< Acts 20 >

1 Nígbà tí ariwo náà sí rọlẹ̀, Paulu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn, ó sì gbà wọ́n ní ìyànjú, ó dágbére fún wọn, ó dìde láti lọ sí Makedonia.
ⲁ̅ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⳿ⲑⲣⲉϥⲟⲩⲱ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ⳿ⲁ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲛⲥⲁ ⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϯⲛⲟⲙϯ ⲛⲱⲟⲩ ⲁϥⲉⲣⲁⲥⲡⲁⲍⲉⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉϣⲉ ⳿ⲉ⳿ⲑⲙⲁⲕⲉⲇⲟⲛⲓⲁ.
2 Nígbà tí ó sì tí la apá ìhà wọ̀nyí kọjá, tí ó sì ti fi ọ̀rọ̀ púpọ̀ gbà wọ́n ní ìyànjú, ó wá sí ilẹ̀ Giriki.
ⲃ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϯⲛⲟⲙϯ ⲛⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲥⲁϫⲓ ⲉϥⲟϣ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϯⲉⲗⲗⲁⲥ.
3 Ó sì dúró níbẹ̀ ní oṣù mẹ́ta, nígbà tí àwọn Júù sì dènà dè é, bí ó ti ń pète àti bá ọkọ̀ ojú omi lọ sí Siria, ó pinnu rẹ̀ láti gbà Makedonia padà lọ.
ⲅ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲉⲣ ⲅ̅ ⲇⲉ ⳿ⲛ⳿ⲁⲃⲟⲧ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲥⲟϭⲛⲓ ⲉϥϩⲱⲟⲩ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲉϥⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲤⲩⲣⲓ⳿ⲁ ⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲥⲟϭⲛⲓ ⲉⲑⲣⲉϥⲕⲟⲧϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲑⲙⲁⲕⲉⲇⲟⲛⲓ⳿ⲁ.
4 Sopateru ará Berea ọmọ Pirusi sì bá a lọ dé Asia, àti nínú àwọn ará Tẹsalonika, Aristarku àti Sekundu, àti Gaiusi ará Dabe, àti Timotiu; Tikiku àti Tirofimu ará Asia.
ⲇ̅ⲛⲁϥⲛⲉⲙⲁϥ ⲇⲉ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲥⲱⲥⲓⲡⲁⲧⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲩⲣⲣⲟⲥ ⲡⲓⲣⲉⲙⲃⲉⲣⲟⲓ⳿ⲁ ⲛⲁ ⲑⲉⲥⲥⲁⲗⲟⲛⲓⲕⲏⲇⲉ ⳿ⲁⲣⲓⲥⲧⲁⲣⲭⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲥⲉⲕⲟⲩⲛⲑⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲅⲁⲓⲟⲥ ⲡⲓⲣⲉⲙⲧⲉⲣⲃⲏⲛⲉⲙ ⲧⲓⲙⲟⲑⲉⲟⲥ ⲛⲁ ϯⲁⲥⲓⲁ ⲇⲉ ⲧⲩⲭⲓⲕⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⳿ⲧⲣⲟⲫⲏⲙⲟⲥ.
5 Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí tí lọ síwájú, wọ́n dúró dè wá ni Troasi.
ⲉ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲉⲣϣⲟⲣⲡ ⳿ⲉⲣⲟⲛ ⲁⲩⲟϩⲓ ⲛⲁⲛ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲣⲱⲁⲥ.
6 Àwa sì ṣíkọ̀ láti Filipi lọ lẹ́yìn àjọ àìwúkàrà, a sì dé ọ̀dọ̀ wọn ní Troasi ni ọjọ́ méje.
ⲋ̅⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⲛⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲁⲧϣⲉⲙⲏⲣ ⲁⲛⲉⲣϩⲱⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲫⲓⲗⲓⲡⲡⲟⲓⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲛ⳿ⲓ ϣⲁⲣⲱⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ⲧⲣⲱⲁⲥ ⳿ⲙⲡ⳿ⲉⲛⲉ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲛϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ϧⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲍ̅ ⳿ⲛ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ.
