< Acts 14 >

1 Ó sí ṣe, ni Ikoniomu, Paulu àti Barnaba jùmọ̀ wọ inú Sinagọgu àwọn Júù lọ, wọ́n sì sọ̀rọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Júù àti àwọn Helleni gbàgbọ́.
ⲁ̅ⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚⲒⲔⲞⲚⲒⲞⲚ ⲔⲀⲦⲀ ⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲢⲰ ⲈⲐⲢⲞⲨϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲚⲦⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲈⲤⲀϪⲒ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ϨⲰⲤⲆⲈ ⲚⲤⲈⲚⲀϨϮ ⲚϪⲈⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲘⲘⲎϢ ⲚⲦⲈⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲞⲨⲈⲒⲚⲒⲚ.
2 Ṣùgbọ́n àwọn aláìgbàgbọ́ Júù rú ọkàn àwọn aláìkọlà sókè, wọ́n sì mú wọn ni ọkàn ìkorò sí àwọn arákùnrin náà.
ⲃ̅ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲈⲢⲀⲦⲐⲰⲦ ⲚϨⲎⲦ ⲀⲨⲦⲰⲞⲨⲚⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϮⲘⲔⲀϨ ⲚⲚⲒⲮⲨⲬⲎ ⲚⲦⲈⲚⲒⲈⲐⲚⲞⲤ ⲈⲐⲂⲈ ⲚⲒⲤⲚⲎⲞⲨ.
3 Nítorí náà Paulu àti Barnaba gbé ibẹ̀ pẹ́, wọ́n ń fi ìgboyà sọ̀rọ̀ nínú Olúwa, ẹni tí ó jẹ́rìí sí ọ̀rọ̀ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, ó sì mu kí iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu máa ti ọwọ́ wọn ṣe.
ⲅ̅ⲀⲨⲈⲢ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲚ ⲚⲬⲢⲞⲚⲞⲤ ⲘⲘⲀⲨ ⲈⲨⲞⲨⲞⲚϨ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲪⲢⲀⲚ ⲘⲠϬⲞⲒⲤ ⲪⲀⲒ ⲈⲦⲈⲢⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲤⲀϪⲒ ⲚⲦⲈⲠⲈϤϨⲘⲞⲦ ⲈϤϮ ⲚϨⲀⲚⲘⲎⲒⲚⲒ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚϢⲪⲎ ⲢⲒ ⲈⲐⲢⲞⲨϢⲰⲠⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲚⲞⲨϪⲒϪ.
4 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ìlú náà pín sí méjì: apá kan dàpọ̀ mọ́ àwọn Júù, apá kan pẹ̀lú àwọn aposteli.
ⲇ̅ⲀϤⲪⲰⲢϪ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲠⲒⲘⲎϢ ⲚⲦⲈϮⲠⲞⲖⲒⲤ ϨⲀⲚⲞⲨⲞⲚ ⲘⲈⲚ ⲚⲀⲨⲬⲎ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲨⲬⲎ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲀⲠⲞⲤⲦⲞⲖⲞⲤ.
5 Bí àwọn aláìkọlà, àti àwọn Júù pẹ̀lú àwọn olórí wọn ti fẹ́ kọlù wọ́n láti fi àbùkù kàn wọ́n, àti láti sọ wọ́n ní òkúta,
ⲉ̅ⲈⲦⲀⲨϬⲞϪⲒ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲈⲐⲚⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲞⲨⲔⲈⲀⲢⲬⲰⲚ ⲈϢⲞϢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲤⲈⲦⲰⲚⲒ ⲈϪⲰⲞⲨ.
6 wọ́n gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì sálọ sí Lysra, àti Dabe, àwọn ìlú Likaonia àti sí agbègbè àyíká.
