< Acts 3 >
1 Ní ọjọ́ kan Peteru àti Johanu jùmọ̀ ń gòkè lọ sí tẹmpili ní wákàtí àdúrà; tí í ṣe wákàtí mẹ́ta ọ̀sán.
A Piotr i Jan społem wstępowali do kościoła w godzinę modlitwy, dziewiątą.
2 Wọn sì gbé ọkùnrin kan ti ó yarọ láti inú ìyá rẹ̀ wá, tí wọ́n máa ń gbé kalẹ̀ lójoojúmọ́ ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili ti a ń pè ni Dáradára, láti máa ṣagbe lọ́wọ́ àwọn tí ń wọ inú tẹmpili lọ.
A mąż niektóry będąc chromy, zaraz z żywota matki swojej był noszony, którego na każdy dzień sadzano u drzwi kościelnych, które zwano piękne, aby prosił jałmużny od tych, którzy wchodzili do kościoła.
3 Nígbà tí ó rí Peteru àti Johanu bí wọn tí fẹ́ wọ inú tẹmpili, ó ṣagbe.
Ten ujrzawszy Piotra i Jana, że mieli wnijść do kościoła, prosił ich o jałmużnę.
4 Peteru sì tẹjúmọ́ ọn, pẹ̀lú Johanu, ó ní “Wò wá!”
A Piotr z Janem pilnie na niego patrząc, rzekli: Wejrzyj na nas!
5 Ó sì fiyèsí wọn, ó ń retí láti rí nǹkan láti gbà lọ́wọ́ wọn.
Tedy on z pilnością patrzał na nie, spodziewając się co wziąć od nich.
6 Peteru wí pé, “Wúrà àti fàdákà èmi kò ní, ṣùgbọ́n ohun tí mo ní èyí náà ni mo fi fún ọ. Ní orúkọ Jesu Kristi ti Nasareti, dìde kí o sì máa rìn.”
I rzekł Piotr: Srebra i złota nie mam; lecz co mam, to ci daję: W imieniu Jezusa Chrystusa Nazareńskiego wstań, a chodź.
7 Ó sì fà á lọ́wọ́ ọ̀tún, ó sì gbé dìde; lójúkan náà ẹsẹ̀ rẹ̀ àti egungun kókósẹ̀ rẹ̀ sì mókun.
A ująwszy go za prawą rękę jego, podniósł go, a zarazem utwierdzone były nogi jego i kostki.
8 Ó sì ń fò sókè, ó dúró, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí rìn, ó sì bá wọn wọ inú tẹmpili lọ, ó ń rìn, ó sì ń fò, ó sì yín Ọlọ́run.
I wyskoczywszy, stanął i chodził, a wszedł z nimi do kościoła, chodząc i skacząc, a chwaląc Boga.
9 Gbogbo ènìyàn sì rí i, ó ń rìn, ó sì yin Ọlọ́run,
A widział go wszystek lud chodzącego i chwalącego Boga.
10 Wọn sì mọ̀ pé òun ni ó ti jókòó tí ń ṣagbe ní ẹnu-ọ̀nà Dáradára ti tẹmpili náà; hà, sì ṣe wọn, ẹnu sì yà wọn gidigidi sí ohun tí ó ṣe lára rẹ̀.
I poznali go, iż to on był, który dla jałmużny siadał u drzwi pięknych kościelnych; i napełnieni są strachu i zdumienia nad tem, co mu się stało.
11 Bí arọ ti a mú láradá sì ti di Peteru àti Johanu mú, gbogbo ènìyàn jùmọ̀ súre tọ̀ wọ́n lọ ni ìloro ti a ń pè ní ti Solomoni, pẹ̀lú ìyàlẹ́nu ńlá.
A gdy się trzymał on chromy, który był uzdrowiony, Piotra i Jana, zbieżał się do nich wszystek lud do przysionka, który zwano Salomonowym, zdumiawszy się.
12 Nígbà tí Peteru sì rí i, ó dáhùn, ó wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, èéṣe tí háà fi ń ṣe yín sí èyí? Tàbí èéṣe ti ẹ̀yin fi tẹjúmọ́ wa, bí ẹni pé agbára tàbí ìwà mímọ́ wa ni àwa fi ṣe é ti ọkùnrin yìí fi ń rìn?
Co widziąc Piotr, przemówił do ludu: Mężowie Izraelscy! cóż się temu dziwujecie, albo czemu się nam tak pilnie przypatrujecie, jakobyśmy to własną mocą albo pobożnością uczynili, aby ten chodził?
13 Ọlọ́run Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, Ọlọ́run àwọn baba wa, òun ni ó ti yin Jesu ìránṣẹ́ rẹ̀ lógo; ẹni tí ẹ̀yin ti fi lé wọn lọ́wọ́, tí ẹ̀yin sì sẹ́ níwájú Pilatu, nígbà tí ó ti pinnu rẹ̀ láti dá a sílẹ̀.
Bóg Abrahama i Izaaka i Jakóba, Bóg ojców naszych, uwielbił Jezusa, Syna swego, któregoście wy wydali i zaparliście się go przed twarzą Piłatową, który go sądził być godnym wypuszczenia.
