< Acts 13 >
1 Àwọn wòlíì àti àwọn olùkọ́ni sì ń bẹ nínú ìjọ ti ó wà ni Antioku; Barnaba àti Simeoni tí a ń pè ni Nigeri, àti Lukiu ará Kirene, àti Manaeni (ẹni tí a tọ́ pọ̀ pẹ̀lú Herodu tetrarki) àti Saulu.
Antakyadiki jamaǝt iqidǝ bǝzi pǝyƣǝmbǝrlǝr wǝ tǝlim bǝrgüqilǝr bar idi. Ular Barnabas, «Ⱪara» dǝpmu atilidiƣan Ximeon, Kurinilik Lukius, Ⱨerod han bilǝn billǝ qong bolƣan Manaǝn wǝ Saullar idi.
2 Bí wọn sì ti ń jọ́sìn fún Olúwa, tí wọ́n sì ń gbààwẹ̀, Ẹ̀mí Mímọ́ wí pé, “Ẹ ya Barnaba àti Saulu sọ́tọ̀ fún mi fún iṣẹ́ ti mo ti pè wọ́n sí!”
Ular Rǝbning ibaditidǝ bolup roza tutuwatⱪan bir mǝzgildǝ, Muⱪǝddǝs Roⱨ ularƣa: — Barnabas bilǝn Saulni Mǝn ularni ⱪilixⱪa qaⱪirƣan hizmǝt üqün Manga ayrip ⱪoyunglar, — dedi.
3 Nígbà tí wọ́n sì ti gbààwẹ̀, tí wọn sì ti gbàdúrà, wọ́n gbé ọwọ́ lé wọn, wọ́n sì rán wọn lọ.
Xuning bilǝn, ular yǝnǝ roza tutup dua ⱪilƣandin keyin, ikkiylǝnning üstigǝ ⱪollirini tǝgküzüp uzitip ⱪoydi.
4 Ǹjẹ́ bí Ẹ̀mí Mímọ́ ti rán àwọn méjèèjì lọ, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Seleusia; láti ibẹ̀ wọ́n sì wọ ọkọ̀ ojú omi lọ sí Saipurọsi.
Ular Muⱪǝddǝs Roⱨ tǝripidin ǝwǝtilgǝn bolup, Sǝlyukiyǝ xǝⱨirigǝ berip, u yǝrdin kemigǝ qiⱪip Siprus ariliƣa ⱪarap yolƣa qiⱪti.
5 Nígbà ti wọ́n sì wà ni Salami, wọ́n ń wàásù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ní Sinagọgu àwọn Júù. Johanu náà sì wà pẹ̀lú wọn láti ràn wọ́n lọ́wọ́ fún ìránṣẹ́ wọn.
Salamis xǝⱨirigǝ yetip kelip, ular Yǝⱨudiylarning sinagoglirida Hudaning sɵz-kalamini yǝtküzüxkǝ baxlidi. Yuⱨanna ularning yardǝmqisi idi.
6 Nígbà tí wọ́n sì la gbogbo erékùṣù já dé Pafosi, wọ́n rí ọkùnrin oṣó àti wòlíì èké kan ti i ṣe Júù, orúkọ ẹni ti ó ń jẹ́ Bar-Jesu.
Ular pütün aralni arilap qiⱪip, Pafos xǝⱨirigǝ kǝldi. Ular u yǝrdǝ Baryǝxua isimlik bir kixi bilǝn uqrixip ⱪaldi. U seⱨirgǝr bolup, sahta pǝyƣǝmbǝr bolƣan bir Yǝⱨudiy idi.
7 Ó wà lọ́dọ̀ Segiu Paulusi baálẹ̀ ìlú náà tí í ṣe amòye ènìyàn. Òun náà ni ó ránṣẹ́ pe Barnaba àti Saulu, nítorí tí ó fẹ́ gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
U kixi bu [aralning] rimliⱪ waliyisi Sergiyus Pawlusning ⱨǝmraⱨi idi. Waliy uⱪumuxluⱪ bir kixi bolup, Barnabas bilǝn Saulni qaⱪirtip, Hudaning sɵz-kalamini anglimaⱪqi boldi.
