< Acts 16 >
1 Ó sì wá sí Dabe àti Lysra: sí kíyèsi i, ọmọ-ẹ̀yìn kan wà níbẹ̀, tí a ń pè ní Timotiu, ọmọ obìnrin kan tí í ṣe Júù, tí ó gbàgbọ́; ṣùgbọ́n Giriki ní baba rẹ̀.
ⲁ̅ⲀϤⲒ ⲆⲈ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲦⲔⲈⲦⲈⲢⲂⲎ ⲚⲈⲘ ⲖⲨⲤⲦⲢⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲒⲤ ⲞⲨⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲈⲚⲀϤⲬⲎ ⲘⲘⲀⲨ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲠⲈ ⲦⲒⲘⲞⲐⲈⲞⲤ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲚⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲚⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲘⲠⲒⲤⲦⲎ ⲠⲈϤⲒⲰⲦ ⲆⲈ ⲚⲈⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ ⲠⲈ.
2 Ẹni tí a ròhìn rẹ̀ ní rere lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin tí ó wà ní Lysra àti Ikoniomu.
ⲃ̅ⲪⲀⲒ ⲚⲀⲨⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈⲐⲂⲎⲦϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ ⲈⲦϦⲈⲚ ⲖⲨⲤⲦⲢⲀ ⲚⲈⲘ ⲒⲔⲞⲚⲒⲞⲚ.
3 Òun ni Paulu fẹ́ kí ó bá òun lọ; ó sì mú un, ó sì kọ ọ́ ní ilà, nítorí àwọn Júù tí ó wà ní agbègbè wọ̀nyí, nítorí gbogbo wọn mọ̀ pé, Giriki ni baba rẹ̀.
ⲅ̅ⲪⲀⲒ ⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈⲐⲢⲈϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲞⲖϤ ⲀϤⲤⲞⲨⲂⲎⲦϤ ⲈⲐⲂⲈ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲈⲦϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲚⲀⲨⲤⲰⲞⲨⲚ ⲄⲀⲢ ⲦⲎⲢⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲈϤⲒⲰⲦ ⲞⲨⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ ⲠⲈ.
4 Bí wọn sì ti ń la àwọn ìlú lọ, wọ́n ń fi àwọn àṣẹ, tí a tí pinnu láti ọ̀dọ̀ àwọn aposteli àti àwọn alàgbà tí ó wà ní Jerusalẹmu, lé wọn lọ́wọ́ láti máa pa wọ́n mọ́.
ⲇ̅ⲈⲨⲔⲰϮ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲚⲒⲠⲞⲖⲒⲤ ⲚⲀⲨϮ ⲘⲘⲞⲤ ⲈⲦⲞⲦⲞⲨ ⲈⲀⲢⲈϨ ⲈⲚⲒϨⲰⲚ ⲈⲦⲀⲨⲤⲈⲘⲚⲎ ⲦⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲚⲒⲀⲠⲞⲤⲦⲞⲖⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲈⲦϦⲈⲚ ⲒⲈⲢⲞⲤⲀⲖⲎⲘ.
5 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìjọ sì fẹsẹ̀múlẹ̀ ní ìgbàgbọ́, wọn sí ń pọ̀ sí i ní iye lójoojúmọ́.
ⲉ̅ⲚⲒⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲚ ⲚⲀⲨⲚⲎⲞⲨ ⲚⲦⲀϪⲢⲞ ϦⲈⲚⲠⲒⲚⲀϨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲚⲎⲞⲨ ⲚⲀϢⲀⲒ ϦⲈⲚⲦⲞⲨⲎⲠⲒ ⲘⲘⲎⲚⲒ.
6 Wọ́n sì la agbègbè Frigia já, àti Galatia, nítorí tí Ẹ̀mí Mímọ́ kọ̀ fún wọn láti sọ ọ̀rọ̀ náà ni Asia.
ⲋ̅ⲀⲨⲤⲒⲚⲒ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ϮⲪⲢⲒⲔⲒⲀ ⲚⲈⲘ ϮⲬⲰⲢⲀ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲀⲦⲒⲀ ⲈⲀϤⲦⲀϨⲚⲞ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲈⲐⲞⲨⲀⲂ ⲈϢⲦⲈⲘⲤⲀϪⲒ ⲘⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ϦⲈⲚϮⲀⲤⲒⲀ.
