< Amos 2 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
Yahvé dit: « Pour trois transgressions de Moab, oui, pour quatre, Je ne détournerai pas son châtiment, car il a brûlé les os du roi d'Édom pour en faire de la chaux;
2 Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
mais j'enverrai un feu sur Moab, et il dévorera les palais de Kerioth; et Moab mourra dans le tumulte, dans les cris et au son de la trompette;
3 Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
et je retrancherai le juge du milieu d'eux, et tuera tous ses princes avec lui, » dit Yahvé.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
Yahvé dit: « Pour trois transgressions de Juda, oui, pour quatre, Je ne détournerai pas son châtiment, parce qu'ils ont rejeté la loi de Yahvé, et n'ont pas gardé ses statuts, et leurs mensonges les ont égarés, après laquelle leurs pères ont marché;
5 Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
mais je vais envoyer un feu sur Juda, et il dévorera les palais de Jérusalem. »
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
Yahvé dit: « Pour trois transgressions d'Israël, oui, pour quatre, Je ne détournerai pas son châtiment, car ils ont vendu les justes pour de l'argent, et les nécessiteux pour une paire de sandales;
7 Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
Ils piétinent la tête des pauvres dans la poussière de la terre. et refuser la justice aux opprimés. Un homme et son père utilisent la même jeune fille, pour profaner mon saint nom.
8 Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
Ils se couchent à côté de chaque autel sur des vêtements pris en gage. Dans la maison de leur Dieu, ils boivent le vin de ceux qui ont été condamnés à une amende.
9 “Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
Mais j'ai détruit l'Amoréen devant eux, dont la hauteur était semblable à celle des cèdres, et il était fort comme les chênes; mais j'ai détruit son fruit d'en haut, et ses racines par en dessous.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
Je vous ai aussi fait monter du pays d'Égypte et vous a conduit pendant quarante ans dans le désert, pour posséder le pays des Amorites.
11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
J'ai élevé certains de tes fils comme prophètes, et certains de vos jeunes hommes pour des naziréens. N'est-ce pas vrai? vous, enfants d'Israël? » dit Yahvé.
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
« Mais tu as donné du vin à boire aux naziréens, et a ordonné aux prophètes de ne pas prophétiser.
13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
Voici, je vais t'écraser sur place, comme un chariot écrase ce qui est plein de grain.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
La fuite périra chez les rapides. Le fort ne renforcera pas sa force. Le puissant ne se délivrera pas lui-même.
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
Celui qui manie l'arc ne tient pas debout. Celui qui a le pied rapide ne s'échappera pas. Celui qui monte le cheval ne se délivrera pas lui-même.
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.
Celui qui est courageux parmi les puissants s'enfuiront nus en ce jour-là, » dit Yahvé.

< Amos 2 >