< Amos 3 >
1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
Perwerdigar silerni eyiblep éytqan bu söz-kalamni anglanglar, i Israil baliliri, Yeni Men Misir zéminidin élip chiqarghan bu pütkül jemet: —
2 “Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
«Yer yüzidiki barliq jemetler arisidin peqet silerni tonup keldim; Shunga üstünglargha barliq qebihlikliringlarning [jazasini] chüshürimen».
3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
Ikki kishi bir niyette bolmisa, qandaqmu bille mangalisun?
4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
Oljisi yoq shir ormanda hörkiremdu? Arslan héchnémini almighan bolsa uwisida huwlamdu?
5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
Tuzaqta yemchük bolmisa qush yerge yiqilamdu? Alghudek nerse bolmisa, qismaq yerdin étilip chiqamdu?
6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
Sheherde [agah] kaniyi chélinsa, xelq qorqmamdu? Perwerdigar qilmighan bolsa, sheherge yamanliq chüshemdu?
7 Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Reb Perwerdigar Öz qulliri bolghan peyghemberlerge awwal ashkarilimay turup, U héch ish qilmaydu.
8 Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
Shir hörkirigen tursa, kim qorqmaydu? Reb Perwerdigar söz qilghanda, kim [Uning] bésharitini yetküzmey turalaydu?
9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
Ashdodtiki qel’e-ordilarda, Shundaqla Misirdiki qel’e-ordilarda élan qilip: — «Samariye taghliri üstide yighilinglar, Uning otturisidiki zor qiyqas-sürenlerni, Uning ichidiki jebir-zulumlarni körüp béqinglar» — denglar.
10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
— Ular heq ish qilishni bilmeydu — deydu Perwerdigar, — Ular ordilirigha zulum-zorawanliq bilen tartiwalghanlirini hem oljilarni jughlighuchilar!
11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
Shunga Perwerdigar mundaq deydu: — «Mana bir yaw! U zéminni qorshiwaldi! U mudapiengni élip tashlaydu, Qel’e-ordiliring bulang-talang qilinidu.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
Perwerdigar mundaq deydu: — Padichi shirning aghzidin qoyning ikki putini yaki quliqining bir parchisini qutquzup alghandek, Samariyide olturghan Israillarmu shundaq qutquzulidu, — Sheherde peqet kariwatning bir burjiki, Diwandiki bir parche Demeshq libasila qalidu!
13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
— Anglanglar, Yaqupning jemetide guwahliq béringlar, — deydu Reb Perwerdigar, samawi qoshunlarning Serdari bolghan Xuda,
14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
— Men Israilning asiyliqlirini öz béshigha chüshürgen künide, Beyt-El shehirining qurban’gahlirinimu jazalaymen; Qurban’gahning burjekliridiki münggüzler késiwétilip yerge chüshürülidu.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.
Men «Qishliq Saray» we «Yazliq Saray»ni biraqla uruwétimen; Pil chishi öylermu yoqilip kétidu, Köpligen öyler tügishidu, — deydu Perwerdigar.