7 Nígbà tí wọ́n dé ọ̀kánkán Misia, wọ́n gbìyànjú láti lọ sí Bitinia, ṣùgbọ́n Ẹ̀mí Jesu kò gbà fún wọn.
ⲍ̅ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲆⲈ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲚⲒⲘⲀ ⲚⲦⲈϮⲘⲨⲤⲒⲀ ⲚⲀⲨϬⲰⲚⲦ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈϢⲈ ⲈϮⲂⲎⲐⲈⲚⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲬⲰ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲦⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ.
8 Nígbà tí wọ́n sì kọjá lẹ́bàá Misia, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Troasi.
ⲏ̅ⲈⲦⲀⲨⲤⲒⲚⲒ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚϮⲘⲨⲤⲒⲀ ⲀⲨⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲦⲢⲰⲀⲤ.
9 Ìran kan si hàn sì Paulu ni òru, ọkùnrin kan ará Makedonia dúró, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, wí pé, “Rékọjá wá sí Makedonia, kí o sí ràn wá lọ́wọ́!”
ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲞⲚϨ ⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚϪⲈⲞⲨϨⲞⲢⲀⲘⲀ ⲘⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲘⲘⲀⲔⲈⲆⲰⲚ ⲈϤⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦϤ ⲈϤⲦⲰⲂϨ ⲘⲘⲞϤ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲘⲞⲨ ⲈⲐⲘⲀⲔⲈⲆⲞⲚⲒⲀ ⲀⲢⲒⲂⲞⲎⲐⲒⲚ ⲈⲢⲞⲚ.
10 Nígbà tí ó sì tí rí ìran náà, lọ́gán ó múra láti lọ sí Makedonia, a ka á sí pé, Ọlọ́run tí pè wá láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
ⲓ̅ϨⲰⲤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲚⲚⲀⲨ ⲈⲠⲒϨⲞⲢⲀⲘⲀ ⲤⲀⲦⲞⲦⲈⲚ ⲀⲚⲔⲰϮ ⲚⲤⲀⲒⲈⲐⲘⲀⲔⲈⲆⲞⲚⲒⲀ ⲈⲚⲤⲞϬⲚⲒ ϪⲈ ⲈⲦⲀ ⲪⲚⲞⲨϮ ⲐⲀϨⲘⲈⲚ ⲈϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ⲚⲰⲞⲨ.
11 Nítorí náà nígbà tí àwa ṣíkọ̀ ní Troasi a ba ọ̀nà tààrà lọ sí Samotrakea, ni ọjọ́ kejì a sì dé Neapoli;
ⲓ̅ⲁ̅ⲈⲦⲀⲚⲒ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲢⲰⲀⲤ ⲀⲚϢⲈ ⲚⲬⲰⲖⲈⲘ ⲈⲤⲀⲘⲞⲐⲢⲀⲔⲎ ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲆⲈ ⲀⲚⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲚⲈⲀⲠⲞⲖⲒⲤ.
12 láti ibẹ̀ àwa sì lọ si Filipi, tí í ṣe ìlú Makedonia, olú ìlú ìhà ibẹ̀, ìlú lábẹ́ Romu, àwa sì jókòó ní ìlú yìí fún ọjọ́ mélòó kan.
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲀⲨ ⲀⲚⲒ ⲈⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲒⲤ ⲈⲦⲈ ⲚⲐⲞⲤ ⲦⲈ ϮϨⲞⲨⲒϮ ⲚⲦⲈϮⲦⲞⲒ ⲚⲦⲈⲐⲘⲀⲔⲈⲆⲞⲚⲒⲀ ⲞⲨⲠⲞⲖⲒⲤ ⲚⲔⲞⲖⲰⲚⲒⲀ ⲚⲀⲚϢⲞⲠ ⲆⲈ ⲠⲈ ϦⲈⲚϮⲠⲞⲖⲒⲤ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲚϨⲀⲚⲈϨⲞⲞⲨ.
