< Acts 19 >
1 Nígbà ti Apollo wà ni Kọrinti, ti Paulu kọjá lọ sí apá òkè ìlú, ó sì wá sí Efesu, o sì rí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kan;
I stało się, gdy Apollos był w Koryncie, iż Paweł obszedłszy górne krainy, przyszedł do Efezu; a znalazłszy tam niektórych uczniów,
2 o wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ha gba Ẹ̀mí Mímọ́ náà nígbà tí ẹ̀yin gbàgbọ́?” Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò gbọ́ rárá pé Ẹ̀mí Mímọ́ kan wà.”
Rzekł do nich: Izaliście wzięli Ducha Świętego, uwierzywszy? A oni mu rzekli: Owszemeśmy ani słyszeli, jeźli jest Duch Święty.
3 Ó sì wí pé, “Ǹjẹ́ irú bamitiisi wo ni a bamitiisi yín sí?” Wọ́n sì wí pé, “Sí bamitiisi tí Johanu.”
Tedy rzekł do nich: W cóżeście tedy ochrzczeni? A oni rzekli: W chrzest Janowy.
4 Paulu sí wí pé, “Nítòótọ́, ní Johanu fi bamitiisi tí ìrònúpìwàdà bamitiisi, ó ń wí fún àwọn ènìyàn pé, kí wọ́n gba ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn òun gbọ́, èyí sì ni Kristi Jesu.”
Zatem rzekł Paweł: Janci chrzcił chrztem pokuty, mówiąc ludowi, aby w onego, który miał przyjść po nim, uwierzyli, to jest w Jezusa Chrystusa.
5 Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, a bamitiisi wọn lórúkọ Jesu Olúwa.
A usłyszawszy to, ochrzczeni są w imię Pana Jezusowe.
6 Nígbà tí Paulu sì gbé ọwọ́ lé wọn, Ẹ̀mí Mímọ́ sì bà lé wọn, wọ́n sì ń fọ́ èdè mìíràn, wọ́n sì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀.
A gdy na nie włożył Paweł ręce, zstąpił na nie Duch Święty i mówili językami i prorokowali.
7 Iye àwọn ọkùnrin náà gbogbo tó méjìlá.
A było wszystkich mężów około dwunastu.
8 Nígbà tí ó sì wọ inú Sinagọgu lọ ó fi ìgboyà sọ̀rọ̀ ni oṣù mẹ́ta, ó ń fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀, ó sì ń yí wọn lọ́kàn padà sí nǹkan tí i ṣe tí ìjọba Ọlọ́run.
A wszedłszy do bóżnicy, mówił bezpiecznie przez trzy miesiące, nauczając i namawiając ich do królestwa Bożego.
9 Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn àwọn mìíràn nínú wọn di líle, tí wọn kò sì gbàgbọ́, tí wọn ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọ̀nà náà níwájú ìjọ ènìyàn, ó lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì ya àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sọ́tọ̀, ó sì ń sọ àsọyé lójoojúmọ́ ni ilé ìwé Tirannusi.
A gdy się niektórzy zatwardzili, a wierzyć nie chcieli, źle mówiąc o tej drodze Bożej przed mnóstwem, odstąpiwszy od nich, odłączył ucznie, na każdy dzień ucząc w szkole niektórego Tyranna.
10 Èyí n lọ bẹ́ẹ̀ fún ìwọ̀n ọdún méjì; tó bẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn tí ń gbé Asia gbọ́ ọ̀rọ̀ Jesu Olúwa, àti àwọn Júù àti àwọn Giriki.
A to się działo przez dwa lata, tak iż wszyscy, którzy mieszkali w Azyi, słuchali słowa Pana Jezusowego, tak Żydowie, jako i Grekowie.
11 Ọlọ́run sì tí ọwọ́ Paulu ṣe àwọn àkànṣe iṣẹ́ ìyanu,
A nie lada cuda czynił Bóg przez ręce Pawłowe;
12 tó bẹ́ẹ̀ tí a fi ń mú aṣọ àti aṣọ ìnuwọ́ rẹ̀ tọ àwọn ọlọkùnrùn lọ, ààrùn sì fi wọ́n sílẹ̀, àwọn ẹ̀mí búburú sì jáde kúrò lára wọn.
Tak iż na chore przynoszono chustki albo przepaski od ciała jego, i odchodziły od nich choroby, i duchowie źli wychodzili z nich.
