< Amos 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Słuchajcie słowa tego, o krowy Basańskie! któreście na górach Samaryi, które uciskacie nędzników a niszczycie ubogich, które mówicie panom ich: Przynieście, abyśmy piły.
2 Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Przysiągł panujący Pan przez świętobliwość swoję, iż oto dni idą na was, których nieprzyjaciel weźmie was na haki, a potomki wasze na wędy rybackie, i wyjdziecie przerwami, każda tak jako stoi;
3 Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
I będziecie rozrzucać cokolwiek było w pałacach waszych, mówi Pan.
4 “Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Idźcież do Betel a bądzcie tułaczami w Galgal; rozmnóżcie przestępstwa, a przynoście na każdy poranek ofiary wasze, i trzeciego roku dziesięciny wasze;
5 Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
A paląc ofiarę chwały z kwaszonych rzeczy, obwołajcie ofiary dobrowolne, i rozgłoście, ponieważ się wam tak podoba, o synowie Izraelscy! mówi panujący Pan.
6 “Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
A chociażem Ja wam dał czystość zębów we wszystkich miastach waszych, to jest, niedostatek chleba po wszystkich miejscach waszych, wszakżeście się nie nawrócili do mnie, mówi Pan.
7 “Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Jam też zahamował od was deszcz, gdy jeszcze były trzy miesięce do żniwa, a spuściłem deszcz na jedne miasto, a na drugiem miasto nie spuścił; jedna dziedzina była deszczem odwilżona, a druga dziedzina, na którą deszcz nie padał, uschła.
8 Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
I chodziły dwa i trzy miasta do jednego miasta, aby piły wodę, a nie mogły się napić; a wszakżeście się nie nawrócili do mnie, mówi Pan.
9 “Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Uderzyłem was suszą i rdzą; obfitość, którą przynosiły ogrody wasze, i winnice wasze, i figowe sady wasze, i oliwnice wasze, gąsienice pożarły, a wszakżeście się nie nawrócili do mnie, mówi Pan.
10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Posłałem na was mór, tak jako na Egipt, pobiłem mieczem młodzieńców waszych, w pojmaniem podał konie wasze, i sprawiłem, że smród wojsk waszych występował w nozdrza wasze; a wszakżeście się nie nawrócili do mnie, mówi Pan.
11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Wywróciłem was, jako Bóg wywrócił Sodomę i Gomorę, tak, żeście byli jako głownia wyrwana z ognia; a wszakżeście się nie nawrócili do mnie, mówi Pan.
12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
Przetoż tak ci uczynię, o Izraelu! a iż ci tak uczynić chcę, bądźże gotowym na zabieżenie Bogu swemu, o Izraelu!
13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Albowiem oto on jest, który kształtuje góry, a tworzy wiatry, i który oznajmuje człowiekowi, jaka jest myśl jego; on z rannej zorzy ciemność czyni, a depcze wysokości ziemi; Pan Bóg zastępów jest imię jego.

< Amos 4 >