< Amos 3 >
1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
Mijanjiña ty nitsarà’ Iehovà ry ana’ Israeleo, ry hene foko nakareko an-tane’ i Mitsraimeo, ami’ty hoe:
2 “Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
Inahareo avao ty napotako amo kila foko ty tane toio; aa le fonga havaleko ama’ areo o hakeo’ areoo.
3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
Mahay miharo lia hao ty roe naho tsy milahatse hey?
4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
Hitroñe añ’ala ao hao ty liona naho tsy aman-tsàtsa’e? Hañaolo boak’ an-dakato’e ao hao ty liona tora’e naho tsy nahatsepake?
5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
Mete hikoropok’ am-pandri-bo an-tane eo hao ty voroñe, naho tsy ama’e ty fitake? Hidraitse an-tane eo hao i bitsokey, ie tsy aman-ko tsepaheñe?
6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
Naho tiofeñe an-drova ao i antsivay, tsy hangebahebake hao ondatio? Ie hizò hankàñe ty rova, tsy ho sata’ Iehovà hao?
7 Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Toe tsy hanao ndra inoñ’inoñe t’Iehovà, Talè, naho tsy borahe’e amo mpitoro’e mpitokio heike o safiri’e mietakeo.
8 Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
Fa nitroñe i lionay, ia ty tsy ho hembañe? Fa nitsara t’Iehovà, Talè, ia ty tsy hitoky?
9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
Tseizo amo anjomba’ i Asdodeo naho amo anjomba an-tane’ Mitsraime añeo ty hoe: mitontona am-bohi’ i Somerone eo, naho mahaisaha ty fifandraparapahañe añivo’e ao vaho o forekekeñe ama’e aoo.
10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
Fa tsy fohi’ iareo ty hanao ty hiti’e, hoe t’Iehovà, ie mañaja fikatramoañe, naho fampikamerañe añ’anjomba’ iareo ao.
11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
Aa hoe t’Iehovà, Talè: Hiarikatohe’ ty rafelahy i taney naho harotsa’e o hafatrara’oo, vaho ho kopahe’e o anjomba’oo.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
Hoe t’i Iehovà: Manahake ty añakara’ ty mpiarake ami’ty montsilin-diona ty tombo’e roe ndra ty silan-tsofi’e, ty haneseañe o ana’ Israele mimoneñe e Someroneo, reketse ty indran-tihy ndra ty tombom-pandreañe.
13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
Mijanjiña, le asisio ty anjomba’ Iakobe, hoe t’Iehovà, Talè Andrianañahare’ i màroy;
14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
fa amy andro hañondrohako o fiolà’ Israeleoy, le ho valeako o kitreli’ i Beteleo, naho ho kitsifañe i tsifan-kitrely rey vaho hipok’ an-tane eo.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.
Hatraoko lafa i anjomban’asaray naho i anjomban’asotriy, hikoromake ka o anjomba aman-tsifao; toe hirotsake o anjomba jabajabao, hoe t’Iehovà.