8 Ṣùgbọ́n Elimu oṣó (nítorí bẹ́ẹ̀ ni ìtumọ̀ orúkọ rẹ̀) takò wọ́n, ó ń fẹ́ pa baálẹ̀ ni ọkàn dà kúrò ni ìgbàgbọ́.
Lekin ⱨeliⱪi seⱨirgǝr (uning grekqǝ ismi Əlimas bolup, «seⱨirgǝr» degǝn mǝnidǝ) ularƣa ⱪarxi qiⱪip, waliyning rayini etiⱪadtin ⱪayturuxni urunmaⱪta idi.
9 Ṣùgbọ́n Saulu ti a ń pè ni Paulu, ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì tẹjúmọ́ Elimu, ó sì wí pé,
Biraⱪ Muⱪǝddǝs Roⱨⱪa toldurulƣan Saul (yǝnǝ «Pawlus» dǝpmu atilidu) ⱨeliⱪi seⱨirgǝrgǝ tikilip ⱪarap
10 “Ìwọ ti ó kún fún àrékérekè gbogbo, àti fún ìwà ìkà gbogbo, ìwọ ọmọ èṣù, ìwọ ọ̀tá ohun gbogbo, ìwọ kì yóò ha dẹ́kun láti máa yí ọ̀nà òtítọ́ Olúwa po?
uningƣa: — Əy, ⱪǝlbing ⱨǝrhil ⱨiyligǝrlik wǝ aldamqiliⱪ bilǝn tolƣan Iblisning oƣli, ⱨǝmmǝ ⱨǝⱪⱪaniyliⱪning düxmini! Pǝrwǝrdigarning tüz yollirini burmilaxni zadi tohtatmamsǝn?!
11 Ǹjẹ́ nísinsin yìí wò ó, ọwọ́ Olúwa ń bẹ lára rẹ̀, ìwọ ó sì fọjú ìwọ kì yóò rí oòrùn ní sá à kan!” Lójúkan náà, ìkùùkuu àti òkùnkùn sí bò ó; ó sì ń wá ènìyàn kiri láti fa òun lọ́wọ́ lọ.
Əmdi Rǝbning ⱪoli üstünggǝ qüxti! Kɵzliring kor bolup, bir mǝzgil künning yoruⱪini kɵrǝlmǝysǝn! — dedi. Xuan, bir hil tuman wǝ ⱪarangƣuluⱪ uni basti. U yolni silaxturup, kixilǝrdin meni ⱪolumdin yetilǝnglar, dǝp iltija ⱪilatti.
12 Nígbà tí baálẹ̀ rí ohun tí ó ṣe, ó gbàgbọ́, ẹnu sì yà á sì ẹ̀kọ́ Olúwa.
Yüz bǝrgǝn ixni kɵrgǝn waliy Rǝbning tǝlimigǝ ⱪattiⱪ ⱨǝyran bolup, Uningƣa etiⱪad ⱪildi.
13 Nígbà tí Paulu àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ si ṣíkọ̀ ni Pafosi wọ́n wá sí Perga ni Pamfilia: Johanu sì fi wọ́n sílẹ̀, ó sì padà lọ sí Jerusalẹmu.
Pawlus bilǝn uning ⱨǝmraⱨliri kemigǝ qiⱪip, Pafostin Pamfiliyǝ ɵlkisidiki Pǝrgǝ xǝⱨirigǝ bardi. U yǝrdǝ Yuⱨanna ulardin ayrilip Yerusalemƣa ⱪaytti.
14 Nígbà ti wọ́n sì là Perga kọjá, wọ́n wá sí Pisidia ní Antioku. Wọ́n sì wọ inú Sinagọgu ní ọjọ́ ìsinmi, wọ́n sì jókòó.
Pawluslar bolsa Pǝrgǝ xǝⱨiridin qiⱪip, dawamliⱪ mengip Pisidiyǝ rayonidiki Antakya xǝⱨirigǝ berip, xabat küni sinagogⱪa kirdi.
