< Acts 24 >

1 Lẹ́yìn ọjọ́ márùn-ún Anania olórí àlùfáà náà sọ̀kalẹ̀ lọ pẹ̀lú àwọn alàgbà àti ẹnìkan, Tertulu agbẹjọ́rò, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ẹjọ́ Paulu fún baálẹ̀.
pa nchabhyo dinebhyaH paraM hanAnIyanAmA mahAyAjako. adhipateH samakShaM paulasya prAtikUlyena nivedayituM tartullanAmAnaM ka nchana vaktAraM prAchInajanAMshcha sa NginaH kR^itvA kaisariyAnagaram AgachChat|
2 Nígbà tí a sí tí pè Paulu jáde, Tertulu gbé ẹjọ́ rẹ̀ kalẹ̀ níwájú Feliksi ó wí pé, “Àwa ti wà ní àlàáfíà ní abẹ́ ìjọba rẹ láti ìgbà pípẹ́ wá, àti pé ìfojúsùn rẹ ti mú àyípadà rere bá orílẹ̀-èdè yìí.
tataH paule samAnIte sati tartullastasyApavAdakathAM kathayitum Arabhata he mahAmahimaphIlikSha bhavato vayam atinirvvighnaM kAlaM yApayAmo bhavataH pariNAmadarshitayA etaddeshIyAnAM bahUni ma NgalAni ghaTitAni,
3 Ní ibi gbogbo àti ní ọ̀nà gbogbo, Feliksi ọlọ́lá jùlọ, ní àwa ń tẹ́wọ́gbà á pẹ̀lú ọpẹ́ gbogbo.
iti heto rvayamatikR^itaj nAH santaH sarvvatra sarvvadA bhavato guNAn gAyamaH|
4 Ṣùgbọ́n kí èmi má ba á dá ọ dúró pẹ́ títí, mo bẹ̀ ọ́ kí o fi ìyọ́nú rẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ díẹ̀ lẹ́nu wa.
kintu bahubhiH kathAbhi rbhavantaM yena na vira njayAmi tasmAd vinaye bhavAn banukampya madalpakathAM shR^iNotu|
5 “Nítorí àwa rí ọkùnrin yìí, ó jẹ́ oníjàngbàn ènìyàn, ẹni tí ó ń dá rúkèrúdò sílẹ̀ láàrín gbogbo àwọn Júù tí ó wà ní gbogbo ayé. Òun ni aṣáájú búburú kan nínú ẹ̀yà àwọn Nasarene,
eSha mahAmArIsvarUpo nAsaratIyamatagrAhisaMghAtasya mukhyo bhUtvA sarvvadesheShu sarvveShAM yihUdIyAnAM rAjadrohAcharaNapravR^ittiM janayatItyasmAbhi rnishchitaM|
6 ẹni tí ó gbìyànjú láti ba tẹmpili jẹ́.
sa mandiramapi ashuchi karttuM cheShTitavAn; iti kAraNAd vayam enaM dhR^itvA svavyavasthAnusAreNa vichArayituM prAvarttAmahi;
7
kintu luShiyaH sahasrasenApatirAgatya balAd asmAkaM karebhya enaM gR^ihItvA
8 Nígbà tí ìwọ fúnra rẹ̀ bá wádìí ọ̀rọ̀ fínní fínní lẹ́nu rẹ̀, ìwọ ó lè ní òye òtítọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí àwa fi ẹ̀sùn rẹ̀ kàn án.”
etasyApavAdakAn bhavataH samIpam Agantum Aj nApayat| vayaM yasmin tamapavAdAmo bhavatA padapavAdakathAyAM vichAritAyAM satyAM sarvvaM vR^ittAntaM vedituM shakShyate|
9 Àwọn Júù pẹ̀lú sì fi ohùn sí i wí pé, ní òtítọ́ bẹ́ẹ̀ ni nǹkan wọ̀nyí rí.
tato yihUdIyA api svIkR^itya kathitavanta eShA kathA pramANam|
10 Nígbà tí baálẹ̀ ṣẹ́wọ́ sì i pé kí ó sọ̀rọ̀, Paulu sì dáhùn wí pe, “Bí mo tí mọ̀ pé láti ọdún mélòó yìí wá, ní ìwọ tí ṣe onídàájọ́ orílẹ̀-èdè yìí, nítorí náà mo fi tayọ̀tayọ̀ wí tí ẹnu mi.
adhipatau kathAM kathayituM paulaM pratI NgitaM kR^itavati sa kathitavAn bhavAn bahUn vatsarAn yAvad etaddeshasya shAsanaM karotIti vij nAya pratyuttaraM dAtum akShobho. abhavam|
11 Ìwọ pẹ̀lú sì ní òye rẹ̀ pé, ìjejìlá ni mo lọ sí Jerusalẹmu láti lọ jọ́sìn.
adya kevalaM dvAdasha dinAni yAtAni, aham ArAdhanAM karttuM yirUshAlamanagaraM gatavAn eShA kathA bhavatA j nAtuM shakyate;
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn olùfisùn mi kò rí mi kí ń máa bá ẹnikẹ́ni jiyàn nínú tẹmpili, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ru àwọn ènìyàn sókè nínú Sinagọgu tàbí ní ibikíbi nínú ìlú.
kintvibhe mAM madhyemandiraM kenApi saha vitaNDAM kurvvantaM kutrApi bhajanabhavane nagare vA lokAn kupravR^ittiM janayantuM na dR^iShTavantaH|
13 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò lè fi ìdí ẹ̀sùn múlẹ̀ níwájú rẹ, èyí tí wọn fi mí sùn sí nísinsin yìí.
idAnIM yasmin yasmin mAm apavadante tasya kimapi pramANaM dAtuM na shaknuvanti|
14 Ṣùgbọ́n, èmí jẹ́wọ́ fún ọ pé, èmi ń sin Ọlọ́run àwọn baba wa gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń tẹ̀lé ọ̀nà tí wọ́n ń pè ni ìyapa ìsìn. Èmi ń gbá gbogbo nǹkan ti a kọ sínú ìwé òfin gbọ́, àti tí a kọ sínú ìwé àwọn wòlíì,
kintu bhaviShyadvAkyagranthe vyavasthAgranthe cha yA yA kathA likhitAste tAsu sarvvAsu vishvasya yanmatam ime vidharmmaM jAnanti tanmatAnusAreNAhaM nijapitR^ipuruShANAm Ishvaram ArAdhayAmItyahaM bhavataH samakSham a NgIkaromi|
15 mo sí ní ìrètí kan náà nínú Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí àwọn tìkára wọn jẹ́wọ́ pẹ̀lú, wí pé àjíǹde òkú ń bọ̀, àti tí olóòtítọ́, àti tí aláìṣòótọ́.
dhArmmikANAm adhArmmikANA ncha pramItalokAnAmevotthAnaM bhaviShyatIti kathAmime svIkurvvanti tathAhamapi tasmin Ishvare pratyAshAM karomi;
16 Nínú èyí ni èmi sì ti ń gbìyànjú láti ní ẹ̀rí ọkàn tí kò lẹ́sẹ̀ sí Ọlọ́run, àti sí ènìyàn nígbà gbogbo.
Ishvarasya mAnavAnA ncha samIpe yathA nirdoSho bhavAmi tadarthaM satataM yatnavAn asmi|
17 “Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ọdún púpọ̀, mo wá sí Jerusalẹmu láti mu ẹ̀bùn wá fún àwọn ènìyàn mi fún aláìní àti láti fi ọrẹ lélẹ̀.
bahuShu vatsareShu gateShu svadeshIyalokAnAM nimittaM dAnIyadravyANi naivedyAni cha samAdAya punarAgamanaM kR^itavAn|
18 Nínú ṣíṣe nǹkan wọ̀nyí, wọ́n rí mí nínú ìyẹ̀wù tẹmpili, bí mo ti ń parí ètò ìwẹ̀nù, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ní àárín àwùjọ ènìyàn, tàbí pẹ̀lú ariwo.
tatohaM shuchi rbhUtvA lokAnAM samAgamaM kalahaM vA na kAritavAn tathApyAshiyAdeshIyAH kiyanto yihudIyalokA madhyemandiraM mAM dhR^itavantaH|
19 Ṣùgbọ́n àwọn Júù kan láti ẹkùn Asia wà níbẹ̀, àwọn tí ìbá wà níhìn-ín yìí níwájú rẹ, kí wọn já mi nírọ́, bí wọ́n bá ní ohunkóhun sí mi.
