< Amos 2 >
1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
Thus says the Lord: For three wicked deeds of Moab, and for four, I will not convert him, in so far as he has burned the bones of the king of Idumea, all the way to ashes.
2 Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
And I will send a fire onto Moab, and it will devour the buildings of Kerioth. And Moab will die with a noise, with the blare of a trumpet.
3 Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
And I will destroy the judge in their midst, and I will execute all his leaders with him, says the Lord.
4 Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
Thus says the Lord: For three wicked deeds of Judah, and for four, I will not convert him, in so far as he has rejected the law of the Lord and has not kept his commandments. For their idols, which their fathers followed, have deceived them.
5 Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
And I will send a fire onto Judah, and it will devour the buildings of Jerusalem.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
Thus says the Lord: For three wicked deeds of Israel, and for four, I will not convert him, in so far as he has sold the just for silver and the poor for shoes.
7 Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
They grind the heads of the poor into the dust of the earth, and they divert the way of the humble. And the son, as well as his father, have gone to the same girl, so that they outrage my holy name.
8 Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
And they have lain on garments taken in pledge next to every altar. And they drank the wine of the damned in the house of their God.
9 “Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
Yet I exterminated the Amorites before their face, whose height was like the height of cedars, and whose strength was like the oak. And I crushed his fruit from above and his roots below.
10 Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
It is I who caused you to ascend from the land of Egypt, and I led you in the wilderness for forty years, so that you might possess the land of the Amorite.
11 “Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
And I stirred up prophets from your sons, and Nazirites from your young men. Is it not so, sons of Israel, says the Lord?
12 “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
Yet you would offer wine to the Nazirites, and you would command the prophets, saying: “Do not prophesy.”
13 “Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
Behold, I will creak under you, just as a wagon creaks that is laden with hay.
14 Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
And flight will perish from the swift, and the strong will not maintain his strength, and the healthy will not save his life.
15 Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
And one holding the bow will not stand firm, and the swift of foot will not be saved, and the rider on the horse will not save his life.
16 Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.
And the stout of heart among the strong will flee away naked in that day, says the Lord.