13 Ṣùgbọ́n àwọn Júù kan n lọ káàkiri láti máa le ẹ̀mí èṣù jáde, wọn dáwọ́lé àdábọwọ́ ara wọn, láti pé orúkọ Jesu Olúwa sí àwọn tí ó ni ẹ̀mí búburú, wí pé, “Àwa fi orúkọ Jesu tí Paulu ń wàásù fi yín bú.”
Tedy niektórzy z biegunów żydowskich, którzy się bawili zaklinaniem, ważyli się wzywać imienia Pana Jezusowego nad tymi, którzy mieli duchy złe, mówiąc: Poprzysięgamy was przez Jezusa, którego Paweł opowiada.
14 Àwọn méje kan sì wà, tí wọn ń ṣe bẹ́ẹ̀, àwọn ọmọ ẹnìkan tí a ń pè ni Sikẹfa, tí í ṣe olórí àlùfáà gíga láàrín àwọn Júù.
A było ich siedm synów jednego Żyda, imieniem Scewas, najwyższego kapłana, którzy to czynili.
15 Ẹ̀mí búburú náà sì dáhùn, ó ní “Jesu èmi mọ̀ ọ́n, mo sì mọ Paulu pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin?”
Tedy odpowiedziawszy duch zły, rzekł: Znam Jezusa i wiem co Paweł; ale wy coście zacz?
16 Nígbà tí ọkùnrin tí ẹ̀mí búburú náà wà lára rẹ̀ sì fò mọ́ wọn, ó pa kúúrù mọ́ wọn, ó sì borí wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sá jáde kúrò ní ilé náà ní ìhòhò pẹ̀lú ni ìfarapa.
A rzuciwszy się na nie człowiek on, w którym był duch zły, a opanowawszy je, zmocnił się przeciwko nim, tak iż nadzy i zranieni wybiegli z onego domu.
17 Ìròyìn yìí sì di mí mọ̀ fún gbogbo àwọn Júù àti àwọn ará Giriki pẹ̀lú tí ó ṣe àtìpó ní Efesu; ẹ̀rù sì ba gbogbo wọn, a sì gbé orúkọ Jesu Olúwa ga.
I było to wiadomo wszystkim, i Żydom i Grekom, którzy mieszkali w Efezie; i przypadł strach na nie wszystkie, i było uwielbione imię Pana Jezusowe.
18 Ọ̀pọ̀ àwọn tí wọ́n gbàgbọ́ sì wá, wọ́n jẹ́wọ́, wọ́n sì fi iṣẹ́ wọn hàn.
A wiele tych, którzy uwierzyli, przychodziło, wyznawając i oznajmując sprawy swoje.
19 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn tí ń ṣe alálúpàyídà ni ó kó ìwé wọn jọ, wọ́n dáná sun wọ́n lójú gbogbo ènìyàn. Wọ́n sì ṣírò iye wọn, wọ́n sì rí i, ó jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ìwọ̀n fàdákà.
I wiele z tych, którzy się naukami niepotrzebnemi parali, zniósłszy księgi, spalili je przed wszystkimi, a obrachowawszy cenę ich, znaleźli tego pięćdziesiąt tysięcy srebrników.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ Olúwa gbèrú tí o sí gbilẹ̀ si í gidigidi.
Tak potężnie rosło słowo Pańskie i zmacniało się.
21 Ǹjẹ́ bí nǹkan wọ̀nyí tí parí tan, Paulu pinnu nínú ọkàn rẹ̀ pé, nígbà tí òun bá kọjá ní Makedonia àti Akaia, òun ó lọ sí Jerusalẹmu, ó wí pé, “Lẹ́yìn ìgbà tí mo bá dé ibẹ̀, èmi kò lè ṣàìmá dé Romu pẹ̀lú.”
A gdy się to dokonało, postanowił Paweł w duchu, aby przeszedłszy Macedoniję i Achaję, szedł do Jeruzalemu, mówiąc: Iż potem, gdy tam będę, muszę i Rzym widzieć.
22 Nígbà tí ó sì tí rán méjì nínú àwọn tí ń ṣe ìránṣẹ́ fún un lọ sí Makedonia, Timotiu àti Erastu, òun tìkára rẹ̀ dúró díẹ̀ ní ilẹ̀ Asia.
