< Acts 15 >
1 Àwọn ọkùnrin kan tí Judea sọ̀kalẹ̀ wá, wọ́n sì kọ́ àwọn arákùnrin pé, “Bí kò ṣe pé a bá kọ yín ni ilà bí ìṣe Mose, ẹ̀yin kí yóò lè là.”
But men from Jihud came down and taught the brethren, If you be not circumcised after the custom of the law, you cannot be saved.
2 Nígbà tí Paulu àti Barnaba ni ìyapa àti ìyàn jíjà tí kò mọ níwọ̀n pẹ̀lú ara wọn, wọ́n yan Paulu àti Barnaba àti àwọn mìíràn nínú aposteli kí wọn gòkè lọ sí Jerusalẹmu, sọ́dọ̀ àwọn alàgbà nítorí ọ̀ràn yìí.
And there were great agitation and disputation for Paulos and Bar Naba with them; and it was that Paulos and Bar Naba, and others with them, went up to the apostles and presbyters who were in Urishlem on account of this question.
3 Nítorí náà, bí ìjọ ti rán wọn jáde lọ sí ọ̀nà wọn, wọn la Fonisia àti Samaria kọjá, wọ́n ń ròyìn ìyípadà àwọn aláìkọlà, wọ́n sì fi ayọ̀ ńlá fún gbogbo àwọn arákùnrin.
And conducting, the church dismissed them; and they went through all Punika, and also among the Shomroyee, declaring the conversion of the Gentiles; and they caused great joy unto all the brethren.
4 Nígbà tí wọn sì dé Jerusalẹmu, ìjọ àti àwọn aposteli àti àwọn alàgbà tẹ́wọ́gbà wọ́n, wọ́n sì ròyìn ohun gbogbo tí Ọlọ́run ti ṣe nípasẹ̀ wọn.
AND when they came to Urishlem, they were received by the church, and by the apostles, and by the presbyters. And they recounted to them how much Aloha had done with them;
5 Ṣùgbọ́n àwọn kan nínú ẹ̀yà àwọn Farisi tí wọ́n gbàgbọ́ dìde, wọ́n ń wí pé, “A ní láti kọ wọ́n ní ilà, àti láti pàṣẹ fún wọn pé kí wọn máa pa òfin Mose mọ́.”
but (that) certain had arisen who had believed from the doctrine of the Pharishee, and said, It behoved you to circumcise them, and require them to keep the law of Musha.
6 Àwọn aposteli àti àwọn alàgbà péjọ láti rí si ọ̀ràn yìí.
But the apostles and presbyters assembled to consider this doctrine.
7 Nígbà tí iyàn sì di púpọ̀, Peteru dìde, ó sì wí fún wọn pé, “Ará, ẹ̀yin mọ̀ pé, láti ìbẹ̀rẹ̀ ni Ọlọ́run ti yàn nínú yín pé, kí àwọn aláìkọlà lè gbọ́ ọ̀rọ̀ ìyìnrere láti ẹnu mi, kí wọn sì gbàgbọ́.
And when there had been much investigation, Shemun arose, and said to them, Men, brethren, you know that from the first days from my mouth did Aloha choose that the Gentiles should hear the word of the gospel and believe.
8 Ọlọ́run, tí ó jẹ́ olùmọ̀-ọkàn, sì jẹ́ wọn lẹ́rìí, ó fún wọn ni Ẹ̀mí Mímọ́, gẹ́gẹ́ bí àwa.
And Aloha, who knoweth what is in the hearts, testified of them, and gave them the Spirit of Holiness, as to us.
9 Kò sí fi ìyàtọ̀ sí àárín àwa àti àwọn, ó ń fi ìgbàgbọ́ wẹ̀ wọ́n lọ́kàn mọ́.
And nothing distinguished between us and them, because he had purified by faith their hearts.
10 Ǹjẹ́ nítorí náà èéṣe tí ẹ̀yin o fi dán Ọlọ́run wò, láti fi àjàgà bọ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́rùn, èyí tí àwọn baba wa àti àwa kò lè rù?
And now why tempt you Aloha, that you would lay a yoke upon the necks of the disciples, which nor our fathers nor we could bear?
11 Ṣùgbọ́n àwa gbàgbọ́ pé nípa oore-ọ̀fẹ́ Olúwa Jesu àwa ó là, gẹ́gẹ́ bí àwọn.”
But by the grace of our Lord Jeshu Meshiha, we believe that we shall be saved, as they.
12 Gbogbo àjọ sí dákẹ́, wọ́n sì fi etí sí Barnaba àti Paulu, tí wọn ń ròyìn iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì tí Ọlọ́run tí ti ọwọ́ wọn ṣe láàrín àwọn aláìkọlà.
