< Acts 7 >
1 Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”
Bax kaⱨin Istipandin: — Bularning eytⱪanliri rastmu? — dǝp soridi.
2 Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Abrahamu baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamia, kí ó to ṣe àtìpó ni Harani.
Istipan mundaⱪ jawab bǝrdi: — Ⱪerindaxlar wǝ ata-bowilar, sɵzümgǝ ⱪulaⱪ selinglar! Atimiz Ibraⱨim tehi Mesopotamiyǝ rayonida turuwatⱪanda, yǝni Ⱨaran xǝⱨirigǝ kɵqüp makanlixixtin ilgiri, xan-xǝrǝpning Igisi Huda uningƣa ayan bolup:
3 Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.’
«Sǝn ɵz yurtung wǝ uruⱪ-jǝmǝtingdin ayrilip qiⱪip, Mǝn sanga kɵrsitidiƣan zeminƣa barƣin» degǝnidi.
4 “Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kaldea, ó sì ṣe àtìpó ni Harani. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.
Buning bilǝn u Kaldiylǝrning zeminini taxlap, Ⱨaran xǝⱨirigǝ berip olturaⱪlaxti. Atisi ɵlgǝndin keyin, Huda uni bu zeminƣa, yǝni silǝr ⱨazir turuwatⱪan zeminƣa yɵtkǝp kǝldi.
5 Kò sí fún un ni ìní kan, ànító bi ìwọ̀n ààyè ẹsẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ṣe ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀ ìní náà fún un àti fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.
U waⱪitta, [Huda] uningƣa bu zemindin miras bǝrmidi, ⱨǝtta uningⱪa tǝwǝ put ⱪoyƣudǝkmu bir yǝr bǝrmigǝnidi. Gǝrqǝ u tehiqǝ pǝrzǝnt kɵrmigǝn bolsimu, [Huda] bu zeminni uningƣa wǝ uning nǝsligǝ igiliki bolux üqün berixkǝ wǝdǝ ⱪildi.
6 Ọlọ́run sì sọ báyìí pé, ‘Irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
Andin Huda uningƣa mundaⱪ dedi: «Sening nǝsilliring yaⱪa yurtta musapir bolup turidu, xu yurttikilǝr ularni ⱪul ⱪilip tɵt yüz yil horlaydu.
7 Ọlọ́run wí pé, Orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde kúrò, wọn ó sì wá sìn mí níhìn-ín yìí.’
Biraⱪ ularni ⱪulluⱪⱪa salƣan ǝlni jazalaymǝn», dedi Huda, «wǝ uningdin keyin, [nǝsilliring] u yǝrdin qiⱪip, bu yǝrdǝ Mening ibadǝt-hizmitimdǝ bolidu».
8 Ó sì fún Abrahamu ni májẹ̀mú ìkọlà. Abrahamu bí Isaaki, ó kọ ọ́ ní ilà ni ọjọ́ kẹjọ tí ó bí i. Isaaki sí bí Jakọbu, Jakọbu sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.
Keyin Huda Ibraⱨim bilǝn bǝlgisi hǝtnǝ bolƣan ǝⱨdini tüzgǝn, xuning bilǝn Isⱨaⱪ uningdin tɵrǝldi; [Ibraⱨim] uni sǝkkizinqi küni hǝtnǝ ⱪildi; xundaⱪ ⱪilip Isⱨaⱪtin Yaⱪup [tɵrǝldi], Yaⱪuptin on ikki «ⱪǝbilǝ atisi» [tɵrǝldi].
9 “Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Josẹfu, wọ́n sì tà á sí Ejibiti; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,
Keyin, «ⱪǝbilǝ atiliri» inisi Yüsüpkǝ ⱨǝsǝt ⱪilip, uni Misirƣa ⱪulluⱪⱪa setiwǝtti. Lekin Huda uning bilǝn billǝ bolup,
10 ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Josẹfu ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Farao ọba Ejibiti; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Ejibiti àti gbogbo ilé rẹ̀.
uni barliⱪ jǝbir-japalardin ⱪutⱪuzup, uni Misir padixaⱨi Pirǝwnning nǝziridǝ iltipatⱪa igǝ ⱪilip, uningƣa danixmǝnlik ata ⱪildi. Padixaⱨ uni Misirƣa bax wǝzir, ordisiƣa bax ƣojidar ⱪildi.