ⲋ̅ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲀⲨⲪⲰⲦ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲚⲒⲠⲞⲖⲒⲤ ⲚⲦⲈⲖⲨⲔⲀⲞⲚⲒⲀ ⲖⲨⲤⲦⲢⲀ ⲚⲈⲘ ⲦⲈⲢⲂⲎ ⲚⲈⲘ ϮⲠⲈⲢⲒⲬⲰⲢⲞⲤ
7 Níbẹ̀ ni wọ́n sì ń wàásù ìyìnrere.
ⲍ̅ⲚⲀⲨϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ⲘⲘⲀⲨ ⲠⲈ
8 Ọkùnrin kan sí jókòó ni Lysra, ẹni tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò mókun, arọ láti inú ìyá rẹ̀ wá, tí kò rìn rí.
ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲀⲦϪⲞⲘ ϦⲈⲚⲚⲈϤϬⲀⲖⲀⲨϪ ϦⲈⲚⲖⲨⲤⲦⲢⲀ ⲚⲀϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲈϤⲞⲒ ⲚϬⲀⲖⲈ ⲒⲤϪⲈⲚ ⲈϤϦⲈⲚ ⲐⲚⲈϪⲒ ⲚⲦⲈⲦⲈϤⲘⲀⲨ ⲘⲠⲈϤⲘⲞϢⲒ ⲈⲚⲈϨ.
9 Ọkùnrin yìí gbọ́ bí Paulu ti ń sọ̀rọ̀: ẹni, nígbà tí ó tẹjúmọ́ ọn ti ó sì rí i pé, ó ni ìgbàgbọ́ fún ìmúláradá.
ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲪⲀⲒ ⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲤⲞⲘⲤ ⲈⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲈⲘⲒ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲀϨϮ ⲚϦⲎⲦϤ ⲈⲚⲞϨⲈⲘ.
10 Ó wí fún un ní ohùn rara pé, “Dìde dúró ṣánṣán lórí ẹsẹ̀ rẹ!” Ó sì ń fò sókè, ó sì ń rìn.
ⲓ̅ⲠⲈϪⲀϤ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲤⲘⲎ ϪⲈ ⲦⲰⲚⲔ ⲞϨⲒ ⲈⲢⲀⲦⲔ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲈⲔϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϬⲒⲪⲈⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲘⲞϢⲒ.
11 Nígbà tí àwọn ènìyàn sì rí ohun tí Paulu ṣe, wọ́n gbé ohùn wọn sókè ni èdè Likaonia, wí pé, “Àwọn ọlọ́run sọ̀kalẹ̀ tọ̀ wá wá ni àwọ̀ ènìyàn!”
ⲓ̅ⲁ̅ⲚⲒⲘⲎϢ ⲘⲈⲚ ⲞⲨⲚ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲈⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲀⲒϤ ⲚϪⲈⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲀⲨϬⲒⲤⲒ ⲚⲦⲞⲨⲤⲘⲎ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲘⲘⲈⲦⲖⲨⲔⲀⲰⲚ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ Ⲁ- ⲚⲒⲚⲞⲨϮ ⲈⲢ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲀⲨⲒ ⲈⲠⲈⲤⲎⲦ ϢⲀⲢⲞⲚ.
12 Wọn sì pe Barnaba ni Seusi àti Paulu ni Hermesi nítorí òun ni olórí ọ̀rọ̀ sísọ.
ⲓ̅ⲃ̅ⲚⲀⲨⲘⲞⲨϮ ⲘⲈⲚ ⲈⲂⲀⲢⲚⲀⲂⲀⲤ ϪⲈ ⲠⲒⲌⲈⲨⲤ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲆⲈ ϪⲈ ⲠⲒⲈⲢⲘⲎⲤ ⲈⲠⲒⲆⲎ ⲚⲐⲞϤ ⲈⲦⲞⲒ ⲚϨⲨⲄⲞⲨⲘⲈⲚⲞⲤ ⲚⲦⲈⲠⲒⲤⲀϪⲒ.