7 Ọjọ́ èkínní ọ̀sẹ̀ nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn péjọ láti bu àkàrà, Paulu sì wàásù fún wọn, ó múra láti lọ ní ọjọ́ kejì: ó sì fa ọ̀rọ̀ rẹ̀ gùn títí di àárín ọ̀gànjọ́.
ⲍ̅ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲥⲁⲃⲃⲁⲧⲟⲛ ⲉⲧⲁⲛⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲉⲫⲱϣ ⳿ⲛⲟⲩⲱⲓⲕ ⲛⲁϥⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲉϥⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲥϯ ⲛⲁϥⲫⲱⲣϣ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϣⲁ ⳿ⲧⲫⲁϣⲓ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ.
8 Fìtílà púpọ̀ sì wà ní iyàrá òkè náà, níbi tí wọn gbé péjọ sí.
ⲏ̅ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲇⲉ ⳿ⲛⲗⲁⲙⲡⲁⲥ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁ ⲉⲧⲥⲁ⳿ⲡϣⲱⲓ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲛⲁⲩⲑⲟⲩⲏⲧ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
9 Ọ̀dọ́mọkùnrin kan tí a ń pè ní Eutiku sì jókòó lójú fèrèsé, oorun sì wọ̀ ọ́ lára; bí Paulu sì ti pẹ́ ní ìwàásù, ó ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n lójú oorun, ó ṣubú láti òkè kẹta wá sílẹ̀, a sì gbé e dìde ní òkú.
ⲑ̅ⲛⲁϥϩⲉⲙⲥⲓ ⲇⲉ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩϧⲉⲗϣ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ ⲉⲩⲧⲩⲭⲟⲥ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓϣⲟⲩϣⲧ ⲉϥⲟⲃϣ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛⲉⲛⲕⲟⲧ ⳿ⲉⲣⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲇⲉ ⲥⲁϫⲓ ⳿ⲁ ⲡⲓⲉⲛⲕⲟⲧ ⲥⲟⲕϥ ⳿ⲛϩⲟⲩⲟ ⲁϥϩⲉⲓ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ϧⲉⲛ ϯⲙⲁϩⲅ̅ϯ ⳿ⲛⲟⲩⲁϩⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϥⲓⲧϥ ⲉϥⲙⲱⲟⲩⲧ.
10 Nígbà tí Paulu sì sọ̀kalẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ tì i, ó sì gbé e mọ́ra, ó ní, “Ẹ má ṣe yọ ara yín lẹ́nu; nítorí tí òun wà láààyè.”
ⲓ̅ⲁϥ⳿ⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲏⲧ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲁϥϩⲓⲧϥ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲗϫϥ ⳿ⲉϧⲏⲧϥ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲣ⳿ϣⲑⲟⲣⲧⲉⲣ ⲧⲉϥ ⲯⲩⲭⲏ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ.
11 Nígbà tí ó sì tún gòkè lọ, ó sì jẹ oúnjẹ Olúwa, ó sì sọ̀rọ̀ pẹ́ títí ó fi di àfẹ̀mọ́júmọ́, nígbà náà ni ó sì lọ.
ⲓ̅ⲁ̅⳿ⲉⲧⲁϥϣⲉ ⲇⲉ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲫⲱϣ ⳿ⲙⲡⲓⲱⲓⲕ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲉⲙϯⲡⲓ ⲁϥⲥⲱⲕ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ϣⲁⲧⲉ ⳿ⲫⲟⲩⲱⲓⲛⲓ ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
12 Wọ́n sì mú ọmọkùnrin náà lọ sílẹ̀ láààyè, inú gbogbo wọn sì dùn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
ⲓ̅ⲃ̅ⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲉϥⲱⲛϧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϭⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲉⲧⲑⲁⲧϩⲏ ⲧ ⳿ⲛⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ⲁⲛ.
13 Nígbà ti àwa sì ṣáájú, àwa sì ṣíkọ̀ lọ sì Asosi, níbẹ̀ ni a ti lérò láti gba Paulu sínú ọkọ̀: nítorí bẹ́ẹ̀ ni ó tí pinnu rẹ̀, òun tìkára rẹ̀ ń fẹ́ bá ti ọ̀nà-ẹsẹ̀ lọ.
