< Amos 6 >

1 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá.
وای بر آنانی که در صهیون ایمن و درکوهستان سامره مطمئن هستند که نقبای امت های اولی که خاندان اسرائیل نزد آنها آمدندمی باشند.۱
2 Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì. Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini. Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ? Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
به کلنه عبور کنید و ملاحظه نمایید واز آنجا به حمات بزرگ بروید و به جت فلسطینیان فرود آیید؛ آیا آنها از این ممالک نیکوتر است یا حدود ایشان از حدود شمابزرگتر؟۲
3 Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú, ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí.
شما که روز بلا را دور می‌کنید و مسند ظلم را نزدیک می‌آورید.۳
4 Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ.
که بر تختهای عاج می‌خوابید و بر بسترها دراز می‌شوید و بره‌ها را ازگله و گوساله‌ها را از میان حظیره‌ها می‌خورید.۴
5 Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin.
که با نغمه بربط می‌سرایید و آلات موسیقی رامثل داود برای خود اختراع می‌کنید.۵
6 Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan àti ìkunra tí o dára jùlọ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro.
و شراب رااز کاسه‌ها می‌نوشید و خویشتن را به بهترین عطریات تدهین می‌نمایید اما به جهت مصیبت یوسف غمگین نمی شوید.۶
7 Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.
بنابراین ایشان الان بااسیران اول به اسیری خواهند رفت و صدای عیش کنندگان دور خواهد شد.۷
8 Olúwa Olódùmarè ti búra fúnra rẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé: “Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀, Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
خداوند یهوه به ذات خود قسم خورده ویهوه خدای لشکرها فرموده است که من ازحشمت یعقوب نفرت دارم و قصرهایش نزد من مکروه است. پس شهر را با هر‌چه در آن است تسلیم خواهم نمود.۸
9 Bí ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú.
و اگر ده نفر در یک شهرباقی‌مانده باشند ایشان خواهند مرد.۹
10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”
و چون خویشاوندان و دفن کنندگان کسی را بردارند تااستخوانها را از خانه بیرون برند آنگاه به کسی‌که در اندرون خانه باشد خواهند گفت: آیا دیگری نزد تو هست؟ او جواب خواهد داد که نیست. پس خواهند گفت: ساکت باش زیرا نام یهوه نبایدذکر شود.۱۰
11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà, Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú, àti àwọn ilé kéékèèké sí wẹ́wẹ́.
زیرا اینک خداوند امر می‌فرماید وخانه بزرگ به خرابیها و خانه کوچک به شکافهاتلف می‌شود.۱۱
12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí? Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
آیا اسبان بر صخره می‌دوند یاآن را با گاوان شیار می‌کنند؟ زیرا که شما انصاف را به حنظل و ثمره عدالت را به افسنتین مبدل ساخته‌اید.۱۲
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari, ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”
و به ناچیز شادی می‌کنید ومی گویید آیا با قوت خویش شاخها برای خودپیدا نکردیم؟۱۳
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli, wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà, láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”
زیرا یهوه خدای لشکرهامی گوید: اینک‌ای خاندان اسرائیل من به ضدشما امتی برمی انگیزانم که شما را از مدخل حمات تا نهر عربه به تنگ خواهند‌آورد.۱۴

< Amos 6 >