< Acts 18 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Paulu jáde kúrò ni Ateni lọ sí Kọrinti.
After this he left Athens and came to Corinth.
2 Ó sì rí Júù kan tí a ń pè ní Akuila, tí a bí ni Pọntu, tí ó ti Itali dé ní lọ́ọ́lọ́ọ́, pẹ̀lú Priskilla aya rẹ̀; nítorí tí Kilaudiu pàṣẹ pé, kí gbogbo àwọn Júù jáde kúrò ní Romu. Ó sì tọ̀ wọ́n lọ láti rí wọn.
Here he found a Jew, a native of Pontus, of the name of Aquila. He and his wife Priscilla had recently come from Italy because of Claudius's edict expelling all the Jews from Rome. So Paul paid them a visit;
3 Nítorí tí òun náà jẹ́ oníṣẹ̀-ọwọ́ kan náà, ó bá wọn jókòó, ó sì ń ṣiṣẹ́: nítorí àgọ́ pípa ni iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
and because he was of the same trade--that of tent-maker--he lodged with them and worked with them.
4 Ó sì ń fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn nínú Sinagọgu lọ́jọjọ́ ìsinmi, ó sì ń yí àwọn Júù àti àwọn Giriki lọ́kàn padà.
But, Sabbath after Sabbath, he preached in the synagogue and tried to win over both Jews and Greeks.
5 Nígbà tí Sila àti Timotiu sì tí Makedonia wá, ọ̀rọ̀ náà ká Paulu lára, ó ń fihàn fún àwọn Júù pé, Jesu ni Kristi náà.
Now at the time when Silas and Timothy came down from Macedonia, Paul was preaching fervently and was solemnly telling the Jews that Jesus is the Christ.
6 Nígbà tí wọ́n sì sàtakò rẹ̀, tí wọ́n sì sọ̀rọ̀-òdì, ó gbọ́n aṣọ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀jẹ̀ yin ń bẹ lórí ara yin; ọrùn mi mọ́: láti ìsinsin yìí lọ, èmi yóò tọ àwọn aláìkọlà lọ.”
But upon their opposing him with abusive language, he shook his clothes by way of protest, and said to them, "Your ruin will be upon your own heads. I am not responsible: in future I will go among the Gentiles."
7 Ó sì lọ kúrò níbẹ̀, ó wọ ilé ọkùnrin kan tí a ń pé ní Titu Justu, ẹni tí o ń sin Ọlọ́run; ilé rẹ̀ sì wà lẹ́gbẹ̀ Sinagọgu tímọ́tímọ́.
So he left the place and went to the house of a person called Titius Justus, a worshipper of the true God. His house was next door to the synagogue.
8 Krisipu, olórí Sinagọgu, sì gba Olúwa gbọ́ pẹ̀lú gbogbo ilé rẹ̀, àti ọ̀pọ̀ nínú àwọn ara Kọrinti, nígbà tí wọ́n gbọ́, wọ́n gbàgbọ́, a sì bamitiisi wọn.
And Crispus, the Warden of the synagogue, believed in the Lord, and so did all his household; and from time to time many of the Corinthians who heard Paul believed and received baptism.
9 Olúwa sì sọ fún Paulu lóru ni ojúran pé, “Má bẹ̀rù, ṣá máa sọ, má sì ṣe pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
And, in a vision by night, the Lord said to Paul, "Dismiss your fears: go on speaking, and do not give up.
10 Nítorí tí èmí wà pẹ̀lú rẹ, kò sì sí ẹni tí yóò dìde sí ọ láti pa ọ lára: nítorí mo ní ènìyàn púpọ̀ ni ìlú yìí.”
I am with you, and no one shall attack you to injure you; for I have very many people in this city."
11 Ó sì jókòó níbẹ̀ ní ọdún kan àti oṣù mẹ́fà, ó ń kọ́ni ní ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láàrín wọn.
So Paul remained in Corinth for a year and six months, teaching among them the Message of God.
12 Nígbà tí Gallioni sì jẹ baálẹ̀ Akaia, àwọn Júù fi ìfìmọ̀ṣọ̀kan dìde sí Paulu wọn sì mú un wá síwájú ìtẹ́ ìdájọ́.
But when Gallio became Proconsul of Greece, the Jews with one accord made a dead set at Paul, and brought him before the court.
13 Wọ́n wí pé, “Ọkùnrin yìí ń yí àwọn ènìyàn lọ́kàn padà, láti máa sin Ọlọ́run lòdì sí òfin.”
"This man," they said, "is inducing people to offer unlawful worship to God."
14 Nígbà tí Paulu ń fẹ́ dáhùn, Gallioni wí fún àwọn Júù pé, “Ìbá ṣe pé ọ̀ràn búburú tàbí tí jàgídíjàgan kan ni, èmi ìbá gbè yín, ẹ̀yin Júù,
But, when Paul was about to begin his defence, Gallio said to the Jews, "If it had been some wrongful act or piece of cunning knavery I might reasonably have listened to you Jews.
15 Ṣùgbọ́n bí ó ti ṣe ọ̀ràn nípa ọ̀rọ̀ àti orúkọ, àti ti òfin yín ni, ki ẹ̀yin bojútó o fúnra yín; nítorí tí èmi kò fẹ́ ṣe onídàájọ́ nǹkan báwọ̀nyí.”
