< Amos 4 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Slyšte slovo toto, ó krávy Bázanské, kteréž jste na horách Samařských, kteréž nátisk činíte chudým, a potíráte nuzné, kteréž říkáte pánům jejich: Přineste, ať pijeme.
2 Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Přisáhl Panovník Hospodin skrze svatost svou, že aj, dnové jdou na vás, v nichž vezme vás na háky, a potomky vaše na udice rybářské.
3 Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
I vyjdete mezerami, každá tak, jakž stojí, a budete rozhazovati, což na palácích, dí Hospodin.
4 “Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Jdětež do Bethel, a buďtež poběhlci Galgala, rozmnožujte převrácenost, a přinášejte každého jitra oběti své, třetího roku desátky své.
5 Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
A pálíce obět chvály z kvašených věcí, provolejte i oběti dobrovolné, a rozhlaste, poněvadž se vám tak líbí, ó synové Izraelští, dí Panovník Hospodin.
6 “Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
A ačkoli já dal jsem vám čistotu zubů po všech městech vašich, totiž nedostatek chleba na všech místech vašich, a však jste se ke mně neobrátili, dí Hospodin.
7 “Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Já také zadržel jsem vám déšť, když ještě tři měsícové byli do žně, a dštil jsem na jedno město, a na druhé město jsem nedštil; jeden díl deštěm svlažen byl, a ten díl, na kterýž nepršelo, uschl.
8 Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
A toulali se dvě i tři města k jednomu městu, aby se napili vody, aniž se napiti mohli, a však jste se neobrátili ke mně, dí Hospodin.
9 “Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Bil jsem vás suchem a rzí; hojnost, kterouž přinášely zahrady vaše a vinice vaše, i fíkoví vaše, i olivoví vaše, pojedly housenky, a však jste se neobrátili ke mně, dí Hospodin.
10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Poslal jsem na vás mor tak jako na Egypt, zbil jsem mečem mládence vaše, v zajetí jsem vydal koně vaše, a učinil jsem, že vstupoval smrad vojsk vašich i v chřípě vaše, a však jste se neobrátili ke mně, dí Hospodin.
11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
Podvrátil jsem vás, jako podvrátil Bůh Sodomu a Gomoru, tak že jste byli jako hlavně vychvácená z ohně, vždy však neobrátili jste se ke mně, dí Hospodin.
12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
A protož takť učiním, ó Izraeli, a poněvadž takť učiniti míním, připraviž se vstříc Bohu svému, ó Izraeli.
13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Nebo aj, on jest sformovatel hor a stvořitel větrů, a oznamuje člověku, jaké by bylo jeho myšlení; činí z záře jitřní tmu, a šlapá po vysokostech země. Hospodin Bůh zástupů jest jméno jeho.

< Amos 4 >