15 Lẹ́yìn kíka ìwé òfin àti ìwé àwọn wòlíì, àwọn olórí Sinagọgu ránṣẹ́ sí wọn, pé, “Ará, bí ẹ̀yin bá ni ọ̀rọ̀ ìyànjú kan fún àwọn ènìyàn, ẹ sọ ọ́!”
Tǝwrat ⱪisimliridin wǝ pǝyƣǝmbǝrlǝrning yazmiliridin oⱪulƣandin keyin, sinagogning qongliri ularni qaⱪirtip: — Ⱪerindaxlar, ǝgǝr halayiⱪⱪa birǝr nǝsiⱨǝt sɵzünglar bolsa, eytinglar, — dedi.
16 Paulu sì dìde dúró, ó sì juwọ́ sí wọn, ó ní, “Ẹ̀yin Israẹli, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, ẹ fi etí sílẹ̀ sí mi!
Pawlus ornidin turup, ⱪol ixiriti ⱪilip, halayiⱪⱪa mundaⱪ dedi: — Əy Israillar wǝ Hudadin ⱪorⱪⱪanlar, ⱪulaⱪ selinglar!
17 Ọlọ́run àwọn ènìyàn Israẹli yìí yan àwọn baba wa, ó sì gbé àwọn ènìyàn náà lékè, nígbà tí wọ́n ṣe àtìpó ní ilẹ̀ Ejibiti, pẹ̀lú agbára ńlá ni ó sì fi mú wọn jáde kúrò nínú rẹ̀,
Bu Israil hǝlⱪining Hudasi ata-bowilirimizni tallidi; ular Misirda musapir bolup yaxiƣan waⱪitlarda ularni uluƣ ⱪildi, Ɵzining egiz kɵtürgǝn biliki bilǝn ularni Misirdin ⱪutⱪuzup qiⱪti.
18 ní ìwọ̀n ìgbà ogójì ọdún ni ó fi mú sùúrù fún ìwà wọn ní ijù,
U qɵldǝ ularƣa tǝhminǝn ⱪiriⱪ yil ƣǝmhorluⱪ ⱪildi
19 nígbà tí ó sì ti run orílẹ̀-èdè méje ni ilẹ̀ Kenaani, ó sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ni ìní.
andin Ⱪanaan zeminidiki yǝttǝ ǝlni yoⱪitip, ularning zeminlirini ularƣa miras ⱪilip bǝrdi.
20 Gbogbo èyí sì ṣẹlẹ̀ fún ìwọ̀n àádọ́ta lé ní irinwó ọdún. “Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run fi onídàájọ́ fún wọn, títí ó fi di ìgbà Samuẹli wòlíì.
Bu ixlarƣa aldi-kǝyni bolup tǝhminǝn tɵt yüz ǝllik yil kǝtti. Keyin, taki Samuil pǝyƣǝmbǝr otturiƣa qiⱪⱪiqǝ, u ularƣa batur ⱨakimlarni tiklǝp bǝrdi.
21 Lẹ́yìn náà ni wọ́n sì béèrè ọba; Ọlọ́run sì fún wọn ní Saulu ọmọ Kiṣi, ọkùnrin kan nínú ẹ̀yà Benjamini, fún ogójì ọdún.
Andin ular bizgǝ bir padixaⱨni bǝrsikǝn, dǝp [Samuil pǝyƣǝmbǝrdin] tilidi. Xuning bilǝn Huda ularƣa Binyamin ⱪǝbilisidin Kix isimlik adǝmning oƣli Saulni tiklǝp bǝrdi. U ⱪiriⱪ yil ⱨɵküm sürdi.
22 Nígbà ti ó sì mú Saulu kúrò, ó gbé Dafidi dìde ní ọba fún wọn, ẹni tí ó sì jẹ́rìí rẹ̀ pé, ‘Mo rí Dafidi ọmọ Jese ẹni bí ọkàn mi, ti yóò ṣe gbogbo ìfẹ́ mi.’