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲁⲛⲟⲛ ⲇⲉ ⲁⲛⲁⲗⲏⲓ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲉⲡⲓϫⲟⲓ ⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉⲁⲥⲥⲟⲥ ⲉⲛⲑⲱϣ ⳿ⲉⲧⲁⲗⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲛⲉ ⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲧⲟⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲉϥⲛⲁⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲣⲁⲧϥ.
14 Nígbà tí ó sì pàdé wa ní Asosi, a gbà á sínú ọkọ̀, a sì wá sí Miletu.
ⲓ̅ⲇ̅⳿ⲉⲧⲁϥϯⲙⲁϯ ⲇⲉ ⳿ⲉⲣⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲁⲥⲥⲟⲥ ⲁⲛⲧⲁⲗⲟϥ ⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲉⲙⲓⲗⲓⲧⲓⲛⲏ.
15 Nígbà tí a sì ṣíkọ̀ kúrò níbẹ̀, ní ọjọ́ kejì a dé ọ̀kánkán Kiosi; ní ọjọ́ kejì rẹ̀ a dé Samosi, ni ọjọ́ kejì rẹ̀ a sì dé Miletu.
ⲓ̅ⲉ̅ⲡⲉϥⲣⲁⲥϯ ⲇⲉ ⲁⲛⲉⲣϩⲱⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁⲛϯⲙⲁϯ ⳿ⲙⲡⲉ⳿ⲙⲑⲟ ⳿ⲛⲭⲓⲟⲥ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲁⲣⲟⲩϩⲓ ⲇⲉ ⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲉⲥⲁⲙⲟⲥ ⲙ⳿ⲉⲛⲉⲛⲥⲱϥ ⲁⲛ⳿ⲓ ⳿ⲉⲙⲓⲗⲏⲧⲟⲥ.
16 Paulu ṣa ti pinnu rẹ̀ láti bá ọkọ̀ ojú omi kọjá sí Efesu, nítorí ki ó má ba à lo àkókò kankan ni Asia: nítorí tí ó ń yára bí yóò ṣe ṣe é ṣe fún un láti wà ní Jerusalẹmu lọ́jọ́ Pentikosti.
ⲓ̅ⲋ̅ⲛⲉ ⲁϥⲑⲱϣ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⳿ⲉⲉⲣϩⲱⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲉⲫⲉⲥⲟⲥ ϩⲟⲡⲱⲥ ϫⲉ ⳿ⲛⲛⲉϥⲱⲥⲕ ϧⲉⲛ ϯⲁⲥⲓⲁ ⲛⲁϥⲓⲏⲥ ⲅⲁⲣ ⲡⲉ ϩⲓⲛⲁ ⲓⲥϫⲉ ⲟⲩⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉϥⲉⲣ ⳿ⲡ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛϯⲡⲉⲛⲧⲏⲕⲟⲥⲧⲏϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅.
17 Ní àti Miletu ni Paulu ti ránṣẹ́ sí Efesu, láti pé àwọn alàgbà ìjọ wá sọ́dọ̀ rẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲙⲓⲗⲏⲧⲟⲥ ⲁϥⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲉⲉⲫⲉⲥⲟⲥ ⲁϥⲙⲟⲩϯ ⳿ⲉⲛⲓ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ.
18 Nígbà tí wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin tìkára yín mọ̀, láti ọjọ́ kìn-ín-ní tí mo tí dé Asia, bí mo ti bá yín gbé, ní gbogbo àkókò náà.
ⲓ̅ⲏ̅⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⲇⲉ ϣⲁⲣⲟϥ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲓⲥϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛϩⲟⲩⲓⲧ ⳿ⲉⲧⲁⲓ⳿ⲓ ⳿ⲉϯⲁⲥⲓⲁ ϫⲉ ⲁⲓϣⲱⲡⲓ ⲛⲉⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛⲁϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲥⲏⲟⲩ ⲧⲏⲣϥ.
