< Amos 6 >

1 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá.
Aue, te mate mo te hunga e noho humarie ana i Hiona, mo te hunga hoki e whakawhirinaki ana ki te maunga o Hamaria, nga tangata whai ingoa o te tuatahi o nga iwi, i tae atu nei te whare o Iharaira ki a ratou.
2 Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì. Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini. Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ? Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
Haere tonu ki Karane titiro ai, haere atu i reira ki Hamata nui; haere tonu atu ki Kata o nga Pirihitini: he pai atu ranei i enei kingitanga? nui atu ranei to ratou rohe i to koutou rohe?
3 Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú, ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí.
E te hunga e whakamatara atu na i te ra kino, e mea na i te nohoanga o te tutu kia tata mai;
4 Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ.
E takoto na i runga i te moenga rei, e wharoro na i runga i o ratou takotoranga, e kai na i nga reme o te kahui, i nga kuao kau o waenganui i te turanga kau;
5 Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin.
E waiata na i nga waiata poauau ki te rangi hatere; e whakaaroa ana hoki e ratou nga mea whakatangi, e pera ana me Rawiri;
6 Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan àti ìkunra tí o dára jùlọ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro.
E inu ana i te waina o nga peihana, a e whakawahi ana i a ratou ki nga hinu pai rawa; kahore ia o ratou pouri mo te aitua o Hohepa.
7 Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.
Na aianei ko ratou ki mua ka whakaraua atu o te hunga e whakaraua ana, a ka kore te hakari a te hunga i wharoro ra.
8 Olúwa Olódùmarè ti búra fúnra rẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé: “Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀, Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
Kua oatitia te Ariki, a Ihowa, e ia ano, e ai ta Ihowa, ta te Atua o nga mano, E whakarihariha ana ahau ki ta Hakopa e whakai na, e kino ana ki ona whare kingi: mo reira ka tukua atu e ahau te pa me nga mea i roto.
9 Bí ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú.
Na, ki te toe nga tangata kotahi tekau i roto i te whare kotahi, ka mate ratou.
10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”
A, ki te tangohia ake tetahi e tona matua keke, ara e te kaitahu mona, kia maua mai ai nga wheua i roto i te whare, a ka mea ia ki te tangata i roto rawa i te whare, He tangata ano ranei tena kei a koe na? a ka mea ia, Kahore; katahi ia ka mea, Whakarongoa; e kore hoki tatou e whakahua i te ingoa o Ihowa.
11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà, Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú, àti àwọn ilé kéékèèké sí wẹ́wẹ́.
No te mea, nana, kei te whakahau a Ihowa, a ka patua te whare nui ki nga pakaru, te whare iti ki nga ngatata.
12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí? Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
E rere ranei te hoiho i runga i te kamaka? e parautia ranei a reira ki te kau? i whakaputaina ketia ai e koutou te whakawa hei au, nga hua hoki o te tika hei taru kawa.
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari, ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”
E koa na hoki koutou ki te kahore noa iho, e mea na, He teka ianei kua riro mai he haona i a tatou, he mea na to tatou uaua?
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli, wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà, láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”
Otiia, nana, ka ara i ahau tetahi iwi ki a koutou, e te whare o Iharaira, e ai ta Ihowa, ta te Atua o nga mano, a ka whakatupuria kinotia koutou e ratou i te haerenga atu ki Hamata a tae noa ki te awa o te Arapa.

< Amos 6 >