< Acts 23 >

1 Paulu tẹjúmọ́ ìgbìmọ̀, ó sì wí pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi tí ń fi gbogbo ẹ̀rí ọkàn rere lo ayé mi níwájú Ọlọ́run títí fi di òní yìí.”
Paul ing Sanhedrinkhqi ce toek khqi ceet ceet nawh, “Ka koeinaakhqi, tuhngawi dy awh kawpoek dyngnaak ing Khawsa bi ce bi nyng,” tinak khqi hy.
2 Nígbà yìí ni Anania olórí àlùfáà pàṣẹ fún àwọn tí ó dúró tí Paulu pé, kí wọn ó gbá a lẹ́nu.
Ce ak awi ce ang zaak awh khawsoih boeikhyt Ananias ing Paul a venawh ak dyikhqi venawh Paul ce am kha awh vyk aham awi pehy.
3 Nígbà náà ni Paulu wí fún un pé, “Ọlọ́run yóò lù ọ́, ìwọ ògiri tí a kùn lẹ́fun: ìwọ jókòó láti dá mi lẹ́jọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin, ṣùgbọ́n ìwọ gan an rú òfin nípa pípàṣẹ pé kí a lù mí!”
Cawh Paul ing, “Nang ak baawkna amik thuut vawng, Khawsa ing namah ni vyk kaw! Anaa awi amyihna kai awideng aham cawh ngawi hyk ti, cehlai namah ing kai vyk aham awi pe tiksaw anaa awi ce hqe nawn hyk ti! tina hy.
4 Àwọn tí ó dúró tì Paulu sì wí pé, “Ìwọ́ ń gan olórí àlùfáà Ọlọ́run?”
Paul a venawh ak dyikhqi ing, “Khawsa a khawsoeih boei khyt awm na zyih hy? tina uhy.
5 Paulu sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi kò mọ̀ pé olórí àlùfáà ni: nítorí a tí kọ ọ́ pé, ‘Ìwọ kò gbọdọ̀ sọ̀rọ̀ olórí àwọn ènìyàn rẹ̀ ní búburú.’”
Paul ing, “Koeinaakhqi, anih ve khawsoeih boei khyt tinawh am ka sim dawngawh ni; ‘Nak thlangkhqi ak ukkung ce awih che ing koeh zyi,’ tinawh a qee awm zawk hy,” tinak khqi hy.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí Paulu ṣàkíyèsí pé, apá kan wọn jẹ́ Sadusi, apá kan sì jẹ́ Farisi, ó kígbe ní ìgbìmọ̀ pé, “Ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi jẹ́ Farisi, ọmọ Farisi sì ni èmi. Mo dúró ní ìdájọ́ nítorí ìrètí mi nínú àjíǹde òkú.”
Cawhkaw amik awmkhqi ak khuiawh thlang vang taw Sadusikhqi na awm nawh, thlang vang taw Farasikhqi na awm uhy, tice Paul ing a huh awh, cawhkaw Sanhedrinkhqi venawh, “Koeinaa khqi, kai ve Farasi capa na ka awm dawngawh Farasi na awm nyng. Thlakthi thawh tlaih ngaih-uunaak ka taak dawngawh tuh awidengnaak hun awh dyi nyng,” tinak khqi hy.
7 Nígbà tí ó sì tí wí èyí, ìyapa dé láàrín àwọn Farisi àti àwọn Sadusi: àjọ sì pín sì méjì.
Ce ak awi ce ak kqawn awh, Farasikhqi ingkaw Sadusikhqi ce oelh qu unawh, pakkhih na pek qu uhy.
8 Nítorí tí àwọn Sadusi wí pé, kò sì àjíǹde, tàbí angẹli, tàbí ẹ̀mí: ṣùgbọ́n àwọn Farisi jẹ́wọ́ méjèèjì.
(Sasusikhqi ingtaw, thlakthi thawh tlaihnaak am awm hy, khan ceityih awm am awm nawh myihla awm am awm hy, ti uhy, cehlai Farasikhqi ingtaw vemyihkhqi boeih ve awm hy, ti uhy.)
9 Ó sì di ariwo ńlá, nínú àwọn olùkọ́ òfin tí ó wà ni apá tí àwọn Farisi dìde, wọ́n ń jà, wí pé, “Àwa kò rí ohun búburú kan lára ọkùnrin yìí,” wọ́n wí “àwa kò sì mọ̀ nítòótọ́ bí angẹli kan tàbí ẹ̀mí kan ń ba à sọ̀rọ̀?”
