< Acts 2 >

1 Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan.
Əmdi «orma ⱨeyt» künining waⱪti-saiti toxⱪanda, bularning ⱨǝmmisi Yerusalemda bir yǝrgǝ jǝm bolƣanidi.
2 Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó.
Asmandin tuyuⱪsiz küqlük xamal soⱪⱪandǝk bir awaz anglinip, ular olturuwatⱪan ɵyni bir aldi.
3 Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn.
Ot yalⱪunidǝk tillar ularƣa kɵrünüp, ularning ⱨǝrbirining üstigǝ tarⱪilip ⱪondi.
4 Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.
Ularning ⱨǝmmisi Muⱪǝddǝs Roⱨⱪa toldurulup, Roⱨ ularƣa sɵz ata ⱪilixi bilǝn ular namǝlum tillarda sɵzligili turdi.
5 Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu.
U qaƣda, asman astidiki barliⱪ ǝllǝrdin kǝlgǝn nurƣun ihlasmǝn Yǝⱨudiy ǝrlǝrmu Yerusalemda turuwatⱪanidi.
6 Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀.
Əmdi [etiⱪadqilarning] bu awazi anglinip, top-top adǝmlǝr xu yǝrgǝ jǝm boluxti ⱨǝmdǝ [etiⱪadqilarning] ɵzliri turuxluⱪ jaydiki tillarda sɵzlixiwatⱪanliⱪini anglap, tengirⱪap ⱪelixti.
7 Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́?
Ular ⱨǝyran bolup tǝǝjjüplinip: — Ⱪaranglar, sɵzlixiwatⱪanlarning ⱨǝmmisi Galiliyǝliklǝrƣu?
8 Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀?
Ⱪandaⱪlarqǝ ularning bizning ana yurtimizdiki tillirimizda sɵzlixiwatⱪanliⱪini anglawatⱪandimiz?
9 Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia.
Arimizda Partiyalar, Medialar, Elamlar, xundaⱪla Mesopotamiyǝ, Yǝⱨudiyǝ, Kapadokiya, Pontus, Asiya,
10 Frigia, àti Pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù
Frigiyǝ ⱨǝm Pamfiliyǝ, Misir, Liwiyǝning Kurinigǝ yeⱪin jayliridin kǝlgǝnlǝr, xuningdǝk muxu yǝrdǝ musapir bolup turuwatⱪan Rim xǝⱨiridin kǝlgǝnlǝr — Yǝⱨudiylar bolsun, Tǝwrat etiⱪadiƣa kirgǝnlǝr bolsun, Kretlar wǝ Ərǝblǝr bolsun, ⱨǝmmimiz ularning Hudaning ⱪilƣan uluƣ ǝmǝllirini bizning ana tillirimizda sɵzlǝwatⱪanliⱪini anglawatimiz! — deyixti.
11 (àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.”
12 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”
Ular ⱨang-tang ⱪelip alaⱪzadilik bilǝn bir-birigǝ: — Bu zadi ⱪandaⱪ ixtu? — deyixti.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.
Əmma bǝzilǝr: — Bular yengi xarab bilǝn obdanla mǝst bolup ⱪaptu! — dǝp mǝshirǝ ⱪilixti.
14 Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi.
Əmma Petrus ⱪalƣan on birǝylǝn bilǝn ornidin turup, awazini kɵtürüp kɵpqilikkǝ mundaⱪ dedi: — Əy Yǝⱨudiyǝdikilǝr wǝ Yerusalemda barliⱪ turuwatⱪanlar! Bu ix silǝrgǝ mǝlum bolƣayki, sɵzlirimgǝ ⱪulaⱪ selinglar!
15 Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí.
Bular silǝr oyliƣandǝk mǝst ǝmǝs, qünki ⱨazir pǝⱪǝt ǝtigǝn saǝt toⱪⱪuz boldi.
16 Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joẹli wá pé:
Əmǝliyǝttǝ bu dǝl Yoel pǝyƣǝmbǝr arⱪiliⱪ aldin eytilƣan xu ixtur:
17 “Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́, Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran, àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá,
— «Huda mundaⱪ dedi: «Mǝn ahirⱪi künlǝrdǝ Ɵz Roⱨimni barliⱪ ǝt igiliri üstigǝ ⱪuyimǝn; Silǝrning oƣul-ⱪizliringlar wǝⱨiylik bexarǝt yǝtküzidu, Silǝrning yigitliringlar ƣayibanǝ alamǝt kɵrünüxlǝrni kɵridu; Silǝrning ⱪeriliringlar alamǝt qüxlǝrni kɵridu;
18 àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin, ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀.
