< Acts 22 >

1 “Ẹ̀yin ará àti baba, ẹ gbọ́ tí ẹnu mi nísinsin yìí.”
ہے پِترِگَنا ہے بھْراترِگَناح، اِدانِیں مَمَ نِویدَنے سَمَوَدھَتَّ۔
2 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ pé ó ń bá wọn sọ̀rọ̀ ni èdè Aramaiki, wọ́n túbọ̀ dákẹ́ jẹ́ẹ́. Nígbà náà ni ó wí pé,
تَدا سَ اِبْرِییَبھاشَیا کَتھاں کَتھَیَتِیتِ شْرُتْوا سَرْوّے لوکا اَتِیوَ نِحشَبْدا سَنْتوتِشْٹھَنْ۔
3 “Júù ni èmi í ṣe, a bí mi ni Tarsu ìlú kan ní Kilikia, ṣùgbọ́n tí a tọ́ mi dàgbà ni ìlú yìí. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ Gamalieli ni a sì gbé kọ́ mi ní òfin àwọn baba wa, tí mo sì ní ìtara fún Ọlọ́run àní gẹ́gẹ́ bí gbogbo yin tí rí ni òní.
پَشْچاتْ سوکَتھَیَدْ اَہَں یِہُودِییَ اِتِ نِشْچَیَح کِلِکِیادیشَسْیَ تارْشَنَگَرَں مَمَ جَنْمَبھُومِح،ایتَنَّگَرِییَسْیَ گَمِلِیییلَنامْنودھْیاپَکَسْیَ شِشْیو بھُوتْوا پُورْوَّپُرُشاناں وِدھِوْیَوَسْتھانُسارینَ سَمْپُورْنَرُوپینَ شِکْشِتوبھَوَمْ اِدانِینْتَنا یُویَں یادرِشا بھَوَتھَ تادرِشوہَمَپِیشْوَرَسیوایامْ اُدْیوگِی جاتَح۔
4 Mo sì ṣe inúnibíni sí àwọn ènìyàn tí ń tọ ọ̀nà yìí dé ojú ikú wọn, mo dè tọkùnrin tobìnrin wọ́n, mo sì fi wọ́n sínú túbú,
مَتَمیتَدْ دْوِشْٹْوا تَدْگْراہِنارِیپُرُشانْ کارایاں بَدّھوا تیشاں پْرانَناشَپَرْیَّنْتاں وِپَکْشَتامْ اَکَرَوَمْ۔
5 àní bí olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo àjọ àwọn alàgbà tí lè jẹ́ mi ní ẹ̀rí. Mo tilẹ̀ gba ìwé àṣẹ lọ́wọ́ wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Damasku láti mú àwọn tí ó wà níbẹ̀ ní dídè wá sí Jerusalẹmu, láti jẹ wọ́n ní yà.
مَہایاجَکَح سَبھاسَدَح پْراچِینَلوکاشْچَ مَمَیتَسْیاح کَتھایاح پْرَمانَں داتُں شَکْنُوَنْتِ، یَسْماتْ تیشاں سَمِیپادْ دَمّیشَکَنَگَرَنِواسِبھْراترِگَنارْتھَمْ آجْناپَتْرانِ گرِہِیتْوا یے تَتْرَ سْتھِتاسْتانْ دَنْڈَیِتُں یِرُوشالَمَمْ آنَیَنارْتھَں دَمّیشَکَنَگَرَں گَتوسْمِ۔
6 “Bí èmi tí súnmọ́ etí Damasku níwọ̀n ọjọ́-kanrí, lójijì ìmọ́lẹ̀ ńlá láti ọ̀run wá mọ́lẹ̀ yí mi ká.
کِنْتُ گَچّھَنْ تَنَّگَرَسْیَ سَمِیپَں پْراپْتَوانْ تَدا دْوِتِییَپْرَہَرَویلایاں سَتْیامْ اَکَسْمادْ گَگَنانِّرْگَتْیَ مَہَتِی دِیپْتِ رْمَمَ چَتُرْدِشِ پْرَکاشِتَوَتِی۔
7 Mo sì ṣubú lulẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan tí ó wí fún mi pé, ‘Saulu, Saulu èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi?’
تَتو مَیِ بھُومَو پَتِتے سَتِ، ہے شَولَ ہے شَولَ کُتو ماں تاڈَیَسِ؟ مامْپْرَتِ بھاشِتَ ایتادرِشَ ایکو رَووپِ مَیا شْرُتَح۔
8 “Mo sì béèrè pé, ‘Ta ni ìwọ, Olúwa?’ “Ó sì dá mi lóhùn pé, ‘Èmi ni Jesu tí Nasareti, ẹni tí ìwọ ń ṣe inúnibíni sí.’
