< Acts 2 >
1 Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan.
Când a sosit ziua Cincizecimii, erau toți la un loc, deodată, în același loc.
2 Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó.
Deodată s-a auzit din cer un zgomot ca un vuiet de vânt puternic, care a umplut toată casa în care stăteau.
3 Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn.
Au apărut limbi ca de foc și li s-au împărțit, și câte una s-a așezat pe fiecare dintre ei.
4 Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.
Cu toții au fost umpluți de Duhul Sfânt și au început să vorbească în alte limbi, după cum le dădea Duhul să vorbească.
5 Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu.
În Ierusalim locuiau iudei evrei, oameni evlavioși, din toate neamurile de sub cer.
6 Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀.
Când s-a auzit acest sunet, mulțimea s-a adunat și a rămas nedumerită, pentru că fiecare îi auzea vorbind în limba lui.
7 Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́?
Toți erau uimiți și se mirau, spunându-și unii altora: “Iată, oare nu sunt galileeni toți aceștia care vorbesc?
8 Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀?
Cum îi auzim, fiecare în limba sa maternă?
9 Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia.
Parțieni, medi, elamiți și oameni din Mesopotamia, Iudeea, Capadocia, Pont, Asia,
10 Frigia, àti Pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù
Frigia, Pamfilia, Egipt, părțile Libiei din jurul Cirenei, vizitatori din Roma, atât evrei cât și prozeliți,
11 (àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.”
cretani și arabi — noi îi auzim vorbind în limbile noastre despre lucrările mărețe ale lui Dumnezeu!”
12 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”
Toți au rămas uimiți și perplecși, spunându-și unii altora: “Ce înseamnă aceasta?”
13 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.
Alții, batjocorind, spuneau: “Sunt plini de vin nou”.
14 Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi.
Dar Petru, stând în picioare cu cei unsprezece, a ridicat glasul și le-a zis: “Bărbați din Iudeea și voi toți cei ce locuiți la Ierusalim, să vă fie cunoscut lucrul acesta și ascultați cuvintele mele.
15 Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí.
Căci aceștia nu sunt beți, așa cum credeți voi, întrucât este abia al treilea ceas al zilei.
16 Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joẹli wá pé:
Ci iată ce s-a spus prin profetul Ioel:
17 “Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́, Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran, àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá,
“Așa va fi în zilele de pe urmă, zice Dumnezeu, că Îmi voi revărsa Duhul Meu peste toată făptura. Fiii și fiicele voastre vor profeți. Tinerii tăi vor avea viziuni. Bătrânii tăi vor visa vise.
18 àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin, ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀.
Și pe robii mei și pe roabele mele în zilele acelea, Voi revărsa Duhul Meu și ei vor profeți.
19 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run, àti àwọn àmì nísàlẹ̀ ilẹ̀; ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;
Voi face minuni pe cerul de sus, și semne pe pământul de dedesubt: sânge, foc și valuri de fum.
20 A ó sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.
Soarele se va preface în întuneric, și luna în sânge, înainte ca ziua cea mare și glorioasă a Domnului să vină.
21 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’
Oricine va invoca Numele Domnului va fi mântuit.
22 “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti àmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú.
“Bărbați ai lui Israel, ascultați aceste cuvinte! Pe Isus din Nazaret, un om aprobat de Dumnezeu pentru voi prin fapte puternice, minuni și semne pe care Dumnezeu le-a făcut prin el printre voi, după cum știți voi înșivă,
23 Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, tí a sì pa á pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú, a kàn mọ́ àgbélébùú.
pe El, care a fost predat prin sfatul hotărât și prin știința mai dinainte a lui Dumnezeu, L-ați prins prin mâna unor oameni fără de lege, L-ați răstignit și L-ați ucis;
24 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú, nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú.
pe care Dumnezeu L-a înviat, eliberându-L de agonia morții, pentru că nu era cu putință ca El să fie ținut de ea.
25 Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé: “‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí, nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi, a kì ó ṣí mi ní ipò.
Căci David spune despre El: “Nu este posibil să fi fost învins de Dumnezeu, pentru că nu era cu putință să fie învins, 'Îl vedeam pe Domnul mereu înaintea feței mele, Căci El este la dreapta mea, ca să nu mă clatin.
26 Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.
De aceea inima mea s-a bucurat și limba mea s-a veselit. Mai mult, și carnea mea va locui în speranță,
27 Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs )
pentru că nu vei lăsa sufletul meu în Locuința morților, nici nu vei permite ca Sfântul tău să vadă putreziciunea. (Hadēs )
28 Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè, ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’
Tu mi-ai făcut cunoscute căile vieții. Mă vei umple de bucurie cu prezența ta.
29 “Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí.
“Fraților, pot să vă spun, în mod liber, despre patriarhul David, că a murit și a fost îngropat, iar mormântul lui este la noi până în ziua de azi.
30 Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
De aceea, fiind profet și știind că Dumnezeu îi jurase cu jurământ că din rodul trupului său, după trup, va ridica pe Hristos ca să șadă pe tronul său,
31 Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs )
el, prevăzând acest lucru, a vorbit despre învierea lui Hristos, că sufletul lui nu a rămas în Hades și că trupul lui nu a văzut putrezirea. (Hadēs )
32 Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí.
Acest Isus pe care Dumnezeu l-a înviat, despre care noi toți suntem martori.
33 A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta.
De aceea, fiind înălțat la dreapta lui Dumnezeu și primind de la Tatăl făgăduința Duhului Sfânt, a revărsat ceea ce vedeți și auziți acum.
34 Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé, “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
Căci David nu s-a înălțat la ceruri, ci el însuși spune, 'Domnul a zis Domnului meu: “Șezi la dreapta Mea.
35 títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.”’
până când voi face din vrăjmașii tăi un tăpșan pentru picioarele tale.”
36 “Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé, Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”
“Să știe deci toată casa lui Israel că Dumnezeu a făcut Domn și Hristos pe acest Isus pe care voi L-ați răstignit.”
37 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”
Auzind acestea, s-au cutremurat și au zis lui Petru și celorlalți apostoli: “Fraților, ce să facem?”
38 Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́.
Petru le-a zis: “Pocăiți-vă și fiecare dintre voi să fie botezat în numele lui Isus Hristos, pentru iertarea păcatelor, și veți primi darul Duhului Sfânt.
39 Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”
Căci făgăduința este pentru voi și pentru copiii voștri și pentru toți cei de departe, pentru toți cei pe care îi va chema la sine Domnul Dumnezeul nostru.”
40 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.”
Cu multe alte cuvinte a dat mărturie și i-a îndemnat, zicând: “Salvați-vă de acest neam strâmb!”.
41 Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.
Și cei ce au primit cu bucurie cuvântul Lui au fost botezați. În ziua aceea s-au adăugat în jur de trei mii de suflete.
42 Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà.
Ei stăruiau cu stăruință în învățătura apostolilor și în părtășia cu ei, în frângerea pâinii și în rugăciune.
43 Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe.
Înfricoșarea a cuprins fiecare suflet, și multe minuni și semne se făceau prin apostoli.
44 Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn;
Toți cei care credeau erau împreună și aveau toate lucrurile în comun.
45 Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí.
Își vindeau averile și bunurile și le împărțeau la toți, după cum avea cineva nevoie.
46 Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn.
Zi de zi, stăruind cu stăruință și de comun acord în templu și frângând pâinea acasă, își luau hrana cu bucurie și cu inimă curată,
47 Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.
lăudând pe Dumnezeu și având parte de bunăvoința întregului popor. Domnul adăuga zi de zi la adunare pe cei care erau salvați.