< Amos 2 >
1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
Így szól az Úr: Három bűne miatt a Moábnak, sőt négy miatt, nem fordítom el; mert mészszé égette Edom királyának csontjait!
2 Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
Tüzet vetek azért Moábra, és az emészti meg Kerijjoth palotáit, és meghal Moáb a zajban, hadi lárma közt, a kürt zengése közben.
3 Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
Kivágom a birót közüle, és minden fejedelmit megölöm vele egyetemben, ezt mondja az Úr.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
Így szól az Úr: Három bűne miatt a Júdának, sőt négy miatt, nem fordítom el; mert megvetették az Úrnak törvényét és nem tartották meg rendeléseit. Eltévelyítették őket az ő hazugságaik, a melyeket az ő atyáik követtek.
5 Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
Tüzet vetek azért Júdára, és az emészti meg Jeruzsálem palotáit.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
Így szól az Úr: Három bűne miatt az Izráelnek, sőt négy miatt, nem fordítom el; mert pénzért adták el az igazat, a szegényt pedig egy öltő saruért.
7 Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
A kik a föld porát áhítják a szegények fejére, és a nyomorultak útját elfordítják. Fiú és az atyja egy leányhoz járnak, hogy megfertőztessék az én szent nevemet.
8 Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
Zálogos ruhákon nyujtózkodnak minden oltár mellett, és az elítéltek borát iszszák az ő istenök házában.
9 “Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
Pedig én irtottam ki előlük az Emoreusokat, a kik magasak voltak, mint a czédrusok, erősek, mint a cserfák. Mégis kiirtottam gyümölcsét felül és gyökerét alul.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
És én hoztalak fel Égyiptom földéről, és negyven esztendeig én hordoztalak a pusztában titeket, hogy bírjátok az Emoreusok földét.
11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
És prófétákat támasztottam a ti fiaitok közül és nazirokat ifjaitok közül. Nem így van-é vajjon, Izráel fiai? ezt mondja az Úr.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
De a nazirokat borral itattátok, és a prófétákra ráparancsoltatok, mondván: Ne prófétáljatok!
13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
Ímé, én is lenyomlak titeket, ott a hol vagytok, mint a cséplő szekér lenyomja a kévékkel teli szérűt.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
Elvész azért a futás a gyorstól, és nem erősíti meg az erőst az ő ereje, és a hős sem menekedhetik.
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
Nem állja meg helyét az íjj-hordozó sem, nem menekülhet el még a gyorslábú sem, és a lovon ülő sem menekedhetik.
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.
És a bátor szívű is a hősök között meztelenül fut el azon a napon, ezt mondja az Úr.