< Acts 7 >
1 Nígbà náà ni olórí àlùfáà wí pé, “Òtítọ́ ha ni àwọn ẹ̀sùn tí wọ́ fi kàn ọ́ bí?”
A főpap pedig megkérdezte: „Vajon tényleg így vannak-e ezek a dolgok?“
2 Ní ìdáhùn sí èyí ó wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin àti ẹ̀yin baba, ẹ fetísílẹ̀ sí mi! Ọlọ́run ògo fi ara hàn fún Abrahamu baba wa, nígbà tí ó wà ni Mesopotamia, kí ó to ṣe àtìpó ni Harani.
Ő pedig ezt mondta: „Férfiak, atyámfiai és atyák, halljátok meg! A dicsőségnek Istene megjelent a mi atyánknak, Ábrahámnak, amikor Mezopotámiában volt, mielőtt Háránban lakott,
3 Ọlọ́run wí fún un pé, ‘Jáde kúrò ní orílẹ̀-èdè rẹ àti kúrò lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ, lọ sí ilẹ̀ kan tí èmi yóò fihàn ọ́.’
és mondta neki: »Eredj ki a földedből és a te nemzetséged közül, és gyere arra a földre, amelyet mutatok neked.«
4 “Nígbà náà ni ó jáde kúrò ní ilẹ̀ àwọn ará Kaldea, ó sì ṣe àtìpó ni Harani. Lẹ́yìn ìgbà tí baba rẹ̀ sì kú, Ọlọ́run mú un sípò padà wá sí ilẹ̀ yìí, níbi tí ẹ̀yin ń gbé báyìí.
Akkor kiment a káldeusok földjéből, és Háránban lakott. Miután pedig meghalt az atyja, kihozta onnan erre a földre, amelyen ti most laktok.
5 Kò sí fún un ni ìní kan, ànító bi ìwọ̀n ààyè ẹsẹ̀ kan. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ṣe ìlérí fún pé, òun yóò fi ilẹ̀ ìní náà fún un àti fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí kò tí ì ní ọmọ.
Nem adott neki abban örökséget, még egy talpalatnyi földet sem, de azt ígérte, hogy neki adja azt birtokul, és utódainak, holott nem is volt neki gyermeke.
6 Ọlọ́run sì sọ báyìí pé, ‘Irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irinwó ọdún.
Az Isten pedig azt mondta neki, hogy az utódai zsellérek lesznek idegen földön, és szolgaság alá vetik, és nyomorgatják négyszáz esztendeig őket.
7 Ọlọ́run wí pé, Orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́; lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde kúrò, wọn ó sì wá sìn mí níhìn-ín yìí.’
De azt a népet, amelynek szolgálnak, megítélem, mondta az Isten, ők pedig ezek után kijönnek, és szolgálnak nekem ezen a helyen.
8 Ó sì fún Abrahamu ni májẹ̀mú ìkọlà. Abrahamu bí Isaaki, ó kọ ọ́ ní ilà ni ọjọ́ kẹjọ tí ó bí i. Isaaki sí bí Jakọbu, Jakọbu sì bí àwọn baba ńlá méjìlá.
És a körülmetélés szövetségét adta neki: és így nemzette Izsákot, és körülmetélte őt a nyolcadik napon, és Izsák Jákobot, és Jákob a tizenkét pátriárkát.
9 “Àwọn baba ńlá sí ṣe ìlara Josẹfu, wọ́n sì tà á sí Ejibiti; ṣùgbọ́n Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀,
A pátriárkák pedig irigységből eladták Józsefet Egyiptomba, de Isten vele volt,
10 ó sì yọ ọ́ kúrò nínú ìpọ́njú rẹ̀ gbogbo. Ó sì fún Josẹfu ní ọgbọ́n, ó sì mú kí ó rí ojúrere Farao ọba Ejibiti; òun sì fi jẹ baálẹ̀ Ejibiti àti gbogbo ilé rẹ̀.
megszabadította őt minden nyomorúságából, kedvességet és bölcsességet adott neki a fáraó, Egyiptom királya előtt, aki őt Egyiptom fölé és az ő egész háza fölé kormányzóul állította.
11 “Ìyàn kan sì mú ni gbogbo ilẹ̀ Ejibiti àti ni Kenaani, àti ìpọ́njú ńlá, àwọn baba wa kò sì rí oúnjẹ.
Egyiptom és Kánaán egész földjére pedig éhínség következett, és nagy nyomorúság, és a mi atyáink nem találtak eledelt.
12 Ṣùgbọ́n nígbà tí Jakọbu gbọ́ pé alikama ń bẹ ni Ejibiti, ó rán àwọn baba wa lọ lẹ́ẹ̀kínní.
