< Amos 6 >
1 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá.
Biada beztroskim na Syjonie i pokładającym ufność w górze Samarii; tym, którzy są przywódcami wśród tych narodów, do których schodzi się dom Izraela.
2 Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì. Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini. Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ? Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
Idźcie do Kalne i rozejrzyjcie się, a stamtąd idźcie do Chamat wielkiego. Potem zstąpcie do Gat filistyńskiego. Czy są to lepsze królestwa niż te? Czy ich obszar jest większy niż wasz obszar?
3 Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú, ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí.
[Biada wam, którzy sądzicie], że dzień zły jest daleko i przybliżacie panowanie przemocy;
4 Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ.
Którzy sypiacie na łożach z kości słoniowej, a rozciągacie się na swoich posłaniach; którzy jadacie jagnięta z trzody, a cielce tuczone z zagrody;
5 Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin.
Którzy śpiewacie przy lutni i wymyślacie sobie instrumenty muzyczne jak Dawid;
6 Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan àti ìkunra tí o dára jùlọ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro.
Którzy pijecie wino z czasz i namaszczacie się drogimi maściami, a nie bolejecie nad utrapieniem Józefa.
7 Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.
Dlatego teraz pójdą do niewoli na czele pojmanych i skończy się biesiada hulaków.
8 Olúwa Olódùmarè ti búra fúnra rẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé: “Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀, Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
Pan BÓG przysiągł na siebie samego, mówi PAN, Bóg zastępów: Obrzydła mi pycha Jakuba i nienawidzę jego pałaców. Dlatego wydam miasto i wszystko, co w nim jest.
9 Bí ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú.
A stanie się tak: Jeśli pozostanie dziesięć osób w jednym domu i one pomrą.
10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”
I każdego z nich weźmie jego stryj, i spali go, aby wynieść kości z domu, i zapyta tego, który jest w zakątkach domu: Czy jest jeszcze ktoś z tobą? A [ten] odpowie: Nie ma. Wtedy powie: Milcz, bo nie wolno wspominać imienia PANA.
11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà, Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú, àti àwọn ilé kéékèèké sí wẹ́wẹ́.
Oto bowiem PAN rozkaże i uderzy w wielki dom rozpadlinami, a w mały dom – pęknięciem.
12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí? Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
Czy konie mogą biegać po skale? Czy można [tam] orać wołami? Sąd bowiem zamieniliście w truciznę, a owoc sprawiedliwości w piołun.
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari, ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”
[Biada wam], którzy się cieszycie, a to z niczego, mówiąc: Czy nie wzięliśmy sobie rogów własną siłą?
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli, wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà, láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”
Ale oto ja wzbudzę naród przeciwko wam, domu Izraela, mówi PAN, Bóg zastępów, który was będzie uciskał od wejścia do Chamat aż do strumienia pustyni.