< Acts 17 >
1 Nígbà tí wọn sì ti kọjá Amfipoli àti Apollonia, wọ́n wá sí Tẹsalonika, níbi tí Sinagọgu àwọn Júù wà.
Then, passing through Amphipolis and Apollonia, they went to Thessalonica. Here there was a synagogue of the Jews.
2 Àti Paulu, gẹ́gẹ́ bí ìṣe rẹ̀, ó wọlé tọ̀ wọ́n lọ, ni ọjọ́ ìsinmi mẹ́ta ó sì ń bá wọn fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀ nínú ìwé mímọ́.
Paul--following his usual custom--betook himself to it, and for three successive Sabbaths reasoned with them from the Scriptures,
3 Ó ń túmọ̀, ó sì ń fihàn pé, Kristi kò lè ṣàìmá jìyà, kí o sì jíǹde kúrò nínú òkú; àti pé, “Jesu yìí ẹni tí èmi ń wàásù fún yin, òun ni Kristi náà.”
which he clearly explained, pointing out that it had been necessary for the Christ to suffer and rise again from the dead, and insisting, "The Jesus whom I am announcing to you is the Christ."
4 A sì yí nínú wọn lọ́kàn padà, wọ́n sì darapọ̀ mọ́ Paulu àti Sila, bákan náà ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn olùfọkànsìn Helleni àti nínú àwọn obìnrin ọlọ́lá, kì í ṣe díẹ̀.
Some of the people were won over, and attached themselves to Paul and Silas, including many God-fearing Greeks and not a few gentlewomen of high rank.
5 Ṣùgbọ́n àwọn Júù jowú, wọn sì fa àwọn jàgídíjàgan nínú àwọn ọmọ ènìyàn mọ́ra, wọ́n ko ẹgbẹ́ jọ, wọ́n sì ń dá ìlú rú; wọ́n sì kọlu ilé Jasoni, wọ́n ń fẹ́ láti mú Paulu àti Sila jáde tọ àwọn ènìyàn lọ.
But the jealousy of the Jews was aroused, and, calling to their aid some ill-conditioned and idle fellows, they got together a riotous mob and filled the city with uproar. They then attacked the house of Jason and searched for Paul and Silas, to bring them out before the assembly of people.
6 Nígbà tí wọn kò sì rí wọn, wọ́n wọ́ Jasoni, àti àwọn arákùnrin kan tọ àwọn olórí ìlú lọ, wọ́n ń kígbe pé, “Àwọn wọ̀nyí tí o tí dorí ayé kodò títí de ìhín yìí pẹ̀lú.
But, failing to find them, they dragged Jason and some of the other brethren before the magistrates of the city, loudly accusing them. "These men," they said, "who have raised a tumult throughout the Empire, have come here also.
7 Àwọn ẹni tí Jasoni gbà sí ọ̀dọ̀: gbogbo àwọn wọ̀nyí ni o sí ń hùwà lòdì sí àṣẹ Kesari, wí pé, ọba mìíràn kan wà tí í ṣe Jesu.”
Jason has received them into his house; and they all set Caesar's authority at defiance, declaring that there is another Emperor-- one called Jesus."
8 Àwọn ènìyàn àti àwọn olórí ìlú kò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ nígbà tí wọ́n gbọ́ nǹkan wọ̀nyí.
Great was the excitement among the crowd, and among the magistrates of the city, when they heard these charges.
9 Nígbà tí wọ́n sì gbà onídùúró lọ́wọ́ Jasoni àti àwọn ìyókù, wọ́n fi wọ́n sílẹ̀ lọ.
They required Jason and the rest to find substantial bail, and after that they let them go.
10 Lọ́gán àwọn arákùnrin sì rán Paulu àti Sila lọ ṣí Berea lóru. Nígbà tí wọ́n sí dé ibẹ̀, wọ́n wọ inú Sinagọgu àwọn Júù lọ.
The brethren at once sent Paul and Silas away by night to Beroea, and they, on their arrival, went to the synagogue of the Jews.
11 Àwọn Júù Berea sì ní ìyìn ju àwọn tí Tẹsalonika lọ, ní tí pé wọn fi tọkàntọkàn gbà ọ̀rọ̀ náà. Wọ́n sì ń wá inú ìwé mímọ́ lójoojúmọ́ bí nǹkan wọ̀nyí bá rí bẹ́ẹ̀.
The Jews at Beroea were of a nobler disposition than those in Thessalonica, for they very readily received the Message, and day after day searched the Scriptures to see whether it was as Paul stated.
