< Acts 16 >

1 Ó sì wá sí Dabe àti Lysra: sí kíyèsi i, ọmọ-ẹ̀yìn kan wà níbẹ̀, tí a ń pè ní Timotiu, ọmọ obìnrin kan tí í ṣe Júù, tí ó gbàgbọ́; ṣùgbọ́n Giriki ní baba rẹ̀.
Il y fit rencontre d'un disciple nommé Timothée, qui était fils d'une Juive fidèle, mais d'un père grec,
2 Ẹni tí a ròhìn rẹ̀ ní rere lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin tí ó wà ní Lysra àti Ikoniomu.
et qui jouissait d'un bon renom parmi les frères de Lystres et d'Icône.
3 Òun ni Paulu fẹ́ kí ó bá òun lọ; ó sì mú un, ó sì kọ ọ́ ní ilà, nítorí àwọn Júù tí ó wà ní agbègbè wọ̀nyí, nítorí gbogbo wọn mọ̀ pé, Giriki ni baba rẹ̀.
Paul voulut remmener avec lui; il le prit et le circoncit à cause des Juifs qui étaient en ces lieux-là, car tous savaient que son père était grec.
4 Bí wọn sì ti ń la àwọn ìlú lọ, wọ́n ń fi àwọn àṣẹ, tí a tí pinnu láti ọ̀dọ̀ àwọn aposteli àti àwọn alàgbà tí ó wà ní Jerusalẹmu, lé wọn lọ́wọ́ láti máa pa wọ́n mọ́.
Dans les villes où ils passaient, ils enseignaient aux frères à garder les arrêtés pris par les apôtres et par les anciens de Jérusalem.
5 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìjọ sì fẹsẹ̀múlẹ̀ ní ìgbàgbọ́, wọn sí ń pọ̀ sí i ní iye lójoojúmọ́.
Les églises s'affermissaient donc dans la foi, et croissaient en nombre de jour en jour.
6 Wọ́n sì la agbègbè Frigia já, àti Galatia, nítorí tí Ẹ̀mí Mímọ́ kọ̀ fún wọn láti sọ ọ̀rọ̀ náà ni Asia.
Ils parcoururent la Phrygie et le pays de Galatie, après avoir été empêchés par le Saint-Esprit d'annoncer la Parole dans l’Asie.
7 Nígbà tí wọ́n dé ọ̀kánkán Misia, wọ́n gbìyànjú láti lọ sí Bitinia, ṣùgbọ́n Ẹ̀mí Jesu kò gbà fún wọn.
Arrivés près de la Mysie, ils essayèrent d'entrer en Bithynie, mais l'Esprit de Jésus ne le leur permit pas.
8 Nígbà tí wọ́n sì kọjá lẹ́bàá Misia, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Troasi.
Alors, ayant traversé rapidement la Mysie, ils descendirent à Troas.
9 Ìran kan si hàn sì Paulu ni òru, ọkùnrin kan ará Makedonia dúró, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, wí pé, “Rékọjá wá sí Makedonia, kí o sí ràn wá lọ́wọ́!”
Là, Paul eut une vision dans la nuit: il vit un Macédonien debout, qui l'appelait, et lui disait: «Passe en Macédoine pour nous secourir.»
10 Nígbà tí ó sì tí rí ìran náà, lọ́gán ó múra láti lọ sí Makedonia, a ka á sí pé, Ọlọ́run tí pè wá láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
Aussitôt après cette vision, nous cherchâmes à passer en Macédoine, concluant que le Seigneur nous appelait à y porter l'évangile.
11 Nítorí náà nígbà tí àwa ṣíkọ̀ ní Troasi a ba ọ̀nà tààrà lọ sí Samotrakea, ni ọjọ́ kejì a sì dé Neapoli;
Étant donc partis de Troas, nous fîmes voile droit vers la Samothrace, et le lendemain nous débarquâmes à Néapolis.