19 Bí mo ti ń fi ìrẹ̀lẹ̀ inú gbogbo sin Olúwa, àti omijé púpọ̀, pẹ̀lú ìdánwò, tí ó bá mi, nípa rìkíṣí àwọn Júù.
ⲓ̅ⲑ̅ⲉⲓⲟⲓ ⳿ⲙⲃⲱⲕ ⳿ⲙⲠ⳪ ϧⲉⲛ ⲑⲉⲃⲓ⳿ⲟ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲉⲣⲙⲱⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲡⲓⲣⲁⲥⲙⲟⲥ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲱⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲟϭⲛⲓ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ.
20 Bí èmí kò ti fàsẹ́yìn láti sọ ohunkóhun tí ó ṣàǹfààní fún un yín, àti láti máa kọ́ ọ yín ní gbangba àti láti ilé dé ilé.
ⲕ̅⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲡⲓϩⲉⲡ ⳿ϩⲗⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲣⲛⲟϥⲣⲓ ⳿ⲛⲟⲩϣⲉⲛ ⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⳿ⲉϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲛⲱⲧⲉⲛ.
21 Tí mo ń sọ fún àwọn Júù, àti fún àwọn Giriki pẹ̀lú, ní ti ìrònúpìwàdà sí Ọlọ́run, àti ti ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi Olúwa wa.
ⲕ̅ⲁ̅ⲉⲓⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲛⲇⲏⲙⲟⲥⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⲕⲁⲧⲁ ⲏⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ ⳿ⲛϯⲙⲉⲧⲁⲛⲟⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲛⲁϩϯ ⳿ⲉⲡⲉⲛ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡⲭ̅ⲥ̅.
22 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, ẹ̀mí mi ń fà sì Jerusalẹmu, láìmọ̀ ohun tí yóò bá mi níbẹ̀.
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲟⲩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲉⲓⲥⲟⲛϩ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ϯⲛⲁϣⲉⲛⲏⲓ ⳿ⲉⲒⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅ ϯⲥⲱⲟⲩⲛ ⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲑⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲥ.
23 Bí kò ṣe bí Ẹ̀mí Mímọ́ tí ń sọ ní ìlú gbogbo pé, ìdè àti ìyà ń bẹ fún mi.
ⲕ̅ⲅ̅⳿ⲡⲗⲏⲛ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⳿ϥⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲏⲓ ⲕⲁⲧⲁ ⲡⲟⲗⲓⲥ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲥⲉⲟϩⲓ ⲛⲁⲕ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲥⲛⲁⲩϩ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛ⳿ⲑⲗⲩⲯⲓⲥ.
24 Ṣùgbọ́n èmi kò ka ọkàn mi sí nǹkan rárá bi ohun tí ó ṣọ̀wọ́n fún mi àti iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí mo tí gbà lọ́dọ̀ Jesu Olúwa, láti máa ròyìn ìyìnrere oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲇ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲧⲁⲯⲩⲭⲏ ϯⲭⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲥⲧⲁⲓⲏⲟⲩⲧ ⳿ⲛⲧⲟⲧ ϧⲉⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲛⲥⲁϫⲓ ϣⲁ ϯϫⲱⲕ ⳿ⲙⲡⲁ⳿ⲇⲣⲟⲙⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲛⲉⲙ ϯⲇⲓ⳿ⲁⲕⲟⲛⲓ⳿ⲁ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲁⲓϭⲓⲧⲥ ⳿ⲛⲧⲉⲛ Ⲡ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲩⲁⲅⲅⲉⲗⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲓ⳿ϩⲙⲟⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
25 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, èmi mọ̀ pé gbogbo yín, láàrín ẹni tí èmi tí ń wàásù ìjọba Ọlọ́run, kì yóò rí ojú mi mọ́.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲟⲩ ϩⲏⲡⲡⲉ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ϯ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲁϩⲟ ⲁⲛ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲏⲉⲧⲁⲓⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⲉⲓϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲛϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫϯ.
