< Amos 3 >
1 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
Слушайте това слово, което Госопд изговори против вас, Израиляни, - против целия род, рече Господ, който възведох от Египетската земя, като казах:
2 “Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
Само вас познах Измежду всичките родове на света; Затова, ще ви накажа за всичките ви беззакония.
3 Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
Ще ходят ли двама заедно Освен по съгласие?
4 Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
Ще изреве ли лъвът в леса Ако няма лов? Ще издаде ли гласа си младият лъв от леговището си, Ако не е хванал нещо?
5 Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
Може ли птица да попадне в клопка на земята, Дето няма примка за нея? Скача ли примка от земята Без да е хванала нещо?
6 Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
Може ли да засвири тръба в град И людете да не се уплашат? Може ли бедствие да сполети град И да не го е направил Господ?
7 Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
Наистина Господ Иеова няма да направи нищо Без да открие своето намерение на слугите си пророците.
8 Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
Лъвът изрева; кой не ще се уплаши? Господ Иеова изговори; кой не ще пророкува?
9 Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
Прогласете в палатите на Азот И в палатите на Египтската земя, И речете - Съберете се по планините на Самария Та вижте големите метежи всред нея, И какви насилия има вътре в нея.
10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
Защото, казва Господ, Ония, които натрупват в палатите си плода на насилие и грабеж, Не знаят да вършат правото.
11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
За това, така казва Господ Иеова; Неприятел ще окръжава земята ти, И ще смъкне от тебе силата ти, И палатите ти ще бъдат разграбени.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
Така казва Господ: Както овчарят изтръгва из лъвовите уста Две голени, или част от ухо, Така ще изтръгнат Израиляните, Които в Самария седят в ъгъла на канапе И на копринени възглавници на постелка.
13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
Слушайте, и предупредете Якововия дом, Казва Господ Иеова, Бог на Силите,
14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
Че в деня, когато нанеса наказание върху Израиля за престъплението му, Ще накажа и жертвениците на Ветил, И роговете на жертвеника ще се отсекат и ще паднат наземи.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.
Още ще поразя зимната къща зедно с лятната къща, Къщите от слонова кост ще се съсипят, И на големите къщи ще се тури край, казва Господ.