Bǝrⱨǝⱪ, xu künlǝrdǝ ⱪullirim üstigimu, dedǝklirim üstigimu Roⱨimni ⱪuyimǝn, ular bexarǝt yǝtküzidu.
19 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run, àti àwọn àmì nísàlẹ̀ ilẹ̀; ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;
Mǝn yuⱪirida asmanlarda karamǝt ixlar, tɵwǝndǝ, zeminda mɵjizilik alamǝtlǝrni, Ⱪan, ot, is-tütǝk tüwrüklirini kɵrsitimǝn.
20 A ó sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.
Rǝbning uluƣ ⱨǝm karamǝt-xǝrǝplik küni bolmiƣuqǝ, Ⱪuyax ⱪarangƣuluⱪⱪa, Ay ⱪanƣa aylandurulidu.
21 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’
Ⱨǝm xu qaƣda xundaⱪ ǝmǝlgǝ axuruliduki, Rǝbning namini qaⱪirip nida ⱪilƣanlarning ⱨǝmmisi ⱪutⱪuzulidu».
22 “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti àmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú.
Əy Israillar, muxu sɵzlǝrni anglanglar. Nasarǝtlik Əysa bolsa, Huda aranglarda u arⱪiliⱪ kɵrsǝtkǝn ⱪudrǝtlik ǝmǝllǝr, karamǝtlǝr wǝ mɵjizilik alamǝtlǝr bilǝn silǝrgǝ tǝstiⱪliƣan bir zat — bu ixlar ⱨǝmminglarƣa mǝlum —
23 Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, tí a sì pa á pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú, a kàn mọ́ àgbélébùú.
u kixi Hudaning bekitkǝn mǝⱪsiti wǝ aldin’ala bilixi boyiqǝ satⱪunluⱪⱪa uqrap tutup berilgǝndin keyin, silǝr uni Tǝwrat ⱪanunisiz yürgǝn adǝmlǝrning ⱪoli arⱪiliⱪ krestlǝp ɵltürgüzdünglar.
24 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú, nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú.
Lekin Huda uni ɵlümning azablarning ilkidin azad ⱪilip ⱪayta tirildürdi. Qünki ɵlümning uni tutⱪun ⱪilixi ⱨǝrgiz mumkin ǝmǝs.
25 Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé: “‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí, nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi, a kì ó ṣí mi ní ipò.
Dawut [Zǝburda] u toƣruluⱪ mundaⱪ aldin eytⱪan: «Mǝn Pǝrwǝrdigarni ⱨǝrdaim kɵz aldimda kɵrüp keliwatimǝn; U ong yenimda bolƣaqⱪa, Mǝn ⱨǝrgiz tǝwrǝnmǝymǝn.
26 Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.
Xunga mening ⱪǝlbim huxallandi, Mening tilim xadlinip yayridi; Mening tenim ümid-arzu iqidǝ turidu;
27 Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs g86)
Qünki Sǝn jenimni tǝⱨtisarada ⱪaldurmaysǝn, Xundaⱪla Sening Muⱪǝddǝs Bolƣuqungƣa qirixlǝrni kɵrgüzmǝysǝn. (Hadēs g86)
28 Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè, ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’
Sǝn manga ⱨayat yollirini kɵrsǝtkǝnsǝn; Ⱨuzurung bilǝn meni xad-huramliⱪⱪa tolup taxⱪuzisǝn».
29 “Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí.
Ⱪerindaxlar, mǝn atimiz [padixaⱨ] Dawut toƣruluⱪ ⱨeq ikkilǝnmǝy xuni eytimǝnki, u ɵldi wǝ uning ⱪǝbrisi bügünki küngiqǝ arimizda bar.
30 Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
Əmdi u pǝyƣǝmbǝr bolup, Hudaning uning tǝhtigǝ olturuxⱪa ɵz puxtidin birǝylǝnni turƣuzuxⱪa ⱪǝsǝm bilǝn wǝdǝ bǝrgǝnlikini bilǝtti.
31 Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs g86)
U Mǝsiⱨning [ɵlgǝndin keyin] tirildürülidiƣinini aldin’ala kɵrüp yǝtkǝn wǝ bu munasiwǝt bilǝn Mǝsiⱨning tǝⱨtisarada ⱪaldurulmaydiƣinini wǝ tenining qirimǝydiƣinini tilƣa alƣan. (Hadēs g86)
32 Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí.