12 láti ibẹ̀ àwa sì lọ si Filipi, tí í ṣe ìlú Makedonia, olú ìlú ìhà ibẹ̀, ìlú lábẹ́ Romu, àwa sì jókòó ní ìlú yìí fún ọjọ́ mélòó kan.
De là, nous allâmes à Philippes, colonie romaine, qui est la première ville du district de Macédoine. Nous nous arrêtâmes quelques jours dans cette ville.
13 Lọ́jọ́ ìsinmi, àwa sí jáde lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà, lẹ́bàá odò kan, níbi tí a rò pé ibi àdúrà wà; àwa sí jókòó, a sì bá àwọn obìnrin tí o péjọ sọ̀rọ̀.
Le jour du sabbat, nous nous rendîmes hors de la porte, vers une rivière, où se trouvait, selon la coutume, un lieu de prière, et nous étant assis, nous nous entretînmes avec les femmes qui s'y étaient assemblées.
14 Àti obìnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Lidia, elése àlùkò, ará ìlú Tiatira, ẹni tí ó sin Ọlọ́run, ó gbọ́ ọ̀rọ̀ wa, ọkàn ẹni tí Olúwa ṣí láti fetísí ohun tí a tí ẹnu Paulu sọ.
L'une d'elles écouta: c'était une marchande de pourpre, nommée Lydie, de la ville de Thyatire, femme craignant Dieu. Le Seigneur lui ouvrit le coeur pour qu'elle fût attentive aux choses que Paul disait.
15 Nígbà tí a sí bamitiisi rẹ̀, àti àwọn ara ilé rẹ̀, ó bẹ̀ wá, wí pé, “Bí ẹ̀yin bá kà mí ni olóòtítọ́ sí Olúwa, ẹ wá si ilé mi, kí ẹ sí wọ̀ níbẹ̀!” O sí rọ̀ wá.
Lorsqu'elle eut été baptisée, ainsi que sa famille, elle nous adressa cette invitation: «Puisque vous avez jugé que j'ai foi au Seigneur, venez demeurer chez moi.» Et elle nous y contraignit.
16 Bí àwa tí n lọ sí ibi àdúrà náà, ọmọbìnrin kan tí o ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ, pàdé wa, ẹni tí ó fi àfọ̀ṣẹ mú èrè púpọ̀ wá fún àwọn ọ̀gá rẹ̀.
Un jour que nous nous acheminions vers le lieu de prière, nous rencontrâmes une servante qui avait un esprit Python, et qui, en devinant, procurait un grand profit à ses maîtres.
17 Òun náà ni ó ń tọ Paulu àti àwa lẹ́hìn, ó sì ń kígbe, pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ń kéde ọ̀nà ìgbàlà fún yin!”
Elle se mit à nous suivre, Paul et nous, en criant: «Ces hommes-là sont des serviteurs du Dieu Très-Haut, ils nous annoncent la voie du salut.
18 Ó sì ń ṣe èyí lọ́jọ́ púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí inú Paulu bàjẹ́, tí ó sì yípadà, ó wí fún ẹ̀mí náà pé, “Mo pàṣẹ fún ọ ní orúkọ Jesu Kristi kí o jáde kúrò lára rẹ̀!” Ó sí jáde ni wákàtí kan náà.
Elle fit cela plusieurs jours de suite, et Paul en étant fatigué, se retourna, et dit à l'esprit: «Je te commande, au nom de Jésus, de sortir de cette fille; » et il sortit à l'heure même.
19 Nígbà tí àwọn ọ̀gá rẹ̀ sì rí i pé, ìgbẹ́kẹ̀lé èrè wọn pin, wọ́n mú Paulu àti Sila, wọn sì wọ́ wọn lọ sí ọjà tọ àwọn aláṣẹ lọ.
Les maîtres de la servante, voyant que leur espérance de gain s'était évanouie, se saisirent de Paul et de Silas, et les traînèrent à la place publique vers les magistrats.
