< Amos 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Écoutez cette parole génisses de Basan qui êtes sur la montagne de Samarie, qui opprimez les petits, froissez les indigents, dites à votre seigneur: Donne, afin que nous puissions boire!
2 Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Le Seigneur, l'Éternel, le jure par sa sainteté: Voici, il vient pour vous un temps où l'on vous enlèvera avec l'hameçon, et votre postérité avec le harpon du pêcheur,
3 Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
et par les brèches vous sortirez, chacune en avant, pour aller vous jeter dans les montagnes, dit l'Éternel.
4 “Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Allez à Béthel! et commettez le crime à Guilgal, nombre de crimes, et tous les matins offrez vos victimes, tous les trois jours vos dîmes!
5 Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Encensez avec du levain en actions de grâces, et proclamez, publiez des offrandes volontaires! car ainsi vous aimez à faire, enfants d'Israël, dit le Seigneur, l'Éternel.
6 “Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
Je vous envoyai aussi la famine dans toutes vos villes, et la disette de pain dans tous vos lieux, mais vous ne revîntes pas à moi, dit l'Éternel.
7 “Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Je vous refusai aussi la pluie durant trois mois jusqu'à la moisson; et je fis tomber la pluie sur une ville, mais sur l'autre je ne la fis point tomber; un champ fut arrosé, mais le champ où il ne plut pas devint aride;
8 Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
et deux, trois villes se portèrent sur une ville pour y trouver de l'eau à boire, et ne se désaltérèrent point; mais vous ne revîntes point à moi, dit l'Éternel.
9 “Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Je frappai vos blés du charbon et de la carie; vos nombreux jardins et vos vignes et vos figuiers et vos oliviers furent dévorés par les sauterelles; mais vous ne revîntes point à moi, dit l'Éternel.
10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
J'envoyai parmi vous une peste, telle que celle d'Egypte, je tuai par l'épée vos jeunes gens, laissant emmener vos chevaux; et je fis monter l'infection de vos camps et jusque dans vos narines; mais vous ne revîntes point à moi, dit l'Éternel.
11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Je fis parmi vous un bouleversement tel que celui que Dieu fit de Sodome et de Gomorrhe, et vous fûtes comme un tison sauvé de l'incendie; mais vous ne revîntes point à moi, dit l'Éternel.
12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
Aussi te ferai-je ces choses, Israël! Or, puisque je veux te faire ces choses, apprête-toi à venir au-devant de ton Dieu, Israël!
13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Car voici, Il forma les montagnes, et Il crée le vent, Il révèle à l'homme ses propres pensées, Il change l'aurore en ténèbres et marche sur les hauteurs de la terre; l'Éternel, Dieu des armées, tel est son nom.

< Amos 4 >