13 Àlùfáà Seusi, ẹni ti ilé òrìṣà rẹ̀ wá lẹ́yìn odi ìlú wọn sì mú màlúù àti màrìwò wá sí ẹnu ibodè láti rú ẹbọ pẹ̀lú ìjọ ènìyàn sí àwọn aposteli wọ̀nyí.
ⲓ̅ⲅ̅ⲠⲒⲞⲨⲎⲂ ⲆⲈ ⲚⲦⲈⲠⲒⲌⲈⲨⲤ ⲪⲎ ⲈⲚⲀϤⲬⲎ ϦⲀϪⲰⲤ ⲚϮⲠⲞⲖⲒⲤ ⲀϤⲒⲚⲒ ⲚϨⲀⲚⲘⲀⲤⲒ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲬⲖⲞⲘ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲠⲒⲠⲨⲖⲰⲚ ⲚⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲈϢⲰⲦ ⲠⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲘⲎϢ.
14 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn aposteli Barnaba àti Paulu gbọ́, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọn sí súré wọ inú àwùjọ, wọn ń ké rara pé:
ⲓ̅ⲇ̅ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲠⲞⲤⲦⲞⲖⲞⲤ ⲂⲀⲢⲚⲀⲂⲀⲤ ⲚⲈⲘ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲀⲨⲪⲰϦ ⲚⲚⲞⲨϨⲂⲰⲤ ⲀⲨϬⲞϪⲒ ϢⲀ ⲠⲒⲘⲎϢ ⲈⲨⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ
15 “Ará, èéṣe ti ẹ̀yin fi ń ṣe nǹkan wọ̀nyí? Ènìyàn bí ẹ̀yin náà ni àwa ń ṣe pẹ̀lú, ti a sì ń wàásù ìyìnrere fún yín, kí ẹ̀yin ba à lè yípadà kúrò nínú ohun asán wọ̀nyí sí Ọlọ́run alààyè, tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn.
ⲓ̅ⲉ̅ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲒⲢⲰⲘⲒ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲒⲢⲒ ⲚⲚⲀⲒ ⲀⲚⲞⲚ ϨⲰⲚ ⲀⲚⲞⲚ ϨⲀⲚⲢⲰⲘⲒ ⲚⲢⲈϤϢⲈⲠⲘⲔⲀϨ ⲘⲠⲈⲦⲈⲚⲢⲎϮ ⲈⲚϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲈϨⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲚⲚⲒⲘⲈⲦⲈⲪⲖⲎⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲔⲈⲦ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦⲞⲚϦ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤⲐⲀⲘⲒⲞ ⲚⲦⲪⲈ ⲚⲈⲘ ⲠⲔⲀϨⲒ ⲚⲈⲘ ⲪⲒⲞⲘ ⲚⲈⲘ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲈⲚϦⲎⲦⲞⲨ.
16 Ní ìran tí ó ti kọjá, ó faradà á fún gbogbo orílẹ̀-èdè, láti máa rìn ni ọ̀nà tiwọn.
ⲓ̅ⲋ̅ⲪⲎ ⲈⲦⲈ ⲚϦⲢⲎⲒ ϦⲈⲚⲚⲒⲄⲈⲚⲈⲀ ⲈⲦⲀⲨⲤⲒⲚⲒ ⲀϤⲬⲰ ⲚⲚⲒⲈⲐⲚⲞⲤ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲈⲐⲢⲞⲨⲘⲞϢⲒ ϨⲒ ⲚⲞⲨⲘⲰⲒⲦ.
17 Ṣùgbọ́n kò fi ara rẹ̀ sílẹ̀ ní àìní ẹ̀rí, ní ti pé ó ṣe rere, ó ń fún yín lójò láti ọ̀run wá, àti ni àkókò èso, ó ń fi oúnjẹ àti ayọ̀ kún ọkàn yín.”
