< Amos 1 >
1 Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
Judah siangpahrang Uzziah, Isarel siangpahrang Jehoash e capa Jeroboam tinaw e kut dawk talî a no hoehnahlan kum hni navah, tukhoum e lah kaawm e, Tekoa tami Amos ni Isarel ram hanelah, a hmu sak e lawk teh,
2 Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
BAWIPA ni Zion mon dawk hoi a hram teh, Jerusalem kho hoi lawk a pathang dawkvah, tukhoumnae hmuennaw teh, a kamyai vaiteh, Karmel monsom teh a kamyai han.
3 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
Miphunnaw lathueng lawkcengnae ni kâ a poe e teh, Damaskas kho teh, Gilead ram hah cangkatinnae sum e sehnaw hoi katin e yon phun kathum touh dueng hoeh niteh, yon pali touh dawkvah reknae na khang laipalah kaawm mahoeh.
4 Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
Hazael im dawk hmai ka tha vaiteh, Benhadad e imnaw hah ka kak sak han.
5 Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
Damaskas kho e longkha a khannae takhoe pouh han. Aven tanghling pueng, Beth-eden kho dawk e bawi katawknaw pueng, ka raphoe han. Sirianaw hah Kir kho lah a man awh han telah BAWIPA ni a dei.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
Hahoi BAWIPA ni a dei e teh, Gaza kho teh, paung e tami abuemlah hah Edom bawi koe poe hanlah, a man e yon kathum touh dueng laipalah, yon pali touh dawkvah, reknae na khang laipalah na awm mahoeh.
7 Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
Gaza kho rapan lathueng vah hmai ka tha vaiteh siangpahrang imnaw pueng hah ka kak sak han.
8 Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ashdod kho e tami pueng, Ashkelon kho dawk bawi katawknaw pueng, ka raphoe han. Ekron kho hai ka tuk vaiteh, kaawm rae Filistin taminaw hai be a ro han telah Bawipa Jehovah ni a dei.
9 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
Hahoi BAWIPA ni a dei e teh, Taire kho teh hmaunawngha reira lawkkamnae pâkuem hoeh. Paung e tami abuemlah naw hah, Edom bawi koe a poe e yon kathum touh laipalah, yon pali touh dawk reknae na khang laipalah na awm mahoeh.
10 Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
Taire kho rapan dawkvah hmai ka tha vaiteh, imnaw ka kak sak han.
11 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
Hahoi BAWIPA Cathut ni a dei e teh, Edom ram teh, pahrennae lungthin ka panguep teh hmaunawngha hah tahloi hoi pâlei e yon, lungkhueknae hoi pout laipalah, ao teh, pout laipalah kâtarannae yon kathum touh dueng laipalah yon pali touh dawkvah reknae na khang laipalah na awm mahoeh.
12 Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
Teman kho dawk hmai ka tha vaiteh, Bozrah kho e imnaw pueng hah a kak han.
13 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
Hahoi BAWIPA ni a dei e teh, Ammon ram e taminaw ni amamae hmuen hah kaw sak hanelah, camo ka vawn e, Gilead ram e napui camo kanengnaw e vonnaw hah vak a khei awh e yon kathum touh dueng laipalah, yon pali touh dawk kaie reknae na khang laipalah na awm mahoeh.
14 Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
Rabbah khopui rapan hmaisawi vaiteh, imnaw ka kak sak han. Tarantuk nah hnin vah, hramkinae, kho hoi tûilî a thonae hnin nah palek e lah ao han.
15 Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.
Ahnimae siangpahrang koehoi kamtawng vaiteh, a bawinaw hai man lah ao han telah BAWIPA ni a dei.