< Acts 26 >
1 Agrippa sì wí fún Paulu pé, “A fún ọ láààyè láti sọ tí ẹnu rẹ.” Nígbà náà ní Paulu ná ọwọ́, ó sì sọ ti ẹnu rẹ pé,
Potom Agrippa řekl Pavlovi: Dopouštíť se, abys sám za sebe promluvil. Tedy Pavel vztáh ruku, mluvil:
2 “Agrippa ọba, inú èmi tìkára mi dùn nítorí tí èmi yóò wí ti ẹnu mi lónìí níwájú rẹ, ní ti gbogbo ẹ̀sùn tí àwọn Júù fi kan mi,
Na všecky ty věci, z kterýchž mne viní Židé, králi Agrippo, za šťastného se počítám, že dnes před tebou odpovídati mám,
3 pàápàá bí ìwọ tí mọ gbogbo àṣà àti ọ̀ràn tí ń bẹ́ láàrín àwọn Júù dájúdájú. Nítorí náà, èmi bẹ̀ ọ́ kí ìwọ fi sùúrù tẹ́tí gbọ́ tèmi.
A zvláště proto, poněvadž jsi ty povědom všech těch, kteříž u Židů jsou, obyčejů a otázek. Protož prosím tebe, vyslyšiž mne trpělivě.
4 “Àwọn Júù mọ irú ìgbé ayé tí mo ń gbé láti ìgbà èwe mi, láti ìbẹ̀rẹ̀ ayé mi ní orílẹ̀-èdè mi àti ní Jerusalẹmu.
O životu mém hned od mladosti mé, jaký byl od počátku v národu mém v Jeruzalémě, vědí všickni Židé,
5 Nítorí wọ́n mọ̀ mi láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, bí wọ́n bá fẹ́ jẹ́rìí sí i, wí pé, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìsìn wa tí ó lè jùlọ, Farisi ni èmi.
Měvše mne prve zdávna v dobré známosti, (kdyby chtěli svědectví vydati, ) kterak vedle nejjistší sekty v našem náboženství byl jsem živ farizeus.
6 Nísinsin yìí nítorí ìrètí ìlérí tí Ọlọ́run tí ṣe fún àwọn baba wa ni mo ṣe dúró níhìn-ín fún ìdájọ́.
A nyní pro naději toho zaslíbení, kteréž se stalo otcům našim od Boha, teď stojím, soudu jsa poddán,
7 Ìlérí èyí tí àwọn ẹ̀yà wa méjèèjìlá tí ń fi ìtara sin Ọlọ́run lọ́sàn án àti lóru tí wọ́n ń retí àti rí i gbà. Ọba Agrippa, nítorí ìrètí yìí ni àwọn Júù ṣe ń fi mi sùn.
K kterémužto zaslíbení dvanáctero pokolení naše, sloužíce Bohu ustavičně dnem i nocí, naději má, že přijde; pro kteroužto naději žalují na mne Židé, ó králi Agrippo.
8 Èéṣe tí ẹ̀yin fi rò o sí ohun tí a kò lè gbàgbọ́ bí Ọlọ́run bá jí òkú dìde?
A tak-liž se to od vás za nepodobné k víře soudí, že Bůh křísí mrtvé?
9 “Èmi tilẹ̀ rò nínú ará mi nítòótọ́ pé, ó yẹ ki èmi ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun lòdì sí orúkọ Jesu tí Nasareti.
Ačť i mně se zdálo, že by mi náležité bylo, proti jménu Ježíše Nazaretského mnoho odporného činiti,
10 Èyí ni mo sì ṣe ni Jerusalẹmu. Pẹ̀lú àṣẹ tí mo tí gba lọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà, mo sọ àwọn púpọ̀ nínú àwọn ènìyàn mímọ́ sí inú túbú, nígbà tí wọ́n sí ń pa wọ́n, mo ní ohùn sí i.
Jakož jsem i činil v Jeruzalémě, a mnohé z svatých já jsem do žalářů dával, vzav moc od předních kněží. A když měli mordováni býti, já jsem pomáhal ortele vynášeti.
11 Nígbà púpọ̀ ni mo ń fi ìyà jẹ wọ́n láti inú Sinagọgu dé inú Sinagọgu, mo ń fi tipá mú wọn láti sọ ọ̀rọ̀-òdì. Mo sọ̀rọ̀ lòdì sí wọn gidigidi, kódà mo wá wọn lọ sí ìlú àjèjì láti ṣe inúnibíni sí wọn.