Biraⱪ [Huda] Saulni sǝltǝnitidin qüxürüp, ularƣa Dawutni padixaⱨ ⱪilip turƣuzup bǝrdi. Huda uning ⱨǝⱪⱪidǝ guwaⱨliⱪ berip: «Kɵnglümdikidǝk bir adǝmni, yǝni Yǝssǝning oƣli Dawutni taptim. U Mening toluⱪ iradǝmgǝ ǝmǝl ⱪilidu», — dedi.
23 “Láti inú irú-ọmọ ọkùnrin yìí ni Ọlọ́run ti gbé Jesu Olùgbàlà dìde fún Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìlérí.
Ɵzi wǝdǝ ⱪilƣandǝk Huda bu adǝmning nǝslidin Israil hǝlⱪigǝ bir Ⱪutⱪuzƣuqi tiklǝp bǝrdi — u bolsa Əysaning ɵzidur!
24 Ṣáájú wíwá Jesu ni Johanu ti wàásù bamitiisi ìrònúpìwàdà fún gbogbo ènìyàn Israẹli.
U hǝlⱪning otturisiƣa qiⱪixtin alwwal, Yǝⱨya [pǝyƣǝmbǝr] qiⱪip, barliⱪ Israil hǝlⱪini towa ⱪilixni [bildüridiƣan] qɵmüldürüxni ⱪobul ⱪilinglar, dǝp jakarlidi.
25 Bí Johanu sì ti ńlá ipa tirẹ̀ já, ó ni, ‘Ta ni ẹ̀yin ṣe bí èmi jẹ́? Èmi kì í ṣe òun. Ṣùgbọ́n ẹ kíyèsi í, ẹnìkan ń bọ̀ lẹ́yìn mi, bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú.’
Yǝⱨya [pǝyƣǝmbǝr] wǝzipini tamamliƣanda, halayiⱪⱪa mundaⱪ degǝnidi: «Silǝr meni kim dǝp bilisilǝr? Mǝn silǝr kütkǝn zat ǝmǝsmǝn. Biraⱪ mana, mǝndin keyin birsi kelidu, mǝn ⱨǝtta uning ayaƣ kǝxlirini yexixkimu layiⱪ ǝmǝsmǝn!»
26 “Ará, ẹ̀yin ọmọ ìran Abrahamu, àti ẹ̀yin ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, àwa ni a rán ọ̀rọ̀ ìgbàlà yìí sí.
Əy ⱪerindaxlar, Ibraⱨimning jǝmǝtining nǝsilliri wǝ aranglardiki Hudadin ⱪorⱪⱪanlar, bu nijatliⱪning sɵz-kalami silǝrgǝ ǝwǝtildi!
27 Nítorí àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu, àti àwọn olórí wọn, nítorí tiwọn kò mọ̀ Jesu, tí wọn kò sì ní òye ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì, tí a ń kà ní ọjọọjọ́ ìsinmi fún wọn, kò yé wọn, wọ́n mú ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì yìí ṣẹ nípa dídá a lẹ́bi.
Yerusalemda turuwatⱪanlar wǝ ularning ⱨakimliri [Əysani] tonumay, uning üstidin gunaⱨkar dǝp ⱨɵküm qiⱪarƣini bilǝn, ⱨǝr xabat küni oⱪulidiƣan pǝyƣǝmbǝrlǝrning aldin eytⱪan sɵzlirini ǝmǝlgǝ axurdi.
28 Àti bí wọn kò tilẹ̀ ti rí ọ̀ràn ikú sí i, síbẹ̀ wọn rọ Pilatu láti pa á.
Gǝrqǝ ular uningdin ɵlüm jazasiƣa ⱨɵküm ⱪilixⱪa tegixlik birǝr gunaⱨ tapalmiƣan bolsimu, waliy Pilatustin yǝnila uni ɵlümgǝ mǝⱨkum ⱪilixni ɵtündi.