26 Nítorí náà mo pè yín ṣe ẹlẹ́rìí lónìí yìí pé, ọrùn mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn gbogbo.
ⲕ̅ⲋ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲁⲓ ϯⲉⲣⲙⲉⲑⲣⲉ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲁⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲫⲟⲟⲩ ϫⲉ ϯⲟⲩⲁⲃ ⳿ⲁⲛⲟⲕ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲡⲉⲧⲉⲛ⳿ⲥⲛⲟϥ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
27 Nítorí tí èmi kò fàsẹ́yìn láti sọ gbogbo ìpinnu Ọlọ́run fún un yin.
ⲕ̅ⲍ̅ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲡⲓϩⲟⲡⲧ ⳿ⲉ⳿ϣⲧⲉⲙⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉ⳿ⲫⲟⲩⲱϣ ⲧⲏⲣϥ ⳿ⲙⲪϯ.
28 Ẹ kíyèsára yin, àti sí gbogbo agbo tí Ẹ̀mí Mímọ́ fi yín ṣe alábojútó rẹ̀, láti máa tọ́jú ìjọ Ọlọ́run, tí ó tí fi ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ rà.
ⲕ̅ⲏ̅ⲙⲁϩⲑⲏⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⲛⲉⲙ ⲡⲓⲟϩⲓ ⲧⲏⲣϥ ⲉⲧ⳿ⲁ ⲡⲠⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⲉⲑⲟⲩⲁⲃ ⲭⲁ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ⲉⲡⲓⲥⲕⲟⲡⲟⲥ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲉ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛϯⲉⲕ⳿ⲕⲗⲏⲥⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ϫⲫⲟⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⲡⲉϥ⳿ⲥⲛⲟϥ ⳿ⲙⲙⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
29 Nítorí tí èmi mọ̀ pé, lẹ́yìn lílọ mi, ìkookò búburú yóò wọ àárín yín, yóò sì tú agbo ká.
ⲕ̅ⲑ̅⳿ⲁⲛⲟⲕ ⲇⲉ ϯ⳿ⲉⲙⲓ ϫⲉ ⲙⲉⲛⲉⲛⲥⲁ ⳿ⲑⲣⲓϣⲉⲛⲏⲓ ⲥⲉⲛⲁ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲟⲩⲱⲛϣ ⲉⲩϩⲟⲣϣ ⳿ⲛⲥⲉⲛⲁϯ⳿ⲁⲥⲟ ⲁⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲟϩⲓ.
30 Láàrín ẹ̀yin tìkára yín ni àwọn ènìyàn yóò sì dìde, tí wọn yóò máa sọ̀rọ̀-òdì, láti fa àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sẹ́yìn wọn.
ⲗ̅ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲛⲁⲧⲱⲟⲩⲛ ⳿ⲛϫⲉ ϩⲁⲛⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲛϩⲁⲛⲥⲁϫⲓ ⲉⲩⲫⲱⲛϩ ⲉⲑⲣⲟⲩⲥⲱⲕ ⳿ⲛⲛⲓⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲥⲁⲙⲉⲛϩⲏⲟⲩ.
31 Nítorí náà ẹ máa ṣọ́ra, ki ẹ sì máa rántí pé, fún ọdún mẹ́ta, èmi kò dẹ́kun láti máa fi omijé kìlọ̀ fún olúkúlùkù ní ọ̀sán àti ní òru.
ⲗ̅ⲁ̅ⲉⲑⲃⲉ ⲫⲁⲓ ⲟⲩⲛ ⲣⲱⲓⲥ ⳿ⲉⲣⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ϫⲉ ⲁⲓⲉⲣ ⲅ̅ϯ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲙⲡⲓ ⲭⲁⲧⲟⲧ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲉⲓϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲙ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲉⲣⲙⲱⲟⲩ⳿ⲓ.
32 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ará, mo fi yín lé Ọlọ́run lọ́wọ́ àti ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, tí ó lè gbé yín dúró, tí ó sì lè fún yín ní ìní láàrín gbogbo àwọn tí a sọ di mímọ́.
