< Acts 2 >

1 Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan.
A gdy przyszedł dzień pięćdziesiąty, byli wszyscy jednomyślnie pospołu.
2 Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó.
Tedy się stał z prędka z nieba szum, jakoby przypadającego wiatru gwałtownego i napełnił wszystek dom, kędy siedzieli.
3 Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn.
I ukazały się im rozdzielone języki na kształt ognia, który usiadł na każdym z nich.
4 Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.
I napełnieni są wszyscy Duchem Świętym, a poczęli mówić innemi językami, jako im Duch on dawał wymawiać.
5 Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu.
A byli w Jeruzalemie mieszkający Żydowie, mężowie nabożni, z każdego narodu tych, którzy są pod niebem.
6 Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀.
A gdy się stał ten głos, zeszło się mnóstwo ludzi i strwożyli się, że je słyszał każdy z nich mówiące własnym językiem swoim.
7 Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́?
I zdumiewali się wszyscy, i dziwowali się, mówiąc jedni do drugich: Izali oto ci wszyscy, którzy mówią, nie są Galilejczycy?
8 Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀?
A jakoż my od nich słyszymy każdy z nas swój własny język, w którymeśmy się urodzili?
9 Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia.
Partowie i Medowie, i Elamitowie, i którzy mieszkamy w Mezopotamii, w Judzkiej ziemi, i w Kapadocyi, w Poncie, i w Azyi;
10 Frigia, àti Pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù
W Frygii, i w Pamfilii, w Egipcie, i w stronach Libii, która jest podle Cyreny, i przychodniowie Rzymscy; Żydowie, i nowonawróceni;
11 (àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.”
Kreteńczycy, i Arabczycy; słyszymy ich, mówiących językami naszemi wielkie sprawy Boże.
12 Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”
I zdumiewali się wszyscy, i dziwowali się, mówiąc jeden do drugiego: Cóż to wżdy ma być?
13 Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.
Lecz drudzy naśmiewając się, mówili: Ci się młodem winem popili.
14 Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi.
A stanąwszy Piotr z jedenastoma, podniósł głos swój i przemówił do nich: Mężowie Judzcy i wszyscy, którzy mieszkacie w Jeruzalemie! niech wam to jawno będzie, a przyjmijcie w uszy słowa moje.
15 Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí.
Albowiem nie są ci, jako wy mniemacie, pijani, gdyż dopiero jest trzecia na dzień godzina.
16 Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joẹli wá pé:
Aleć to jest ono, co przepowiedziano przez proroka Joela:
17 “Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́, Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran, àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá,
I będzie w ostateczne dni, (mówi Bóg): Wyleję z Ducha mego na wszelkie ciało, a prorokować będą synowie wasi i córki wasze, a młodzieńcy wasi widzenia widzieć będą, a starcom waszym sny się śnić będą.
18 àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin, ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀.
Nawet w oneż dni na sługi moje i na służebnice moje wyleję z Ducha mego, i będą prorokować;
19 Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run, àti àwọn àmì nísàlẹ̀ ilẹ̀; ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;
I ukażę cuda na niebie w górze i znamiona na ziemi nisko, krew, i ogień, i parę dymu.
20 A ó sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.
Słońce się obróci w ciemność, a księżyc w krew, przedtem niż przyjdzie on dzień Pański wielki i znaczny.
21 Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’
I stanie się, że ktobykolwiek wzywał imienia Pańskiego, zbawion będzie.
22 “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti àmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú.
Mężowie Izraelscy! słuchajcie słów tych Jezusa, onego Nazareńskiego, męża od Boga wsławionego u was mocami i cudami, i znamionami, które czynił Bóg przez niego w pośrodku was, jako i wy sami wiecie;
23 Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, tí a sì pa á pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú, a kàn mọ́ àgbélébùú.
Tego za ułożoną radą i przejrzeniem Bożem wydanego wziąwszy, a przez ręce niezbożników ukrzyżowawszy, zabiliście.