29 Bí wọ́n ti mú nǹkan gbogbo ṣẹ ti a kọ̀wé nítorí rẹ̀, wọn sì sọ̀ ọ́ kalẹ̀ kúrò lórí igi, wọ́n sì tẹ́ ẹ sí ibojì.
Ular [bu] [ixlarni ⱪilip] muⱪǝddǝs yazmilarda uning ⱨǝⱪⱪidǝ aldin pütülgǝnlǝrning ⱨǝmmisini [ɵzliri bilmigǝn ⱨalda] ǝmǝlgǝ axurƣandin keyin, uning jǝsitini kresttin qüxürüp, bir ⱪǝbrigǝ ⱪoydi.
30 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú,
Lekin Huda uni ɵlümdin tirildürdi!
31 o sì farahàn lọ́jọ́ púpọ̀ fún àwọn tí ó bá a gòkè láti Galili wá sí Jerusalẹmu, àwọn tí í ṣe ẹlẹ́rìí rẹ̀ nísinsin yìí fún àwọn ènìyàn.
Tirilgǝndin keyin, u burun ɵzi bilǝn Galiliyǝdin Yerusalemƣiqǝ ǝgixip kǝlgǝnlǝrgǝ kɵp künlǝr iqidǝ [nǝqqǝ ⱪetim] kɵrünüp turdi. Bu kixilǝr ⱨazir [Israil] hǝlⱪigǝ uning guwaⱨqiliri boluwatidu.
32 “Àwa sì mú ìyìnrere wá fún yín pé, ìlérí èyí tí Ọlọ́run ti ṣe fún àwọn baba wa,
Bizmu ata-bowilirimizƣa ⱪilinƣan wǝdining hux hǝwirini silǝrgǝ ⱨazir jakarlaymiz — Huda Əysani [arimizda] tiklǝp, bu wǝdini ularning ǝwladliri bolƣan bizlǝrgǝ ǝmǝlgǝ axurdi. Bu ⱨǝⱪtǝ Zǝburning ikkinqi küyidǝ aldin’ala mundaⱪ pütülgǝn: «Sǝn Mening Oƣlum, Ɵzüm seni bügünki künidǝ tuƣdurdum».
33 èyí ni Ọlọ́run ti mú ṣẹ fún àwa ọmọ wọn, nípa gbígbé Jesu dìde, bí a sì ti kọ̀wé rẹ̀ nínú Saamu kejì pé, “‘Ìwọ ni Ọmọ mi; lónìí ni mo bí ọ.’
34 Àti ni tí pé Ọlọ́run jí i dìde kúrò nínú òkú, ẹni tí kì yóò tún padà sí ìbàjẹ́ mọ́, ó wí báyìí pé: “‘Èmi ó fún yín ní ọ̀rẹ́ mímọ́ Dafidi, tí ó dájú.’
Əmdiliktǝ Hudaning Əysaƣa qirixni ⱪayta kɵrgüzmǝy ɵlümdin tirildüridiƣanliⱪi ⱨǝⱪⱪidǝ u [muⱪǝddǝs yazmilarda] mundaⱪ aldin eytⱪan: «Dawutⱪa wǝdǝ ⱪilƣan meⱨir-xǝpⱪǝtlǝrni silǝrgǝ ata ⱪilimǝn!»
35 Nítorí ó sì wí nínú Saamu mìíràn pẹ̀lú pé, “‘Ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́.’
Xunga yǝnǝ bu ⱨǝⱪtǝ yǝnǝ bir ayǝttǝ: — «[I Huda], Sening muⱪǝddǝs Bolƣuqungƣa tenining qirixini kɵrgüzmǝysǝn».
36 “Nítorí lẹ́yìn ìgbà ti Dafidi ti sin ìran rẹ tan nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, ó sùn, a sì tẹ́ ẹ ti àwọn baba rẹ̀, ara rẹ̀ sì rí ìdíbàjẹ́.
Qünki Dawut dǝrwǝⱪǝ Hudaning iradisi boyiqǝ ɵz dǝwri üqün hizmǝt ⱪilip, ɵz ata-bowiliriƣa ⱪoxulup ɵlümdǝ uhlap uning teni qirip kǝtkǝnidi.