mamopari yadi kAchidapavAdakathAsti tarhi bhavataH samIpam upasthAya teShAmeva sAkShyadAnam uchitam|
20 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, jẹ́ kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí tìkára wọn sọ iṣẹ́ búburú tí wọ́n rí lọ́wọ́ mi, nígbà tí mo dúró níwájú àjọ ìgbìmọ̀.
nochet pUrvve mahAsabhAsthAnAM lokAnAM sannidhau mama daNDAyamAnatvasamaye, ahamadya mR^itAnAmutthAne yuShmAbhi rvichAritosmi,
21 Bí kò ṣe tí gbólóhùn kan yìí, tí mo kégbe rẹ̀ síta nígbà tí mo dúró láàrín wọn: ‘Èyí ni tìtorí àjíǹde òkú ni a ṣe ba mi wíjọ́ lọ́dọ̀ yín ló ni yìí!’”
teShAM madhye tiShThannahaM yAmimAM kathAmuchchaiH svareNa kathitavAn tadanyo mama kopi doSho. alabhyata na veti varam ete samupasthitalokA vadantu|
22 Nígbà tí Feliksi gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, òye sá à ye é ní àyétán nípa ọ̀nà náà; ó tú wọn ká ná, ó ní, “Nígbà tí Lisia olórí ogun bá sọ̀kalẹ̀ wá, èmi ó wádìí ọ̀ràn yín dájú.”
tadA phIlikSha etAM kathAM shrutvA tanmatasya visheShavR^ittAntaM vij nAtuM vichAraM sthagitaM kR^itvA kathitavAn luShiye sahasrasenApatau samAyAte sati yuShmAkaM vichAram ahaM niShpAdayiShyAmi|
23 Ó sì pàṣẹ fún balógun ọ̀run kan kí ó máa ṣe ìtọ́jú Paulu, kí ó fún un ní ààyè, àti pé kí ó má ṣe dá àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ lẹ́kun láti máa ṣe ìránṣẹ́ fún un.
anantaraM bandhanaM vinA paulaM rakShituM tasya sevanAya sAkShAtkaraNAya vA tadIyAtmIyabandhujanAn na vArayitu ncha shamasenApatim AdiShTavAn|
24 Lẹ́yìn ọjọ́ mélòó kan Feliksi pẹ̀lú Drusilla ìyàwó rẹ̀ dé, obìnrin tí í ṣe Júù. Ó ránṣẹ́ pé Paulu, ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu rẹ̀ nípa ìgbàgbọ́ nínú Kristi Jesu.
alpadinAt paraM phIlikSho. adhipati rdruShillAnAmnA yihUdIyayA svabhAryyayA sahAgatya paulamAhUya tasya mukhAt khrIShTadharmmasya vR^ittAntam ashrauShIt|
25 Bí Paulu sì tí ń sọ àsọyé nípa tí òdodo àti àìrékọjá àti ìdájọ́ tí ń bọ̀, ẹ̀rù ba Feliksi, ó dáhùn wí pé, “Èyí tí o sọ nì tó ná! Máa lọ nísinsin yìí ná. Nígbà tí mo bá sì ní àkókò tí ó wọ̀, èmi ó ránṣẹ́ pè ọ́.”
paulena nyAyasya parimitabhogasya charamavichArasya cha kathAyAM kathitAyAM satyAM phIlikShaH kampamAnaH san vyAharad idAnIM yAhi, aham avakAshaM prApya tvAm AhUsyAmi|
26 Ní àkókò yìí kan náà, ó ń retí pẹ̀lú pé Paulu yóò mú owó ẹ̀yìn wá fún òun, kí òun ba à lè dá a sílẹ̀, nítorí náà a sì máa ránṣẹ́ sì í nígbàkígbà, a máa bá a sọ̀rọ̀.
muktipraptyarthaM paulena mahyaM mudrAdAsyante iti patyAshAM kR^itvA sa punaH punastamAhUya tena sAkaM kathopakathanaM kR^itavAn|
27 Lẹ́yìn ọdún méjì, Porkiu Festu rọ́pò Feliksi, Feliksi sì ń fẹ́ ṣe ojúrere fún àwọn Júù, ó fi Paulu sílẹ̀ nínú túbú.
kintu vatsaradvayAt paraM parkiyaphIShTa phAlikShasya padaM prApte sati phIlikSho yihUdIyAn santuShTAn chikIrShan paulaM baddhaM saMsthApya gatavAn|

< Acts 24 >