But since these are questions about words and names and your Law, you yourselves must see to them. I refuse to be a judge in such matters."
16 Ó sì lé wọn kúrò ní ibi ìtẹ́ ìdájọ́.
So he ordered them out of court.
17 Gbogbo àwọn Giriki sì mú Sostene, olórí Sinagọgu, wọ́n sì lù ú níwájú ìtẹ́ ìdájọ́. Gallioni kò sì bìkítà fún nǹkan wọ̀nyí.
Then the people all set upon Sosthenes, the Warden of the synagogue, and beat him severely in front of the court. Gallio did not concern himself in the least about this.
18 Paulu sì dúró sí i níbẹ̀ lọ́jọ́ púpọ̀, nígbà tí ó sì dágbére fún àwọn arákùnrin, ó bá ọkọ̀ ojú omi lọ si Siria, àti Priskilla àti Akuila pẹ̀lú rẹ̀; ó tí fá orí rẹ̀ ni Kenkerea, nítorí tí ó ti jẹ́ ẹ̀jẹ́.
After remaining a considerable time longer in Corinth, Paul took leave of the brethren and set sail for Syria; and Priscilla and Aquila were with him. He had shaved his head at Cenchreae, because he was bound by a vow.
19 Ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Efesu, ó sì fi wọ́n sílẹ̀ níbẹ̀, ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wọ inú Sinagọgu lọ, ó sì bá àwọn Júù fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀.
They put in at Ephesus, and there Paul left his companions behind. As for himself, he went to the synagogue and had a discussion with the Jews.
20 Nígbà tí wọ́n sì bẹ̀ ẹ́ pé, kí ó bá àwọn jókòó díẹ̀ sí i, ó kọ̀.
When they asked him to remain longer he did not consent,
21 Ṣùgbọ́n ó dágbére fún wọn, ó sì wí pé, “Èmi ó tún padà tọ̀ yín wá, bí Ọlọ́run bá fẹ́.” Ó sì lọ kúrò láti Efesu.
but took leave of them with the promise, "I will return to you, God willing." So he set sail from Ephesus.
22 Nígbà tí ó sì tí gúnlẹ̀ ni Kesarea, ó gòkè lọ si Jerusalẹmu láti kí ìjọ, lẹ́yìn náà ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí Antioku.
Landing at Caesarea, he went up to Jerusalem and inquired after the welfare of the Church, and then went down to Antioch.
23 Nígbà tí ó sì gbé ọjọ́ díẹ̀ níbẹ̀, ó n lọ, láti káàkiri ni agbègbè Galatia àti Frigia, o ń mu àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́kàn le.
After spending some time in Antioch, Paul set out on a tour, visiting the whole of Galatia and Phrygia in order, and strengthening all the disciples.
24 Júù kan sì wà tí a ń pè ni Apollo, tí a bí ni Alekisandiria, ó wá sí Efesu. Ó ní ẹ̀bùn ọ̀rọ̀ sísọ, ó sì mọ ìwé mímọ́ púpọ̀.
Meanwhile a Jew named Apollos came to Ephesus. He was a native of Alexandria, a man of great learning and well versed in the Scriptures.
25 Ọkùnrin yìí ni a tí kọ́ ní ọ̀nà tí Olúwa; ó sì ṣe ẹni tí ó ní ìtara tí ẹ̀mí, ó ń sọ̀rọ̀ ó sì ń kọ́ni ní àwọn ohun tí i ṣe ti Jesu dáradára; kìkì bamitiisi tí Johanu ní ó mọ̀.
He had been instructed by word of mouth in the way of the Lord, and, being full of burning zeal, he used to speak and teach accurately the facts about Jesus, though he knew of no baptism but John's.
26 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí fi ìgboyà sọ̀rọ̀ ni Sinagọgu. Nígbà tí Akuila àti Priskilla gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀, wọ́n mú un sọ́dọ̀, wọ́n sì túbọ̀ sọ ọ̀nà Ọlọ́run fún un dájúdájú.
He began to speak boldly in the synagogue, and Priscilla and Aquila, after hearing him, took him home and explained God's way to him more accurately.
27 Nígbà tí ó sì ń fẹ́ kọjá lọ sì Akaia, àwọn arákùnrin gbà á ní ìyànjú, wọ́n sì kọ̀wé sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn kí wọ́n gbà á, nígbà tí ó sì dé, ó ràn àwọn tí ó gbàgbọ́ nípasẹ̀ oore-ọ̀fẹ́ lọ́wọ́ púpọ̀.
Then, as he had made up his mind to cross over into Greece, the brethren wrote to the disciples in Corinth begging them to give him a kindly welcome. Upon his arrival he rendered valuable help to those who through grace had believed;
28 Nítorí tí o sọ àsọyé fún àwọn Júù ní gbangba, ó ń fi í hàn nínú ìwé mímọ́ pé, Jesu ni Kristi.
for he powerfully and in public overcame the Jews in argument, proving to them from the Scriptures that Jesus is the Christ.

< Acts 18 >