Amikor pedig meghallotta Jákob, hogy Egyiptomban van gabona, elküldte először a mi atyáinkat.
13 Nígbà kejì Josẹfu fi ara rẹ̀ hàn fún àwọn arákùnrin rẹ̀, a sì tún fi wọ́n hàn fún Farao.
Második alkalommal fölismerték Józsefet testvérei, és a fáraó megtudta József származását.
14 Lẹ́yìn èyí, Josẹfu ránṣẹ́ pe Jakọbu baba rẹ̀, àti àwọn ìbátan rẹ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ, gbogbo wọ́n sì tó àrùndínlọ́gọ́rin ọkàn.
József elküldve, magához hívatta atyját, Jákobot és az egész hetvenöt lélekből álló rokonságát.
15 Nígbà náà ni Jakọbu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti, ní ibi tí òun àti àwọn baba wa kú sí.
Elment tehát Jákob Egyiptomba, és meghalt ő és a mi atyáink is.
16 A sì gbé òkú wọn padà wá sí Ṣekemu, a sì tẹ́ wọn sínú ibojì ti Abrahamu rà ni ọwọ́ àwọn ọmọ Amori ní Ṣekemu ní iye owó wúrà kan.
Elvitték őket Sikembe, és abba a sírba helyezték el, melyet Ábrahám vett ezüstpénzen, Emórnak, a Sikem atyjának fiaitól.
17 “Nígbà tí àkókò tí Ọlọ́run yóò mú ìlérí tí ó ṣe fún Abrahamu ṣẹ kù sí dẹ̀dẹ̀, àwọn ènìyàn wa ń gbèrú si gidigidi ní iye ní ilẹ̀ Ejibiti.
Amikor pedig közeledett az ígéret ideje, melyet Isten esküvel ígért Ábrahámnak, megnövekedett a nép, és megsokasodott Egyiptomban.
18 Ṣùgbọ́n ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
Egészen addig, míg egy másik király nem lett, aki nem ismerte Józsefet.
19 Òun náà ni ó ṣe àrékérekè sí àwọn ìbátan wa. Wọn sì hùwà búburú sí àwọn baba wa, tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n fi já àwọn ọmọ ọwọ́ wọn kúrò lọ́wọ́ wọn nítorí kí wọn má ṣe yè.
Ez a mi nemzetségünkkel álnokul bánt, nyomorgatta atyáinkat, hogy csecsemőiket tegyék ki, hogy életben ne maradjanak.
20 “Ní àkókò náà ni a bí Mose ọmọ tí ó se iyebíye, tí wọn sí bọ́ lóṣù mẹ́ta ni ilé baba rẹ̀.
Ekkor született Mózes, aki ékes volt az Isten előtt. Három hónapig atyja házában tartották.
21 Nígbà tí wọn sí gbe é sọnù, ọmọbìnrin Farao gbé e, ó sì tọ ọ́ dàgbà gẹ́gẹ́ bí ọmọ ara rẹ̀.
Amikor pedig kitették, a fáraó leánya vette fel, és nevelte fel őt a saját fia gyanánt.
22 A sì kọ́ Mose ni gbogbo ọgbọ́n ara Ejibiti, ó sì pọ̀ ni ọ̀rọ̀ àti ní ìṣe.
Mózest az egyiptomiak minden bölcsességére megtanították, és hatalmas volt beszédben és cselekedetben.
23 “Nígbà tí Mose di ọmọ ogójì ọdún, ó sọ sí i lọ́kàn láti lọ bẹ àwọn ọmọ Israẹli ará rẹ̀ wò.
Amikor pedig a negyvenedik évét betöltötte, eszébe jutott, hogy meglátogassa atyjafiait, az Izrael fiait.
24 Nígbà tí ó sì rí ọ̀kan nínú wọ́n tí ará Ejibiti kan ń jẹ́ ní ìyà, ó gbèjà rẹ̀, ó gbẹ̀san ẹni tí wọ́n jẹ ní ìyà nípa lílu ará Ejibiti náà pa.
Amikor látta, hogy egyiket bántalmazzák, oltalmába vette, és az egyiptomi embert megölve, bosszút állt azért, akit bántottak.
25 Mose rò bí àwọn ará òun mọ̀ pé Ọlọ́run yóò ti ọwọ́ òun gbà wọn; ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀.
Azt gondolta, hogy atyjafiai megértik, hogy az Isten az ő keze által ad nekik szabadulást, de azok nem értették meg.
26 Ní ọjọ́ kejì Mose yọ sí àwọn ọmọ Israẹli méjì bí wọ́n ti ń jà. Òun si fẹ́ parí ìjà fún wọn. Ó wí pé, ‘Ènìyàn mi, ará ni ẹ̀yin; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣe ohun tí kò tọ́ sí ara yín?’