13 Lọ́jọ́ ìsinmi, àwa sí jáde lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà, lẹ́bàá odò kan, níbi tí a rò pé ibi àdúrà wà; àwa sí jókòó, a sì bá àwọn obìnrin tí o péjọ sọ̀rọ̀.
ⲓ̅ⲅ̅ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲚⲦⲈⲚⲒⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ ⲀⲚⲒ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲚϮⲠⲞⲖⲒⲤ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲒⲀⲢⲞ ⲠⲒⲘⲀ ⲈⲚⲀⲚⲘⲈⲨⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲚⲀϢⲰⲠⲒ ⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲚϨⲈⲘⲤⲒ ⲚⲀⲚⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒϨⲒⲞⲘⲒ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ.
14 Àti obìnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Lidia, elése àlùkò, ará ìlú Tiatira, ẹni tí ó sin Ọlọ́run, ó gbọ́ ọ̀rọ̀ wa, ọkàn ẹni tí Olúwa ṣí láti fetísí ohun tí a tí ẹnu Paulu sọ.
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲈⲠⲈⲤⲢⲀⲚ ⲠⲈ ⲖⲨⲆⲒⲀ ⲈⲞⲨⲤⲀⲚϬⲎϪⲒ ⲦⲈ ⲚⲦⲈⲞⲨⲠⲞⲖⲒⲤ ϪⲈ ⲐⲨⲀⲦⲎⲢⲰⲚ ⲈⲤⲈⲢⲤⲈⲂⲈⲤⲐⲈ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲀⲤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲐⲀⲒ Ⲁ- ⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲰⲚ ⲘⲠⲈⲤϨⲎⲦ ⲈϮϨⲐⲎⲤ ⲈⲚⲎ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ϪⲰ ⲘⲘⲰⲞⲨ.
15 Nígbà tí a sí bamitiisi rẹ̀, àti àwọn ara ilé rẹ̀, ó bẹ̀ wá, wí pé, “Bí ẹ̀yin bá kà mí ni olóòtítọ́ sí Olúwa, ẹ wá si ilé mi, kí ẹ sí wọ̀ níbẹ̀!” O sí rọ̀ wá.
ⲓ̅ⲉ̅ⲈⲦⲀⲤϬⲒⲰⲘⲤ ⲆⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲤⲎⲒ ⲀⲤϮϨⲞ ⲈⲢⲞⲚ ⲈⲤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲒⲤϪⲈ ⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲞⲠⲦ ⲈⲞⲨⲠⲒⲤⲦⲎ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲀⲎⲒ ϢⲰⲠⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϬⲒⲦⲦⲈⲚ ⲚϪⲞⲚⲤ.
16 Bí àwa tí n lọ sí ibi àdúrà náà, ọmọbìnrin kan tí o ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ, pàdé wa, ẹni tí ó fi àfọ̀ṣẹ mú èrè púpọ̀ wá fún àwọn ọ̀gá rẹ̀.
ⲓ̅ⲋ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲈⲚⲚⲀ ⲈϮⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲎ ⲀⲤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϨⲢⲀⲚ ⲚϪⲈⲞⲨⲀⲖⲞⲨ ⲘⲂⲰⲔⲒ ⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲢⲈϤϢⲒⲚⲒ ⲚⲈⲘⲀⲤ ⲐⲀⲒ ⲈⲚⲀⲤϮ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲈⲢⲄⲀⲤⲒⲀ ⲚⲚⲈⲤϬⲒⲤⲈⲨ ⲈⲤⲞⲒ ⲚⲢⲈϤϢⲒⲚⲒ.
17 Òun náà ni ó ń tọ Paulu àti àwa lẹ́hìn, ó sì ń kígbe, pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ń kéde ọ̀nà ìgbàlà fún yin!”
