< Acts 4 >

1 Bí wọn sì tí ń bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀, àwọn àlùfáà àti olórí ẹ̀ṣọ́ tẹmpili àti àwọn Sadusi dìde sí wọn.
But, as they were speaking unto the people, the High-priests and the Captain of the temple and the Sadducees came upon them,
2 Inú bí wọn, nítorí tí wọn kọ́ àwọn ènìyàn, wọ́n sì ń wàásù àjíǹde kúrò nínú òkú nínú Jesu.
Being tired out because of their teaching the people, and announcing, in Jesus, the resurrection from among the dead;
3 Wọn sì nawọ́ mú wọn, wọn sì tì wọ́n mọ́ ilé túbú títí ó fi dí ọjọ́ kejì; nítorí tí alẹ́ ti lẹ́ tan.
And they thrust on them their hands, and put them in custody for the morrow, for it was evening, already.
4 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà gbàgbọ́; iye àwọn ọkùnrin náà sì tó ẹgbẹ̀rún márùn-ún.
Howbeit, many of them that heard the word, believed; and the number of the men became about five thousand.
5 Ó sì ṣe ní ọjọ́ kejì, àwọn olórí wọn àti àwọn alàgbà àti àwọn olùkọ́ni ní òfin péjọ sí Jerusalẹmu.
And it came to pass, upon the morrow, that there were gathered together of them, the rulers and the elders and the scribes, in Jerusalem;
6 Àti Annasi olórí àlùfáà, àti Kaiafa, àti Johanu, àti Aleksanderu, àti iye àwọn tí i ṣe ìbátan olórí àlùfáà.
Also Annas, the high-priest, and Caiaphas, and John, and Alexander, and as many as were of high-priestly descent; —
7 Wọ́n mú Peteru àti Johanu dúró níwájú wọn, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè ìbéèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Nípa agbára tàbí orúkọ wo ni ẹ̀yin fi ṣe èyí?”
And, setting them in the midst, they began to enquire—In what manner of power, or in what manner of name, did, ye, do this?
8 Nígbà náà ni Peteru kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin olórí àti ẹ̀yin alàgbà àwọn ènìyàn!
Then Peter, filled with Holy Spirit, said unto them—Ye rulers of the people, and elders!
9 Bí ó bá ṣe pé a ń wádìí wa lónìí ní tí iṣẹ́ rere ti a ṣe lára abirùn náà, bí a ti ṣe mú ọkùnrin yìí láradá,
If, we, this day, are to be examined for doing good to a sick man, —in whom, this, man hath been made well,
10 kí èyí yé gbogbo yín àti gbogbo ènìyàn Israẹli pé, ni orúkọ Jesu Kristi ti Nasareti, tí ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, tí Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, nípa rẹ̀ ni ọkùnrin yìí fi dúró níwájú yín ni ara dídá-ṣáṣá.
Be it known unto you all, and unto all the people of Israel: that, in the name of Jesus Christ the Nazarene, —whom, ye, crucified, whom, God, raised from among the dead, in him, doth, this man stand by, in your presence, whole.
11 Èyí ni “‘òkúta tí a ti ọwọ́ ẹ̀yin ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, tí ó sì di pàtàkì igun ilé.’
This, is the stone, set at nought by you the builders, which became the head of the corner;
12 Kò sì sí ìgbàlà lọ́dọ̀ ẹlòmíràn; nítorí kò sí orúkọ mìíràn lábẹ́ ọ̀run ti a fi fún ni nínú ènìyàn, nípa èyí tí a lè fi gbà wá là.”
And there is in no one else, salvation, for, neither is there any other name, under heaven, which hath been set forth among men, in which we must needs be saved.
13 Nígbà tí wọ́n sì kíyèsi ìgboyà Peteru àti Johanu, tí wọ́n mọ̀ pé, aláìkẹ́kọ̀ọ́ àti òpè ènìyàn ni wọn, ẹnu yà wọ́n, wọ́n sì wòye pé, wọ́n ti ń bá Jesu gbé.
And, looking at Peter’s boldness of speech, and John’s, and having discovered that they were unlettered and obscure men, they began to marvel, recognising them also, that they had been with Jesus;
14 Nígbà tí wọ́n sì ń wo ọkùnrin náà tí a mú láradá, tí ó bá wọn dúró, wọn kò rí nǹkan wí sí i.
Seeing, the man also standing, with them, even the [man] who had been cured, they had nothing wherewith to contradict.
15 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n sì ti pàṣẹ pé kí wọn jáde kúrò ní ìgbìmọ̀, wọ́n bá ara wọn gbèrò.
Howbeit, ordering them to go forth outside the high-council, they began to confer one with another,
16 Wí pé, “Kí ni a ó ṣe sí àwọn ọkùnrin wọ̀nyí? Ní ti pé iṣẹ́ àmì tí ó dájú tí ọwọ́ wọn ṣe, ó hàn gbangba fún gbogbo àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu; àwa kò sì lè sẹ́ èyí.
Saying—What are we to do with these men? For, indeed, that a notable sign hath come to pass through their means, unto all who are dwelling in Jerusalem, is manifest, and we cannot deny [it]!
17 Ṣùgbọ́n kí ó má ba à tànkálẹ̀ síwájú mọ́ láàrín àwọn ènìyàn, ẹ jẹ́ kí a kìlọ̀ fún wọn pé, láti ìsinsin yìí lọ kí wọn má ṣe fi orúkọ yìí sọ̀rọ̀ sí ẹnikẹ́ni mọ́.”
Nevertheless, lest it further spread abroad among the people, let us charge them with threats, to be no more speaking upon this name, to any soul of man.
18 Wọ́n sì pè wọ́n, wọ́n pàṣẹ fún wọn, kí wọn má ṣe sọ̀rọ̀ tàbí kọ́ni rárá mọ́ ní orúkọ Jesu.
And, calling them, they gave them the sweeping charge, —not to be sounding aloud, nor even to be teaching, upon the name of Jesus.
19 Ṣùgbọ́n Peteru àti Johanu dáhùn, wọ́n sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá tọ́ lójú Ọlọ́run láti gbọ́ tiyín ju ti Ọlọ́run lọ ẹ gbà á rò.
But, Peter and John, answering, said unto them—Whether it be right in presence of God, unto you, to be hearkening, rather than unto God, judge!
20 Àwa kò lè ṣàìmá sọ ohun tí àwa ń rí, tí a sì ti gbọ́.”
For, we, cannot but be speaking the things which we have seen and heard.
21 Nígbà tí wọ́n sì kìlọ̀ fún wọn sí i, wọn fi wọ́n sílẹ̀ lọ, nígbà tí wọn kò ì tí ì rí nǹkan tí wọn ìbá fi jẹ wọ́n ní ìyà, nítorí àwọn ènìyàn; nítorí gbogbo wọn ni wọ́n yin Ọlọ́run lógo fún ohun tí ó ṣe.
They, however, further charging them with threats, let them go, finding nothing as to how they might chastise them, on account of the people; because, all, were glorifying God for that which had come to pass; —
22 Nítorí ọkùnrin náà lára ẹni tí a ṣe iṣẹ́ àmì ìmúláradá, ju ẹni ogójì ọdún lọ.
For, more than forty years old, was the man, upon whom had taken place, this healing sign.
23 Nígbà tí wọ́n sì ti fi wọ́n sílẹ̀ wọ́n lọ sọ́dọ̀ àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, wọ́n sì ròyìn ohun gbogbo tí àwọn olórí àlùfáà àti àwọn alàgbà sọ fún wọn.
But, when they had been let go, they came unto their own [friends], and told as many things as, unto them, the High-priests and Elders, had said.
24 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n fi ọkàn kan gbé ohùn wọn sókè sí Ọlọ́run, wọ́n sì wí pé, “Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn.
And, they, having heard, with one accord, uplifted voice unto God, and said—O Sovereign! Thou, art he that made the heaven, and the earth, and the sea, and all things that are herein:
25 Ìwọ nípa Ẹ̀mí Mímọ́ tí ó ti ẹnu Dafidi baba wa ìránṣẹ́ rẹ̀ wí pé: “‘E é ṣe tí àwọn kèfèrí fi ń bínú, àti tí àwọn ènìyàn ń gbèrò ohun asán?
Who, by our father, through means of the Holy Spirit, even by the mouth of David thy servant, said—Unto what end did nations rage, and, peoples, busy themselves with empty things?
26 Àwọn ọba ayé dìde, àti àwọn ìjòyè kó ara wọn jọ sí Olúwa, àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.’
The kings of the earth stationed themselves, and, the rulers, were gathered together, with one intent, against the Lord, and against his Christ.
27 Àní nítòótọ́ ní Herodu àti Pọntiu Pilatu, pẹ̀lú àwọn aláìkọlà àti àwọn ènìyàn Israẹli kó ara wọn jọ ní ìlú yìí láti dìtẹ̀ sí Jesu Ìránṣẹ́ mímọ́ rẹ, ẹni tí ìwọ ti fi àmì òróró yàn,
For they were gathered together, of a truth, in this city, against thy holy servant Jesus, whom thou hadst anointed, —both Herod, and Pontius Pilate, with them of the nations, and peoples of Israel; —
28 láti ṣe ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ àti ìmọ̀ rẹ̀ ti pinnu ṣáájú pé yóò ṣe.
To do whatsoever, thy hand and thy counsel, marked out beforehand to come to pass.
29 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, Olúwa, kíyèsi ìhàlẹ̀ wọn; kí ó sì fi fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ láti máa fi ìgboyà ńlá sọ ọ̀rọ̀ rẹ.
As to the present things, then, O Lord, —look upon their threats, and grant unto thy servants, with all freedom of utterance, to be speaking thy word,
30 Kí ìwọ sì fi nína ọwọ́ rẹ ṣe ìmúláradá, àti kí iṣẹ́ ìyanu máa ṣẹ̀ ní orúkọ Jesu ìránṣẹ́ mímọ́ rẹ.”
By stretching forth thy hand for healing, and by the coming to pass of both signs and wonders, through the name of thy holy servant Jesus.
31 Nígbà tí wọ́n gbàdúrà tan, ibi tí wọ́n gbé péjọpọ̀ sí mì tìtì; gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọ́n sì ń fi ìgboyà sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
And, when they had made supplication, the place was shaken in which they were gathered together, and they were filled, one and all, with the Holy Spirit, and began speaking the word of God with freedom of utterance.
32 Ìjọ àwọn tí ó gbàgbọ́ sì wà ní ọkàn kan àti inú kan; kò sì ṣí ẹnìkan tí ó wí pé ohun kan nínú ohun ìní rẹ̀ jẹ́ ti ara rẹ̀; ṣùgbọ́n gbogbo wọn ní ohun gbogbo ní ìṣọ̀kan.
And, the throng of them that believed, had one heart and soul, and not so much as one was saying that, aught of his goods, was, his own, but they had all things common.
33 Agbára ńlá ni àwọn aposteli sì fi ń jẹ́rìí àjíǹde Jesu Olúwa, oore-ọ̀fẹ́ púpọ̀ sì wà lórí gbogbo wọn.
And, with great power, were the apostles giving forth their witness of the resurrection of the Lord Jesus; great favour also was upon them all.
34 Nítorí kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó ṣe aláìní, nítorí iye àwọn tí ó ní ilẹ̀ tàbí ilé tà wọ́n, wọ́n sì mú owó ohun tí wọn tà wá.
For there was not so much as anyone, lacking, among them; for, as many as were possessors of lands or houses, selling them, were bringing the prices of the things that were being sold,
35 Wọ́n sì fi í lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aposteli, wọn sì ń pín fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe aláìní sí.
And laying them at the feet of the Apostles, while on the other hand they were distributing unto each one, in so far as any one had, need.
36 Àti Josẹfu, tí a ti ọwọ́ àwọn aposteli sọ àpèlé rẹ̀ ní Barnaba (ìtumọ̀ èyí tí ń jẹ ọmọ ìtùnú), ẹ̀yà Lefi, àti ará Saipurọsi.
And, Joseph, who had been surnamed Barnabas by the Apostles, which is to be translated Son of Exhortation, —a Levite, a Cyprian by nation,
37 Ó ní ilẹ̀ kan, ó tà á, ó mú owó rẹ̀ wá, ó sì fi í lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aposteli.
Having a field, sold it, and brought the money and laid it at the feet of the Apostles.

< Acts 4 >