And all the assembly were silent. And they listened to Paulos and Bar Naba, who related how Aloha had done by their hands signs and mighty works among the Gentiles.
13 Lẹ́yìn tí wọn sì dákẹ́, Jakọbu dáhùn, wí pé, “Ará, ẹ gbọ́ tèmi,
AND after they were silent, Jakub arose, and said, Men, brethren, hear me:
14 Simeoni ti ròyìn bí Ọlọ́run ti kọ́kọ́ bojú wo àwọn aláìkọlà, láti yàn ènìyàn nínú wọn fún orúkọ rẹ̀.
Shemun hath related to you how Aloha hath begun to elect from the Gentiles a people to his name.
15 Báyìí ni ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì bá ṣe déédé; bí a ti kọ̀wé rẹ̀ pé:
And with this accord the words of the prophets; as when it is written,
16 “‘Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni èmi ó padà, èmi ó sì tún àgọ́ Dafidi pa tí ó ti wó lulẹ̀: èmi ó sì tún ahoro rẹ̀ kọ́, èmi ó sì gbé e ró.
After these I will return, And raise the dwelling of David which hath fallen; And I will build that which hath fallen from it, And will raise it up:
17 Kí àwọn ènìyàn ìyókù lè máa wá Olúwa, àti gbogbo àwọn kèfèrí, lára ẹni tí a ń pe orúkọ mi,’ ni Olúwa wí, ta ni ó ń ṣe nǹkan wọ̀nyí,
That the residue of men may seek the Lord, And all the Gentiles, on whom my name is called,
18 ẹni tí ó sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí di mímọ́ láti ọjọ́ pípẹ́ wá. (aiōn )
Saith the Lord, who doeth all these. Known from eternity are the works of Aloha. (aiōn )
19 “Ǹjẹ́ ìmọ̀ràn tèmi ni pé, kí a máa ṣe yọ àwọn ti aláìkọlà ti ó yípadà sí Ọlọ́run lẹ́nu.
On this account I say, that we should not molest those who from the Gentiles have been converted unto Aloha;
20 Ṣùgbọ́n kí a kọ̀wé si wọn, kí wọ́n fàsẹ́yìn kúrò nínú oúnjẹ tí a ṣe fún òrìṣà, àti kúrò nínú àgbèrè, àti nínú ẹ̀jẹ̀.
but that we send to them, that they shall separate from the uncleanness of (idol) sacrifice, and from fornication, and from the strangled, and from blood.
21 Nítorí òfin Mose nígbà àtijọ́ ṣá ní a ti ń wàásù rẹ̀, ni ìlú gbogbo, a máa ń kà á nínú Sinagọgu ni ọjọọjọ́ ìsinmi.”
For Musha from former generations in all cities hath had preachers in the synagogues who on all shabaths read him.
22 Nígbà nà án ni ó tọ́ lójú àwọn aposteli, àti àwọn alàgbà pẹ̀lú gbogbo ìjọ, láti yan ènìyàn nínú wọn, àti láti rán wọ́n lọ sí Antioku pẹ̀lú Paulu àti Barnaba: Judasi ti a ń pè àpèlé rẹ̀ ní Barsaba, àti Sila, ẹni tí ó lórúkọ nínú àwọn arákùnrin.
Then the apostles and presbyters, with all the church, elected men from them, and sent to Antiokia with Paulos and Bar Naba Jihuda, who was called Bar Shaba, and Shilo, men who were chief among the brethren.
23 Wọn sì kọ ìwé lé wọn lọ́wọ́ báyìí pé, Àwọn aposteli, àti àwọn alàgbà, tí ó jẹ́ ti aláìkọlà tí ó wà ní Antioku, àti ní Siria, àti ní Kilikia.
AND they wrote an epistle by their hands, thus: The apostles and presbyters and brethren, to those who are in Antiokia and in Syria and in Cilicia, the brethren who are of the Gentiles; peace.
24 Níwọ́n bí àwa ti gbọ́ pé, àwọn kan ti ó ti ọ̀dọ̀ wa jáde wá ń fi ọ̀rọ̀ yọ yín lẹ́nu, tí wọ́n ń yí yín ní ọkàn padà (wí pé, ẹ kò gbọdọ̀ ṣàìmá kọ ilà, àti ṣàìmá pa òfin Mose mọ́), ẹni tí àwa kò fún ní àṣẹ.
It hath been heard by us, that men from us have gone forth and disturbed you with words, and have subverted your souls by saying, that you should be circumcised and observe the law, whom we have not commanded.
25 Ó yẹ lójú àwa, bí wa ti fi ìmọ̀ ṣọ̀kan láti yan ènìyàn láti rán wọn sí yín, pẹ̀lú Barnaba àti Paulu àwọn olùfẹ́ wa.