A posławszy do Macedonii dwóch z tych, którzy mu służyli, Tymoteusza i Erasta, sam do czasu został w Azyi.
23 Ní àkókò náà ìrúkèrúdò díẹ̀ kan wà nítorí ọ̀nà náà.
A pod on czas stał się rozruch niemały około drogi Bożej.
24 Nítorí ọkùnrin kan tí a ń pè ní Demetriusi, alágbẹ̀dẹ fàdákà, tí o máa ń fi fàdákà ṣe ilé òrìṣà fún Artemisi, ó mú ère tí kò mọ níwọ̀n wá fún àwọn oníṣọ̀nà.
Albowiem niektóry złotnik, imieniem Demetryjusz, który robił kościoły srebrne Dyjany, niemały zysk przywodził rzemieślnikom;
25 Nígbà tí ó pè wọ́n jọ, àti irú àwọn oníṣẹ́-ọnà bẹ́ẹ̀, ó wí pé, “Alàgbà, ẹ̀yin mọ̀ pé nípa iṣẹ́ ọnà yìí ni àwa fi ní ọrọ̀ wa.
Które zgromadziwszy i inne, którzy takież rzemiosło robili, rzekł: Mężowie! wiecie, iż z tego rzemiosła mamy dostatki nasze.
26 Ẹ̀yin sì rí i, ẹ sì gbọ́ pé, kì í ṣe ni Efesu nìkan ṣoṣo ni, ṣùgbọ́n ó fẹ́rẹ jẹ́ gbogbo Asia ni Paulu yìí ń yí ọ̀pọ̀ ènìyàn lọ́kàn padà, tí ó sì ń dárí wọn wí pé, ohun tí a fi ọwọ́ ṣe, kì í ṣe Ọlọ́run.
A widzicie i słyszycie, że nie tylko w Efezie, ale mało nie po wszystkiej Azyi ten Paweł namówił i odwrócił wielki lud, mówiąc: Że to nie są bogowie, którzy są rękami uczynieni.
27 Kì í sì ṣe pé kìkì iṣẹ́ ọnà wa yìí ni ó wà nínú ewu dídí asán; ṣùgbọ́n tẹmpili Artemisi òrìṣà ńlá yóò di gígàn pẹ̀lú, àti gbogbo ọláńlá rẹ̀ yóò sì run, ẹni tí gbogbo Asia àti gbogbo ayé ń bọ.”
Przetoż nam się obawiać potrzeba, aby nie tylko rzemiosło nasze w lekkie poważenie nie przyszło, ale aby i kościół wielkiej bogini Dyjany za nic nie był poczytany, a żeby nie przyszło do skazy dostojeństwo jej, którą wszystka Azyja i wszystek świat chwali.
28 Nígbà tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, wọ́n kún fún ìbínú, wọ́n kígbe, wí pé, “Òrìṣà ńlá ni Artemisi ti ará Efesu!”
A słuchając tego i będąc pełni gniewu, krzyknęli, mówiąc: Wielka jest Dyjana Efeska!
29 Gbogbo ìlú náà sì kún fún ìrúkèrúdò: wọ́n sì fi ọkàn kan rọ́ wọn sí inú ilé ìṣeré, wọ́n sì mú Gaiusi àti Aristarku ara Makedonia, àwọn ẹlẹgbẹ́ Paulu nínú ìrìnàjò.
I było pełno po wszystkiem mieście zamieszania, i wpadli jednomyślnie na plac, porwawszy Gaja i Arystarcha, Macedończyki, podróżne towarzysze Pawłowe.
30 Nígbà ti Paulu sì ń fẹ́ wọ àárín àwọn ènìyàn lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kọ̀ fún un.
A gdy Paweł chciał wnijść do pospólstwa, nie dopuścili mu uczniowie.
31 Àwọn olórí kan ara Asia, tí i ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀, ránṣẹ́ sí i, wọ́n bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó má ṣe fi ara rẹ̀ wéwu nínú ilé ìṣeré náà.
A niektórzy też z przedniejszych mężów Azyjackich, będąc mu przyjaciołmi, posławszy do niego, prosili go, aby nie wychodził na plac.
32 Ǹjẹ́ àwọn kan ń wí ohun kan, àwọn mìíràn ń wí òmíràn: nítorí àjọ di rúdurùdu; ọ̀pọ̀ ènìyàn ni kò sì mọ̀ ìdí ohun tí wọ́n tilẹ̀ fi péjọpọ̀.