Cawh a mimah ce hqo unawh, a mingmih anglak awhkaw anaa awi ak qeekung Farasi thlang vang ce dyi unawh oelh uhy. Cekkhqi ing, “Ve ak thlang awh ve a thawlhnaak ikaw awm am awm hy. Myihla ing nu khan ceityih ing nu awi ak kqawn peek mai mantaw ikawmyihna ni ti hly?” ti uhy.
10 Nígbà tí ìyapa sì di ńlá, tí olórí ogun bẹ̀rù kí Paulu má ba à di fífàya lọ́wọ́ wọn, ó pàṣẹ pé ki àwọn ọmọ-ogun sọ̀kalẹ̀ lọ láti fi ipá mú un kúrò láàrín wọn, kí wọn sì mú un wá sínú àgọ́ àwọn ológun.
A ming oelh qu khqoet khqoet awh qaalboei ing Paul khqaak kawm uh a ti awh, qalkapkhqi ce tyi khqi nawh Paul ce a mingmih a venawh kawng qalkapkhqi awmnaak na lawh sak khqi hy.
11 Ní òru ọjọ́ náà Olúwa dúró tì Paulu, ó wí pé, “Mú ọkàn le! Bí ìwọ ti jẹ́rìí fún mi ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò lè ṣàìjẹ́rìí ni Romu pẹ̀lú.”
Khawmthan awh Bawipa ing Paul a venawh dang pe nawh, “Nam thin cak sak! Jerusalem khawk khuiawh kai akawng nang dyih pyi amyih na, Rom awh awm kai ve ning dyih pyi hly bai hyk ti,” tina hy.
12 Nígbà tí ilẹ̀ mọ́, àwọn Júù kan dìtẹ̀, wọ́n fi ara wọn bú pé, àwọn kì yóò jẹ, bẹ́ẹ̀ ní àwọn kì yóò mú títí àwọn ó fi pa Paulu.
A khawngawi mymcang awh Paul him hlan dy taw buh a an ama ai aham Juda thlangkhqi ing awi kam uhy.
13 Àwọn tí ó dìtẹ̀ yìí sì ju ogójì ènìyàn lọ.
Vemyihna Paul him aham ak tengkhqi ce thlang phlikip hlai law uhy.
14 Wọ́n sì tọ olórí àwọn àlùfáà àti àwọn alàgbà lọ, wọn sì wí pé, “Àwa tí fi ara wa sínú ìdè ìbúra pé, a kì yóò tọ́ oúnjẹ kan wò títí àwa ó fi pa Paulu.
Cekkhqi ing khawsoeih boeikhqi ingkaw a hqamcakhqi venna cet unawh, “Paul am ka mi him hlan dy taw buh an am kami ai aham awi kam unyng.
15 Ǹjẹ́ nísinsin yìí kí ẹ̀yin pẹ̀lú àjọ ìgbìmọ̀ wí fún olórí ogun, kí ó mú un sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá, bí ẹni pé ẹ̀yin ń fẹ́ wádìí ọ̀ràn rẹ̀ dájúdájú. Kí ó tó súnmọ́ tòsí, àwa ó ti múra láti pa á.”
Cedawngawh tuh nangmih ingkaw Sanhedrinkhqi ing ve akawng ve ak caih na sim thainaak aham anih ce nangmih a venawh ami tyih law tlaihnaak aham qaalboei a venawh thoeh uh. Cawh ve a pha law hlan awh lam lakawh kaimih ing him vang unyng,” tinak khqi uhy.
16 Nígbà tí ọmọ arábìnrin Paulu sí gbúròó ìdìtẹ̀ wọn, ó lọ, ó sì wọ inú àgọ́ àwọn ológun lọ, ó sì sọ fún Paulu.
Cehlai cawhkaw awi ce Paul a koeinanu a capa ing za nawh, qalkapkhqi awmnaak na a ceh awh Paul a venawh kqawn pehy.
17 Paulu sì pé ọ̀kan nínú àwọn balógun ọ̀run sọ́dọ̀ rẹ̀, ó ní, “Mú ọmọkùnrin yìí tọ olórí ogun lọ, nítorí ó ní nǹkan láti sọ fún un.”