On account of this we have deliberated, all being assembled, and have chosen men and sent them to you, with Paulos and Bar Naba, our beloved;
26 Àwọn ọkùnrin ti ó fi ọkàn wọn wéwu nítorí orúkọ Olúwa wa Jesu Kristi.
men who have delivered their lives for the sake of the name of our Lord Jeshu Meshiha.
27 Nítorí náà àwa rán Judasi àti Sila àwọn tí yóò sì fi ọ̀rọ̀ ẹnu sọ ohun kan náà fún yín.
And we have sent with them Jihuda and Shilo, that by word they may tell you the same things.
28 Nítorí ó dára lójú Ẹ̀mí Mímọ́, àti lójú wa, kí a má ṣe di ẹrù le é yin lórí, bí kò ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tí ó ṣe pàtàkì;
For it hath been the will of the Spirit of Holiness, and also of us, not to lay upon you greater burden beyond these things which are constraining;
29 í ẹ̀yin fàsẹ́yìn kúrò nínú ẹran ti à pa bọ òrìṣà, àti nínú ẹ̀jẹ̀ àti nínú ohun ìlọ́lọ́rùnpa, àti nínú àgbèrè. Bí ẹ̀yin bá pa ara yín mọ́ kúrò, ẹ̀yin ó ṣe rere. Àlàáfíà.
that you abstain from that which hath been sacrificed (to idols), and from blood, and from that which is strangled, and from fornication; and while you keep yourselves from these, you will be well. Be confirmed in our Lord.
30 Ǹjẹ́ nígbà tí wọ́n sì fi wọ́n sílẹ̀ láti lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá si Antioku. Nígbà tí wọn sì pé àwọn ìjọ papọ̀, wọn fi ìwé náà fún wọn.
Now they who were sent came to Antiokia, and they assembled all the people and gave the epistle.
31 Nígbà tí wọn sì kà á, wọ́n yọ̀ fún ìtùnú náà.
And when they had read, they rejoiced and were comforted.
32 Bí Judasi àti Sila tìkára wọn ti jẹ́ wòlíì pẹ̀lú, wọ́n fi ọ̀rọ̀ púpọ̀ gba àwọn arákùnrin níyànjú, wọ́n sì mú wọn lọ́kàn le.
And by the word the brethren were the more strengthened, and Jihuda and Shilo established them because they were prophets also.
33 Nígbà tí wọn sì pẹ́, díẹ̀, àwọn arákùnrin rán wọn padà lọ ni àlàáfíà sí ọ̀dọ̀ àwọn tí ó rán wọn wá.
And when they had been there a time, the brethren dismissed them with peace unto the apostles.
35 Paulu àti Barnaba sì dúró díẹ̀ ni Antioku, wọ́n ń kọ́ni, wọ́n sì ń wàásù ọ̀rọ̀, Olúwa, àti àwọn púpọ̀ mìíràn pẹ̀lú wọn.
BUT Paulos and Bar Naba remained in Antiokia, and taught and preached, with many others, the word of Aloha.
36 Lẹ́yìn ọjọ́ mélòó kan, Paulu sì sọ fún Barnaba pé, “Jẹ́ kí a tún padà lọ bẹ àwọn arákùnrin wa wò, bí wọn ti ń ṣe sí ni ìlú gbogbo tí àwa ti wàásù ọ̀rọ̀ Olúwa.”
And after (certain) days Paulos said to Bar Naba, Let us return and visit the brethren in every city in which we have preached the word of Aloha, and see what they do.
37 Barnaba sì pinnu rẹ̀ láti mú Johanu lọ pẹ̀lú wọn, ẹni tí àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Marku.
But Bar Naba willed to take Juhanon, he who is surnamed Markos.
38 Ṣùgbọ́n Paulu rò pé, kò yẹ láti mú un lọ pẹ̀lú wọn, ẹni tí ó fi wọn sílẹ̀ ni Pamfilia, tí kò sì bá wọn lọ sí iṣẹ́ náà.
But Paulos willed not to take him with them, because he had forsaken them when they were in Pamphylia, and had not come with them.
39 Ìjà náà sì pọ̀ tó bẹ́ẹ̀, tí wọn ya ara wọn sì méjì, Barnaba sì mu Marku ó tẹ ọkọ́ létí lọ sí Saipurọsi.
On account of this contention they separated one from the other; and Bar Naba took Markos, and they went by sea and came to Cypros.
40 Ṣùgbọ́n Paulu yan Sila, ó sì lọ, bí a ti fi lé oore-ọ̀fẹ́ Olúwa lọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin.
But Paulos chose for him Shilo, and went forth commended by the brethren to the grace of Aloha.
41 Ó sì la Siria àti Kilikia lọ, ó ń mú ìjọ ní ọkàn le.
And he went through Syria and Cilicia, confirming the churches. And he came to Derbe the city, and to Lystra.