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ϯⲛⲟⲩ ϯⲭⲱ ⳿ⲙⲙⲱⲧⲉⲛ ϧⲁⲧⲉⲛ Ⲡ⳪ ⲛⲉⲙ ⳿ⲡⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥ⳿ϩⲙⲟⲧ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲑⲱϣ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϯ ⳿ⲕⲗⲏⲣⲟⲛⲟⲙⲓⲁ ϧⲉⲛ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩⲧⲟⲩⲃⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
33 Èmí kò ṣe ojúkòkòrò fàdákà, tàbí wúrà, tàbí aṣọ ẹnikẹ́ni.
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩϩⲁⲧ ⲓⲉ ⲟⲩⲛⲟⲩⲃ ⲓⲉ ⲟⲩ⳿ϩⲃⲱⲥ ⳿ⲙⲡⲓⲉⲣⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
34 Ẹ̀yin tìkára yín sá à mọ̀ pé, ọwọ́ mi wọ̀nyí ni mo fi ṣiṣẹ́ láti fi pèsè fún àìní mi, àti tí àwọn tí ó wà pẹ̀lú mi.
ⲗ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲟⲩⲛ ϫⲉ ⲛⲁϫⲓϫ ⲛⲁⲓ ⲁⲩϣⲉⲙϣⲓ ⳿ⲛⲧⲁ⳿ⲭⲣⲓⲁ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲑⲛⲉⲙⲏⲓ.
35 Nínú ohun gbogbo mo fi àpẹẹrẹ fún un yín pé, nípa ṣíṣe iṣẹ́ bẹ́ẹ̀, ó yẹ kí ẹ máa ran àwọn aláìlera lọ́wọ́, ki ẹ sì máa rántí ọ̀rọ̀ Jesu Olúwa, bí òun tìkára rẹ̀ tí wí pé, ‘Láti fún ni ní ìbùkún ju láti gbà lọ.’”
ⲗ̅ⲉ̅ⲁⲓⲧⲁⲙⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ϫⲉ ⳿ⲥϣⲉ ⳿ⲛϧⲟⲥⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲛⲧⲉⲛϯⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲏⲉⲧϣⲱⲛⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲧ⳿ⲉⲛⲉⲣ⳿ⲫⲙⲉⲩⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲡ⳪ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲁϥϫⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲙⲉⲧⲙⲁⲕⲁⲣⲓⲟⲥ ⲧⲉ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⳿ⲉϯ ⳿ⲉϩⲟⲧⲉ ⳿ⲉϭⲓ.
36 Nígbà tí ó sì tí wí nǹkan wọ̀nyí, ó kúnlẹ̀, ó sì bá gbogbo wọn gbàdúrà.
ⲗ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟⲧⲟⲩ ⲁϥϩⲓⲧϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲉϥⲕⲉⲗⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲁⲩⲉⲣⲡⲣⲟⲥⲉⲩⲭⲉⲥⲑⲉ.
37 Gbogbo wọn sì sọkún gidigidi, wọ́n sì rọ̀ mọ́ Paulu lọ́rùn, wọ́n sì fi ẹnu kò ó lẹ́nu.
ⲗ̅ⲍ̅ⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲇⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛⲣⲓⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲱⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϩⲓⲧⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⳿ⲑⲛⲁϩⲃⲓ ⳿ⲙⲡⲁⲩⲗⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϯⲫⲓ ⳿ⲉⲣⲱϥ.
38 Inú wọn sì bàjẹ́ jùlọ fún ọ̀rọ̀ tí ó sọ pé, wọn kì yóò rí ojú òun mọ́, wọ́n sì sìn ín títí dé inú ọkọ̀.
ⲗ̅ⲏ̅ⲉⲩⲟⲓ ⳿ⲛ⳿ⲙⲕⲁϩ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲙⲁⲗⲓⲥⲧⲁ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟϥ ϫⲉ ⲥⲉⲛⲁⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲁϩⲟ ⲁⲛ ϫⲉ ⲛⲁⲩ⳿ⲧⲫⲟ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓϫⲟⲓ.

< Acts 20 >