11 “Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti àti ni Kenaani, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.
Keyin, eƣir aqarqiliⱪ pütkül Misir wǝ Ⱪanaan yǝrlirini besip, zor ⱪiyinqiliⱪ boldi. Ata-bowilirimiz ozuⱪ-tülük tapalmidi.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jakọbu gbọ́ pé alikama ń bẹ ni Ejibiti, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.
Yaⱪup ǝmdi Misirda axliⱪ barliⱪini angliƣan bolup, [oƣullirini], yǝni ata-bowilirimizni u yǝrgǝ birinqi ⱪetim ǝwǝtti.
13 Nígbà kejì Josẹfu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Farao.
Ikkinqi ⱪetim barƣanda, Yüsüp akiliriƣa ɵzini axkarilidi. Xuning bilǝn Yüsüpning jǝmǝtidikilǝr Pirǝwn padixaⱨⱪa mǝlum boldi.
14 Lẹ́yìn èyí, Josẹfu ránṣẹ́ pe Jakọbu baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrùndínlọ́gọ́rin ọkàn.
Andin Yüsüp atisi Yaⱪupning aldiƣa hǝwǝr yǝtküzüp, uni pütün ailǝ-jǝmǝti bilǝn, jǝmiy yǝtmix bǝx kixini Misirƣa ɵzigǝ qaⱪirdi.
15 Nígbà náà ni Jakọbu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ní ibi tí òun àti àwọn baba wa kú sí.
Xuning bilǝn Yaⱪup Misirƣa qüxti wǝ xu yǝrdǝ ɵldi; keyin [uningdin bolƣan] ata-bowilirimizmu xu yǝrdǝ ɵldi.
16 A sì gbé òkú wọn padà wá sí Ṣekemu, a sì tẹ́ wọn sínú ibojì ti Abrahamu rà ni ọwọ́ àwọn ọmọ Amori ní Ṣekemu ní iye owó wúrà kan.
Ularning jǝsǝtliri keyin Xǝkǝm xǝⱨirigǝ ⱪayturulup, Ibraⱨim burun Ⱨamorning oƣulliridin mǝlum pulƣa setiwalƣan, Xǝkǝmdiki bir yǝrlikkǝ ⱪoyuldi.
17 “Nígbà tí àkókò tí Ọlọ́run yóò mú ìlérí tí ó ṣe fún Abrahamu ṣẹ kù sí dẹ̀dẹ̀, àwọn ènìyàn wa ń gbèrú si gidigidi ní iye ní ilẹ̀ Ejibiti.
Lekin Huda Ibraⱨimƣa ǝsli ⱪilƣan wǝdining waⱪti yeⱪinlaxⱪanda, Misirda turuwatⱪan [Israil] hǝlⱪining nopusi heli kɵpǝygǝnidi.
18 Ṣùgbọ́n ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
U waⱪitta, Yüsüptin hǝwiri bolmiƣan yengi bir padixaⱨ Misirda tǝhtkǝ qiⱪti.
19 Òun náà ni ó ṣe àrékérekè sí àwọn ìbátan wa. Wọn sì hùwà búburú sí àwọn baba wa, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi já àwọn ọmọ ọwọ́ wọn kúrò lọ́wọ́ wọn nítorí kí wọn má ṣe yè.
Bu padixaⱨ ⱪowmimizƣa ⱨiylǝ-mikirlǝr bilǝn muamilǝ ⱪilip, ata-bowilirimizni ezip horlidi, ⱨǝtta ularni ɵz bowaⱪlirini ⱨayat ⱪaldurmasliⱪi üqün taxliwetixkǝ mǝjbur ⱪildi.
20 “Ní àkókò náà ni a bí Mose ọmọ tí ó se iyebíye, tí wọn sí bọ́ lóṣù mẹ́ta ni ilé baba rẹ̀.
Musa mana xu qaƣlarda tuƣulƣanidi. U Hudaning aldida alaⱨidǝ yeⱪimliⱪ bala bolup, atisining ɵyidǝ üq ay beⱪildi.
21 Nígbà tí wọn sí gbe é sọnù, ọmọbìnrin Farao gbé e, ó sì tọ ọ́ dàgbà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ara rẹ̀.
Keyin u sirtⱪa ⱪoyup ⱪoyulƣanda, Pirǝwnning ⱪizi uni [sudin] elip, ɵz oƣli ⱪilip qong ⱪildi.
22 A sì kọ́ Mose ni gbogbo ọgbọ́n ara Ejibiti, ó sì pọ̀ ni ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe.
Musa Misirliⱪlarning barliⱪ bilim-ⱨekmiti bilǝn tǝrbiyilinip, sɵzdǝ wǝ ǝmǝldǝ intayin ⱪabiliyǝtlik adǝm bolup qiⱪti.
23 “Nígbà tí Mose di ọmọ ogójì ọdún, ó sọ sí i lọ́kàn láti lọ bẹ àwọn ọmọ Israẹli ará rẹ̀ wò.
Lekin uning tuƣulƣiniƣa ⱪiriⱪ yil toxⱪanda, ɵz ⱪerindaxliri bolƣan Israillarning ⱨaliƣa yetix niyitigǝ kǝldi.
24 Nígbà tí ó sì rí ọ̀kan nínú wọ́n tí ará Ejibiti kan ń jẹ́ ní ìyà, ó gbèjà rẹ̀, ó gbẹ̀san ẹni tí wọ́n jẹ ní ìyà nípa lílu ará Ejibiti náà pa.
U ulardin birining uwal ⱪilinip bozǝk ⱪiliniwatⱪanliⱪini kɵrüp, uni ⱪoƣdap, harlanƣan kixi üqün intiⱪam elip harliƣuqi Misirliⱪni ɵltürdi.
25 Mose rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.
Qünki u ɵz ⱪerindaxlirini: — Huda mening ⱪolum arⱪiliⱪ bizgǝ ⱪutⱪuzux yolini aqⱪan dǝp qüxinidiƣu, dǝp oyliƣanidi. Lekin ular buni qüxǝnmidi.
26 Ní ọjọ́ kejì Mose yọ sí àwọn ọmọ Israẹli méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun si fẹ́ parí ìjà fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’
Ətisi, Musa ularning arisidiki bir urux-jedǝlni kɵrüp, arisiƣa kirip yaraxturmaⱪqi bolup: Silǝr ⱪerindax turup, nemixⱪa bir-biringlarƣa yolsizliⱪ ⱪiliwatisilǝr? — dedi.
27 “Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ ti Mose sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa?
Biraⱪ ⱪerindixini yolsiz bozǝk ⱪilƣan kixi uni qǝtkǝ ittiriwetip: — Kim seni bizgǝ bax ⱨǝm soraⱪqi bolsun dǝptu?!
28 Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti lánàá?’
Menimu tünügünki Misirliⱪni ɵltürgǝndǝk ɵltürmǝkqimusǝn? — dedi.
29 Mose sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Midiani, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.
Musa bu sɵzni anglap ⱪorⱪup, Misirdin ⱪeqip Midiyan zeminiƣa berip, u yǝrdǝ musapir bolup turup ⱪaldi. U xu yǝrdǝ ikki oƣul pǝrzǝnt kɵrdi.
30 “Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, angẹli Olúwa fi ara han Mose ní ijù, ní òkè Sinai, nínú ọ̀wọ́-iná nínú igbó.
Ⱪiriⱪ yil toxⱪandin keyin, Sinay teƣining yenidiki qɵldǝ, kɵyüwatⱪan bir qatⱪalliⱪning ot yalⱪunida bir pǝrixtǝ uningƣa kɵründi.
31 Nígbà tí Mose sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,
Bu ƣayibanǝ kɵrünüxni kɵrgǝn Musa uningƣa intayin ⱨǝyran bolup ⱪaldi; buning ⱪandaⱪ ix ikǝnlikini bilǝy dǝp yeⱪinraⱪ barƣanda Pǝrwǝrdigarning awazi anglinip:
32 wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu,’ Mose sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dáṣà láti wò ó mọ́.
«Mǝn sening ata-bowiliringning Hudasi, yǝni Ibraⱨim, Isⱨaⱪ wǝ Yaⱪupning Hudasidurmǝn» dedi. Musa ⱪorⱪunqta titrǝp, ⱪaraxⱪimu jür’ǝt ⱪilalmidi.
33 “Olúwa sì wí fún un pé, ‘Bọ́ bàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.
Pǝrwǝrdigar uningƣa yǝnǝ: — Ayiƣingni seliwǝt; qünki sǝn turuwatⱪan yǝr muⱪǝddǝstur.
34 Ní rí rí, mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsin yìí, Èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.’
Mǝn dǝrⱨǝⱪiⱪǝt Misirda turuwatⱪan hǝlⱪimning harliniwatⱪanliⱪini kɵrdüm, ularning nalǝ-pǝryadlirini anglidim. Xunga mǝn ularni elip qiⱪⱪili qüxtüm. Əmdi barƣin, mǝn seni Misirƣa ǝwǝtǝy!» dedi.
35 “Mose náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ angẹli, tí ó farahàn án ní pápá, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.
Mana ⱨeliⱪi kixilǝr: «Kim seni bizgǝ bax ⱨǝm soraⱪqi bolsun dǝptu!?» dǝp rǝt ⱪilƣan dǝl muxu Musani, Huda uningƣa qatⱪalliⱪta kɵrüngǝn pǝrixtining ⱪoli bilǝn Israillarƣa ⱨǝm bax ⱨǝm ⱪutⱪuzƣuqi boluxⱪa ǝwǝtti.
36 Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ni Òkun pupa, àti ni aginjù ní ogójì ọdún.
Ənǝ xu Musa hǝlⱪⱪǝ yetǝkqilik ⱪilip, ularni [Misirdin] qiⱪardi ⱨǝmdǝ Misir zeminida, Ⱪizil dengizning boyida wǝ ⱪiriⱪ yilni ɵtküzgǝn qɵldǝ karamǝtlǝrni wǝ mɵjizilik alamǝtlǝrni kɵrsǝtti.
37 “Èyí ni Mose náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’
Ənǝ xu Musa ɵzi Israillarƣa: «Huda ⱪerindaxliringlar arisidin manga ohxax bir pǝyƣǝmbǝrni tiklǝydu» degǝnidi.
38 Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú angẹli náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sinai, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.
Qɵl-bayawandiki jamaǝtkǝ ⱨǝmraⱨ bolƣan, Sinay teƣida ɵzigǝ sɵz ⱪilƣan pǝrixtǝ bilǝn billǝ bolƣan, ata-bowilirimiz bilǝn billǝ bolƣan ⱨǝmraⱨ dǝl ǝnǝ xu idi; ⱨayatliⱪ bǝhx yǝtküzidiƣan wǝⱨiylǝrni bizgǝ yǝtküzüx üqün ⱪobul ⱪilƣuqi bolƣan dǝl ǝnǝ xu idi;
39 “Ṣùgbọ́n àwọn baba wa kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀, àti pé nínú ọkàn wọn, wọn fẹ́ yípadà lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
xundaⱪ bolsimu, ata-bowilirimiz uningƣa itaǝt ⱪilixni halimay, uni qǝtkǝ ⱪeⱪip, kɵnglidǝ Misirƣa ⱪaytixni arzu ⱪildi;
40 Wọ́n wí fún Aaroni pé, ‘Dá òrìṣà fún wa tí yóò máa tọ́nà ṣáájú wa; nítorí bí ó ṣe ti Mose yìí tí ó mú wa jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, a kò mọ̀ ohun tí ó ṣe é.’
xunga ular Ⱨarunƣa: — «Bizgǝ yol baxlaydiƣan ilaⱨlarni yasap bǝrgin! Qünki bizni Misir zeminidin elip qiⱪⱪan ⱨeliⱪi Musaning nemǝ bolup kǝtkǝnlikini bilǝlmiduⱪ» dedi.
41 Wọ́n sì yá ère ẹgbọrọ màlúù ni ọjọ́ wọ̀nyí. Wọ́n sì rú ẹbọ sí ère náà, wọ́n sì ń yọ̀ nínú ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.
Xuning bilǝn xu künlǝrdǝ ular mozay xǝklidǝ bir but yasap, bu mǝbudⱪa atap ⱪurbanliⱪ sundi. Xundaⱪ ⱪilip ular ɵz ⱪolliri bilǝn yasiƣan bir nǝrsini huxal-huramliⱪ bilǝn tǝbriklǝxkǝ kirixti.
42 Ọlọ́run sì padà, ó fi wọn sílẹ̀ láti máa sin ogun ọ̀run: òòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé: “‘Ẹ̀yin ha mú ẹran tí a pa àti ẹbọ wa fún mi ní ogójì ọdún ní ijù bí, ìwọ ilé Israẹli?
Lekin Huda ulardin yüzini ɵrüp, ularni asmandiki yultuz ⱪoxunliriƣa qoⱪunuxⱪa ⱪoyup bǝrdi. Xuning bilǝn pǝyƣǝmbǝrlǝrning muⱪǝddǝs yazmisida pütülgǝdǝk, [Huda ularni mundaⱪ ǝyiblidi]: — «Silǝr qɵl-bayawanda bolƣan ⱪiriⱪ yil jǝryanida ⱪilƣan ⱪurbanliⱪ-ⱨǝdiyǝlǝrni ⱨǝⱪiⱪǝtǝn Manga elip kǝlgǝnmusilǝr, i Israil jǝmǝti?
43 Ẹ̀yin sì tẹ́wọ́gbà àgọ́ Moleki, àti ìràwọ̀ Refani òrìṣà yín, àwòrán tí ẹ̀yin ṣe láti máa bọ wọ́n. Nítorí náà èmi yóò kó yín lọ sí ìgbèkùn rékọjá Babeli.’
Bǝrⱨǝⱪ, silǝr qoⱪunux üqün yasiƣan mǝbudlar, yǝni «Moloⱪ»ning qediri ⱨǝm butung bolƣan «Rǝmfan»ning yultuz bǝlgisini kɵtürüp mangdinglar; ǝmdi Mǝn silǝrni ǝsir ⱪilip Babildin yiraⱪⱪa sürgün ⱪildurimǝn».
44 “Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí.
Ata-bowilirimiz qɵldin kǝzgǝn waⱪtida, «ⱨɵküm-guwaⱨliⱪ» qediri ularning otturisida tiklǝngǝnidi; u dǝl Musaƣa sɵz-kalam Yǝtküzgüqining buyruƣinidǝk, kɵrsitilgǝn ɵrnǝk boyiqǝ yasalƣanidi.
45 Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi.
Xu ibadǝt qedirini ata-bowilirimiz ilgiridikilǝrdinmu igidarqiliⱪiƣa tapxurup, Yǝxuaning yetǝkqilikidǝ, Huda ularning aldidila ⱪoƣliƣan ǝllǝrning zeminlirini besiwalƣinida, uni bu yǝrgǝ elip kǝlgǝn; qedir xundaⱪla [padixaⱨ] Dawutning zamaniƣiqǝ turƣan.
46 Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu.
Dawut Hudaning xapaitigǝ erixip, Yaⱪupning Hudasi üqün bir muⱪim makan selixⱪa ijazǝt soriƣan.
47 Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.