24 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú, nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú.
Którego Bóg wzbudził, rozwiązawszy boleści śmierci, jakoż było to niepodobne, aby od niej miał być zatrzymany.
25 Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé: “‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí, nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi, a kì ó ṣí mi ní ipò.
Albowiem o nim mówi Dawid: Upatrywałem zawsze Pana przed obliczem mojem; bo mi jest po prawicy, abym nie był wzruszony.
26 Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.
Przetoż rozweseliło się serce moje i rozradował się język mój, nadto i ciało moje odpocznie w nadziei;
27 Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs g86)
Albowiem nie zostawisz duszy mojej w piekle, a nie dasz świętemu twojemu oglądać skażenia. (Hadēs g86)
28 Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè, ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’
Oznajmiłeś mi drogi żywota, a napełnisz mię radością przed obliczem twojem.
29 “Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí.
Mężowie bracia! mogę bezpiecznie mówić do was o patryjarsze Dawidzie, żeć umarł i pogrzebiony jest, a grób jego jest u nas aż do dnia dzisiejszego.
30 Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
Będąc tedy prorokiem i wiedząc, że mu się Bóg obowiązał przysięgą, iż z owocu biódr jego według ciała miał wzbudzić Chrystusa, a posadzić na stolicy jego.
31 Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs g86)
To przeglądając, powiedział o zmartwychwstaniu Chrystusowem, iż nie została dusza jego w piekle, ani ciało jego widziało skażenia. (Hadēs g86)
32 Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí.
Tegoć Jezusa wzbudził Bóg, czego my wszyscy jesteśmy świadkami.
33 A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta.
Prawicą tedy Bożą będąc wywyższony, a obietnicę Ducha Świętego wziąwszy od Ojca, wylał to, co wy teraz widzicie i słyszycie.
34 Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé, “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
Albowiemci Dawid nie wstąpił do nieba, lecz sam powiada: Rzekł Pan Panu memu, siądź po prawicy mojej,
35 títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.”’
Aż położę nieprzyjacioły twoje podnóżkiem nóg twoich.
36 “Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé, Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”
Niechajże tedy wie zapewne wszystek dom Izraelski, że go Bóg i Panem, i Chrystusem uczynił, tego Jezusa, któregoście wy ukrzyżowali.
37 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”
A to słysząc, przerażeni są na sercu i rzekli do Piotra i do innych Apostołów: Cóż mamy czynić, mężowie bracia?
38 Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́.
Tedy Piotr rzekł do nich: Pokutujcie, a ochrzcij się każdy z was w imieniu Jezusa Chrystusa na odpuszczenie grzechów, a weźmiecie dar Ducha Świętego.
39 Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”
Albowiemci wam ta obietnica należy i dziatkom waszym, i wszystkim, którzy daleko są, którekolwiek by powołał Pan, Bóg nasz.
40 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.”
I wielą inszych słów oświadczał się i napominał je, mówiąc: Wyzwólcie się od tego rodzaju przewrotnego.
41 Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.
Którzy tedy wdzięcznie przyjęli słowa jego, ochrzczeni są i przystało dnia onego dusz około trzech tysięcy.
42 Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà.
I trwali w nauce apostolskiej i w społeczności, i w łamaniu chleba, i w modlitwach.
43 Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe.
I przyszedł strach na każdą duszę, a wiele się znamion i cudów przez Apostołów działo.
44 Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn;
A wszyscy, którzy uwierzyli byli pospołu, i wszystkie rzeczy mieli spólne.
45 Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí.
A osiadłości i majętności sprzedawali, i udzielali ich wszystkim, jako komu było potrzeba.
46 Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn.
A na każdy dzień trwając zgodnie w kościele i chleb łamiąc po domach, przyjmowali pokarm z radością i w prostocie serdecznej.
47 Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.
Chwaląc Boga i mając łaskę u wszystkiego ludu. A Pan przydawał zborowi na każdy dzień tych, którzy mieli być zbawieni.

< Acts 2 >