< Amos 6 >
1 Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá.
Malheur à ceux qui méprisent Sion, et qui mettent leur confiance en la montagne de Samarie! Ils ont recueilli les prémices des nations, puis ils sont entrés.
2 Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì. Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini. Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ? Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
Passez tous auprès, et voyez; et de là traversez Ématrabba, et de là descendez à Geth des Philistins; ce sont les plus puissants de tous les royaumes. Voyez si leurs frontières sont plus étendues que vos frontières.
3 Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú, ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí.
Vous qui venez pour le mauvais jour, vous qui approchez des sabbats trompeurs, et vous y attachez;
4 Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ.
vous qui dormez sur des lits d'ivoire, et vous y étendez pour vivre avec mollesse; vous qui mangez les chevreaux de votre menu bétail, et de jeunes veaux tirés de vos troupeaux et nourris de lait;
5 Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin.
vous qui battez des mains au son des instruments! Ils ont cru que ces choses seraient durables, et non fugitives.
6 Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan àti ìkunra tí o dára jùlọ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro.
Vous qui buvez du vin clarifié, et vous parfumez de la meilleure myrrhe, et ne souffrez nullement de l'affliction de Joseph.
7 Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.
À cause de cela, ils passeront de la puissance des forts à la captivité, et l'on n'entendra plus le hennissement des chevaux en Éphraïm.
8 Olúwa Olódùmarè ti búra fúnra rẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé: “Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀, Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́ àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”
Car le Seigneur en Lui-même a juré, disant: Puisque J'ai en abomination toute l'insolence de Jacob, j'ai pris également en haine leurs contrées, J'effacerai donc la ville avec tous ceux qui l'habitent.
9 Bí ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú.
Et voici ce qui arrivera: Si dans une maison il y a dix hommes, ils mourront; et ceux qui y resteront cachés mourront aussi.
10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”
Et leurs parents les prendront, et ils se feront violence pour enlever leurs os de la maison; et l'on dira au chef de la maison: Y a-t-il encore quelqu'un avec toi? Et celui-ci répondra: Il n'y a personne; et le premier répondra: Tais-toi, garde-toi de prononcer le Nom du Seigneur.
11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà, Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú, àti àwọn ilé kéékèèké sí wẹ́wẹ́.
Car voilà que le Seigneur a donné Ses ordres; et Il frappera les grandes maisons pour ouvrir des brèches, et les petites pour y faire des crevasses.
12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí? Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
Les chevaux peuvent-ils courir au milieu des rochers? Peuvent-ils s'empêcher de hennir au milieu des cavales? Vous qui à la place du jugement avez mis la colère, et qui avez changé en amertume les fruits de la justice;
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari, ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”
vous qui mettez votre joie dans le néant; vous qui dites: N'est-ce point par notre force que nous avons des fronts puissants?
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli, wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà, láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”
Maison d'Israël, J'exciterai contre vous une nation, dit le Seigneur Dieu des armées; et elle vous brisera depuis l'entrée d'Émath jusqu'au torrent du désert d'Occident.