Másnap meg olyankor jelent meg köztük, mikor összevesztek, és békességre intette őket: Férfiak, ti testvérek vagytok, miért bosszantjátok egymást?
27 “Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fínràn sí ẹnìkejì rẹ̀ ti Mose sí ẹ̀gbẹ́ kan, ó wí pé, ‘Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa?
De az, aki felebarátját bántalmazta, elutasította őt magától, ezt mondva: »Kicsoda tett téged fejedelemmé és bíróvá mi rajtunk?
28 Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti lánàá?’
Csak nem akarsz engem is megölni, ahogyan megölted tegnap az egyiptomit?«
29 Mose sì sá nítorí ọ̀rọ̀ yìí, ó sì wa ṣe àtìpó ni ilẹ̀ Midiani, níbi tí ó gbé bí ọmọ méjì.
Erre a beszédre azután Mózes elmenekült, és jövevény lett Midján földjén, ahol két fia született.
30 “Nígbà tí ogójì ọdún sì pé, angẹli Olúwa fi ara han Mose ní ijù, ní òkè Sinai, nínú ọ̀wọ́-iná nínú igbó.
Negyven esztendő elteltével az Úr angyala megjelent neki a Sínai hegy pusztájában csipkebokornak tüzes lángjában.
31 Nígbà tí Mose sì rí i, ẹnu yà á sí ìran náà; nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn láti wò ó fín, ohùn Olúwa kọ sí i,
Mózes pedig mikor meglátta, elcsodálkozott azon, amit látott. Amikor pedig oda ment, hogy megszemlélje, az Úr szava szólt hozzá:
32 wí pé ‘Èmi ni Ọlọ́run àwọn baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki, àti Ọlọ́run Jakọbu,’ Mose sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù, kò sì dáṣà láti wò ó mọ́.
»Én vagyok a te atyáidnak Istene, Ábrahámnak Istene, Izsáknak Istene, és Jákobnak Istene.« Mózes pedig megrémült, és nem mert odanézni.
33 “Olúwa sì wí fún un pé, ‘Bọ́ bàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.
Az Úr pedig ezt mondta neki: »Oldozd le sarudat lábaidról, mert a hely, amelyen állsz, szent föld.
34 Ní rí rí, mo ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi tí ń bẹ ni Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ìkérora wọn, mo sì sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n. Wá nísinsin yìí, Èmi ó sì rán ọ lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.’
Megláttam népemnek nyomorúságát, mely Egyiptomban van, és fohászkodásukat meghallgattam, és azért szálltam le, hogy őket megszabadítsam. Most azért jöjj, elküldelek téged Egyiptomba.«
35 “Mose náà yìí tí wọ́n kọ̀, wí pé, ‘Ta ni ó fi jẹ olórí àti onídàájọ́?’ Òun náà ni Ọlọ́run rán lọ láti ọwọ́ angẹli, tí ó farahàn án ní pápá, láti ṣe olórí àti olùdáǹdè.
Ezt a Mózest, akit megtagadtak ezt mondva: Ki tett téged fejedelemmé és bíróvá? – ezt az Isten fejedelmül és szabadítóul küldte el angyala által, aki megjelent neki a csipkebokorban.
36 Òun ni ó mú wọn jáde, lẹ́yìn ìgbà tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ni Òkun pupa, àti ni aginjù ní ogójì ọdún.
Ez hozta ki őket, csodákat és jeleket téve Egyiptom földjén, és a Vörös tengeren és a pusztában negyven esztendeig.
37 “Èyí ni Mose náà ti ó wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Ọlọ́run yóò gbé wòlíì kan bí èmi dìde nínú àwọn ènìyàn yín.’
Ez az a Mózes, aki Izrael fiainak ezt mondta: »Prófétát támaszt nektek az Úr, a ti Istenetek, testvéreitek közül, mint engem: őt hallgassátok.«
38 Èyí náà ni ẹni tí ó wà nínú ìjọ ní ijù pẹ̀lú angẹli náà tí ó bá a sọ̀rọ̀ ní orí òkè Sinai, àti pẹ̀lú àwọn baba wa; ẹni ti ó gba ọ̀rọ̀ ìyè láti fi fún wa.
Ez az, aki ott volt a gyülekezetben, a pusztában a Sínai hegyen vele beszélő angyallal és atyáinkkal, aki az élő igéket vette át, hogy nekünk adja.
39 “Ṣùgbọ́n àwọn baba wa kò fẹ́ gbọ́ tirẹ̀. Dípò bẹ́ẹ̀, wọ́n kọ̀ ọ́ sílẹ̀, àti pé nínú ọkàn wọn, wọn fẹ́ yípadà lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Neki nem akartak engedni atyáink, hanem eltaszították maguktól, és szívükben Egyiptom felé fordultak,
40 Wọ́n wí fún Aaroni pé, ‘Dá òrìṣà fún wa tí yóò máa tọ́nà ṣáájú wa; nítorí bí ó ṣe ti Mose yìí tí ó mú wa jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, a kò mọ̀ ohun tí ó ṣe é.’