ⲓ̅ⲍ̅ⲐⲀⲒ ⲈⲦⲀⲤⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲀⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲈⲘⲀⲚ ⲚⲀⲤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲀⲒⲢⲰⲘⲒ ϨⲀⲚⲈⲂⲒⲀⲒⲔ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦϬⲞⲤⲒ ⲚⲈⲚⲀⲒ ⲈⲦϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲚⲞⲨⲘⲰⲒⲦ ⲚⲞⲨϪⲀⲒ.
18 Ó sì ń ṣe èyí lọ́jọ́ púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí inú Paulu bàjẹ́, tí ó sì yípadà, ó wí fún ẹ̀mí náà pé, “Mo pàṣẹ fún ọ ní orúkọ Jesu Kristi kí o jáde kúrò lára rẹ̀!” Ó sí jáde ni wákàtí kan náà.
ⲓ̅ⲏ̅ⲪⲀⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲤⲢⲀ ⲘⲘⲞϤ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲈϨⲞⲞⲨ ⲈⲦⲀϤⲈⲢⲘⲔⲀϨ ⲚϨⲎⲦ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲔⲞⲦϤ ⲈⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ϮϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲚⲀⲔ ϦⲈⲚⲪⲢⲀⲚ ⲚⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠⲬⲢⲒⲤⲦⲞⲤ ⲈⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ.
19 Nígbà tí àwọn ọ̀gá rẹ̀ sì rí i pé, ìgbẹ́kẹ̀lé èrè wọn pin, wọ́n mú Paulu àti Sila, wọn sì wọ́ wọn lọ sí ọjà tọ àwọn aláṣẹ lọ.
ⲓ̅ⲑ̅ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲚⲈⲤϬⲒⲤⲈⲨ ϪⲈ ⲀⲤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϦⲎⲦⲤ ⲚϪⲈⲦϨⲈⲖⲠⲒⲤ ⲚⲦⲈⲠⲞⲨϨⲰⲂ ⲀⲨⲀⲘⲞⲚⲒ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲤⲒⲖⲀⲤ ⲀⲨⲰϢϮ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲈϮⲀⲄⲞⲢⲀ ϢⲀ ⲚⲒⲀⲢⲬⲰⲚ
20 Nígbà tí wọ́n sì mú wọn tọ àwọn onídàájọ́ lọ, wọ́n wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí tí í ṣe Júù, wọ́n ń yọ ìlú wa lẹ́nu jọjọ,
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲈⲚⲞⲨ ϨⲀ ⲚⲒⲤⲀⲦⲎⲄⲞⲨⲤ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲀⲒⲢⲰⲘⲒ ⲤⲈϢⲐⲞⲢⲦⲈⲢ ⲚⲦⲈⲚⲠⲞⲖⲒⲤ ⲈϨⲀⲚⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲚⲈ.
21 wọ́n sì ń kọ́ni ní àṣà tí kò yẹ fún wa, àwa ẹni tí í ṣe ara Romu, láti gbà àti láti tẹ̀lé.”
ⲕ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲈϨⲒⲰⲒϢ ⲚⲀⲚ ⲚϨⲀⲚⲔⲈⲔⲀϨⲤ ⲚⲀⲒ ⲈⲦⲈⲤϢⲈ ⲚⲀⲚ ⲀⲚ ⲈϢⲞⲠⲞⲨ ⲞⲨⲆⲈ ⲈⲀⲒⲦⲞⲨ ⲈⲀⲚⲞⲚ ϨⲀⲚⲢⲰⲘⲈⲞⲤ.
22 Ọ̀pọ̀ ènìyàn sí jùmọ̀ dìde sì Paulu àti Sila. Àwọn olórí sí fà wọ́n ní aṣọ ya, wọ́n sí pàṣẹ pé, ki a fi ọ̀gọ̀ lù wọ́n.
ⲕ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲠⲒⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲤⲀⲦⲎⲄⲞⲨⲤ ⲀⲨⲪⲰϦ ⲚⲚⲞⲨϨⲂⲰⲤ ⲀⲨⲈⲢⲔⲈⲖⲈⲨⲒⲚ ⲚⲤⲈϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲘⲠϢⲂⲰⲦ.
23 Nígbà tí wọ́n sì lù wọ́n púpọ̀, wọ́n sọ wọ́n sínú túbú, wọ́n kìlọ̀ fún onítúbú kí ó pa wọ́n mọ́ dáradára.
ⲕ̅ⲅ̅ⲈⲦⲀⲨϮ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϢⲀϢ ⲚⲰⲞⲨ ⲀⲨϨⲒⲦⲞⲨ ⲈⲠⲒϢⲦⲈⲔⲞ ⲈⲀⲨϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲈⲦⲞⲦϤ ⲘⲠⲒⲢⲈϤⲀⲢⲈϨ ⲚⲦⲈⲠⲒⲘⲀ ⲚⲤⲰⲚϨ ⲈⲀⲢⲈϨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲞⲨⲦⲀϪⲢⲞ.
24 Nígbà tí ó gbọ́ irú ìkìlọ̀ bẹ́ẹ̀, ó sọ̀ wọ́n sínú túbú tí inú lọ́hùn, ó sí kan àbà mọ wọ́n lẹ́sẹ̀.
ⲕ̅ⲇ̅ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲀϤϬⲒ ⲚⲞⲨϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲀϤϨⲒⲦⲞⲨ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒϢⲦⲈⲔⲞ ⲈⲦⲤⲀϦⲞⲨⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲀϪⲢⲞ ⲚⲚⲞⲨϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲈⲠⲒϢⲈ.
25 Ṣùgbọ́n láàrín ọ̀gànjọ́ Paulu àti Sila ń gbàdúrà, wọ́n sì ń kọrin ìyìn si Ọlọ́run, àwọn ara túbú sì ń tẹ́tí sí wọn.
ⲕ̅ⲉ̅ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲦⲪⲀϢⲒ ⲘⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲤⲒⲖⲀⲤ ⲈⲨⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲈⲤⲐⲈ ⲚⲀⲨⲤⲘⲞⲨ ⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲚⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦⲤⲞⲚϨ.
26 Lójijì ilẹ̀ mímì ńlá sì mi, tó bẹ́ẹ̀ tí ìpìlẹ̀ ilé túbú mì tìtì: lọ́gán, gbogbo ìlẹ̀kùn sì ṣí, ìdè gbogbo wọn sì tú sílẹ̀.
ⲕ̅ⲋ̅ⲚⲞⲨϨⲞϮ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲞϮ ⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲘⲘⲞⲚⲘⲈⲚ ϨⲰⲤⲆⲈ ⲚⲤⲈⲔⲒⲘ ⲚϪⲈⲚⲒⲤⲈⲚϮ ⲚⲦⲈⲠⲒⲘⲀ ⲚⲤⲰⲚϨ ⲚϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲆⲈ ⲀⲨⲞⲨⲰⲚ ⲚϪⲈⲚⲒⲢⲰⲞⲨ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲒⲤⲚⲀⲨϨ ⲚⲦⲰⲞⲨ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲀⲨⲂⲰⲖ ⲈⲂⲞⲖ.
27 Nígbà tí onítúbú si tají, tí o sì ri pé, àwọn ìlẹ̀kùn túbú tí ṣí sílẹ̀, ó fa idà rẹ̀ yọ, ó sì fẹ́ pa ara rẹ̀, ó ṣe bí àwọn ara túbú ti sálọ.
ⲕ̅ⲍ̅ⲈⲦⲀϤⲚⲈϨⲤⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲒⲢⲈϤⲀⲢⲈϨ ⲚⲦⲈⲠⲒⲘⲀ ⲚⲤⲰⲚϨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲚⲒⲢⲰⲞⲨ ⲚⲦⲈⲠⲒϢⲦⲈⲔⲞ ⲈⲨⲞⲨⲎⲚ ⲀϤⲐⲰⲔⲈⲘ ⲚⲦⲈϤⲤⲎϤⲒ ⲈϤⲚⲀϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲈϤⲘⲈⲨⲒ ϪⲈ ⲀⲨⲪⲰⲦ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦⲤⲰⲚϨ.
28 Ṣùgbọ́n Paulu gbé ohun rẹ̀ sókè, wí pé, “Má ṣe pa ara rẹ lára: nítorí gbogbo wa ń bẹ níhìn-ín yìí!”
ⲕ̅ⲏ̅ⲀϤⲰϢ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲤⲘⲎ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢ ϨⲖⲒ ⲘⲠⲈⲦϨⲰⲞⲨ ⲚⲀⲔ ⲦⲈⲚⲘⲠⲀⲒⲘⲀ ⲄⲀⲢ ⲦⲎⲢⲞⲨ.
29 Nígbà tí ó sì béèrè iná, ó bẹ́ wọ inú ilé, ó ń wárìrì, ó wólẹ̀ níwájú Paulu àti Sila.
ⲕ̅ⲑ̅ⲀϤϬⲒ ⲆⲈ ⲚⲞⲨⲰⲒⲚⲒ ⲀϤϬⲞϪⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲐⲈⲢⲦⲈⲢ ⲀϤϨⲒⲦϤ ⲈϦⲢⲎⲒ ϦⲀⲢⲀⲦϤ ⲘⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲤⲒⲖⲀⲤ.
30 Ó sì mú wọn jáde, ó ní, “Alàgbà, kín ni ki èmi ṣe ki n lè là?”
ⲗ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲈⲚⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲀϬⲒⲤⲈⲨ ⲞⲨ ⲠⲈⲦⲤⲈⲘⲠϢⲀ ⲚⲦⲀⲀⲒϤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲀⲚⲞϨⲈⲘ.
31 Wọ́n sì wí fún un pé, “Gbá Jesu Kristi Olúwa gbọ́, a ó sì gbà ọ́ là, ìwọ àti àwọn ará ilé rẹ pẹ̀lú.”
ⲗ̅ⲁ̅ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲀϨϮ ⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲔⲈⲚⲞϨⲈⲘ ⲚⲐⲞⲔ ⲚⲈⲘ ⲠⲈⲔⲎⲒ.
32 Wọ́n sì sọ ọ̀rọ̀ Olúwa fún un, àti fún gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀.
ⲗ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲘⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲠϬⲞⲒⲤ ⲚⲐⲞϤ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤⲎⲒ ⲦⲎⲢϤ.
33 Ó sì mú wọn ní wákàtí náà lóru, ó wẹ ọgbẹ́ wọn; a sì bamitiisi rẹ̀, àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ lójúkan náà.
ⲗ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲖⲞⲨ ⲚϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲚⲦⲈⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲀϤϪⲞⲔⲘⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲞⲨⲈⲢϦⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϬⲒⲰⲘⲤ ⲚⲐⲞϤ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤⲎⲒ ⲦⲎⲢϤ.
34 Ó sì mú wọn wá sí ilé rẹ̀, ó sì gbé oúnjẹ kalẹ̀ níwájú wọn, ó sì yọ̀ gidigidi pẹ̀lú gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, nítorí ó gba Ọlọ́run gbọ́.
ⲗ̅ⲇ̅ⲈⲦⲀϤⲈⲚⲞⲨ ⲆⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲈϤⲎⲒ ⲀϤⲬⲀ ⲞⲨⲦⲢⲀⲠⲈⲌⲀ ϦⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲐⲈⲖⲎ ⲖⲘⲘⲞϤ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤⲎⲒ ⲦⲎⲢϤ ⲈⲦⲀϤⲚⲀϨϮ ⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
35 Ṣùgbọ́n nígbà tí ilẹ̀ mọ́, àwọn onídàájọ́ rán àwọn ọlọ́pàá pé, “Tú àwọn ènìyàn náà sílẹ̀.”
