< Acts 21 >
1 Lẹ́yìn tí àwa ti kúrò lọ́dọ̀ wọn, tí a sì ṣíkọ̀, àwa bá ọ̀nà wa lọ tààrà sí Kosi. Ní ọjọ́ kejì a sì lọ sí Rodu, à si gba ibẹ̀ lọ sí Patara,
A gdyśmy odjechali, rozstawszy się z nimi, prosto jadąc, przyjechaliśmy do Kou, a nazajutrz do Rodu, a stamtąd do Patary.
2 A rí ọkọ̀ ojú omi kan tí ń rékọjá lọ sí Fonisia, a wọ inú ọkọ̀ náà, a sì ṣíkọ̀.
A tam znalazłszy okręt, który miał płynąć do Fenicyi, wsiadłszy weń, jechaliśmy.
3 Nígbà tí àwa sì ń wo Saipurọsi lókèèrè, a sì fi í sí ọwọ́ òsì, a fi orí ọ́kọ̀ le Siria, a sì gúnlẹ̀ ni Tire; nítorí níbẹ̀ ni ọkọ̀ yóò tí já ẹrù sílẹ̀.
A gdy się nam ukazał Cypr, tedy zostawiwszy go po lewej stronie, płynęliśmy do Syryi i przypłynęliśmy do Tyru; albowiem tam z okrętu towary składać miano.
4 Nígbà tí a sì ti rí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn níbẹ̀, a dúró ní ọ̀dọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọjọ́ méje: àwọn ẹni tí ó ti ipá Ẹ̀mí wí fún Paulu pé, kí ó má ṣe lọ sí Jerusalẹmu.
A znalazłszy uczniów, zamieszkaliśmy tam siedm dni; którzy mówili Pawłowi przez ducha, aby nie chodził do Jeruzalemu.
5 Nígbà tí a sì tí lo ọjọ́ wọ̀nyí tan, àwa jáde, a sì mu ọ̀nà wá pọ̀n; gbogbo wọn sì sìn wá, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé títí àwa fi jáde sí ẹ̀yìn ìlú, nígbà tí àwa sì gúnlẹ̀ ní èbúté, a sì gbàdúrà.
A gdyśmy przemieszkali one dni, wyszedłszy, poszliśmy, a wszyscy nas prowadzili z żonami i z dziatkami aż za miasto, a klęknąwszy na kolana na brzegu, modliliśmy się.
6 Nígbà tí a sì ti dágbére fún ara wa, a bọ́ sí ọkọ̀; bẹ́ẹ̀ ni àwọn sì padà lọ sí ilé wọn.
A pożegnawszy się jedni z drugimi, wstąpiliśmy w okręt, a oni się wrócili do domu.
7 Nígbà tí a sì ti parí àjò wa láti Tire, àwa dé Pitolemai; nígbà ti a sì kí àwọn ará, a sì bá wọn gbé ní ọjọ́ kan.
A my odprawiwszy płynienie z Tyru, przypłynęliśmy do Ptolemaidy, a pozdrowiwszy braci, zamieszkaliśmy u nich przez jeden dzień.
8 Ní ọjọ́ kejì a lọ kúrò, a sì wá sí Kesarea; nígbà tí á sì wọ ilé Filipi efangelisti tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méje; àwa sì wọ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀.
A nazajutrz wyszedłszy Paweł i my, którzyśmy z nim byli, przyszliśmy do Cezaryi, a wszedłszy w dom Filipa Ewangielisty, który był jeden z onych siedmiu, zostaliśmy u niego.
9 Ọkùnrin yìí sì ní ọmọbìnrin mẹ́rin, wúńdíá, tí wọ́n máa ń sọtẹ́lẹ̀.
A ten miał cztery córki panny, które prorokowały.
10 Bí a sì tí wà níbẹ̀ lọ́jọ́ púpọ̀, wòlíì kan tí Judea sọ̀kalẹ̀ wá, tí a ń pè ní Agabu.
A gdyśmy tam przez niemało dni zamieszkali, przyszedł z Judzkiej ziemi prorok niektóry, imieniem Agabus.
11 Nígbà tí ó sì dé ọ̀dọ̀ wa, ó mú àmùrè Paulu, ó sì de ara rẹ̀ ní ọwọ́ àti ẹsẹ̀, ó sì wí pé, “Báyìí ni Ẹ̀mí Mímọ́ wí, ‘Báyìí ni àwọn Júù tí ó wà ní Jerusalẹmu yóò de ọkùnrin tí ó ní àmùrè yìí, wọn ó sì fi í lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́.’”
Ten przyszedłszy do nas i wziąwszy pas Pawła, a związawszy sobie ręce i nogi, rzekł: To mówi Duch Święty: Męża, którego jest ten pas, tak zwiążą w Jeruzalemie Żydowie i podadzą go w ręce poganom.
12 Nígbà tí a sì tí gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, àti àwa, àti àwọn ará ibẹ̀ náà bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó má ṣe gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
A gdyśmy to usłyszeli, prosiliśmy i my i ci, którzy na onem miejscu byli, aby on nie chodził do Jeruzalemu.
13 Nígbà náà ni Paulu dáhùn wí pé, “Èwo ni ẹ̀yin ń ṣe yìí, tí ẹ̀yin ń sọkún, tí ẹ sì ń mú àárẹ̀ bá ọkàn mi; nítorí èmí tí múra tan, kì í ṣe fún dídè nìkan, ṣùgbọ́n láti kú pẹ̀lú ni Jerusalẹmu, nítorí orúkọ Jesu Olúwa.”
Tedy odpowiedział Paweł: Cóż czynicie płacząc i serce mi psując? Albowiem ja nie tylko być związanym, ale i umrzeć jestem gotowy w Jeruzalemie dla imienia Pana Jezusowego.
14 Nígbà tí a kò lè pa á ní ọkàn dà, a dákẹ́ wí pé, “Ìfẹ́ tí Olúwa ni kí ó ṣe!”
A gdy się on nie dał namówić, daliśmy pokój, mówiąc: Niech się stanie wola Pańska.
15 Lẹ́yìn ọjọ́ wọ̀nyí, a palẹ̀mọ́, a sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
A po onych dniach, wziąwszy rzeczy swoje, szliśmy do Jeruzalemu.
16 Nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn láti Kesarea bá wa lọ, wọ́n sì mú wa lọ sí ilé Munasoni ọmọ-ẹ̀yìn àtijọ́ kan ara Saipurọsi, lọ́dọ̀ ẹni tí àwa yóò dé sí.
A szli z nami i niektórzy uczniowie z Cezaryi, wiodąc z sobą tego, u któregośmy gospodą stać mieli, niejakiego Mnazona Cypryjczyka, starego ucznia.
17 Nígbà tí a sì dé Jerusalẹmu, àwọn arákùnrin sì fi ayọ̀ gbà wá.
A gdyśmy przyszli do Jeruzalemu, wdzięcznie nas bracia przyjęli.
18 Ní ọjọ́ kejì, a bá Paulu lọ sọ́dọ̀ Jakọbu; gbogbo àwọn alàgbà sì wà níbẹ̀.
A nazajutrz wszedł z nami Paweł do Jakóba, gdzie się byli wszyscy starsi zeszli.
19 Nígbà tí ó sì kí wọn tan, ó ròyìn lẹ́sẹẹsẹ ohun gbogbo tí Ọlọ́run ṣe láàrín àwọn aláìkọlà nípa iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀.
Które pozdrowiwszy, rozpowiedział im wszystko porządnie, co Bóg uczynił między pogany przez usługę jego.
20 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, wọ́n yin Ọlọ́run lógo, wọ́n sì wí fún un pé, “Arákùnrin, ìwọ rí iye ẹgbẹẹgbẹ̀rún nínú àwọn Júù tí ó gbàgbọ́, gbogbo wọn ni ó sì ní ìtara fún òfin.
Co oni usłyszawszy, chwalili Pana i rzekli mu: Widzisz, bracie! jako jest wiele tysięcy Żydów, którzy uwierzyli; a ci wszyscy gorliwi są miłośnicy zakonu.
21 Wọ́n sì ti ròyìn rẹ̀ fún wọn pé, ìwọ ń kọ́ gbogbo àwọn Júù tí ó wà láàrín àwọn aláìkọlà pé, kí wọn kọ Mose sílẹ̀, ó ń wí fún wọn pé kí wọn má ṣe kọ àwọn ọmọ wọn ní ilà mọ́, kí wọn má sì ṣe rìn gẹ́gẹ́ bí àṣà wọn.
Ale o tobie wzięli sprawę, że odwodzisz od Mojżesza wszystkich tych Żydów, którzy są między pogany, mówiąc, że nie mają obrzezywać dziatek, ani mają chodzić według ustaw zakonnych.