37 Ṣùgbọ́n ẹni tí Ọlọ́run jí dìde kò rí ìdíbàjẹ́.
Lekin Huda ɵlümdin tirildürgüqi bolsa qirixni ⱨeq kɵrmidi.
38 “Ǹjẹ́ kí ó yé yín, ará pé nípasẹ̀ Jesu yìí ni a ń wàásù ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ fún yín.
Əmdi xunga silǝr xuni bilixinglar kerǝkki, i ⱪerindaxlar, ⱨazir gunaⱨlardin kǝqürüm ⱪilinix yoli dǝl xu kixi arⱪiliⱪ silǝrgǝ jakarliniwatidu.
39 Nípa rẹ̀ ni a ń dá olúkúlùkù ẹni tí ó gbàgbọ́ láre kúrò nínú ohun gbogbo, tí a kò lè dá yín láre rẹ̀ nínú òfin Mose.
Musa pǝyƣǝmbǝrgǝ qüxürülgǝn Tǝwrat ⱪanuni bilǝn silǝr halas bolalmaywatⱪan ixlardin uningƣa etiⱪad ⱪilƣuqilar u arⱪiliⱪ halas ⱪilinip ⱨǝⱪⱪaniy ⱪilinidu!
40 Nítorí náà, ẹ kíyèsára, kí èyí tí a ti sọ nínú ìwé àwọn wòlíì má ṣe dé bá yín pé:
Xunga, pǝyƣǝmbǝrlǝr aldin eytⱪan xu balayi’apǝt bexinglarƣa qüxmǝsliki üqün eⱨtiyat ⱪilinglar! —
41 “‘Ẹ wò ó, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn, kí ẹnu sì yà yín, kí a sì fẹ́ yín kù; nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín, tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.’”
«Ⱪaranglar, i mazaⱪ ⱪilƣuqilar, ⱨǝyranuⱨǝs bolup ⱨalak bolunglar! Qünki silǝrning künliringlarda bir ix ⱪilimǝnki, Uni birsi silǝrgǝ elan ⱪilsimu silǝr xu ixⱪa ⱨǝrgiz ixǝnmǝysilǝr!»
42 Bí Paulu àti Barnaba sì ti ń jáde láti inú Sinagọgu, wọ́n bẹ̀bẹ̀ pé kí a sọ̀rọ̀ wọ̀nyí sí i fún wọn lọ́jọ́ ìsinmi tí ń bọ̀.
Pawlus bilǝn Barnabas sinagogdin qiⱪiwatⱪanda, jamaǝt ularƣa kelǝrki xabat küni bu ixlar ⱨǝⱪⱪidǝ yǝnǝ sɵzlǝxni yelindi.
43 Nígbà tí wọn sì jáde nínú Sinagọgu, ọ̀pọ̀ nínú àwọn Júù àti nínú àwọn olùfọkànsìn aláwọ̀ṣe Júù tẹ̀lé Paulu àti Barnaba, àwọn ẹni tí ó bá wọn sọ̀rọ̀ tí wọ́n sì rọ̀ wọ́n láti dúró nínú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run.
Sinagogtiki jamaǝt tarⱪalƣanda, nurƣun Yǝⱨudiylar wǝ Hudadin ⱪorⱪⱪan Tǝwratⱪa etiⱪad ⱪilƣan Yǝⱨudiy ǝmǝslǝrmu Pawlus bilǝn Barnabasⱪa ǝgǝxti. Ikkisi ularƣa sɵz ⱪilip, ularni Hudaning meⱨir-xǝpⱪitidǝ qing turuxⱪa dǝwǝt ⱪildi.
44 Ní ọjọ́ ìsinmi kejì, gbogbo ìlú sí fẹ́rẹ̀ péjọ tan láti gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Keyinki xabat küni, pütün xǝⱨǝr hǝlⱪi degüdǝk Hudaning sɵz-kalamini angliƣili kelixti.
45 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Júù rí ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, wọ́n kún fún owú, wọ́n ń sọ̀rọ̀-òdì sí ohun ti Paulu ń sọ.
