< Amos 2 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
diz Yahweh: “Para três transgressões de Moab, sim, para quatro”, Eu não vou recusar sua punição, porque ele queimou os ossos do rei de Edom em cal;
2 Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
mas vou mandar um incêndio em Moab, e devorará os palácios de Kerioth; e Moab morrerá com tumulto, com gritos, e com o som da trombeta;
3 Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
e eu cortarei o juiz de entre eles, e matará todos os seus príncipes com ele”. diz Yahweh.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
diz Yahweh: “Para três transgressões de Judá, sim, para quatro, Eu não vou recusar sua punição, porque eles rejeitaram a lei de Yahweh, e não mantiveram seus estatutos, e suas mentiras os desviaram do caminho, depois do qual seus pais caminharam;
5 Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
but Vou mandar um incêndio contra Judah, e devorará os palácios de Jerusalém”.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
diz Yahweh: “Para três transgressões de Israel, sim, para quatro”, Eu não vou recusar sua punição, porque eles venderam os justos por prata, e os necessitados por um par de sandálias;
7 Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
Eles pisam a cabeça dos pobres para o pó da terra e negar justiça aos oprimidos. Um homem e seu pai usam a mesma donzela, para profanar meu santo nome.
8 Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
Eles se deitam ao lado de cada altar sobre roupas levadas em penhor. Na casa de seu Deus, eles bebem o vinho daqueles que foram multados.
9 “Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
Yet Eu destruí o Amorito antes deles, cuja altura era como a altura dos cedros, e ele era forte como os carvalhos; no entanto, destruí seus frutos lá de cima, e suas raízes a partir de baixo.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
Também o tirei da terra do Egito e o conduziu por quarenta anos no deserto, para possuir a terra do Amorita.
11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
Eu criei alguns de seus filhos para profetas, e alguns de seus jovens para os nazistas. Isto não é verdade? vocês, filhos de Israel?” diz Yahweh.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
“Mas você deu aos nazistas vinho para beber, e ordenou aos profetas, dizendo: “Não profetizem!
13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
Eis que eu o esmagarei em seu lugar, como uma carroça que está cheia de grãos.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
Vôo perecerá do rápido. O forte não fortalecerá sua força. O poderoso não se entrega sozinho.
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
Aquele que maneja o arco não vai ficar de pé. Aquele que é rápido de pés não escapará. Aquele que monta o cavalo não se entrega sozinho.
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.
Aquele que é corajoso entre os poderosos fugirão nus naquele dia”. diz Yahweh.

< Amos 2 >