< Amos 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Hear ye this word, ye heifers of Bashan, that are in the mountain of Samaria, who oppress the poor, who crush the needy, —who say to their lords, Bring in, and let us drink!
2 Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Sworn hath My Lord, Yahweh, by his own holiness, That lo! days, are coming upon you, —when he will take you away with hooks, and your followers with fishhooks;
3 Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
And, through fissures, shall ye go out, every woman, straight before her, —and ye shall be thrust forth towards the castle, Declareth Yahweh.
4 “Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Enter ye Bethel, and transgress, At Gilgal, cause transgression, to abound, —Yea, carry in, every morning, your sacrifices, every three days, your tithes;
5 Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Yea, burn thou incense, of that which is leavened, as a thank-offering, and proclaim ye freewill-offerings, let them be known, —for, so, ye love [to have it], ye sons of Israel, Declareth My Lord, Yahweh.
6 “Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
Moreover also, I, have given you cleanness of teeth throughout all your cities, and want of bread throughout all your dwelling-places, —Yet have ye not returned unto me, Declareth Yahweh.
7 “Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Moreover also, I, have withholden from you the abundant rain, when yet there were only three mouths to the harvest, Or I might rain upon one city, and, on another city, might not rain, —One portion, would be rained upon, and, the portion whereupon it should not rain, would be dried up;
8 Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
Then would two or three cities totter to one city to drink water, without being satisfied, —Yet have ye not returned unto me, Declareth Yahweh.
9 “Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
I have smitten you with blight and with mildew, When your gardens and your vineyards and your fig-trees and your olive-trees have increased, the creeping locust would devour them, —Yet have ye not returned unto me, Declareth Yahweh.
10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
I have sent among you pestilence, in the manner of Egypt, I have slain, with the sword, your young men, and therewith have been taken captive your horses, And I have caused to ascend—the stench of your camps, even into your own nostrils, Yet ye have not returned unto me, Declareth Yahweh.
11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
I have made an overthrew among you, like the divine overthrow of Sodom and Gomorrah, and ye have become like a brand snatched out of the burning, —Yet hate ye not returned unto me, Declareth Yahweh.
12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
Therefore, thus, will I do unto thee, O Israel, —Because this thing I will do unto thee, Prepare to meet thy God, O Israel.
13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
For lo! He that fashioned the mountains, and created the wind, and who telleth the son of earth what is his thought, who turneth dawn into darkness, and marcheth upon the high places of the earth, Yahweh, God of hosts, is his name!

< Amos 4 >