< Acts 22 >

1 “Ẹ̀yin ará àti baba, ẹ gbọ́ tí ẹnu mi nísinsin yìí.”
—Drodzy przyjaciele i starsi! Posłuchajcie tego, co mam na swoją obronę!
2 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́ pé ó ń bá wọn sọ̀rọ̀ ni èdè Aramaiki, wọ́n túbọ̀ dákẹ́ jẹ́ẹ́. Nígbà náà ni ó wí pé,
Gdy usłyszeli, że mówi po hebrajsku, uciszyli się jeszcze bardziej. Paweł zaś mówił dalej:
3 “Júù ni èmi í ṣe, a bí mi ni Tarsu ìlú kan ní Kilikia, ṣùgbọ́n tí a tọ́ mi dàgbà ni ìlú yìí. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ Gamalieli ni a sì gbé kọ́ mi ní òfin àwọn baba wa, tí mo sì ní ìtara fún Ọlọ́run àní gẹ́gẹ́ bí gbogbo yin tí rí ni òní.
—Jestem Żydem urodzonym w Tarsie, w Cylicji, ale wychowałem się tu, w Jerozolimie. Pod okiem Gamaliela uczyłem się dokładnie przestrzegać Prawa Mojżesza. Byłem całkowicie oddany Bogu—tak samo jak wy dziś.
4 Mo sì ṣe inúnibíni sí àwọn ènìyàn tí ń tọ ọ̀nà yìí dé ojú ikú wọn, mo dè tọkùnrin tobìnrin wọ́n, mo sì fi wọ́n sínú túbú,
Prześladowałem zwolenników tej drogi: ścigałem ich, więziłem i zabijałem mężczyzn i kobiety.
5 àní bí olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo àjọ àwọn alàgbà tí lè jẹ́ mi ní ẹ̀rí. Mo tilẹ̀ gba ìwé àṣẹ lọ́wọ́ wọn lọ sọ́dọ̀ àwọn arákùnrin wọn ní Damasku láti mú àwọn tí ó wà níbẹ̀ ní dídè wá sí Jerusalẹmu, láti jẹ wọ́n ní yà.
Może to poświadczyć najwyższy kapłan oraz starsi. To od nich bowiem otrzymałem listy do przywódców w Damaszku, chciałem bowiem udać się tam, aby aresztować tamtejszych uczniów Jezusa i związanych oddać pod sąd w Jerozolimie.
6 “Bí èmi tí súnmọ́ etí Damasku níwọ̀n ọjọ́-kanrí, lójijì ìmọ́lẹ̀ ńlá láti ọ̀run wá mọ́lẹ̀ yí mi ká.
Ale gdy zbliżałem się do Damaszku, w samo południe oślepiła mnie ogromna jasność z nieba.
7 Mo sì ṣubú lulẹ̀, mo sì gbọ́ ohùn kan tí ó wí fún mi pé, ‘Saulu, Saulu èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi?’
Padłem wtedy na ziemię i usłyszałem głos: „Szawle, Szawle! Dlaczego Mnie prześladujesz?”.
8 “Mo sì béèrè pé, ‘Ta ni ìwọ, Olúwa?’ “Ó sì dá mi lóhùn pé, ‘Èmi ni Jesu tí Nasareti, ẹni tí ìwọ ń ṣe inúnibíni sí.’
„Kim jesteś, Panie?”—zapytałem. „Jestem Jezus z Nazaretu, którego prześladujesz”—odpowiedział.
9 Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi rí ìmọ́lẹ̀ náà nítòótọ́, ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ohùn ẹni tí ń bá mi sọ̀rọ̀.
Moi towarzysze podróży, którzy stali obok, widzieli jasność, ale nie słyszeli żadnego głosu.
10 “Mo sí béèrè pé, ‘Kín ni kí èmí kí ó ṣe, Olúwa?’ “Olúwa sì wí fún mi pé, ‘Dìde, kí o sì lọ sí Damasku; níbẹ̀ ni a ó sì ti sọ ohun gbogbo fún ọ tí a yàn fún ọ láti ṣe.’
„Co mam robić, Panie?”—zapytałem. „Wstań i idź do Damaszku”—rzekł Pan. „Tam się dowiesz, co masz robić”.
11 Àwọn tí ó sì wà pẹ̀lú mi fà mí lọ́wọ́ wọ Damasku lọ nítorí tí èmi kò lè ríran nítorí ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ náà ti fọ́ mi ní ojú.
Ponieważ zostałem oślepiony blaskiem tego światła, do Damaszku zaprowadzili mnie moi towarzysze.
12 “Ọkùnrin kan tí a ń pè ní Anania tọ̀ mí wá, ẹni tó jẹ́ olùfọkànsìn ti òfin, tí ó sì lórúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo àwọn Júù tí ó ń gbé ibẹ̀.
Tam przyszedł do mnie niejaki Ananiasz, człowiek kochający Boga i dokładnie przestrzegający Prawa Mojżesza, co potwierdzają wszyscy tamtejsi Żydzi.
13 Ó sì dúró tì mí, ó sì wí fún mi pé, ‘Arákùnrin Saulu, gba ìríran!’ Ní ẹsẹ̀ kan náà, mo sì ṣí ojú sí òkè mo sì lè rí i.
Stanął przede mną i rzekł: „Szawle, przyjacielu! Przejrzyj!”. W tej samej chwili odzyskałem wzrok i mogłem już go widzieć.
14 “Nígbà náà ni ó wí pé: ‘Ọlọ́run àwọn baba wa ti yàn ọ́ láti mọ ìfẹ́ rẹ̀, àti láti ri Ẹni òdodo náà, àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ láti ẹnu rẹ̀.
Wtedy on powiedział: „Bóg naszych przodków wybrał cię, abyś poznał Jego wolę oraz ujrzał Tego, który jest Prawy i byś usłyszał Jego głos.
15 Ìwọ yóò jẹ́ ẹlẹ́rìí rẹ̀ fún gbogbo ènìyàn, nínú ohun tí ìwọ tí rí tí ìwọ sì ti gbọ́.
Odtąd będziesz mówił o Nim wszystkim ludziom, opowiadając także o tym, co widziałeś i słyszałeś.
16 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kín ni ìwọ ń dúró dè? Dìde, kí a sì bamitiisi rẹ̀, kí ó sì wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù, kí ó sì máa pe orúkọ rẹ̀.’
Nie zwlekaj więc! Wstań i daj się ochrzcić. Niech imię Pana obmyje cię ze wszystkich twoich grzechów”.
17 “Nígbà tí mo padà wá sí Jerusalẹmu tí mo ǹ gbàdúrà ní tẹmpili, mo bọ́ sí ojúran,
Gdy wróciłem do Jerozolimy i modliłem się w świątyni, miałem wizję.
18 mo sì rí Olúwa, ó ń sọ̀rọ̀ fún mi pé, ‘Kíá! Jáde kúrò ní Jerusalẹmu kánkán, nítorí wọn kì yóò gba ẹ̀rí rẹ nípa mi gbọ́.’
Pan rzekł do mnie: „Szybko opuść miasto, ponieważ ci ludzie nie będą słuchać tego, co im o Mnie opowiesz”.
19 “Èmi sì wí pé, ‘Olúwa, àwọn ènìyàn wọ̀nyí pàápàá mọ̀ pé èmi ti lọ láti inú Sinagọgu kan sí èkejì láti máa sọ wọ́n sínú túbú àti láti máa lu àwọn tí ó gbà ọ́ gbọ́.
„Ależ Panie!”—protestowałem. „Przecież oni wiedzą, że wtrącałem do więzień i biczowałem w synagogach tych, którzy Ci uwierzyli.
20 Nígbà tí a sì ta ẹ̀jẹ̀ Stefanu ẹlẹ́rìí rẹ sílẹ̀, èmi náà pẹ̀lú dúró níbẹ̀, mo sì ní ohùn sí ikú rẹ̀, mo sì ń ṣe ìtọ́jú aṣọ àwọn ẹni tí ó pa á.’
Uczestniczyłem przecież nawet w zabójstwie Szczepana, który opowiadał ludziom o Tobie. Popierałem to morderstwo i pilnowałem ubrań tych, którzy zadawali mu śmierć”.
21 “Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, ‘Máa lọ; nítorí èmi ó rán ọ sí àwọn aláìkọlà lókèèrè réré.’”
Bóg rzekł jednak do mnie: „Wyjedź z Jerozolimy, bo chcę cię posłać daleko stąd, do pogan!”.
22 Wọ́n sì fi etí sí ọ̀rọ̀ Paulu títí tí ó fi sọ ọ̀rọ̀ yìí. Nígbà yìí ni wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì kígbe wí pé, “Ẹ mu ẹni yìí kúrò láyé! Kò yẹ kí ó wà láààyè!”
Tłum, który do tego momentu spokojnie słuchał słów Pawła, teraz zaczął krzyczeć: —Precz z nim! On nie zasługuje na życie!
23 Bí wọ́n sì ti ń kígbe, tí wọ́n sì ń jú aṣọ wọn káàkiri, tí wọ́n ń ku eruku sí ojú ọ̀run,
Krzyczeli, wymachiwali ubraniami i zdenerwowani rzucali piaskiem.
24 olórí ogun pàṣẹ pé kí a mú Paulu wá sínú àgọ́ àwọn ológun. Ó sì pàṣẹ kí wọ́n ó lù ú, kí wọn fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò, kí òun ba à lè mọ ìdí tí wọ́n fi ń kígbe lé e lórí bẹ́ẹ̀.
Dowódca zabrał więc Pawła do koszar i rozkazał biczowaniem wydobyć z niego zeznania, aby dowiedzieć się dlaczego tłum tak go nienawidzi.
25 Bí wọ́n sí tí fi ọṣán dè é, Paulu bí balógun ọ̀rún tí ó dúró tì í pé, “Ó ha tọ́ fún yín láti na ẹni tí i ṣe ará Romu ni àìdálẹ́bi bí?”
Gdy żołnierze związali go już do biczowania, Paweł zapytał stojącego obok dowódcę: —Czy wolno wam biczować rzymskiego obywatela i to bez procesu?
26 Nígbà tí balógun ọ̀rún sì gbọ́ èyí, ó lọ wí fún olórí ogun pé, “Kín ni ó fẹ́ ṣe yìí: nítorí ọkùnrin yìí ará Romu ní i ṣe?”
Ten udał się do dowódcy oddziału i powiedział: —Uważaj, co robisz! Ten człowiek to Rzymianin!
27 Alábojútó-ogun sì dé, ó sì bí Paulu pé, “Sọ fún mi, ará Romu ni ìwọ jẹ́ bí?” Ó sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
Dowódca podszedł więc do Pawła i zapytał: —Naprawdę jesteś Rzymianinem? —Tak—odparł Paweł.
28 Alábojútó-ogun sì dáhùn wí pé, “Owó púpọ̀ ni mo fi ra ọlá ìbílẹ̀ yìí.” Paulu wí pé, “Ṣùgbọ́n a bí mi sínú rẹ̀ ni.”
—Mnie rzymskie obywatelstwo kosztowało majątek!—rzekł. —A ja mam je od urodzenia—odpowiedział Paweł.
29 Nítorí náà àwọn tí ó múra láti fi ọ̀rọ̀ wa lẹ́nu wò fàsẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀: lójúkan náà. Olórí ogun pẹ̀lú sì bẹ̀rù nígbà tí ó mọ̀ pé ọmọ ìbílẹ̀ Romu ní Paulu i ṣe, àti nítorí ó tí dè é.
Ci, którzy chcieli przesłuchiwać Pawła, natychmiast się usunęli. A dowódca przestraszył się, że aresztował rzymskiego obywatela.
30 Ní ọjọ́ kejì, nítorí tí olórí ogun fẹ́ mọ̀ dájúdájú ohun tí àwọn Júù ń fi Paulu sùn sí, ó tú u sílẹ̀, ó pàṣẹ kí àwọn olórí àlùfáà àti gbogbo ìgbìmọ̀ péjọ, nígbà náà ni ó mú Paulu sọ̀kalẹ̀, ó sì mú un dúró níwájú wọn.
Następnego dnia, chcąc się dowiedzieć o co żydowscy przywódcy oskarżają Pawła, dowódca zdjął z niego więzy i zarządził zebranie najwyższych kapłanów oraz Wysokiej Rady. Następnie postawił przed nimi Pawła.

< Acts 22 >