Cedawngawh Paul ing qalkap zakhat ak ukkung thlang pynoet ce khy nawh, “Vawhkaw cadawng ve qaalboei a venna ceh pyi lah; awi pynoet kqawn peek aham ngaih hy,” tina hy.
18 Ó mú un, ó sì sìn ín lọ sọ́dọ̀ olórí ogun. Balógun ọ̀rún náà wí pé, “Paulu òǹdè pè mi sọ́dọ̀ rẹ̀, ó síbẹ̀ mí pé ki èmi mú ọmọkùnrin yìí tọ̀ ọ́ wá, ẹni tí ó ní nǹkan láti sọ fún ọ.”
Cedawngawh anih ing ce ceh pyi hy. Qalkap ukkung ing, “Thawngim ak tla Paul ing vawhkaw cadawng ve na venawh awi kqawn aham a ngaih dawngawh ceh pyi tinawh law pyi nyng,” tina hy.
19 Alábojútó-ogun fà á lọ́wọ́, ó sì lọ si apá kan, ó sì bi í léèrè níkọ̀kọ̀ pé, “Kín ni ohun tí ìwọ ní sọ fún mi?”
Qaalboei ing cadawng ca ce a kut awh tu nawh ak chang na sawi nawh doet hy, “Kawmyih ak awi nu kqawn aham na ngaih?” tina hy.
20 Ó sì wí pé, “Àwọn Júù fi ìmọ̀ ṣọ̀kan láti wá bẹ̀ ọ́, kí o mú Paulu sọ̀kalẹ̀ wá sí àjọ ìgbìmọ̀ ní ọ̀la, bí ẹni pé àwọn ń fẹ́ béèrè nǹkan dájúdájú nípa rẹ̀.
Anih ing, “Khawngawi awh Judakhqi ing Paul ve Sanherdrin haiawh awi ak caih na doet aham tina unawh nang a ven awhkawng thoeh u sih, tinawh awi kqawn hawh uhy.
21 Nítorí náà má ṣe gbọ́ tiwọn, nítorí àwọn tí ó dènà dè é nínú wọn ju ogójì ọkùnrin lọ, tí wọ́n fi ara wọn bú pé, àwọn kì yóò jẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn kì yóò mu títí àwọn o fi pa á. Wọ́n sì ti múra tan nísinsin yìí, wọ́n ń retí ìdáhùn lọ́dọ̀ rẹ.”
Cekkhqi venawh Paul ve koeh tyih pek khqi, ikawtih thlang phlikip hlai ing lam awh mah uhy. Paul a mami him hlan dy taw buh am ai aham awi kam hawh uhy. Tuh nang ak awi ni ami lamtoen hawh,” tina hy.
22 Nígbà náà ni olórí ogun fi ọmọ náà sílẹ̀ láti lọ, ó sí kìlọ̀ fún un pé, “Má ṣe wí fún ẹnìkan pé, ìwọ fi nǹkan wọ̀nyí hàn mi.”
Qaalboei ing cawhkaw cadawng ca ce a ceh sak coeng awh, “Ve ak awi nak kqawn law ve u a venawh awm koeh kqawn moe,” tina hy.
23 Ó sì pe méjì nínú àwọn balógun ọ̀run sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ múra igba ọmọ-ogun sílẹ̀, láti lọ sí Kesarea, àti àádọ́rin ẹlẹ́ṣin, àti igba ọlọ́kọ̀, ní wákàtí kẹta òru.
Anih ing qalkap zakhat ak ukkung pakkhih ce khy nawh, “Qalkap zanhih ingkaw, meqang awh ak ngawi thlang khqihkip ingkaw cai ak pawm thlang zanhih ce tawh khawthan khawnoek pakow awh Kaiserea na ceh aham a oepchoeh cana ta lah.
24 Ó sì wí pé, kí wọn pèsè ẹṣin, kí wọ́n gbé Paulu gùn ún; kí wọ́n sì lè mú un dé ọ̀dọ̀ Feliksi baálẹ̀ ní àlàáfíà.”
Qam ukkung Felix a venawh ak cym cana pha thainaak aham Paul ang ngawihnaak aham meqang ce hoep pe uh,” tina hy.