20 Nígbà tí wọ́n sì mú wọn tọ àwọn onídàájọ́ lọ, wọ́n wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí tí í ṣe Júù, wọ́n ń yọ ìlú wa lẹ́nu jọjọ,
Ils les amenèrent devant les préteurs, et dirent: «Ces hommes troublent notre ville.
21 wọ́n sì ń kọ́ni ní àṣà tí kò yẹ fún wa, àwa ẹni tí í ṣe ara Romu, láti gbà àti láti tẹ̀lé.”
Ce sont des Juifs; ils prêchent des pratiques qu'il ne nous est pas permis à nous, Romains, d'adopter ni de suivre.»
22 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sí jùmọ̀ dìde sì Paulu àti Sila. Àwọn olórí sí fà wọ́n ní aṣọ ya, wọ́n sí pàṣẹ pé, ki a fi ọ̀gọ̀ lù wọ́n.
La foule se souleva aussi contre eux, et les préteurs, leur ayant arraché leurs vêtements, ordonnèrent qu'ils fussent battus de verges.
23 Nígbà tí wọ́n sì lù wọ́n púpọ̀, wọ́n sọ wọ́n sínú túbú, wọ́n kìlọ̀ fún onítúbú kí ó pa wọ́n mọ́ dáradára.
Lorsqu'on les eut chargés de coups, ils les firent jeter en prison en commandant au geôlier de les garder sûrement.
24 Nígbà tí ó gbọ́ irú ìkìlọ̀ bẹ́ẹ̀, ó sọ̀ wọ́n sínú túbú tí inú lọ́hùn, ó sí kan àbà mọ wọ́n lẹ́sẹ̀.
D'après cet ordre, le geôlier les mit dans le cachot intérieur, et fixa leurs pieds dans les ceps.
25 Ṣùgbọ́n láàrín ọ̀gànjọ́ Paulu àti Sila ń gbàdúrà, wọ́n sì ń kọrin ìyìn si Ọlọ́run, àwọn ara túbú sì ń tẹ́tí sí wọn.
Vers le milieu de la nuit, Paul et Silas, s'étant mis en prière, chantaient des hymnes à Dieu; et les détenus les entendaient.
26 Lójijì ilẹ̀ mímì ńlá sì mi, tó bẹ́ẹ̀ tí ìpìlẹ̀ ilé túbú mì tìtì: lọ́gán, gbogbo ìlẹ̀kùn sì ṣí, ìdè gbogbo wọn sì tú sílẹ̀.
Tout à coup il se fit un si grand tremblement de terre, que les fondements de la prison en furent ébranlés; au même instant, toutes les portes s'ouvrirent, et les fers de tous les prisonniers tombèrent.
27 Nígbà tí onítúbú si tají, tí o sì ri pé, àwọn ìlẹ̀kùn túbú tí ṣí sílẹ̀, ó fa idà rẹ̀ yọ, ó sì fẹ́ pa ara rẹ̀, ó ṣe bí àwọn ara túbú ti sálọ.
Le geôlier, s'étant réveillé, et voyant les portes de la prison ouvertes, crut que les détenus s'étaient enfuis; il tira une épée et allait se tuer,
28 Ṣùgbọ́n Paulu gbé ohun rẹ̀ sókè, wí pé, “Má ṣe pa ara rẹ lára: nítorí gbogbo wa ń bẹ níhìn-ín yìí!”
lorsque Paul lui cria d'une voix forte: «Ne te fais point de mal mous sommes tous ici.»
29 Nígbà tí ó sì béèrè iná, ó bẹ́ wọ inú ilé, ó ń wárìrì, ó wólẹ̀ níwájú Paulu àti Sila.
Alors, ayant demandé de la lumière, il s'élança dans le cachot, et, tout tremblant, se jeta aux pieds de Paul et de Silas;
30 Ó sì mú wọn jáde, ó ní, “Alàgbà, kín ni ki èmi ṣe ki n lè là?”
puis, les ayant fait sortir, il leur dit: «Seigneurs, que faut-il que je fasse pour être sauvé?»
31 Wọ́n sì wí fún un pé, “Gbá Jesu Kristi Olúwa gbọ́, a ó sì gbà ọ́ là, ìwọ àti àwọn ará ilé rẹ pẹ̀lú.”
Ils lui répondirent: «Crois au Seigneur Jésus, et tu seras sauvé, toi et ta famille; »
32 Wọ́n sì sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un, àti fún gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀.
et ils lui annoncèrent la parole du Seigneur, ainsi qu'à tous ceux qui étaient dans sa maison.
33 Ó sì mú wọn ní wákàtí náà lóru, ó wẹ ọgbẹ́ wọn; a sì bamitiisi rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ lójúkan náà.
A cette même heure de la nuit, le geôlier les prit avec lui, lava leurs plaies, et, immédiatement après, il fut baptisé, lui et tous les siens.
34 Ó sì mú wọn wá sí ilé rẹ̀, ó sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú wọn, ó sì yọ̀ gidigidi pẹ̀lú gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, nítorí ó gba Ọlọ́run gbọ́.
Après les avoir fait monter dans son logement, il leur servit à manger, heureux qu'il était d'avoir cru en Dieu avec toute sa fa- mille.
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí ilẹ̀ mọ́, àwọn onídàájọ́ rán àwọn ọlọ́pàá pé, “Tú àwọn ènìyàn náà sílẹ̀.”
Quand le jour fut venu, les préteurs envoyèrent dire par les licteurs: «Relâche ces gens-là.»
36 Onítúbú sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Paulu, wí pé, “Àwọn onídàájọ́ ránṣẹ́ pé kí á da ìwọ àti Sila sílẹ̀. Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ jáde kí ẹ sì máa lọ ní àlàáfíà.”
Et le geôlier annonça cette nouvelle à Paul: «Les préteurs, dit-il, ont envoyé l'ordre de vous relâcher; maintenant donc sortez, et allez en paix.»
37 Ṣùgbọ́n Paulu wí fún wọn pé, “Wọ́n lù wá ni gbangba, wọ́n sì sọ wá sínú túbú ni àìjẹ̀bi, àwa ẹni tí ì ṣe ara Romu. Ṣe nísinsin yìí wọ́n fẹ́ tì wá jáde níkọ̀kọ̀? Rara! Ṣùgbọ́n kí àwọn tìkára wọn wá mú wa jáde!”
Mais Paul dit aux licteurs: «Quoi! après nous avoir publiquement battus de verges, sans jugement, nous qui sommes romains, ils nous ont jetés en prison, et maintenant ils nous font sortir secrètement! Non pas; mais qu'ils viennent eux-mêmes nous mettre en liberté.»
38 Àwọn ọlọ́pàá sì sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn onídàájọ́: ẹ̀rù sì bà wọ́n, nígbà tí wọ́n gbọ́ pé ará Romu ni Paulu àti Sila.
Les licteurs rapportèrent ces paroles aux préteurs, qui furent effrayés en apprenant que ces hommes étaient romains.
39 Wọ́n sì wá, wọ́n ṣìpẹ̀ lọ́dọ̀ wọ́n, wọn sì mú wọn jáde, wọ́n sì bẹ̀ wọ́n pé, ki wọn jáde kúrò ni ìlú náà.
Ils vinrent leur parler, et, en les élargissant, ils les prièrent de quitter la ville.
40 Paulu àti Sila sì jáde nínú túbú, wọ́n sì wọ ilé Lidia lọ, nígbà tí wọn sì tí rí àwọn arákùnrin, wọ́n tù wọ́n nínú, wọn sì jáde kúrò.
Au sortir de la prison, les apôtres entrèrent chez Lydie, et, après avoir vu et encouragé les frères, ils partirent.

< Acts 16 >