تَداہَں پْرَتْیَوَدَں، ہے پْرَبھے کو بھَوانْ؟ تَتَح سووادِیتْ یَں تْوَں تاڈَیَسِ سَ ناسَرَتِییو یِیشُرَہَں۔
9 Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi rí ìmọ́lẹ̀ náà nítòótọ́, ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ohùn ẹni tí ń bá mi sọ̀rọ̀.
مَمَ سَنْگِنو لوکاسْتاں دِیپْتِں درِشْٹْوا بھِیَں پْراپْتاح، کِنْتُ مامْپْرَتْیُدِتَں تَدْواکْیَں تے نابُدھْیَنْتَ۔
10 “Mo sí béèrè pé, ‘Kín ni kí èmí kí ó ṣe, Olúwa?’ “Olúwa sì wí fún mi pé, ‘Dìde, kí o sì lọ sí Damasku; níbẹ̀ ni a ó sì ti sọ ohun gbogbo fún ọ tí a yàn fún ọ láti ṣe.’
تَتَح پَرَں پرِشْٹَوانَہَں، ہے پْرَبھو مَیا کِں کَرْتَّوْیَں؟ تَتَح پْرَبھُرَکَتھَیَتْ، اُتّھایَ دَمّیشَکَنَگَرَں یاہِ تْوَیا یَدْیَتْ کَرْتَّوْیَں نِرُوپِتَماسْتے تَتْ تَتْرَ تْوَں جْناپَیِشْیَسے۔
11 Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi fà mí lọ́wọ́ wọ Damasku lọ nítorí tí èmi kò lè ríran nítorí ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ náà ti fọ́ mi ní ojú.
اَنَنْتَرَں تَسْیاح کھَرَتَرَدِیپْتیح کارَناتْ کِمَپِ نَ درِشْٹْوا سَنْگِگَنینَ دھرِتَہَسْتَح سَنْ دَمّیشَکَنَگَرَں وْرَجِتَوانْ۔
12 “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Anania tọ̀ mí wá, ẹni tó jẹ́ olùfọkànsìn ti òfin, tí ó sì lórúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn Júù tí ó ń gbé ibẹ̀.
تَنَّگَرَنِواسِناں سَرْوّیشاں یِہُودِییاناں مانْیو وْیَوَسْتھانُسارینَ بھَکْتَشْچَ ہَنانِییَناما مانَوَ ایکو
13 Ó sì dúró tì mí, ó sì wí fún mi pé, ‘Arákùnrin Saulu, gba ìríran!’ Ní ẹsẹ̀ kan náà, mo sì ṣí ojú sí òkè mo sì lè rí i.
مَمَ سَنِّدھِمْ ایتْیَ تِشْٹھَنْ اَکَتھَیَتْ، ہے بھْراتَح شَولَ سُدرِشْٹِ رْبھَوَ تَسْمِنْ دَنْڈےہَں سَمْیَکْ تَں درِشْٹَوانْ۔
14 “Nígbà náà ni ó wí pé: ‘Ọlọ́run àwọn baba wa ti yàn ọ́ láti mọ ìfẹ́ rẹ̀, àti láti ri Ẹni òdodo náà, àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ láti ẹnu rẹ̀.
تَتَح سَ مَہْیَں کَتھِتَوانْ یَتھا تْوَمْ اِیشْوَرَسْیابھِپْرایَں ویتْسِ تَسْیَ شُدّھَسَتّوَجَنَسْیَ دَرْشَنَں پْراپْیَ تَسْیَ شْرِیمُکھَسْیَ واکْیَں شرِنوشِ تَنِّمِتَّمْ اَسْماکَں پُورْوَّپُرُشانامْ اِیشْوَرَسْتْواں مَنونِیتَں کرِتَوانَں۔
15 Ìwọ yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí rẹ̀ fún gbogbo ènìyàn, nínú ohun tí ìwọ tí rí tí ìwọ sì ti gbọ́.
یَتو یَدْیَدْ اَدْراکْشِیرَشْرَوشِیشْچَ سَرْوّیشاں مانَواناں سَمِیپے تْوَں تیشاں ساکْشِی بھَوِشْیَسِ۔
16 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kín ni ìwọ ń dúró dè? Dìde, kí a sì bamitiisi rẹ̀, kí ó sì wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù, kí ó sì máa pe orúkọ rẹ̀.’
اَتَایوَ کُتو وِلَمْبَسے؟ پْرَبھو رْنامْنا پْرارْتھْیَ نِجَپاپَپْرَکْشالَنارْتھَں مَجَّنایَ سَمُتِّشْٹھَ۔
17 “Nígbà tí mo padà wá sí Jerusalẹmu tí mo ǹ gbàdúrà ní tẹmpili, mo bọ́ sí ojúran,
تَتَح پَرَں یِرُوشالَمْنَگَرَں پْرَتْیاگَتْیَ مَنْدِرےہَمْ ایکَدا پْرارْتھَیے، تَسْمِنْ سَمَیےہَمْ اَبھِبھُوتَح سَنْ پْرَبھُوں ساکْشاتْ پَشْیَنْ،
18 mo sì rí Olúwa, ó ń sọ̀rọ̀ fún mi pé, ‘Kíá! Jáde kúrò ní Jerusalẹmu kánkán, nítorí wọn kì yóò gba ẹ̀rí rẹ nípa mi gbọ́.’
تْوَں تْوَرَیا یِرُوشالَمَح پْرَتِشْٹھَسْوَ یَتو لوکامَیِ تَوَ ساکْشْیَں نَ گْرَہِیشْیَنْتِ، مامْپْرَتْیُدِتَں تَسْییدَں واکْیَمْ اَشْرَوشَمْ۔
19 “Èmi sì wí pé, ‘Olúwa, àwọn ènìyàn wọ̀nyí pàápàá mọ̀ pé èmi ti lọ láti inú Sinagọgu kan sí èkejì láti máa sọ wọ́n sínú túbú àti láti máa lu àwọn tí ó gbà ọ́ gbọ́.
تَتوہَں پْرَتْیَوادِشَمْ ہے پْرَبھو پْرَتِبھَجَنَبھَوَنَں تْوَیِ وِشْواسِنو لوکانْ بَدّھوا پْرَہرِتَوانْ،
20 Nígbà tí a sì ta ẹ̀jẹ̀ Stefanu ẹlẹ́rìí rẹ sílẹ̀, èmi náà pẹ̀lú dúró níbẹ̀, mo sì ní ohùn sí ikú rẹ̀, mo sì ń ṣe ìtọ́jú aṣọ àwọn ẹni tí ó pa á.’
تَتھا تَوَ ساکْشِنَح سْتِپھانَسْیَ رَکْتَپاتَنَسَمَیے تَسْیَ وِناشَں سَمَّنْیَ سَنِّدھَو تِشْٹھَنْ ہَنْترِلوکاناں واساںسِ رَکْشِتَوانْ، ایتَتْ تے وِدُح۔
21 “Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, ‘Máa lọ; nítorí èmi ó rán ọ sí àwọn aláìkọlà lókèèrè réré.’”
تَتَح سوکَتھَیَتْ پْرَتِشْٹھَسْوَ تْواں دُورَسْتھَبھِنَّدیشِییاناں سَمِیپَں پْریشَیِشْیے۔
22 Wọ́n sì fi etí sí ọ̀rọ̀ Paulu títí tí ó fi sọ ọ̀rọ̀ yìí. Nígbà yìí ni wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì kígbe wí pé, “Ẹ mu ẹni yìí kúrò láyé! Kò yẹ kí ó wà láààyè!”
تَدا لوکا ایتاوَتْپَرْیَّنْتاں تَدِییاں کَتھاں شْرُتْوا پْروچَّیرَکَتھَیَنْ، اینَں بھُومَنْڈَلادْ دُورِیکُرُتَ، ایتادرِشَجَنَسْیَ جِیوَنَں نوچِتَمْ۔
23 Bí wọ́n sì ti ń kígbe, tí wọ́n sì ń jú aṣọ wọn káàkiri, tí wọ́n ń ku eruku sí ojú ọ̀run,
اِتْیُچَّیح کَتھَیِتْوا وَسَنانِ پَرِتْیَجْیَ گَگَنَں پْرَتِ دھُولِیرَکْشِپَنْ
24 olórí ogun pàṣẹ pé kí a mú Paulu wá sínú àgọ́ àwọn ológun. Ó sì pàṣẹ kí wọ́n ó lù ú, kí wọn fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò, kí òun ba à lè mọ ìdí tí wọ́n fi ń kígbe lé e lórí bẹ́ẹ̀.
تَتَح سَہَسْرَسیناپَتِح پَولَں دُرْگابھْیَنْتَرَ نیتُں سَمادِشَتْ۔ ایتَسْیَ پْرَتِکُولاح سَنْتو لوکاح کِنِّمِتَّمْ ایتاوَدُچَّیحسْوَرَمْ اَکُرْوَّنْ، ایتَدْ ویتُّں تَں کَشَیا پْرَہرِتْیَ تَسْیَ پَرِیکْشاں کَرْتُّمادِشَتْ۔
25 Bí wọ́n sí tí fi ọṣán dè é, Paulu bí balógun ọ̀rún tí ó dúró tì í pé, “Ó ha tọ́ fún yín láti na ẹni tí i ṣe ará Romu ni àìdálẹ́bi bí?”
پَداتَیَشْچَرْمَّنِرْمِّتَرَجُّبھِسْتَسْیَ بَنْدھَنَں کَرْتُّمُدْیَتاسْتاسْتَدانِیں پَولَح سَمُّکھَسْتھِتَں شَتَسیناپَتِمْ اُکْتَوانْ دَنْڈاجْنایامْ اَپْراپْتایاں کِں رومِلوکَں پْرَہَرْتُّں یُشْماکَمْ اَدھِکاروسْتِ؟
26 Nígbà tí balógun ọ̀rún sì gbọ́ èyí, ó lọ wí fún olórí ogun pé, “Kín ni ó fẹ́ ṣe yìí: nítorí ọkùnrin yìí ará Romu ní i ṣe?”
ایناں کَتھاں شْرُتْوا سَ سَہَسْرَسیناپَتیح سَنِّدھِں گَتْوا تاں وارْتّامَوَدَتْ سَ رومِلوکَ ایتَسْماتْ ساوَدھانَح سَنْ کَرْمَّ کُرُ۔
27 Alábojútó-ogun sì dé, ó sì bí Paulu pé, “Sọ fún mi, ará Romu ni ìwọ jẹ́ bí?” Ó sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
تَسْماتْ سَہَسْرَسیناپَتِ رْگَتْوا تَمَپْراکْشِیتْ تْوَں کِں رومِلوکَح؟ اِتِ ماں بْرُوہِ۔ سوکَتھَیَتْ سَتْیَمْ۔
28 Alábojútó-ogun sì dáhùn wí pé, “Owó púpọ̀ ni mo fi ra ọlá ìbílẹ̀ yìí.” Paulu wí pé, “Ṣùgbọ́n a bí mi sínú rẹ̀ ni.”
تَتَح سَہَسْرَسیناپَتِح کَتھِتَوانْ بَہُدْرَوِنَں دَتّواہَں تَتْ پَورَسَکھْیَں پْراپْتَوانْ؛ کِنْتُ پَولَح کَتھِتَوانْ اَہَں جَنُنا تَتْ پْراپْتوسْمِ۔
29 Nítorí náà àwọn tí ó múra láti fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò fàsẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀: lójúkan náà. Olórí ogun pẹ̀lú sì bẹ̀rù nígbà tí ó mọ̀ pé ọmọ ìbílẹ̀ Romu ní Paulu i ṣe, àti nítorí ó tí dè é.
اِتّھَں سَتِ یے پْرَہارینَ تَں پَرِیکْشِتُں سَمُدْیَتا آسَنْ تے تَسْیَ سَمِیپاتْ پْراتِشْٹھَنْتَ؛ سَہَسْرَسیناپَتِسْتَں رومِلوکَں وِجْنایَ سْوَیَں یَتْ تَسْیَ بَنْدھَنَمْ اَکارْشِیتْ تَتْکارَنادْ اَبِبھیتْ۔
30 Ní ọjọ́ kejì, nítorí tí olórí ogun fẹ́ mọ̀ dájúdájú ohun tí àwọn Júù ń fi Paulu sùn sí, ó tú u sílẹ̀, ó pàṣẹ kí àwọn olórí àlùfáà àti gbogbo ìgbìmọ̀ péjọ, nígbà náà ni ó mú Paulu sọ̀kalẹ̀, ó sì mú un dúró níwájú wọn.
یِہُودِییَلوکاح پَولَں کُتوپَوَدَنْتے تَسْیَ ورِتّانْتَں جْناتُں وانْچھَنْ سَہَسْرَسیناپَتِح پَرےہَنِ پَولَں بَنْدھَناتْ موچَیِتْوا پْرَدھانَیاجَکانْ مَہاسَبھایاح سَرْوَّلوکاشْچَ سَمُپَسْتھاتُمْ آدِشْیَ تیشاں سَنِّدھَو پَولَمْ اَوَروہْیَ سْتھاپِتَوانْ۔

< Acts 22 >