Biraⱪ bundaⱪ top-top adǝmlǝrni kɵrgǝn Yǝⱨudiylar ⱨǝsǝtkǝ qɵmüp, Pawlusning sɵzlirigǝ ⱪarxi tǝtür gǝp ⱪilip, uningƣa tɵⱨmǝt ⱪildi.
46 Paulu àti Barnaba sì dá wọn lóhùn láìbẹ̀rù pé, “Ẹ̀yin ni ó tọ́ sí pé ki a kọ́kọ́ sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún yín, ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti ta á nù, tí ẹ sì ka ara yín sí aláìyẹ fún ìyè àìnípẹ̀kun, wò ó, àwa yípadà sọ́dọ̀ àwọn aláìkọlà. (aiōnios )
Əmdi Pawlus bilǝn Barnabas tehimu yürǝklik ⱨalda mundaⱪ dedi: — Hudaning sɵz-kalamini aldi bilǝn silǝr [Yǝⱨudiy hǝlⱪigǝ] yǝtküzüx kerǝk idi. Lekin silǝr uni qǝtkǝ ⱪeⱪip ɵzünglarni mǝnggülük ⱨayatⱪa layiⱪ kɵrmigǝndin keyin, mana biz [silǝrdin] burulup ǝllǝrgǝ yüzlinimiz! (aiōnios )
47 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa ṣa ti pàṣẹ fún wa pé: “‘Mo ti gbé ọ kalẹ̀ láti tan ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà, kí ìwọ lè mú ìgbàlà wá títí dé òpin ayé.’”
Qünki Pǝrwǝrdigar [muⱪǝddǝs yazmilarda] bizgǝ mundaⱪ buyruƣan: — «Mǝn Seni [yat] ǝllǝrgǝ nur boluxⱪa, Yǝr yüzining qǝt-yaⱪiliriƣiqǝ nijatliⱪ boluxung üqün Seni atidim».
48 Nígbà tí àwọn aláìkọlà sì gbọ́ èyí, wọ́n sì yín ọ̀rọ̀ Ọlọ́run lógo: gbogbo àwọn tí a yàn sí ìyè àìnípẹ̀kun sì gbàgbọ́. (aiōnios )
Əllǝrdikilǝr bu sɵzni anglap, huxal boluxup Rǝbning sɵz-kalamini uluƣlaxti; mǝnggülük ⱨayatⱪa erixixkǝ bekitilgǝnlǝrning ⱨǝmmisi etiⱪad ⱪildi. (aiōnios )
49 A sí tan ọ̀rọ̀ Olúwa ká gbogbo agbègbè náà.
Xundaⱪ ⱪilip, Rǝbning sɵz-kalami pütkül zeminƣa tarⱪaldi.
50 Ṣùgbọ́n àwọn Júù rú àwọn obìnrin olùfọkànsìn àti ọlọ́lá sókè àti àwọn àgbà ìlú náà, wọ́n sì gbé inúnibíni dìde sí Paulu àti Barnaba, wọ́n sì le wọn kúrò ni agbègbè wọn.
Biraⱪ Yǝⱨudiylar Hudadin ⱪorⱪⱪan yuⱪiri tǝbiⱪilik ayallarni ⱨǝm xǝⱨǝr mɵtiwǝrlirini ⱪutritip, Pawlus bilǝn Barnabasⱪa ziyankǝxlik ⱪilƣuzup, ular ikkisini ɵz yurtliridin ⱪoƣlap qiⱪardi.
51 Ṣùgbọ́n wọ́n gbọn eruku ẹsẹ̀ wọn sí wọn, wọn sì wá sí Ikoniomu.
Əmma Pawlus bilǝn Barnabas ularƣa ⱪarap ayaƣliridiki topini ⱪeⱪixturuwetip, Konya xǝⱨirigǝ ⱪarap mangdi.
52 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn si kún fún ayọ̀ àti fún Ẹ̀mí Mímọ́.
[Antakyadiki] muhlislar bolsa huxalliⱪⱪa ⱨǝmdǝ Muⱪǝddǝs Roⱨⱪa tolduruldi.