14 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ṣẹ́ Ẹni Mímọ́ àti Olóòótọ́ náà, ẹ̀yin sì béèrè kí a fi apànìyàn fún un yín.
A wyście się onego świętego i sprawiedliwego zaparli, a prosiliście o mężobójcę, aby wam był darowany.
15 Ẹ̀yin sì pa ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìyè, ẹni tí Ọlọ́run sì ti jí dìde kúrò nínú òkú; ẹlẹ́rìí èyí ti àwa jẹ́.
I zabiliście dawcę żywota, którego Bóg wzbudził od umarłych, czego my świadkami jesteśmy.
16 Nípa ìgbàgbọ́ nínú orúkọ Jesu, òun ni ó mú ọkùnrin yìí láradá, ẹni tí ẹ̀yin rí, tí ẹ sì mọ̀. Orúkọ Jesu àti ìgbàgbọ́ tí ó wá nípa rẹ̀ ni ó fún un ní ìlera pípé ṣáṣá yìí ni ojú gbogbo yín.
A przez wiarę w imię jego, tego, którego wy widzicie i znacie, utwierdziło imię jego; wiara, mówię, która przez niego jest, dała temu to zupełne zdrowie przed obliczem was wszystkich.
17 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ará, mo mọ̀ pé nípa àìmọ̀ ni ẹ̀yin fi ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àwọn olórí yín pẹ̀lú ti ṣe.
Ale teraz, bracia! wiem, żeście to z niewiadomości uczynili, jako i książęta wasi.
18 Ṣùgbọ́n báyìí ni Ọlọ́run ti ṣe ìmúṣẹ àwọn ohun tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu gbogbo àwọn wòlíì pé, Kristi rẹ̀ yóò jìyà.
Lecz Bóg, co przez usta wszystkich proroków swoich przepowiedział, iż Chrystus jego cierpieć miał, to tak ziścił.
19 Nítorí náà ẹ ronúpìwàdà, kí ẹ sì yípadà sí Ọlọ́run, kí a lè pa ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́, kí àkókò ìtura bá a lè ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,
Przetoż pokutujcie, a nawróćcie się, aby były zgładzone grzechy wasze.
20 àti kí ó ba à lè rán Kristi tí a ti yàn fún yín tẹlẹ̀: àní Jesu.
Gdyby przyszły czasy ochłody od obliczności Pańskiej, a posłałby onego, który wam opowiedziany jest, Jezusa Chrystusa.
21 Ẹni tí ọ̀run kò lé ṣàìmá gbà títí di ìgbà ìmúpadà ohun gbogbo, tí Ọlọ́run ti sọ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tí wọn ti ń bẹ nígbà tí ayé ti ṣẹ̀. (aiōn )
Który zaiste niebiosa ma objąć aż do czasu naprawienia wszystkich rzeczy, co był przepowiedział Bóg przez usta wszystkich świętych swoich proroków od wieków. (aiōn )
22 Mose wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run yín yóò gbé wòlíì kan dìde fún yín nínú àwọn arákùnrin yín, bí èmi; òun ni ẹ̀yin yóò máa gbọ́ tirẹ̀ ní ohun gbogbo tí yóò máa sọ fún un yín.
Albowiem Mojżesz do ojców rzekł: Proroka wam wzbudzi Pan, Bóg wasz, z braci waszych, jako mię; onego słuchać będziecie we wszystkiem, cokolwiek do was mówić będzie.
23 Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ọkàn ti kò bá gbọ́ ti wòlíì náà, òun ni a ó parun pátápátá kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’
I stanie się, że każda dusza, która by nie słuchała tego proroka, będzie wygładzona z ludu.
24 “Àní, gbogbo àwọn wòlíì láti Samuẹli wá, àti àwọn tí ó tẹ̀lé e, iye àwọn tí ó ti sọ̀rọ̀, wọn sọ ti ọjọ́ wọ̀nyí pẹ̀lú.
Aleć i wszyscy prorocy od Samuela i od innych po nim, ilekolwiek ich mówiło, przepowiadali też te dni.
25 Ẹ̀yin ni ọmọ àwọn wòlíì, àti ti májẹ̀mú tí Ọlọ́run ti bá àwọn baba yín dá nígbà tí ó wí fún Abrahamu pé, ‘Láti ipasẹ̀ irú àwọn ọmọ rẹ̀ ni a ó ti bùkún fún gbogbo ìdílé ayé.’
Wy jesteście synami prorockimi i przymierza, które postanowił Bóg z ojcami naszymi, mówiąc do Abrahama: A w nasieniu twojem błogosławione będą wszystkie narody ziemi.
26 Nígbà ti Ọlọ́run jí Jesu Ọmọ rẹ̀ dìde, ó kọ́ rán an sí i yín láti bùkún fún un yín, nípa yíyí olúkúlùkù yín padà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀.”
Wamci naprzód Bóg wzbudziwszy Syna swego Jezusa, posłał go, aby wam błogosławił; żeby się każdy z was odwrócił od złości swoich.