12 Nítorí náà púpọ̀ nínú wọn gbàgbọ́; àti nínú àwọn obìnrin Giriki ọlọ́lá, àti nínú àwọn ọkùnrin ti kì í ṣe díẹ̀.
As the result many of them became believers, and so did not a few of the Greeks--gentlewomen of good position, and men.
13 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù tí Tẹsalonika mọ̀ pé, Paulu ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní Berea, wọ́n wá síbẹ̀ pẹ̀lú, wọ́n rú àwọn ènìyàn sókè.
As soon, however, as the Jews of Thessalonica learnt that God's Message had been proclaimed by Paul at Beroea, they came there also, and incited the mob to a riot.
14 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rán Paulu jáde lọ́gán láti lọ títí de etí Òkun, ṣùgbọ́n Sila àti Timotiu dúró ní Berea.
Then the brethren promptly sent Paul down to the sea-coast, but Silas and Timothy remained behind.
15 Àwọn tí ó sin Paulu wá sì mú un lọ títí dé Ateni; nígbà tí wọ́n sì gba àṣẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ wá fún Sila àti Timotiu pé, ki wọn ó yára tọ òun wá, wọ́n lọ.
Those who were caring for Paul's safety went with him as far as Athens, and then left him, taking a message from him to Silas and Timothy, asking them to join him as speedily as possible.
16 Nígbà tí Paulu dúró dè wọ́n ni Ateni, ẹ̀mí rẹ̀ ru nínú rẹ̀, nígbà tí ó rí pé ìlú náà kún fún òrìṣà.
While Paul was waiting for them in Athens, his spirit was stirred within him when he noticed that the city was full of idols.
17 Nítorí náà ó ń bá àwọn Júù fi ọ̀rọ̀ wé ọ̀rọ̀ nínú Sinagọgu, àti àwọn olùfọkànsìn, àti àwọn tí ó ń bá pàdé lọ́jà lójoojúmọ́.
So he had discussions in the synagogue with the Jews and the other worshippers, and in the market place, day after day, with those whom he happened to meet.
18 Nínú àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n Epikure ni àti tí àwọn Stoiki kó tì í. Àwọn kan si ń wí pé, “Kín ni aláhesọ yìí yóò rí wí?” Àwọn mìíràn sì wí pé, “Ó dàbí oníwàásù àjèjì òrìṣà, wọ́n sọ èyí nítorí Paulu ń wàásù ìròyìn ayọ̀ nípa Jesu àti àjíǹde fún wọn.”
A few of the Epicurean and Stoic philosophers also encountered him. Some of them asked, "What has this beggarly babbler to say?" "His business," said others, "seems to be to cry up some foreign gods." This was because he had been telling the Good News of Jesus and the Resurrection.
19 Wọ́n sì mú un, wọ́n sì fà á lọ sí Areopagu, wọ́n wí pé, “A ha lè mọ̀ kín ni ẹ̀kọ́ tuntun tí ìwọ ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí jẹ́?
Then they took him and brought him up to the Areopagus, asking him, "May we be told what this new teaching of yours is?
20 Nítorí tí ìwọ mú ohun àjèjì wá sí etí wa, àwa sì ń fẹ́ mọ̀ kín ni ìtumọ̀ nǹkan wọ̀nyí.”
For the things you are saying sound strange to us. We should therefore like to be told exactly what they mean."
21 Nítorí gbogbo àwọn ará Ateni, àti àwọn àjèjì tí ń ṣe àtìpó níbẹ̀ kì í ṣe ohun mìíràn jù kí a máa sọ tàbí kí a máa gbọ́ ohun tuntun lọ.
(For all the Athenians and their foreign visitors used to devote their whole leisure to telling or hearing about something new.)
22 Paulu si dìde dúró láàrín Areopagu, ó ní, “Ẹ̀yin ará Ateni, mo wòye pé ní ohun gbogbo ẹ kún fún ẹ̀sìn lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
So Paul, taking his stand in the centre of the Areopagus, spoke as follows: "Men of Athens, I perceive that you are in every respect remarkably religious.
23 Nítorí bí mo ti ń kọjá lọ, tí mo wo àwọn ohun tí ẹ̀yin ń sìn, mo sì rí pẹpẹ kan tí a kọ àkọlé yìí sí: Fún Ọlọ́run àìmọ̀. Ǹjẹ́ ẹni tí ẹ̀yin ń sìn ni àìmọ̀ òun náà ni èmi ń sọ fún yin.