ⲓ̅ⲍ̅ⲔⲈⲦⲞⲒ ⲘⲠⲈϤⲬⲀϤ ⲈϤⲞⲒ ⲚⲀⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲈϤⲒⲢⲒ ⲚϨⲀⲚⲠⲈⲐⲚⲀⲚⲈⲨ ⲀϤϮ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲘⲞⲨⲚϨⲰⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲪⲈ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚⲤⲎⲞⲨ ⲘⲘⲀⲤⲞⲨⲦⲀϨ ⲈϤⲦⲤⲒⲞ ⲚⲚⲈⲦⲈⲚϨⲎⲦ ⲚϦⲢⲈ ⲚⲈⲘ ⲞⲨⲚⲞϤ.
18 Díẹ̀ ni ó kù kí wọn má le fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ènìyàn dúró, kí wọn má ṣe rú ẹbọ bọ wọ́n.
ⲓ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲘⲞⲄⲒⲤ ⲀⲨⲐⲢⲈ ⲠⲒⲘⲎϢ ϨⲈⲢⲒ ⲈϢⲦⲈⲘϢⲰⲦ ⲚⲰⲞⲨ.
19 Àwọn Júù kan sì ti Antioku àti Ikoniomu wá, nígbà tí wọ́n yí àwọn ènìyàn lọ́kàn padà, wọ́n sì sọ Paulu ní òkúta, wọ́n wọ́ ọ kúrò sí ẹ̀yin odi ìlú náà, wọn ṣe bí ó ti kú.
ⲓ̅ⲑ̅ⲀⲨϢⲈ ⲆⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲦⲀⲚⲦⲒⲞⲬⲒⲀ ⲚⲈⲘ ⲒⲔⲞⲚⲒⲞⲚ ⲚϪⲈϨⲀⲚⲒⲞⲨⲆⲀⲒ ⲀⲨⲐⲈⲦ ϨⲎⲦ ⲚⲚⲒⲘⲎϢ ⲀⲨϨⲒⲰⲚⲒ ⲈϪⲈⲚ ⲠⲀⲨⲖⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲰϢϮ ⲘⲘⲞϤ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲚϮⲠⲞⲖⲒⲤ ⲈⲨⲘⲈⲨⲒ ϪⲈ ⲀϤⲘⲞⲨ.
20 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn dúró ti i yíká, ó dìde ó sì padà wọ inú ìlú náà lọ. Ní ọjọ́ kejì ó bá Barnaba lọ sí Dabe.
ⲕ̅ⲈⲨⲔⲰϮ ⲆⲈ ⲈⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲒⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲈⲦⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲆⲈ ⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲂⲀⲔⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϤⲢⲀⲤϮ ⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚⲈⲘ ⲂⲀⲢⲚⲀⲂⲀⲤ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲦⲈⲢⲂⲎ.
21 Nígbà tí wọ́n sì ti wàásù ìyìnrere fún ìlú náà, tí wọ́n sì ni ọmọ-ẹ̀yìn púpọ̀, wọn padà lọ sí Lysra, àti Ikoniomu, àti Antioku,
ⲕ̅ⲁ̅ⲈⲦⲀⲨϨⲒϢⲈⲚⲚⲞⲨϤⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚϮⲠⲞⲖⲒⲤ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨϮⲤⲂⲰ ⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲘⲘⲎ ϢⲀⲨⲦⲀⲤⲐⲞ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲖⲨⲤⲦⲢⲀ ⲚⲈⲘ ⲒⲔⲞⲚⲒⲞⲚ ⲚⲈⲘ ⲦⲀⲚϮⲞⲬⲒⲀ.
22 wọn sì ń mú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn lọ́kàn le, wọ́n sì ń gbà wọ́n níyànjú láti dúró nínú ìgbàgbọ́, àti pé nínú ìpọ́njú púpọ̀, ni àwa ó fi wọ ìjọba Ọlọ́run.