A po všech školách často trápě je, přinucoval jsem, aby se rouhali; a náramně rozlítiv se na ně, protivil jsem se jim, až i do jiných měst na to jsem jezdil.
12 “Nínú irú ìrìnàjò yìí ní mo ń bá lọ sí Damasku pẹ̀lú ọlá àti àṣẹ ikọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà.
A v tom, když jsem šel do Damašku, s mocí a s poručením předních kněží,
13 Ni ọ̀sán gangan, ìwọ ọba Agrippa, bí mo ti wà ní ojú ọ̀nà, mo rí ìmọ́lẹ̀ kan láti ọ̀run wá, tí ó mọ́lẹ̀ ju oòrùn lọ, ó mọ́lẹ̀ yí mi ká, àti àwọn tí ń bá mi lọ sì àjò.
O poledni na cestě, ó králi, uzřel jsem, ano světlo s nebe, jasnější nad blesk slunečný, obklíčilo mne, i ty, kteříž se mnou šli.
14 Gbogbo wa sì ṣubú lulẹ̀, mo gbọ́ ohùn tí ń fọ sì mi ni èdè Heberu pé, ‘Saulu, Saulu! Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi? Ohun ìrora ní fún ọ láti tàpá sí ẹ̀gún!’
A když jsme my všickni na zem padli, slyšel jsem hlas mluvící ke mně a řkoucí Židovským jazykem: Saule, Saule, proč mi se protivíš? Tvrdoť jest tobě proti ostnům se zpěčovati.
15 “Èmi sì wí pé, ‘Ìwọ ta ni, Olúwa?’ “Olúwa sì wí pé, ‘Èmi ni Jesu tí ìwọ ń ṣe inúnibíni sí.
A já řekl: I kdo jsi, Pane? A on řekl: Já jsem Ježíš, kterémuž ty se protivíš.
16 Ṣùgbọ́n dìde, kí o sí fi ẹsẹ̀ rẹ tẹlẹ̀: nítorí èyí ni mo ṣe farahàn ọ́ láti yàn ọ́ ní ìránṣẹ́ àti ẹlẹ́rìí, fún ohun wọ̀nyí tí ìwọ tí rí nípa mi, àti àwọn ohun tí èmi yóò fi ara hàn fún ọ.
Ale vstaň a stůj na nohách svých; nebo protoť jsem se tobě ukázal, ať bych tebe učinil služebníkem a svědkem i těch věcí, kteréž jsi viděl, i těch, v kterýchžto ukazovati se budu tobě,
17 Èmi yóò gbà ọ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn rẹ àti lọ́wọ́ àwọn aláìgbàgbọ́. Èmi rán ọ sí wọn nísinsin yìí
Vysvobozuje tebe z lidu tohoto, i z pohanů, k nimž tě nyní posílám,
18 láti là wọ́n lójú, kí wọn lè yípadà kúrò nínú òkùnkùn sí ìmọ́lẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ agbára Satani sí Ọlọ́run, kí wọn lè gba ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀, àti ogún pẹ̀lú àwọn tí a sọ di mímọ́ nípa ìgbàgbọ́ nínú mi.’
Otvírati oči jejich, aby se obrátili od temností k světlu a z moci ďábelské k Bohu, aby tak hříchů odpuštění a díl s posvěcenými vzali skrze víru, kteráž jest ve mne.
19 “Nítorí náà, Agrippa ọba, èmi kò ṣe àìgbọ́ràn sì ìran ọ̀run náà.
A protož, ó králi Agrippo, nebyl jsem nevěřící nebeskému vidění.
20 Ṣùgbọ́n mo kọ́kọ́ sọ fún àwọn tí ó wà ní Damasku, àti ní Jerusalẹmu, àti já gbogbo ilẹ̀ Judea, àti fún àwọn kèfèrí, kí wọn ronúpìwàdà, kí wọ́n sì yípadà sí Ọlọ́run, kí wọn máa ṣe iṣẹ́ tí ó yẹ sì ìrònúpìwàdà.
Ale hned nejprv těm, kteříž jsou v Damašku a v Jeruzalémě, i po vší krajině Judské, potom i pohanům zvěstoval jsem evangelium, aby pokání činili a obrátili se k Bohu, skutky hodné pokání činíce.
21 Nítorí nǹkan wọ̀nyí ni àwọn Júù ṣe gbá mi mú nínú tẹmpili, tí wọ́n sì ń fẹ́ pa mí.
A pro tu příčinu Židé javše mne v chrámě, pokoušeli se rukama svýma zamordovati.
