziah, mwet tol fulat in acn Bethel, el supwala kas nu yorol Tokosra Jeroboam lun Israel, su fahk ouinge: “Amos el fahk kas in lain kom inmasrlon mwet uh. Sramsram lal uh ac kunausla facl se inge.
11 Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
Pa inge ma el fahk, ‘Jeroboam el fah misa ke mweun, ac mwet Israel fah utukla liki acn selos nu in sruoh.’”
12 Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
Na Amaziah el fahk nu sel Amos, “Mwet palu, folokla nu Judah ac oru luti lom in acn we. Lela mwet we in moli nu sum.
13 Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
Nimet sifilpa palu in acn Bethel. Acn in alu sin tokosra ac mwet in facl se inge nufon pa inge.”
14 Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
Na Amos el topuk, “Nga tia palu in moul nu sik. Nga sie mwet liyaung sheep, ac nga orekma ke sak fig.
15 Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Tuh pa LEUM GOD El eisyula liki orekma in mwet shepherd, ac sap nga in tuku ac palu nu sin mwet lal, mwet Israel.
16 Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
Inge, lohng ma LEUM GOD El fahk. Kom fahk nu sik nga in tia palu ac in tia kaskas lain mwet Israel.
17 “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
Ke kom fahk ouinge, Amaziah, LEUM GOD El fahk nu sum, ‘Mutan kiom an ac fah ekla sie mutan kosro su eis molin kosro lal in siti uh, ac tulik nutum ac fah anwuki ke mweun. Acn sum ac fah kitakatelik ac itukyang nu sin kutu pacna mwet, ac kom sifacna ac fah misa in facl sin mwet pegan. Pwayena mwet Israel fah utukla liki acn selos nu in sruoh.’”

< Amos 7 >