Huda dǝl bu Əysani ɵlümdin tirildürdi, wǝ ⱨǝmmimiz bu ixning guwaⱨqilirimiz.
33 A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta.
U Hudaning ong yenida xan-xǝrǝp iqidǝ olturƣuzulup, xundaⱪla Ata wǝdǝ ⱪilƣan Muⱪǝddǝs Roⱨni ⱪobul ⱪilip, ⱨazir kɵrüwatⱪan ⱨǝm anglawatⱪanliringlarni tɵküp [bizlǝrgǝ] qüxürdi.
34 Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé, “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
Qünki Dawut ɵzi ǝrxkǝ qiⱪⱪan ǝmǝs; lekin u munu sǝzlǝrni [Zǝburda] eytⱪan: — «Pǝrwǝrdigar mening Rǝbbimgǝ eyttiki: — «Mǝn sening düxmǝnliringni tǝhtipǝring ⱪilmiƣuqǝ, Mening ong yenimda olturƣin!»».
35 títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.”’
36 “Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé, Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”
Xuning üqün, pütkül Israil jǝmǝtidikilǝr xuni ⱪǝt’iy bilsunki, Huda silǝr krestligǝn dǝl uxbu Əysani ⱨǝm Rǝb ⱨǝm Mǝsiⱨ ⱪilip tiklidi!».
37 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”
Bu sɵzlǝr angliƣanlarning yürikigǝ sanjilƣandǝk ⱪattiⱪ tǝgkǝn bolup ular Petrus wǝ baxⱪa rosullardin: — I ⱪerindaxlar, undaⱪta biz nemǝ ⱪiliximiz kerǝk? — dǝp soraxti.
38 Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́.
Petrus ularƣa: — Towa ⱪilinglar, ⱨǝrbiringlar Əysa Mǝsiⱨning namida gunaⱨliringlarning kǝqürüm ⱪilinixi üqün qɵmüldürüxni ⱪobul ⱪilinglar wǝ xundaⱪ ⱪilsanglar Hudaning iltipati bolƣan Muⱪǝddǝs Roⱨ silǝrgǝ ata ⱪilinidu.
39 Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”
Qünki bu wǝdǝ silǝrgǝ wǝ silǝrning baliliringlarƣa, yiraⱪta turuwatⱪanlarning ⱨǝmmisigǝ, yǝni Pǝrwǝrdigar Hudayimiz ɵzigǝ qaⱪirƣanlarning ⱨǝmmisigǝ ata ⱪilinidu.
40 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.”
Petrus yǝnǝ nurƣun baxⱪa sɵzlǝr bilǝn ularni agaⱨlandurup ularƣa: — Silǝr ɵzünglarni bu iplas dǝwrdin ⱪutⱪuzunglar! — dǝp jekilidi.
41 Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.
Xuning bilǝn uning sɵzini ⱪobul ⱪilƣanlar qɵmüldürülüxti. Xu küni [jamaǝtkǝ] ⱪoxulƣanlar üq mingqǝ kixi idi.
42 Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà.
Ular ɵzlirini izqil ⱨalda rosullarning tǝlimigǝ, [etiⱪadqilarning] birlik-ⱨǝmdǝmlikigǝ, nanni oxtuxⱪa wǝ dualarƣa beƣixlidi.
43 Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe.
Wǝ ⱪorⱪunq ularning ⱨǝrbirining üstigǝ qüxti wǝ rosullarning wasitisi bilǝn nurƣun karamǝtlǝr wǝ mɵjizilik alamǝtlǝr yüz bǝrdi.
44 Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn;
Pütün etiⱪadqilar dawamliⱪ jǝm bolup billǝ yaxap, barliⱪini ortaⱪ tutuxti.
45 Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí.
Ular mal-mülüklirini setip, pulini ⱨǝrkimning eⱨtiyajiƣa ⱪarap ⱨǝmmisigǝ tǝⱪsim ⱪilixatti.
46 Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn.
Ular ⱨǝr küni ibadǝthana ⱨoylisiƣa bir niyǝttǝ jǝm boluxatti, ɵy-ɵylǝrdǝ huxal-huramliⱪ wǝ aⱪ kɵngüllük bilǝn ortaⱪ ƣizalinixip, nanni oxtup yeyixip,
47 Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.
Hudaƣa mǝdⱨiyǝ oⱪuxatti; ular pütkül halayiⱪning izzitigǝ sazawǝr boldi. Rǝb ⱨǝr küni ⱪutⱪuzuluwatⱪanlarni jamaǝtkǝ ⱪoxatti.

< Acts 2 >