és ezt mondták Áronnak: »Csinálj nekünk isteneket, akik előttünk járjanak, mert ezzel a Mózessel, aki minket Egyiptom földjéről kihozott, nem tudjuk, mi történt.«
41 Wọ́n sì yá ère ẹgbọrọ màlúù ni ọjọ́ wọ̀nyí. Wọ́n sì rú ẹbọ sí ère náà, wọ́n sì ń yọ̀ nínú ohun tí wọ́n fi ọwọ́ ara wọn ṣe.
És borjút csináltak azokban a napokban, és áldozatot vittek a bálványnak, és gyönyörködtek kezeik alkotásában.
42 Ọlọ́run sì padà, ó fi wọn sílẹ̀ láti máa sin ogun ọ̀run: òòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀. Èyí wà ní ìbámu pẹ̀lú bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé àwọn wòlíì pé: “‘Ẹ̀yin ha mú ẹran tí a pa àti ẹbọ wa fún mi ní ogójì ọdún ní ijù bí, ìwọ ilé Israẹli?
Az Isten pedig elfordult tőlük, és hagyta, hogy az ég seregének szolgáljanak, amint meg van írva a próféták könyvében: »Vajon áldozati állatokat És áldozatokat hoztatok-e nékem negyven esztendeig a pusztában, Izraelnek háza?
43 Ẹ̀yin sì tẹ́wọ́gbà àgọ́ Moleki, àti ìràwọ̀ Refani òrìṣà yín, àwòrán tí ẹ̀yin ṣe láti máa bọ wọ́n. Nítorí náà èmi yóò kó yín lọ sí ìgbèkùn rékọjá Babeli.’
Ellenkezőleg, inkább hordoztátok a Molok sátrát, és a ti isteneteknek, Romfának csillagát, a képeket, melyeket csináltatok, hogy azokat imádjátok: elviszlek azért titeket Babilonon túlra.«
44 “Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí.
A Szövetség sátra a mi atyáinknál volt a pusztában, amint parancsolta az, aki azt mondta Mózesnek, hogy azt arra a mintára csinálja, amelyet látott.
45 Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi.
Amelyet atyáink átvéve, be is hoztak Józsuéval, mikor birtokba vették a pogányok földjét, akiket kiűzött az Isten atyáink színe elől, egészen Dávid idejéig.
46 Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu.
Ő kegyelmet talált az Isten előtt, és könyörgött, hogy hajlékot találhasson Jákób Istenének,
47 Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.
de a házat Salamon építette neki.
48 “Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́, gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:
A Magasságos azonban nem kézzel épített templomokban lakik, amint a próféta mondja:
49 “‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi, ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi. Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi? ni Olúwa wí. Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
»A menny nékem a trónom, a föld pedig az én lábaimnak zsámolya. Milyen házat építhettek nékem? – azt mondja az Úr, vagy melyik az én nyugodalmamnak helye?
50 Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’
Nem az én kezem alkotta-e mindezeket?«
51 “Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí. Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́!
Kemény nyakú és körülmetéletlen szívű és fülű emberek, ti mindenkor ellenálltok a Szentléleknek, ugyan úgy, mint atyáitok.
52 Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa.
A próféták közül kit nem üldöztek atyáitok? Megölték azokat, akik eleve hirdették annak az Igaznak eljövetelét, akinek most árulóivá és gyilkosaivá lettetek.
53 Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”
A törvényt angyalok közvetítésével vettétek, de nem tartottátok meg.“
54 Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i.
Amikor pedig ezeket hallották, szívüket elöntötte a düh, és fogaikat vicsorgatták ellene.
55 Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.
Mivel pedig eltelt Szentlélekkel, föltekintett a mennybe, és látta Isten dicsőségét, és Jézust az Istennek jobbja felől állni,
56 Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”
és ezt mondta: „Íme, látom az egeket megnyílni, és az Emberfiát az Isten jobbja felől állni.“
57 Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú,
Ekkor hangosan felkiáltottak, füleiket bedugták, és egy akarattal rárohantak,
58 wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.
kiűzték a városon kívül, és megkövezték. A tanúk pedig felsőruháikat egy Saul nevezetű ifjú lábaihoz rakták le.
59 Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.”
Megkövezték tehát Istvánt, aki így imádkozott: „Uram Jézus, vedd magadhoz az én lelkemet!“
60 Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.
Térdre esett, és hangosan felkiáltott: „Uram, ne tulajdonítsd nekik ezt a bűnt! És ezt mondva, elaludt.“