Biraⱪ keyin, [Huda] üqün ibadǝthana salƣan [Dawut ǝmǝs], ǝmǝliyǝttǝ Sulayman boldi.
48 “Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́, gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:
Ⱨalbuki, Ⱨǝmmidin Aliy Bolƣuqi insanning ⱪolliri bilǝn yasiƣan makanlarda turmaydu; huddi pǝyƣǝmbǝr mundaⱪ deginidǝk: —
49 “‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi? ni Olúwa wí. Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
«Asmanlar Mening tǝhtim, Zemin bolsa ayaƣlirimƣa tǝhtipǝrdur, Əmdi Manga ⱪandaⱪ ɵy-imarǝt yasimaⱪqisilǝr? Manga ⱪandaⱪ yǝr aramgaⱨ bolalaydu?
50 Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’
Bularning ⱨǝmmisini Mening ⱪolum yaratⱪan ǝmǝsmidi?»
51 “Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí. Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́!
— Əy, boyni ⱪattiⱪ, yüriki wǝ ⱪuliⱪi hǝtnisiz bolƣanlar! Silǝr Muⱪǝddǝs Roⱨ bilǝn daim ⱪarxilixisilǝr; silǝr ata-bowiliringlar nemǝ ⱪilƣan bolsa, xuni ohxax ⱪiliwatisilǝr!
52 Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa.
Pǝyƣǝmbǝrlǝrdin zadi ⱪaysisiƣa ata-bowiliringlar ziyankǝxlik ⱪilip baⱪmiƣan? Xundaⱪ ⱪilip ular «Ⱨǝⱪⱪaniy Bolƣuqi»ning kelidiƣanliⱪini aldin jakarliƣuqilarni ɵltürüxkǝn. Əmdi u ɵzi ⱨazir kǝlgǝndǝ, silǝr uningƣa satⱪunluⱪ ⱪilƣuqi wǝ ⱪatil bolup qiⱪtinglar,
53 Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”
I silǝr Tǝwrat ⱪanunini pǝrixtilǝrning ǝmri-tapiliƣanliri bilǝn tapxuruwelip turup, uningƣa ǝmǝl ⱪilmiƣuqilar!»
54 Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i.
[Istipanning] bu sɵzlirini angliƣan [aliy kengǝxmidikilǝr] yürikigǝ [hǝnjǝr] sanjilƣandǝk bolup, uningƣa qixlirini ƣuqurlatti.
55 Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
Lekin u bolsa Muⱪǝddǝs Roⱨⱪa tolƣan, kɵzlirini kɵkkǝ tikip, Hudaning julasini, xundaⱪla uning ong yenida Əysaning turƣanliⱪini kɵrüp,
56 Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”
— Ⱪaranglar! Asmanlar eqilip, Insan’oƣlining Hudaning ong yenida turƣanliⱪini kɵrüwatimǝn! — dedi.
57 Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú,
Ular buningƣa ⱪulaⱪlirini ⱪolliri bilǝn etiwelip, awazini ⱪattiⱪ kɵtürüp warⱪirixip birliktǝ uningƣa yopurulup keliwidi,
58 wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.
uni xǝⱨǝrning sirtiƣa ittirip qiⱪirip, qalma-kesǝk ⱪilixⱪa baxlidi. [Uni ǝrz ⱪilƣan] guwaⱨqilar [uni qalma-kesǝk ⱪilixtin awwal] qapanlirini Saul isimlik bir yaxning puti aldida ⱪoyup ⱪoyuxti.
59 Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.”
Ular Istipanni qalma-kesǝk ⱪilƣinida u: — I Rǝb Əysa, mening roⱨimni ⱪobul ⱪilƣaysǝn! — dǝp nida ⱪildi.
60 Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.
Andin u tizlinip turup ⱪattiⱪ awaz bilǝn: — I Rǝb, bu gunaⱨning ⱨesabini ulardin almiƣaysǝn, — dedi. U bu sɵzni ⱪilip bolupla jan üzüp uhlap kǝtti.