Tedy jedni tak, a drudzy inaczej wołali; albowiem ona gromada była zamieszana, a więcej ich nie wiedziało, dlaczego się zbieżeli.
33 Àwọn kan nínú àwùjọ Júù ti Aleksanderu síwájú, wọn si pàṣẹ fun láti sọ̀rọ̀. Ó juwọ́ sí wọn láti dákẹ́ kí ó ba lè wí tẹnu rẹ̀ fun àwọn ènìyàn.
A z onej zgrai wywlekli Aleksandra, którego popychali Żydowie; a Aleksander skinąwszy ręką, chciał dać sprawę ludowi.
34 Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n mọ̀ pé Júù ni, gbogbo wọn ni ohùn kan, bẹ̀rẹ̀ sí kígbe fún bi wákàtí méjì pé, “Òrìṣà ńlá ni Artemisi tí ará Efesu!”
Ale gdy poznali, iż był Żydem, wszczął się jednostajny głos od wszystkich, jakoby przez dwie godziny wołających: Wielka jest Dyjana Efeska!
35 Nígbà tí akọ̀wé ìlú sì mú kí ìjọ ènìyàn dákẹ́, “Ẹ̀yin ará Efesu, ta ni ẹni tí ó wà tí kò mọ̀ pé, ìlú Efesu ní í ṣe olùsìn Artemisi òrìṣà ńlá, àti tí ère tí ó ti ọ̀dọ̀ Jupiteri bọ́ sílẹ̀?
Tedy pisarz uśmierzywszy onę zgraję, rzekł: Mężowie Efescy! i któryż jest człowiek, co by nie wiedział, iż miasto Efeskie opiekuje się kościołem wielkiej boginii Dyjany i obrazem, który spadł od Jowisza?
36 Ǹjẹ́ bi a kò tilẹ̀ sọ̀rọ̀-òdì sí nǹkan wọ̀nyí, ó yẹ kí ẹ dákẹ́, kí ẹ̀yin má ṣe fi ìkanra ṣe ohunkóhun.
A ponieważ się temu nikt sprzeciwić nie może, słuszna, abyście się uspokoili, a nic skwapliwie nie czynili.
37 Nítorí ti ẹ̀yin mú àwọn ọkùnrin wọ̀nyí wá, wọn kò ja ilé òrìṣà lólè, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀-òdì sí òrìṣà wa.
Albowiemeście przywiedli tych mężów, którzy nie są ani świętokradcami, ani bluźniercami boginii waszej.
38 Ǹjẹ́ nítorí náà tí Demetriusi, àti àwọn oníṣẹ́-ọnà tí o wà pẹ̀lú rẹ̀ bá ní gbólóhùn asọ̀ kan sí ẹnikẹ́ni, ilé ẹjọ́ ṣí sílẹ̀, àwọn onídàájọ́ sì ń bẹ: jẹ́ kí wọn lọ fi ara wọn sùn.
A jeźliż Demetryjusz i ci, którzy z nim są rzemieślnicy, mają co przeciw komu, wszak bywa prawo, są też starostowie, niechże jedni drugich pozywają.
39 Ṣùgbọ́n bí ẹ ba ń wádìí ohun kan nípa ọ̀ràn mìíràn, a ó parí rẹ̀ ni àjọ tí ó tọ́.
Jeźli się też o czem inszem pytacie, to się może w porządnem zgromadzeniu odprawić.
40 Nítorí àwa ṣa wà nínú ewu, nítorí rògbòdìyàn tí ó bẹ́ sílẹ̀ lónìí yìí; kò ṣáá ní ìdí kan tí rògbòdìyàn yìí fi bẹ́ sílẹ̀, nítorí èyí àwa kì yóò lè dáhùn fún ìwọ́jọ yìí.”
Albowiem trzeba się obawiać, abyśmy oskarżeni nie byli o rozruch dzisiejszy, gdyż nie masz żadnej przyczyny, z której byśmy mogli dać sprawę, żeśmy się tu zbiegli.
41 Nígbà tí ó sì ti sọ bẹ́ẹ̀ tan, ó tú ìjọ náà ká.
A to powiedziawszy, rozpuścił ono zgromadzenie.