25 Ó sì kọ ìwé kan báyìí pé,
Ak kai awhkaw amyihna ca qee pehy:
26 Kilaudiu Lisia, sí Feliksi baálẹ̀ ọlọ́lá jùlọ, àlàáfíà.
Klaudias Lisias ing, Qam uk boei ak leek khyt Felix a venawh, “Kut ni tlaih nyng.
27 Àwọn Júù mú ọkùnrin yìí, wọ́n sì ń pète láti pa á, nígbà náà ni mo dé pẹ̀lú ogun, mo sì gbà á lọ́wọ́ wọn nígbà tí mo gbọ́ pé ará Romu ni í ṣe.
Ve ak thlang ve Judakhqi ing tu unawh him u sih ami ti awh, Rom thlang ni tice ka sim dawngawh, kai ing qalkapkhqi mi cet nawh hul nyng.
28 Nígbà tí mo sì ń fẹ́ mọ ìdí ọ̀ràn tí wọn fi ẹ̀sùn kàn án sí, mo mú un sọ̀kalẹ̀ lọ sí àjọ ìgbìmọ̀ wọn.
Ikawtih thawlh amak puk hy voei tice sim aham ka ngaih dawngawh a mimah a Semhedrin a haiawh dyih sak nyng.
29 Ẹni tí mo rí pé, wọ́n fi sùn nítorí ọ̀ràn òfin wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò dá ọ̀ràn ohun kan tí ó tọ́ sí ikú àti sí ẹ̀wọ̀n.
Cawhkaw thawlh amik puknaak ce a mimah a anaa awi ben ni tice sim nyng, cedawngawh thawng thlak aham ingkaw thih hly kawi dyna a thawlhnaak am awm hy, tinawh hu nyng.
30 Nígbà tí a sì tí jí i sọ fún mi pé, wọn yóò dènà de ọkùnrin náà, mo rán an sí ọ lọ́gán, mo sì pàṣẹ fún àwọn olùfisùn rẹ̀ pẹ̀lú, láti sọ ohun tí wọ́n bá rí wí sí i níwájú rẹ̀.
Anih ce him aham ang hyp na mah uhy tice amik kqawn law dawngawh, nang a venna ang tawnna tyi law nyng. Anih thawlh amik pukkhqi awm anih akawng kqawn aham tyi law pahoei nyng,” tinawh.
31 Nígbà náà ni àwọn ọmọ-ogun gbe Paulu, wọ́n sì mú un lóru lọ si Antipatrisi, gẹ́gẹ́ bí a tí pàṣẹ fún wọn.
Cedawngawh qalkapkhqi ing, awipeeknaak amyihna, khawmthan awh Paul ce Antipatris dyna ceh pyi uhy.
32 Ní ọjọ́ kejì wọ́n sì fi àwọn ẹlẹ́ṣin sílẹ̀ láti máa bá a lọ, àwọn sì padà wá sínú àgọ́ àwọn ológun.
A khawngawi awh meqang awh ak ngawikhqi mi Paul ce ami ceh sak haih awh, a mimah taw qalkap a awmnaak im na hlat tlaih uhy.
33 Nígbà tí wọ́n dé Kesarea, tí wọ́n sí fi ìwé fún baálẹ̀, wọ́n mú Paulu pẹ̀lú wá síwájú rẹ̀.
Meqang awh amik ngawikhqi ce Kaiserea khaw ami pha awh, qam uk boei venawh ca ce pe unawh, Paul ce ap uhy.
34 Nígbà tí ó sì ti ka ìwé náà, ó béèrè pé agbègbè ìlú wo ni tirẹ̀. Nígbà tí ó sì gbọ́ pé ará Kilikia ni;
Qam uk boei ing ca ce a noet coengawh han benna kaw thlang hy voei nu tice doet hy. Kilikia qam awhkaw thlang ni, tice a sim awh,
35 Ó wí pé, “Èmi yóò gbọ́ ẹjọ́ rẹ, nígbà tí àwọn olùfisùn rẹ pẹ̀lú bá dé.” Ó sì pàṣẹ pé kí wọn pa Paulu mọ́ ní abẹ́ àbojútó àwọn olùṣọ́ ní gbọ̀ngàn ìdájọ́ ààfin Herodu.
a venawh, “Nang thawlh anik pukkhqi ami pha law awh na kawng ve kqawn sih nyng,” tina hy. Cekcoengawh Paul ce amah a awmnaak Herod a im awh ak nep na taak aham awi pehy.

< Acts 23 >