22 Ṣùgbọ́n bí mo sì tí ri ìrànlọ́wọ́ gbà láti ọ́dọ̀ Ọlọ́run, mo dúró títí ó fi di òní, mo ń jẹ́rìí fún èwe àti àgbà, èmi kò sọ ohun mìíràn bí kò ṣe ohun tí àwọn wòlíì àti Mose tí wí pé, yóò ṣẹ.
Ale s pomocí Boží ještě až do dnešního dne stojím, vydávaje svědectví i malému i velikému, nic jiného nevypravuje, než to, což jsou Proroci a Mojžíš zvěstovali, že se mělo státi:
23 Pé, Kristi yóò jìyà, àti pé òun ni yóò jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ láti jíǹde kúrò nínú òkú, òun ni yóò sí kéde ìmọ́lẹ̀ fún àwọn ènìyàn àti fún àwọn aláìgbàgbọ́.”
Totiž, že měl Kristus trpěti, a z mrtvých vstana první, zvěstovati světlo lidu tomuto i pohanům.
24 Bí ó sì ti ń sọ tẹnu rẹ̀, Festu wí ní ohùn rara pé, “Paulu! Orí rẹ dàrú; ẹ̀kọ́ àkọ́jù rẹ ti dà ọ́ ní orí rú!”
To když od sebe promluvil Pavel, Festus hlasem velikým řekl: Blázníš, Pavle. Mnohé tvé umění k bláznovství tebe přivodí.
25 Paulu dalóhùn wí pé, “Orí mi kò dàrú, Festu ọlọ́lá jùlọ; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ òtítọ́ àti ọ̀rọ̀ òye ni èmi ń sọ jáde.
On pak řekl: Nebláznímť, výborný Feste, ale slova pravdy a středmosti mluvím.
26 Nítorí ọba mọ̀ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, níwájú ẹni tí èmi ń sọ̀rọ̀ ni àìbẹ̀rù: nítorí mo gbàgbọ́ pé ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò pamọ́ fún un, nítorí tí a kò ṣe nǹkan yìí ní ìkọ̀kọ̀.
Víť zajisté o těch věcech král, před kterýmž směle a svobodně mluvím; nebo mám za to, žeť ho nic z těchto věcí tajno není, poněvadž se toto nedálo pokoutně.
27 Agrippa ọba, ìwọ gba àwọn wòlíì gbọ́ bí? Èmi mọ̀ pé ìwọ gbàgbọ́.”
Věříš-li, králi Agrippo, Prorokům? Vím, že věříš.
28 Agrippa sì wí fún Paulu pé, “Ǹjẹ́ ìwọ lérò pé ìwọ le fi àkókò díẹ̀ yìí sọ mí di Kristiani?”
Tedy Agrippa řekl Pavlovi: Téměř bys mne k tomu naklonil, abych byl křesťanem.
29 Paulu sì dáhùn wí pé, “Ní àkókò kúkúrú tàbí gígùn, mo gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kí ó má ṣe ìwọ nìkan, ṣùgbọ́n kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ mi lónìí pẹ̀lú lè di irú ènìyàn tí èmi jẹ́ láìsí ẹ̀wọ̀n wọ̀nyí.”
A Pavel řekl: Žádalť bych od Boha, abyste i poněkud i z cela, netoliko ty, ale všickni, kteříž slyší mne dnes, byli takoví, jakýž já jsem, kromě okovů těchto.
30 Nígbà tí ó sì sọ nǹkan wọ̀nyí tan, ọba dìde, àti baálẹ̀, àti Bernike, àti àwọn tí o bá wọn jókòó,
A když to Pavel promluvil, vstal král, i vladař a Bernice, i ti, kteříž s nimi seděli.
31 Nígbà tí wọn wọ ìyẹ̀wù lọ, wọn bá ara wọn jíròrò, wọ́n sọ pé, “Ọkùnrin yìí kò ṣe nǹkan kan tí ó yẹ sí ikú tàbí sì ẹ̀wọ̀n.”
A odšedše na stranu, mluvili spolu, řkouce: Nic hodného smrti neb vězení nečiní člověk tento.
32 Agrippa sì wí fún Festu pé, “A bà dá ọkùnrin yìí sílẹ̀ bí ó bá ṣe pe kò ì tí ì fi ọ̀ràn rẹ̀ lọ Kesari.”
Agrippa pak Festovi řekl: Mohl propuštěn býti člověk tento, kdyby se byl neodvolal k císaři.