22 Ǹjẹ́ èwo ni ṣíṣe? Ìjọ kò lè ṣàìmá péjọpọ̀: dájúdájú wọn yóò gbọ́ pé, ìwọ dé.
Cóż tedy jest? Koniecznieć się musi zejść lud; bo usłyszą, żeś przyszedł.
23 Ǹjẹ́ èyí tí àwa ó wí fún ọ yìí ni kí o ṣe, àwa ni ọkùnrin mẹ́rin tí wọ́n wà lábẹ́ ẹ̀jẹ́.
A przetoż czyń to, coć mówimy; Mamy tu czterech mężów, którzy na sobie ślub mają;
24 Àwọn ni kí ìwọ mú, kí o sì ṣe ìwẹ̀nùmọ́ pẹ̀lú wọn, kí ó sì san owó láti fá irun orí wọn: gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, kò sì òtítọ́ kan nínú ohun tí wọ́n gbọ́ sí ọ; àti pé, ìwọ tìkára rẹ ń rìn déédé, ìwọ sì ń pa òfin Mose mọ́.
Tych wziąwszy do siebie, oczyść się z nimi i uczyń nakład na nie, aby ogolili głowy; a poznają wszyscy, że to, co o tobie słyszeli, nic nie jest, ale że i ty sam chodzisz przestrzegając zakonu.
25 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn aláìkọlà tí ó gbàgbọ́, àwa tí kọ̀wé, a sì ti pinnu rẹ̀ pé, kí wọn pa ara wọn mọ́ kúrò nínú ohun tí a fi rú ẹbọ sí òrìṣà, àti ẹ̀jẹ̀ àti ohun ìlọ́lọ́rùnpa, àti àgbèrè.”
A o tych, którzy uwierzyli z pogan, myśmy pisali, stanowiąc, aby nic takowego nie zachowywali, tylko aby się wystrzegali tego, co jest ofiarowane bałwanom i od krwi, i od rzeczy dławionych, i od wszeteczeństwa.
26 Nígbà náà ni Paulu mú àwọn ọkùnrin náà; ní ọjọ́ kejì ó ṣe ìwẹ̀nùmọ́ pẹ̀lú wọn, ó sì wọ inú tẹmpili lọ, láti sọ ìgbà tí ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ náà yóò pé tí a ó sì fi ọrẹ lélẹ̀ fún olúkúlùkù wọn.
Tedy Paweł wziąwszy z sobą one męże, nazajutrz oczyszczony będąc z nimi, wszedł do kościoła, opowiadając wypełnienie dni oczyszczenia, aż za każdego z nich oddana była ofiara.
27 Nígbà tí ọjọ́ méje sì fẹ́rẹ̀ pé, tí àwọn Júù tí ó ti Asia wá rí i ni tẹmpili, wọ́n rú gbogbo àwọn ènìyàn sókè, wọ́n nawọ́ mú un.
A gdy się miało wypełnić siedm dni, niektórzy Żydowie z Azyi, ujrzawszy go w kościele, wzbudzili wszystek lud i wrzucili na niego ręce,
28 Wọ́n ń kígbe wí pé, “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbà wá. Èyí ni ọkùnrin náà tí ń kọ́ gbogbo ènìyàn níbi gbogbo lòdì sí àwọn ènìyàn, àti sí òfin, àti sí ibí yìí, àti pẹ̀lú ó sì mú àwọn ará Giriki wá sínú tẹmpili, ó sì tí ba ibi mímọ́ yìí jẹ́.”
Wołając: Mężowie Izraelscy, ratujcie! Tenci to jest człowiek, który przeciwko ludowi i zakonowi, i miejscu temu wszystkich wszędy uczy, nadto i Greki wprowadził do kościoła, i splugawił to miejsce święte.
29 Nítorí wọ́n tí rí Tirofimu ará Efesu pẹ̀lú rẹ̀ ní ìlú, ẹni tí wọ́n ṣe bí Paulu mú wá sínú tẹmpili.
Albowiem przedtem widzieli z nim w mieście Trofima Efeskiego, o którym mniemali, żeby go Paweł wprowadził do kościoła.
30 Gbogbo ìlú sì wà ní ìrúkèrúdò, àwọn ènìyàn sì súré jọ wọ́n sì mú Paulu, wọ́n sì wọ́ ọ jáde kúrò nínú tẹmpili: lójúkan náà, a sì ti ìlẹ̀kùn.
I wzruszyło się miasto wszystko, i zbiegł się lud; a pojmawszy Pawła, wywlekli go precz z kościoła, a zatem zaraz drzwi zamkniono.