ⲗ̅ⲉ̅ⲈⲦⲀ ⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲆⲈ ϢⲰⲠⲒ ⲀⲨⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚϪⲈⲚⲒⲤⲀⲦⲎⲄⲞⲨⲤ ⲚϨⲀⲚⲢⲀⲂⲆⲞⲨⲬⲞⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲬⲀ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲈⲂⲞⲖ.
36 Onítúbú sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Paulu, wí pé, “Àwọn onídàájọ́ ránṣẹ́ pé kí á da ìwọ àti Sila sílẹ̀. Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ jáde kí ẹ sì máa lọ ní àlàáfíà.”
ⲗ̅ⲋ̅ⲀϤⲦⲀⲘⲈ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲆⲈ ⲈⲚⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲚϪⲈⲠⲒⲢⲈϤⲀⲢⲈϨ ⲚⲦⲈⲠⲒⲘⲀ ⲚⲤⲰⲚϨ ϪⲈ Ⲁ- ⲚⲒⲤⲀⲦⲎⲄⲞⲨⲤ ⲞⲨⲰⲢⲠ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈⲬⲀ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϮⲚⲞⲨ ⲞⲨⲚ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ϦⲈⲚⲞⲨϨⲒⲢⲎⲚⲎ.
37 Ṣùgbọ́n Paulu wí fún wọn pé, “Wọ́n lù wá ni gbangba, wọ́n sì sọ wá sínú túbú ni àìjẹ̀bi, àwa ẹni tí ì ṣe ara Romu. Ṣe nísinsin yìí wọ́n fẹ́ tì wá jáde níkọ̀kọ̀? Rara! Ṣùgbọ́n kí àwọn tìkára wọn wá mú wa jáde!”
ⲗ̅ⲍ̅ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲈⲦⲀⲨϨⲒⲞⲨⲒ ⲈⲢⲞⲚ ⲚⲆⲎⲘⲞⲤⲒⲀ ⲈⲀⲚⲞⲚ ϨⲀⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲚⲦⲈⲚⲈⲢⲠⲔⲈϨⲰⲞⲨⲒ ⲘⲠϨⲀⲠ ⲀⲚ ⲀⲨϨⲒⲦⲦⲈⲚ ⲈⲠϢⲦⲈⲔⲞ ⲞⲨⲞϨ ⲤⲈϨⲒⲞⲨⲒ ⲘⲘⲞⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲬⲰⲠ ⲘⲘⲞⲚ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀⲢⲞⲨⲒ ⲚⲐⲰⲞⲨⲒ ⲚⲤⲈⲈⲚⲦⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ.
38 Àwọn ọlọ́pàá sì sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn onídàájọ́: ẹ̀rù sì bà wọ́n, nígbà tí wọ́n gbọ́ pé ará Romu ni Paulu àti Sila.
ⲗ̅ⲏ̅ⲀⲨⲦⲀⲘⲈ ⲚⲒⲤⲀⲦⲎⲄⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲈⲚⲀⲒⲤⲀϪⲒ ⲚϪⲈⲚⲒⲢⲀⲂⲆⲞⲨⲬⲞⲤ ⲀⲨⲈⲢϨⲞϮ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ϪⲈ ϨⲀⲚⲢⲰⲘⲈⲞⲤ ⲚⲈ.
39 Wọ́n sì wá, wọ́n ṣìpẹ̀ lọ́dọ̀ wọ́n, wọn sì mú wọn jáde, wọ́n sì bẹ̀ wọ́n pé, ki wọn jáde kúrò ni ìlú náà.
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲀⲨϦⲰⲚϪ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲈⲚⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲀⲨϮϨⲞ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲐⲢⲞⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲞⲨⲠⲞⲖⲒⲤ.
40 Paulu àti Sila sì jáde nínú túbú, wọ́n sì wọ ilé Lidia lọ, nígbà tí wọn sì tí rí àwọn arákùnrin, wọ́n tù wọ́n nínú, wọn sì jáde kúrò.
ⲙ̅ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒϢⲦⲈⲔⲞ ⲀⲨϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲎⲒ ⲚⲖⲨⲆⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲀⲨϮⲚⲞⲘϮ ⲚⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ.