< Amos 3 >

1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
Halljátok meg e beszédet, melyet az Úr szól ti felőletek, Izráel fiai; mindama nemzetség felől, a melyet felhoztam Égyiptom földéről, ezt mondván:
2 “Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
Csak titeket választottalak magamnak e földnek minden nemzetségei közül; azért büntetlek meg titeket minden gonoszságtokért.
3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
Vajjon járnak-é ketten együtt, ha nem egyeztek meg egymással?
4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
Ordít-é az oroszlán az erdőben, ha nincs mit ragadoznia? Hallatja-é hangját barlangjából a kölyök-oroszlán, ha semmit nem fogott?!
5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
Tőrbe esik-é a madár a földön, ha nincs tőr vetve néki? Felpattan-é a tőr a földről, ha fogni nem fogott?
6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
Ha megharsan a kürt a városban, nem riad-é meg a nép? Vajjon lehet-é baj a városban, a mit nem az Úr szerezne?
7 Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Mert semmit sem cselekszik az én Uram, az Úr, míg meg nem jelenti titkát az ő szolgáinak, a prófétáknak.
8 Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
Ordít az oroszlán: ki ne rettegne? Az én Uram, az Úr szólt: ki ne prófétálna?
9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
Adjatok hírt Asdód palotáiban és az Égyiptom földében való palotákban, és így szóljatok: Gyűljetek össze Samariának hegyein, és lássátok meg benne a sok háborgást, és az elnyomottakat az ő keblében.
10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
Mert nem tudnak igazán cselekedni, azt mondja az Úr, ők, a kik halomra gyűjtik az erőszakosságot és zsarolást az ő palotáikban.
11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
Annakokáért ezt mondja az Úr Isten: Ellenség jön és körülveszi e földet; ledönti hatalmadat és feldúlatnak a te palotáid.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
Ezt mondja az Úr: A mint a pásztor az oroszlán szájából csak a két lábszárt menti meg, vagy a fül hegyét; akképen menekülnek meg Izráel fiai, a kik Samariában pamlag szegletében ülnek és a nyugágynak selymén.
13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
Halljátok meg és adjátok tudtára a Jákób házának, azt mondja az Úr Isten, a Seregek Istene,
14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
Hogy a mely napon megbüntetem Izráelt az ő vétkeiért, Béth-El oltáraiért is büntetek, és letöretnek az oltár szarvai, és a földre omlanak.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.
És ledöntöm a téli házat a nyári házzal együtt, és elpusztulnak az elefántcsont-házak is, megsemmisülnek a nagy házak, ezt mondja az Úr.

< Amos 3 >