For as I passed along and observed the things you worship, I found also an altar bearing the inscription, 'TO AN UNKNOWN GOD.' "The Being, therefore, whom you, without knowing Him, revere, Him I now proclaim to you.
24 “Ọlọ́run náà tí ó dá ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òun náà tí í ṣe Olúwa ọ̀run àti ayé, kì í gbé tẹmpili tí a fi ọwọ́ kọ́.
GOD who made the universe and everything in it--He, being Lord of Heaven and earth, does not dwell in sanctuaries built by men.
25 Bẹ́ẹ̀ ni a kì í fi ọwọ́ ènìyàn sìn ín, bí ẹni pé ó ń fẹ́ nǹkan, òun ni ó fi ìyè àti èémí àti ohun gbogbo fún gbogbo ènìyàn.
Nor is He ministered to by human hands, as though He needed anything--but He Himself gives to all men life and breath and all things.
26 Ó sì tí tipasẹ̀ ẹnìkan dá gbogbo orílẹ̀-èdè láti tẹ̀dó sí ojú àgbáyé, ó sì ti pinnu àkókò tí a yàn tẹ́lẹ̀, àti ààlà ibùgbé wọn;
He caused to spring from one forefather people of every race, for them to live on the whole surface of the earth, and marked out for them an appointed span of life and the boundaries of their homes;
27 Ọlọ́run ṣe eléyìí kí wọn bá le máa wa, bóyá wọn yóò lè ṣàfẹ́rí rẹ̀, kí wọn sì rí í. Bí ó tilẹ̀ jẹ pé kò jìnnà sí olúkúlùkù wa.
that they might seek God, if perhaps they could grope for Him and find Him. Yes, though He is not far from any one of us.
28 Nítorí nínú rẹ̀ ni àwa wà láààyè, tí a ń rìn kiri, tí a sì ní ẹ̀mí wa, bí àwọn kan nínú àwọn akéwì tí ẹ̀yin tìkára yín tí wí pé, ‘Àwa pẹ̀lú sì jẹ́ ọmọ rẹ̀.’
For it is in closest union with Him that we live and move and have our being; as in fact some of the poets in repute among yourselves have said, 'For we are also His offspring.'
29 “Ǹjẹ́ bí àwa bá jẹ́ ọmọ Ọlọ́run, kò yẹ fún wa láti rò pé, ẹni tí a wa n sìn dàbí wúrà, tàbí fàdákà, tàbí òkúta, tí a fi ọgbọ́n àti ìmọ̀ ènìyàn ya ère àwòrán rẹ̀.
Since then we are God's offspring, we ought not to imagine that His nature resembles gold or silver or marble, or anything sculptured by the art and inventive faculty of man.
30 Pẹ̀lúpẹ̀lú ìgbà àìmọ̀ yìí ni Ọlọ́run tí fojú fò dá; ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó pàṣẹ fún gbogbo ènìyàn níbi gbogbo láti ronúpìwàdà.
Those times of ignorance God viewed with indulgence. But now He commands all men everywhere to repent,
31 Níwọ́n bí ó ti dá ọjọ́ kan, nínú èyí tí yóò ṣe ìdájọ́ ayé lódodo nípasẹ̀ ọkùnrin náà tí ó ti yàn, nígbà tí ó ti fi ohun ìdánilójú fún gbogbo ènìyàn, ní ti pé ó jí dìde kúrò nínú òkú.”
seeing that He has appointed a day on which, before long, He will judge the world in righteousness, through the instrumentality of a man whom He has pre-destined to this work, and has made the fact certain to every one by raising Him from the dead."
32 Nígbà tí wọ́n ti gbọ́ ti àjíǹde òkú, àwọn mìíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn mìíràn wí pé, “Àwa o tún nǹkan yìí gbọ́ lẹ́nu rẹ̀.”
When they heard Paul speak of a resurrection of dead men, some began to scoff. But others said, "We will hear you again on that subject."
33 Bẹ́ẹ̀ ni Paulu sì jáde kúrò láàrín wọn.
So Paul went away from them.
34 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin kan fi ara mọ́ ọn, wọ́n sì gbàgbọ́: nínú àwọn ẹni tí Dionisiu ara Areopagu wà, àti obìnrin kan tí a ń pè ni Damari àti àwọn mìíràn pẹ̀lú wọn.
A few, however, attached themselves to him and believed, among them being Dionysius a member of the Council, a gentlewoman named Damaris, and some others.