ⲕ̅ⲃ̅ⲈⲨⲦⲀϪⲢⲞ ⲚⲚⲒⲮⲨⲬⲎ ⲚⲦⲈⲚⲒⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲈⲨϮⲚⲞⲘϮ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲐⲢⲞⲨⲞϨⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲚⲀϨϮ ⲞⲨⲞϨ ϪⲈ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϨⲞϪϨⲈϪ ϨⲰϮ ⲈⲢⲞⲚ ⲈϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϮⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ.
23 Nígbà tí wọ́n sì ti yan àwọn alàgbà fún olúkúlùkù ìjọ, tí wọn sì ti fi àwẹ̀ gbàdúrà, wọn fi wọ́n lé Olúwa lọ́wọ, ẹni tí wọn gbàgbọ́.
ⲕ̅ⲅ̅ⲀⲨⲬⲀϪⲒϪ ⲆⲈ ⲈϪⲈⲚ ϨⲀⲚⲠⲢⲈⲤⲂⲨⲦⲈⲢⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ⲔⲀⲦⲀ ⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲦⲰⲂϨ ϦⲈⲚϨⲀⲚⲚⲎⲤⲦⲒⲀ ⲀⲨⲬⲀⲨ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲪⲎ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀϨϮ ⲈⲢⲞϤ.
24 Nígbà tí wọn sí la Pisidia já, wọ́n wá sí Pamfilia.
ⲕ̅ⲇ̅ⲈⲦⲀⲨⲤⲈⲚ ϮⲠⲒⲤⲒⲆⲒⲀ ⲆⲈ ⲀⲨⲒ ⲈϮⲠⲀⲘⲪⲨⲖⲒⲀ.
25 Nígbà tí wọn sì ti sọ ọ̀rọ̀ náà ni Perga, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Atalia.
ⲕ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲤⲀϪⲒ ⲘⲠⲒⲤⲀϪⲒ ϦⲈⲚⲠⲈⲢⲄⲎ ⲀⲨⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲀⲦⲦⲀⲖⲒⲀ.
26 Àti láti ibẹ̀ lọ wọ́n ṣíkọ̀ lọ sí Antioku ní ibi tí a gbé ti fi wọ́n lé oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run lọ́wọ́, fún iṣẹ́ tí wọ́n ṣe parí.
ⲕ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲀⲨ ⲀⲨⲈⲢϨⲰⲦ ⲈⲦⲀⲚϮⲞⲬⲒⲀ ⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲀⲨⲦⲎⲒⲦⲞⲨ ⲚϦⲎⲦϤ ϦⲈⲚⲠⲒϨⲘⲞⲦ ⲚⲦⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲠⲒϨⲰⲂ ⲈⲦⲀⲨϪⲞⲔϤ ⲈⲂⲞⲖ.
27 Nígbà tí wọ́n sì dé, tí wọ́n sì pé ìjọ jọ, wọ́n ròhìn gbogbo ohun tí Ọlọ́run fi wọ́n ṣe, àti bí ó ti ṣí ìlẹ̀kùn ìgbàgbọ́ fún àwọn aláìkọlà.
ⲕ̅ⲍ̅ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲆⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚϮⲈⲔⲔⲖⲎⲤⲒⲀ ⲚⲀⲨⲦⲀⲘⲞ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲈⲐⲂⲈ ϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲀϤⲀⲒⲦⲞⲨ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲪⲚⲞⲨϮ ⲞⲨⲞϨ ϪⲈ ⲀϤⲞⲨⲰⲚ ⲚⲞⲨⲢⲞ ⲚⲦⲈⲪⲚⲀϨϮ ⲚⲚⲒⲈⲐⲚⲞⲤ.
28 Níbẹ̀ ni wọ́n ń gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ni ọjọ́ púpọ̀.
ⲕ̅ⲏ̅ⲀⲨϢⲰⲠⲒ ⲆⲈ ⲘⲘⲀⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲚⲞⲨⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲀⲚ.

< Acts 14 >