31 Bí wọn sì ti ń wá ọ̀nà láti pa á, ìròyìn dé ọ̀dọ̀ olórí ẹgbẹ́ ọmọ-ogun pé, gbogbo Jerusalẹmu ti dàrú.
A gdy się starali, jakoby go zabili, dano znać hetmanowi wojska, iż się wzruszyło wszystko Jeruzalem.
32 Lójúkan náà, ó sì ti mú àwọn ọmọ-ogun àti àwọn balógun ọ̀rún, ó sì súré sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wọ́n lọ; nígbà tí wọ́n sì rí í olórí ogun àti àwọn ọmọ-ogun dẹ́kun lílù Paulu.
Który zarazem wziąwszy z sobą żołnierze i setniki, przybieżał do nich. A oni ujrzawszy hetmana i żołnierze, przestali Pawła bić.
33 Nígbà náà ni olórí ogun súnmọ́ wọn, ó sì mú un, ó pàṣẹ pé kí a fi ẹ̀wọ̀n méjì dè é; ó sì béèrè ẹni tí ó jẹ́, àti ohun tí ó ṣe.
Tedy hetman przybliżywszy się, pojmał go i kazał go dwoma łańcuchami związać, i wywiadywał się, kto by był i co by uczynił?
34 Àwọn kan ń kígbe ohun kan, àwọn mìíràn ń kígbe ohun mìíràn nínú àwùjọ; nígbà tí kò sì lè mọ̀ ìdí pàtàkì fún ìrúkèrúdò náà, ó pàṣẹ kí wọ́n mú un lọ sínú àgọ́ àwọn ológun.
A jedni tak, drudzy inaczej między ludem wołali; a gdy się nic pewnego dla zgiełku dowiedzieć nie mógł, rozkazał go wieść do obozu.
35 Nígbà tí ó sì dé orí àtẹ̀gùn, gbígbé ni a gbé e sókè lọ́wọ́ àwọn ọmọ-ogun nítorí ìwà ipá àwọn ènìyàn.
A gdy był u wschodu, przydało się, że go prawie żołnierze nieśli dla gwałtu onego ludu.
36 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn rọ́ tẹ̀lé e, wọ́n ń kígbe pé, “Mú un kúrò!”
Albowiem wielki lud szedł za nim, wołając: Zgładź go.
37 Bí wọ́n sì tí fẹ́rẹ̀ mú Paulu wọ inú àgọ́ àwọn ológun lọ, ó wí fún olórí ogun pé, “Èmi ha lè bá ọ sọ̀rọ̀ bí?” Ó sì dáhùn wí pé, “Ìwọ mọ èdè Giriki bí?
A gdy miał być Paweł prowadzony do obozu, rzekł hetmanowi: A godzi mi się co mówić do ciebie? A on rzekł: Umiesz po grecku?
38 Ìwọ ha kọ ní ara Ejibiti náà, tí ó ṣọ̀tẹ̀ ṣáájú ọjọ́ wọ̀nyí, ti ó sì ti mú ẹgbàajì ọkùnrin nínú àwọn tí í ṣe apànìyàn lẹ́yìn lọ sí ijù?”
I nie tyżeś jest on Egipczanin, któryś przed temi dniami uczynił rozruch i wywiodłeś na puszczę cztery tysiące mężów zbójców?
39 Ṣùgbọ́n Paulu sì wí pé, “Júù ní èmi jẹ́, ará Tarsu ìlú Kilikia, tí kì í ṣe ìlú yẹpẹrẹ kan, èmi síbẹ̀ ọ, fún mi ní ààyè láti bá àwọn ènìyàn wọ̀nyí sọ̀rọ̀!”
A Paweł rzekł: Jamci jest człowiek Żyd Tarseńczyk, mieszczanin nie z podłego miasta w Cylicyi: przetoż proszę cię, dopuść mi mówić do ludu.
40 Nígbà tí ó sì tí fún un ní ààyè, Paulu dúró lórí àtẹ̀gùn, ó sì juwọ́ sí àwọn ènìyàn. Nígbà tí wọ́n sì dákẹ́ rọ́rọ́, ó bá wọn sọ̀rọ̀ ní èdè Heberu, wí pé,
A gdy on dopuścił, Paweł stojąc na wschodzie, skinął ręką na lud. A gdy było wielkie milczenie, uczynił rzecz do nich żydowskim językiem, mówiąc: